< Luke 11 >

1 Bí ó ti ń gbàdúrà ní ibi kan, bí ó ti dákẹ́, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Olúwa, kọ́ wa bí a ti ń gbàdúrà, bí Johanu ti kọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.”
İsa bir yerde dua ediyordu. Duasını bitirince öğrencilerinden biri, “Ya Rab” dedi, “Yahya'nın kendi öğrencilerine öğrettiği gibi sen de bize dua etmesini öğret.”
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbàdúrà, ẹ máa wí pé: “‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ yín. Kí ìjọba yín dé, ìfẹ́ tiyín ni kí a ṣe, bí i ti ọrun, bẹ́ẹ̀ ni ní ayé.
İsa onlara, “Dua ederken şöyle söyleyin” dedi: “Baba, adın kutsal kılınsın. Egemenliğin gelsin.
3 Fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa lójoojúmọ́.
Her gün bize gündelik ekmeğimizi ver.
4 Kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá; nítorí àwa tìkára wa pẹ̀lú a máa dáríjì olúkúlùkù ẹni tí ó jẹ wá ní gbèsè, Má sì fà wá sínú ìdánwò, ṣùgbọ́n gbà wá lọ́wọ́ ẹni búburú ni.’”
Günahlarımızı bağışla. Çünkü biz de bize karşı suç işleyen herkesi bağışlıyoruz. Ayartılmamıza izin verme.”
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí yóò ní ọ̀rẹ́ kan, tí yóò sì tọ̀ ọ́ lọ láàrín ọ̀gànjọ́, tí yóò sì wí fún un pé, ‘Ọ̀rẹ́, yá mi ní ìṣù àkàrà mẹ́ta.
Sonra şöyle dedi: “Sizlerden birinin bir arkadaşı olur da gece yarısı ona gidip, ‘Arkadaş, bana üç ekmek ödünç ver. Bir arkadaşım yoldan geldi, önüne koyacak bir şeyim yok’ derse, öbürü içerden, ‘Beni rahatsız etme! Kapı kilitli, çocuklarım da yanımda yatıyor. Kalkıp sana bir şey veremem’ der mi hiç?
6 Nítorí ọ̀rẹ́ mi kan ti àjò dé sọ́dọ̀ mi, èmi kò sì ní nǹkan tí èmi ó gbé kalẹ̀ níwájú rẹ̀.’
7 Tí òun ó sì gbé inú ilé dáhùn wí fún un pé, ‘Má yọ mí lẹ́nu, a ti sé ìlẹ̀kùn, àwọn ọmọ mi si ń bẹ lórí ẹní pẹ̀lú mi: èmi kò lè dìde fi fún ọ!’
8 Mo wí fún yín, bí òun kò tilẹ̀ ti fẹ́ dìde kí ó fi fún un nítorí tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n nítorí àwíìyánnu rẹ̀, yóò dìde, yóò sì fún un tó bí ó ti ń fẹ́.
Size şunu söyleyeyim, arkadaşlık gereği kalkıp ona istediğini vermese bile, adamın yüzsüzlüğünden ötürü kalkar, ihtiyacı neyse ona verir.
9 “Èmí sì wí fún yín, ẹ béèrè, a ó sì fi fún un yín; ẹ wá kiri, ẹ̀yin ó sì rí; ẹ kànkùn, a ó sì ṣí i sílẹ̀ fún yín.
“Ben size şunu söyleyeyim: Dileyin, size verilecek; arayın, bulacaksınız; kapıyı çalın, size açılacaktır.
10 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá béèrè, ó rí gbà; ẹni tí ó sì ń wá kiri, ó rí; àti ẹni tí ó kànkùn ni a ó ṣí i sílẹ̀ fún.
Çünkü her dileyen alır, arayan bulur, kapı çalana açılır.
11 “Ta ni baba nínú yín tí ọmọ rẹ̀ yóò béèrè àkàrà lọ́dọ̀ rẹ̀, tí yóò fún un ní òkúta? Tàbí bí ó béèrè ẹja, tí yóò fún un ní ejò?
“Aranızda hangi baba, ekmek isteyen oğluna taş verir? Ya da balık isterse balık yerine yılan verir?
12 Tàbí bí ó sì béèrè ẹ̀yin, tí yóò fún un ní àkéekèe?
Ya da yumurta isterse ona akrep verir?
13 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin tí ó jẹ́ ènìyàn búburú bá mọ bí a ti í fi ẹ̀bùn dáradára fún àwọn ọmọ yín, mélòó mélòó ha ni Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ fún àwọn tí ó béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀!”
