< Luke 12 >
1 Ó sì ṣe, nígbà tí àìníye ìjọ ènìyàn péjọpọ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí wọn ń tẹ ara wọn mọ́lẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sísọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ máa ṣọ́ra yín nítorí ìwúkàrà àwọn Farisi tí í ṣe àgàbàgebè.
ⲁ̅((ⲉⲛ ⲟⲓⲥ ⲉⲧⲁⲩⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲑⲃⲁ ⳿ⲙⲙⲏϣ ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲩϩⲱⲙⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲟⲩⲉⲣⲏⲟⲩ ⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϫⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⲙⲁϩⲑⲏⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⳿ⲡϣⲉⲙⲏⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲫⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲉⲧⲉ ⲧⲟⲩⲙⲉⲧϣⲟⲃⲓ ⲧⲉ.
2 Kò sí ohun tí a bò, tí a kì yóò sì fihàn; tàbí tí ó pamọ́, tí a kì yóò mọ̀.
ⲃ̅⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⲉϥϩⲟⲃⲥ ϫⲉ ⳿ϥⲛⲁϭⲱⲣⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ ⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲡⲉⲧϩⲏⲡ ϫⲉ ⲥⲉⲛⲁ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ.
3 Nítorí náà ohunkóhun tí ẹ̀yin sọ ní òkùnkùn, ní gbangba ni a ó ti gbọ́ ọ; àti ohun tí ẹ̀yin bá sọ sí etí ní iyàrá, lórí òrùlé ni a ó ti kéde rẹ̀.
ⲅ̅ⲛⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϫⲟⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡ ⲭⲁⲕⲓ ⲥⲉⲛⲁⲥⲟⲑⲙⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲙⲁϣϫ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲧⲁⲙⲓⲟⲛ ⲉⲩ⳿ⲉϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϩⲓϫⲉⲛ ⲛⲓϫⲉⲛⲉⲫⲱⲣ.
4 “Èmi sì wí fún yín ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn tí ó ń pa ara ènìyàn kú, lẹ́yìn èyí, wọn kò sì ní èyí tí wọ́n lè ṣe mọ́.
ⲇ̅ϯϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲛⲁ⳿ϣⲫⲏⲣ ϫⲉ ⲙⲡⲉⲣⲉⲣϩⲟϯ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲑⲛⲁϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲙⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲉⲁⲓϥ.
5 Ṣùgbọ́n èmi ó sì sọ ẹni tí ẹ̀yin ó bẹ̀rù fún yín: Ẹ bẹ̀rù ẹni tí ó lágbára lẹ́yìn tí ó bá pànìyàn tan, láti wọ́ ni lọ sí ọ̀run àpáàdì. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín òun ni kí ẹ bẹ̀rù. (Geenna )
ⲉ̅ⲛⲁⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ϫⲉ ⲁⲣⲓϩⲟϯ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲛⲛⲓⲙ ⲁⲣⲓϩⲟϯ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲉ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲉⲑⲣⲉϥϧⲱⲧⲉⲃ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉϥ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲉϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϯⲅⲉⲉⲛⲛⲁ ⲁϩⲁ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲁⲣⲓϩⲟϯ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲫⲁⲓ. (Geenna )
6 Ológoṣẹ́ márùn-ún sá à ni a ń tà ní owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì? A kò sì gbàgbé ọ̀kan nínú wọn níwájú Ọlọ́run?
ⲋ̅ⲙⲏ ⲉ̅ ⳿ⲛϭⲁϫ ⲁⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲩϯ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁ ⲧⲉⲃⲓ ⳿ⲥⲛⲟⲩϯ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⲥⲉⲟⲃϣ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫϯ.
7 Ṣùgbọ́n gbogbo irun orí yín ni a kà pé ṣánṣán. Nítorí náà kí ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ̀yin ní iye lórí ju ológoṣẹ́ púpọ̀ lọ.
ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲓⲕⲉϥⲱⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲁⲫⲉ ⲥⲉⲏⲡ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣϩⲟϯ ⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲟⲧ ⳿ⲉⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛϭⲁϫ.
8 “Mo sì wí fún yín pẹ̀lú, Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́wọ́ mi níwájú àwọn ènìyàn. Ọmọ Ènìyàn yóò sì jẹ́wọ́ rẹ̀ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run.
ⲏ̅ϯϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ϩⲱϥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ ⲛⲁⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲙⲡⲉⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
9 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sẹ́ mi níwájú ènìyàn, a ó sẹ́ ẹ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run.
ⲑ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲑⲛⲁϫⲟⲗⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲥⲉⲛⲁϫⲟⲗⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲱϥ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
10 Àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ọmọ Ènìyàn, a ó dárí rẹ̀ jì í; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, a kì yóò dárí rẹ̀ jì í.
ⲓ̅ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁϫⲉ ⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ ⲥⲉⲛⲁⲭⲁϥ ⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲑⲛⲁϫⲉⲟⲩⲁ ⲉⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲛⲛⲟⲩ ⲭⲱ ⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
11 “Nígbà tí wọ́n bá sì mú yin wá sí Sinagọgu, àti síwájú àwọn olórí, àti àwọn aláṣẹ, ẹ má ṣe ṣàníyàn pé, báwo tàbí ohun kín ni ẹ̀yin yóò fèsì rẹ̀ tàbí kín ni ẹ̀yin ó wí.
ⲓ̅ⲁ̅ϩⲟⲧⲁⲛ ⲁⲩϣⲁⲛ⳿ⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲛⲓⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲁⲣⲭⲏ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲉⲝⲟⲩⲥⲓ⳿ⲁ ⲙⲡⲉⲣϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⲓⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲓⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϫⲟϥ.
12 Nítorí Ẹ̀mí Mímọ́ yóò kọ́ yín ní wákàtí kan náà ní ohun tí ó yẹ kí ẹ sọ.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲅⲁⲣ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲛⲁ⳿ⲧⲥⲁⲃⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲏⲉⲑⲛⲁⲥⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛϫⲟⲧⲟⲩ.
13 Ọ̀kan nínú àwùjọ wí fún un pé, “Olùkọ́, sọ fún arákùnrin mi kí ó pín mi ní ogún.”
ⲓ̅ⲅ̅ⲡⲉϫⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⲇⲉ ⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲓⲙⲏϣ ϫⲉ ⲡⲓⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲁϫⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲁⲥⲟⲛ ⲉⲑⲣⲉϥⲫⲱϣ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁϥ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⳿ⲛϯ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓ⳿ⲁ.
14 Ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin yìí, ta ni ó fi mí jẹ onídàájọ́ tàbí olùpíngún fún yín?”
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲙ ⲡⲉⲧⲁϥⲭⲁⲧ ⳿ⲛⲣⲉϥϯϩⲁⲡ ⲓⲉ ⳿ⲛⲣⲉϥⲫⲱϣ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Kíyèsára kí o sì máa ṣọ́ra nítorí ojúkòkòrò: nítorí ìgbésí ayé ènìyàn kò dúró lé ọ̀pọ̀ ohun tí ó ní.”
ⲓ̅ⲉ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲇⲉ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϫⲉ ⲛⲁⲣⲉ ⳿ⲡⲱⲛϧ ϣⲟⲡ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲧⲁϥ.
16 Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ilẹ̀ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
ⲓ̅ⲋ̅ⲁϥϫⲉ ⲟⲩⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲇⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⳿ⲉⲁⲥⲉⲣϣⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲉϥⲭⲱⲣⲁ.
17 Ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èmi ó ti ṣe, nítorí tí èmi kò ní ibi tí èmi ó gbé kó èso mi jọ sí.’
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲙⲟⲕⲙⲉⲕ ⲡⲉ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉϯⲛⲁⲁⲓϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛϯ ⲙⲁ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲑⲣⲓⲑⲱⲟⲩϯ ⲛⲛⲁⲟⲩⲧⲁϩ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
18 “Ó sì wí pé, ‘Èyí ni èmi ó ṣe: èmi ó wó àká mi palẹ̀, èmi ó sì kọ́ èyí tí ó tóbi; níbẹ̀ ni èmi ó gbé to gbogbo èso àti ọrọ̀ mi jọ sí.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲫⲁⲓ ϯⲛⲁⲁⲓϥ ϯⲛⲁϣⲟⲣϣⲉⲣ ⳿ⲛⲛⲁ⳿ⲁⲡⲟⲑⲏⲕⲏ ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲁⲕⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲧⲁⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲉⲙⲁⲩ ⳿ⲙⲡⲁⲥⲟⲩ⳿ⲟ ⲧⲏⲣϥ ⲛⲉⲙ ⲛⲁⲁⲅⲁⲑⲟⲛ.
19 Èmi ó sì wí fún ọkàn mi pé, ọkàn, ìwọ ní ọrọ̀ púpọ̀ tí a tò jọ fún ọ̀pọ̀ ọdún; sinmi, máa jẹ, máa mu, máa yọ̀.’
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲁϫⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲁⲯⲩⲭⲏ ϫⲉ ⲧⲁ ⲯⲩⲭⲏ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲁⲅⲁⲑⲟⲛ ⲭⲏ ⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲙⲧⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲟ ⲟⲩⲱⲙ ⲥⲱ ⲟⲩⲛⲟϥ ⳿ⲙⲙⲟ.
20 “Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Ìwọ aṣiwèrè, lóru yìí ni a ó béèrè ọkàn rẹ lọ́wọ́ rẹ; ǹjẹ́ ti ta ni nǹkan wọ̀nyí yóò ha ṣe, tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀?’
ⲕ̅ⲡⲉϫⲉ ⲫϯ ⲇⲉ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲓⲁⲧϩⲏⲧ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲥⲉⲛⲁⲱⲗⲓ ⲛⲧⲉⲕⲯⲩⲭⲏ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧⲕ ⲛⲏⲉⲧⲁⲕⲑⲟⲩⲱⲧⲟⲩ ⲉⲩⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲙ.
21 “Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó to ìṣúra jọ fún ara rẹ̀, tí kò sì ní ọrọ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲟⲓ ⲛⲣⲁⲙⲁⲟ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⲫϯ.
22 Jesu sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Nítorí náà mo wí fún yín pé, ẹ má ṣe ṣe àníyàn nítorí ẹ̀mí yín pé, kín ni ẹ̀yin yóò jẹ tàbí nípa ara yin pe kín ni ẹyin o fi bora.
ⲕ̅ⲃ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲣϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϧⲁ ⲧⲉⲧⲉⲛⲯⲩⲭⲏ ϫⲉ ⲩ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲟⲩⲟⲙϥ ⲟⲩⲇⲉ ϧⲁ ⲡⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲙⲁ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲧⲏⲓϥ ϩⲓ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
23 Ẹ̀mí sá à ju oúnjẹ lọ, ara sì ju aṣọ lọ.
ⲕ̅ⲅ̅ϯⲯⲩⲭⲏ ⲅⲁⲣ ⲟⲩⲟⲧ ⳿ⲉϯ ⳿ϧⲣⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲉϯϩⲉⲃⲥⲱ.
24 Ẹ kíyèsi àwọn ẹyẹ ìwò: wọn kì í fúnrúgbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í kórè: wọn kò ní àká, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní abà, Ọlọ́run sá à ń bọ́ wọn: mélòó mélòó ni tí ẹ̀yin fi sàn ju ẹyẹ lọ!
ⲕ̅ⲇ̅ⲙⲁⲓⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲃⲱⲕ ϫⲉ ⲥⲉⲥⲓϯ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲱⲥϧ ⲁⲛ ⲛⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲧⲁⲙⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲱⲟⲩ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲁⲡⲟⲑⲏⲕⲏ ⲟⲩⲟϩ ϯ ϣⲁⲛϣ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲁⲩⲏⲣ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲟⲧ ⳿ⲉⲛⲓϩⲁⲗⲁϯ.
25 Ta ni nínú yín nípa àníyàn ṣíṣe tí ó lè fi ìgbọ̀nwọ́ kan kún ọjọ́ ayé rẹ̀?
ⲕ̅ⲉ̅ⲛⲓⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉϥϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ⳿ⲉⲧⲉⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲧⲁⲗⲉ ⲟⲩⲙⲁϩⲓ ⳿ⲛϣⲓⲏ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲧⲉϥⲙⲁⲓⲏ.
26 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò ti lè ṣe èyí tí ó kéré bí eléyìí, èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣàníyàn nítorí ìyókù?
ⲕ̅ⲋ̅ⲓⲥϫⲉ ⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ⲓⲉ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϧⲁ ⳿ⲡⲥⲉⲡⲓ.
27 “Ẹ kíyèsi àwọn lílì bí wọ́n ti ń dàgbà; wọn kì í ṣiṣẹ́, wọn kì í rànwú; ṣùgbọ́n kí èmi wí fún yín, a kò ṣe Solomoni pàápàá lọ́ṣọ̀ọ́ ní gbogbo ògo rẹ̀ tó ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí.
ⲕ̅ⲍ̅ⲙⲁⲓⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ϩⲣⲏⲣⲓ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⲥⲉⲁⲓⲁⲓ ⳿ⲛⲥⲉϧⲟⲥⲓ ⲁⲛ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲛⲥⲉⲉⲣⲓⲟⲡⲏ ⲁⲛ ϯϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⲟⲗⲟⲙⲱⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲙⲡⲉϥϯ ϩⲓⲱⲧϥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ.
28 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá wọ koríko igbó ní aṣọ tó bẹ́ẹ̀ èyí tí ó wà lónìí, tí a sì gbá a sínú iná lọ́la: mélòó mélòó ni yóò wọ̀ yín láṣọ, ẹ̀yin onígbàgbọ́ kékeré.
ⲕ̅ⲏ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⲡⲓⲥⲓⲙ ⳿ϥϣⲟⲡ ⳿ⲙⲫⲟⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲣⲁⲥϯ ⲁⲩϩⲓⲧϥ ⳿ⲉϯ⳿ⲑⲣⲓⲣ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲫϯ ϯϩⲉⲃⲥⲱ ϩⲓⲱⲧϥ ⲡⲟⲥⲱ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲛⲁ ⲡⲓⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛⲛⲁϩϯ.
29 Kí ẹ má sì ṣe lé ohun tí ẹ ó jẹ, tàbí ohun tí ẹ ó mu, kí ẹ má sì ṣe ṣe àníyàn nínú ọkàn.
ⲕ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲕⲱϯ ϫⲉ ⲟⲩ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲟⲩⲟⲙϥ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲥⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉⲣϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ.
30 Nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè ayé ń wá kiri. Baba yín sì mọ̀ pé, ẹ̀yin ń fẹ́ nǹkan wọ̀nyí.
ⲗ̅ⲛⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲓⲉⲑⲛⲓⲕⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲥⲉⲕⲱϯ ⲛⲥⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉⲛⲓⲱⲧ ⲥⲱⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣ⳿ⲭⲣⲓⲁ ⳿ⲛⲛⲁⲓ.
31 Ṣùgbọ́n ẹ máa wá ìjọba Ọlọ́run, gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a ó sì fi kún un fún yín.
ⲗ̅ⲁ̅⳿ⲡⲗⲏⲛ ⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲧⲉϥⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲥⲉⲛⲁⲟⲩⲁϩⲟⲩ ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ.
32 “Má bẹ̀rù, agbo kékeré, nítorí dídùn inú Baba yín ni láti fi ìjọba fún yín.
ⲗ̅ⲃ̅⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣϩⲟϯ ⲡⲓⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛ⳿ⲟϩⲓ ϫⲉ ⲁϥ ϯⲙⲁϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲓⲱⲧ ⳿ⲉϯ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϯ ⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ.
33 Ẹ ta ohun tí ẹ̀yin ní, kí ẹ sì tọrẹ àánú kí ẹ sì pèsè àpò fún ara yín, tí kì í gbó, ìṣúra ní ọ̀run tí kì í tán, ní ibi tí olè kò lè súnmọ́, àti ibi tí kòkòrò kì í bà á jẹ́.
ⲗ̅ⲅ̅ⲙⲁ ⲉⲧⲉⲛϩⲩⲡⲁⲣⲭⲟⲛⲧ⳿ⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲙⲏⲓⲧⲟⲩ ⲉⲑⲙⲉⲧⲛⲁⲏⲧ ⲙⲁⲑⲁⲙⲓ⳿ⲟ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲁⲥⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲩⲉⲣⲁⲡⲁⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲁϩⲟ ⳿ⲛⲁⲑⲙⲟⲩⲛⲕ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲓⲙⲁ ⲧⲉ⳿ⲙⲡⲁⲣⲉ ⲣⲉϥϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ϧⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲉ ϩⲟⲗⲓ ⲧⲁⲕⲟϥ.
34 Nítorí ní ibi tí ìṣúra yín gbé wà, níbẹ̀ ni ọkàn yín yóò gbé wà pẹ̀lú.
ⲗ̅ⲇ̅ⲡⲓⲙⲁ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲁϩⲟ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉϥ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛϫⲉ ⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ.
35 “Ẹ di àmùrè yín, kí fìtílà yín sì máa jó.
ⲗ̅ⲉ̅ⲙⲁⲣⲟⲩϣⲱⲡⲓ ⲉⲩϧⲏⲕ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛϯⲡⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉⲧⲉⲛϧⲏⲃⲥ ⲉⲩⲙⲟϩ.
36 Kí ẹ̀yin tìkára yín dàbí ẹni tí ń retí olúwa wọn, nígbà tí òun ó padà ti ibi ìgbéyàwó dé, pé nígbà tí ó bá dé, tí ó sì kànkùn, kí wọn lè ṣí i sílẹ̀ fún un lọ́gán.
ⲗ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲟⲛⲓ ⳿ⲛϩⲁⲛⲣⲱⲙⲓ ⲉⲩϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲡⲟⲩϫ̅ ⲥ̅ ϫⲉ ⳿ϥⲛⲁϯⲟⲩⲱ ⳿ⲛ⳿ⲑⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓϩⲟⲡ ϩⲓⲛⲁ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥⲕⲱⲗϩ ⲥⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲉⲁⲟⲩⲱⲛ ⲛⲁϥ.
37 Ìbùkún ni fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà nígbà tí olúwa náà bá dé tí yóò bá wọn tí wọn ń ṣọ́nà; lóòótọ́ ni mo wí fún yín, yóò di ara rẹ̀ ní àmùrè yóò sì mú wọn jókòó láti jẹun, yóò sì jáde wá láti ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
ⲗ̅ⲍ̅ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲉⲃⲓⲁⲓⲕ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲏⲉⲧⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲟⲩϫ̅ⲥ̅ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲉⲙⲟⲩ ⲉⲩⲣⲏ ⲥ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ϥⲛⲁϧⲟⲕϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲑⲣⲟⲩⲣⲱⲧⲉⲃ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲉⲙϣⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
38 Bí olúwa wọn bá sì dé nígbà ìṣọ́ kejì, tàbí tí ó sì dé nígbà ìṣọ́ kẹta, tí ó sì bá wọn bẹ́ẹ̀, ìbùkún ni fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà.
ⲗ̅ⲏ̅ⲕⲁⲛ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ϧⲉⲛ ϯⲙⲁϩ⳿ⲥⲛⲟⲩϯ ⲕⲁⲛ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ϧⲉⲛ ϯⲙⲁϩⲅ̅ϯ ⳿ⲛⲟⲩⲉⲣϣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲉⲙⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
39 Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí tí olè yóò wá, òun ìbá máa ṣọ́nà, kì bá tí jẹ́ kí a já wọ inú ilé òun.
ⲗ̅ⲑ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ⲁⲣⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉ ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ⲡⲓⲛⲉⲃⲏⲓ ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ϧⲉⲛ ⲁϣ ⳿ⲛⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲣⲉϥϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲁϥⲛⲁⲣⲱⲓⲥ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲛⲁⲭ ⲁⲩ ⲁⲛ ⲡⲉ ⳿ⲉⲉⲣϣⲁⲧⲥ ⳿ⲉⲡⲉϥⲏⲓ.
40 Nítorí náà, kí ẹ̀yin múra pẹ̀lú, nítorí Ọmọ Ènìyàn ń bọ̀ ní wákàtí tí ẹ̀yin kò nírètí.”
ⲙ̅ⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ϣⲱⲡⲓ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ϫⲉ ϧⲉⲛ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ ⳿ϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ.
41 Peteru sì wí pé, “Olúwa, ìwọ pa òwe yìí fún wa, tàbí fún gbogbo ènìyàn?”
ⲙ̅ⲁ̅ⲡⲉϫⲉ ⲉⲧⲣⲟⲥ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⲁⲕϫⲱ ⳿ⲛⲧⲁⲓⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⳿ⲉⲣⲟⲛ ϣⲁⲛ ⲁⲕϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
42 Olúwa sì dáhùn wí pé, “Ta ni olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ìríjú náà, tí olúwa rẹ̀ fi jẹ olórí agbo ilé rẹ̀, láti máa fi ìwọ̀n oúnjẹ wọ́n fún wọn ní àkókò?
ⲙ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ Ⲡ⳪ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ϩⲁⲣⲁ ⲡⲉ ⲡⲓⲡⲓⲥⲧⲟⲥ ⲛⲟⲓⲕⲟⲛⲟⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲁⲃⲉ ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲡⲉϥϫ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲭⲁϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲉϥⲉⲃⲓⲁⲓⲕ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉϥϯ ⳿ⲛⲧⲟⲩ⳿ϧⲣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲏⲓⲥ.
43 Ìbùkún ni fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nígbà tí olúwa rẹ̀ bá dé, tí yóò bá a kí ó máa ṣe bẹ́ẹ̀.
ⲙ̅ⲅ̅ⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧϥ ⲙⲡⲓⲃⲱⲕ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲫⲏⲉⲧⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉϥϫ̅ⲥ̅ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲉⲙϥ ⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
44 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín yóò fi jẹ olórí ohun gbogbo tí ó ní.
ⲙ̅ⲇ̅ⲧⲁ⳿ⲫⲙⲏⲓ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ϥⲛⲁⲭⲁϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲉϥϩⲩⲡⲁⲣⲭⲟⲛⲧ⳿ⲁ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
45 Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá wí ní ọkàn rẹ̀, pé, ‘Olúwa mi fi ìgbà bíbọ̀ rẹ̀ falẹ̀!’ Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í lu àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ àti sí mu àmupara:
ⲙ̅ⲉ̅ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁϥϣⲁⲛϫⲟⲥ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲃⲱⲕ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ϫⲉ ⲡⲁϫ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲱⲥⲕ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉϥ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲧⲉϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲃⲱⲕ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲃⲱⲕⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥⲟⲩⲱⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲥⲱ ⳿ⲛⲧⲉϥⲑⲓϧⲓ.
46 Olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ náà yóò dé ní ọjọ́ tí kò retí rẹ̀, àti ní wákàtí tí kò dábàá, yóò sì jẹ ẹ́ ní yà gidigidi, yóò sì yan ipò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́.
ⲙ̅ⲋ̅⳿ϥⲛⲁⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲙⲡⲓⲃⲱⲕ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϧⲉⲛ ⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉϥⲥⲟⲙⲥ ϧⲁϫⲱϥ ⲁⲛ ⲛⲉⲙ ϧⲉⲛ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉϥⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲛⲁⲫⲟⲣϫϥ ϧⲉⲛ ⲧⲉϥⲙⲏϯ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉϥⲧⲟⲓ ⲛⲁⲭⲁⲥ ⲛⲉⲙ ⲓⲁⲑⲛⲁϩϯ.
47 “Àti ọmọ ọ̀dọ̀ náà, tí ó mọ ìfẹ́ olúwa rẹ̀, tí kò sì múra sílẹ̀, tí kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, òun ni a ó nà púpọ̀.
ⲙ̅ⲍ̅ⲡⲓⲃⲱⲕ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉ⳿ⲫⲟⲩⲱϣ ⳿ⲙⲡⲉϥϫ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲉϥⲥⲟⲃϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⲛⲉϥⲟⲩⲱϣ ⲥⲉⲛⲁϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲛϣⲁϣ ⲛⲁϥ.
48 Ṣùgbọ́n èyí tí kò mọ̀, tí ó ṣe ohun tí ó yẹ sí lílù, òun ni a ó lù níwọ̀n. Nítorí ẹnikẹ́ni tí a fún ní púpọ̀, lọ́dọ̀ rẹ̀ ni a ó gbé béèrè púpọ̀: lọ́dọ̀ ẹni tí a bá gbé fi púpọ̀ sí, lọ́dọ̀ rẹ ni a ó gbé béèrè sí i.
ⲙ̅ⲏ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧⲥⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛϩⲁⲛϣⲏϣⲓ ⲥⲉⲛⲁϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛϣⲁϣ ⲛⲁϥ ⲟⲩⲟⲛ ⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲁⲩϯ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲛⲁϥ ⲥⲉⲛⲁⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲧⲁⲩϫⲁⲗⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲥⲉⲛⲁⲉⲣ⳿ⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ.
49 “Iná ni èmi wá láti sọ sí ayé; kín ni èmi sì ń fẹ́ bí kò ṣe kí iná náà ti jo!
ⲙ̅ⲑ̅ⲩ⳿ⲭⲣⲱⲙ ⲡⲉ ⲉⲧⲁⲓ⳿ⲓ ⳿ⲉϩⲓⲧϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩ ⲡⲉ ⳿ⲉϯⲛⲁⲟⲩⲁϣϥ ⲓⲉ ϩⲏⲇⲏ ⲁϥⲙⲟϩ.
50 Ṣùgbọ́n èmi ní bamitiisi kan tí a ó fi bamitiisi mi; ara ti ń ni mí tó títí yóò fi parí!
ⲛ̅ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲏⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲙⲥ ⳿ⲉϭⲓⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲱⲥ ⲉⲣⲥⲩⲛⲉⲭⲉⲥⲑⲉ ϣⲁⲧⲉϥϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
51 Ẹ̀yin ṣe bí àlàáfíà ni èmi fi sí ayé? Mo wí fún yín, bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n bí kò ṣe ìyapa.
ⲛ̅ⲁ̅ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲩⲓ ϫⲉ ⲉⲧⲁⲓ⳿ⲓ ⳿ⲉϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲩⲫⲱⲣϫ.
52 Nítorí láti ìsinsin yìí lọ, ènìyàn márùn-ún yóò wà ní ilé kan náà tí a ó yà ní ipa, mẹ́ta sí méjì, àti méjì sí mẹ́ta.
ⲛ̅ⲃ̅ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲅⲁⲣ ⲓⲥϫⲉⲛ ϯⲛⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲉ̅ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲏⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲉⲩⲫⲟⲣϫ ⲅ̅ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲃ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲃ̅ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲅ̅.
53 A ó ya baba nípa sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọkùnrin sí baba; ìyá sí ọmọbìnrin, àti ọmọbìnrin sí ìyá rẹ̀, ìyá ọkọ sí ìyàwó ọmọ, àti ìyàwó ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀.”
ⲛ̅ⲅ̅ⲉⲩ⳿ⲉⲫⲱⲣϫ ⳿ⲛϫⲉ ⲩⲓⲱⲧ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩϣⲏ ⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩϣⲏⲣⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲓⲱⲧ ⲟⲩⲙⲁⲩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩϣⲉⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩϣⲉⲣⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲙⲁⲩ ⲟⲩϣⲱⲙⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩϣⲉⲗⲉⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲩϣⲉⲗⲉⲧ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩϣⲱⲙⲓ.
54 Ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pẹ̀lú pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá rí àwọsánmọ̀ tí ó ṣú ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, lọ́gán ni ẹ̀yin yóò sọ pé, ‘Ọ̀wààrà òjò ń bọ̀,’ a sì rí bẹ́ẹ̀.
ⲛ̅ⲇ̅ⲛⲁϥϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲓⲕⲉⲙⲏϣ ϫⲉ ϩⲟⲧⲁⲛ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲁⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲟⲩϭⲏⲡⲓ ⳿ⲉⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲥⲁ⳿ⲡⲉⲙⲉⲛⲧ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϫⲟⲥ ⲥⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲙⲟⲩ⳿ⲛϩⲱⲟⲩ ⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
55 Nígbà tí afẹ́fẹ́ gúúsù bá ń fẹ́, ẹ̀yin á ní, ‘Oòrùn yóò mú,’ yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀.
ⲛ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲟⲧⲁⲛ ⲟⲩⲑⲟⲩⲣⲏⲥ ⲉϥⲛⲓϥⲓ ϣⲁⲣⲉⲧⲉⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⲕⲁⲩⲥⲱⲛ ⲡⲉⲑⲛⲁϣⲱⲡⲓ.
56 Ẹ̀yin àgàbàgebè! Ẹ̀yin le mòye ojú ọ̀run àti ti ayé. Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin kò mọ àkókò yìí?
ⲛ̅ⲋ̅ⲛⲓϣⲟⲃⲓ ⳿ⲡϩⲟ ⳿ⲛ⳿ⲧⲫⲉ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲉⲣⲇⲟⲕⲓⲙⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲡⲁⲓⲥⲏ ⲟⲩ ⲉ ⲛⲑⲟϥ ⲡⲱⲥ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⲁⲛ ⳿ⲛⲉⲣⲇⲟⲕⲓⲙⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
57 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin tìkára yín kò fi ro ohun tí ó tọ́?
ⲛ̅ⲍ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛϯϩⲁⲡ ⲁⲛ ⳿ⲛϯⲙⲉⲑⲙⲏ ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
58 Nígbà tí ìwọ bá bá ọ̀tá rẹ lọ sọ́dọ̀ onídàájọ́, rí i pé o bá a parí ọ̀rọ̀ ní ọ̀nà kí ó má ba à fà ọ́ fún adájọ́, adájọ́ a fi ọ́ lé ẹ̀ṣọ́ lọ́wọ́, òun a sì tì ọ́ sínú túbú.
ⲛ̅ⲏ̅ϩⲱⲥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲭⲛⲁϣⲉ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲕ⳿ⲁⲛⲧⲓⲇⲓⲕⲟⲥ ϣⲁ ⲟⲩⲁⲣⲭⲱⲛ ⲙⲟⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲱⲃ ⳿ⲛⲛⲟⲩϥⲧ ϩⲓ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁⲣⲟϥ ⲙⲏⲡⲟⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉϥⲥⲟⲕⲕ ϩⲁ ⲡⲓⲣⲉϥϯϩⲁⲡ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲣⲉϥϯ ϩⲁⲡ ⲧⲏⲓⲕ ⳿ⲉⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲡⲣⲁⲕⲧⲱⲣ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳿ⲡⲣⲁⲕⲧⲱⲣ ϩⲓⲧⲕ ⳿ⲉⲡⲓ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ.
59 Kí èmi wí fún ọ, ìwọ kì yóò jáde kúrò níbẹ̀, títí ìwọ ó fi san ẹyọ owó kan tí ó kù!”
ⲛ̅ⲑ̅ϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉⲕ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϣⲁⲧⲉⲕϯ ⳿ⲙⲡⲓϧⲁ⳿ⲉ ⳿ⲛⲗⲉⲡⲧⲟⲛ