Sizler kötü yürekli olduğunuz halde çocuklarınıza güzel armağanlar vermeyi biliyorsanız, gökteki Baba'nın, kendisinden dileyenlere Kutsal Ruh'u vereceği çok daha kesin değil mi?”
14 Ó sì ń lé ẹ̀mí èṣù kan jáde, tí ó sì yadi. Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà jáde, odi sọ̀rọ̀; ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn.
İsa adamın birinden dilsiz bir cini kovuyordu. Cin çıkınca adamın dili çözüldü. Halk hayret içinde kaldı.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn nínú wọn wí pé, “Nípa Beelsebulu olórí àwọn ẹ̀mí èṣù ni ó fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”
Ama içlerinden bazıları, “Cinleri, cinlerin önderi Baalzevul'un gücüyle kovuyor” dediler.
16 Àwọn ẹlòmíràn sì ń dán an wò, wọ́n ń fẹ́ àmì lọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọ̀run wá.
Bazıları ise O'nu denemek amacıyla gökten bir belirti göstermesini istediler.
17 Ṣùgbọ́n òun mọ èrò inú wọn, ó wí fún wọn pé, “Gbogbo ìjọba tí ó ya ara rẹ̀ ní ipá, ni a ń sọ di ahoro; ilé tí ó sì ya ara rẹ̀ nípá yóò wó.
Onların ne düşündüğünü bilen İsa şöyle dedi: “Kendi içinde bölünen ülke yıkılır, kendi içinde bölünen ev çöker.
18 Bí Satani ba yapa sí ara rẹ̀, ìjọba rẹ̀ yóò ha ṣe dúró? Nítorí ẹ̀yin wí pé, nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.
Şeytan da kendi içinde bölünmüşse, onun egemenliği nasıl ayakta kalabilir? Siz, benim Baalzevul'un gücüyle cinleri kovduğumu söylüyorsunuz.
19 Bí ó ba ṣe pé nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, nípa ta ni àwọn ọmọ yín fi ń lé wọn jáde, nítorí náà àwọn ni yóò ṣe onídàájọ́ yín.
Eğer ben cinleri Baalzevul'un gücüyle kovuyorsam, sizin adamlarınız kimin gücüyle kovuyor? Sizi bu durumda kendi adamlarınız yargılayacak.
20 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe pé nípa ìka ọwọ́ Ọlọ́run ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, ǹjẹ́ ìjọba Ọlọ́run dé bá yín tán.
Ama ben cinleri Tanrı'nın eliyle kovuyorsam, Tanrı'nın Egemenliği üzerinize gelmiş demektir.
21 “Nígbà tí alágbára ọkùnrin tí ó ni ìhámọ́ra bá ń ṣọ́ ààfin rẹ̀, ẹrù rẹ̀ yóò wà ní àlàáfíà.
“Tepeden tırnağa silahlanmış güçlü bir adam kendi evini koruduğu sürece, malları güvenlik içinde olur.
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹni tí ó ní agbára jù ú bá kọlù ú, tí ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ a gba gbogbo ìhámọ́ra rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé lọ́wọ́ rẹ̀, a sì pín ìkógun rẹ̀.
Ne var ki, ondan daha güçlü biri saldırıp onu alt ettiğinde güvendiği bütün silahları elinden alır ve mallarını yağmalayarak bölüştürür.
23 “Ẹni tí kò bá wà pẹ̀lú mi, ó lòdì sí mi, ẹni tí kò bá sì bá mi kójọpọ̀, ó fọ́nká.
Benden yana olmayan bana karşıdır, benimle birlikte toplamayan dağıtıyor demektir.
24 “Nígbà tí ẹ̀mí àìmọ́ bá jáde kúrò lára ènìyàn, a máa rìn kiri ní ibi gbígbẹ, a máa wá ibi ìsinmi; nígbà tí kò bá sì rí, a wí pé, ‘Èmi yóò padà lọ sí ilé mi ní ibi tí mo gbé ti jáde wá.’
“Kötü ruh insandan çıkınca kurak yerlerde dolanıp huzur arar. Bulamayınca da, ‘Çıktığım eve, kendi evime döneyim’ der.
25 Nígbà tí ó bá sì dé, tí ó sì rí tí a gbá a, tí a sì ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
Eve gelince orayı süpürülmüş, düzeltilmiş bulur.
26 Nígbà náà ni yóò lọ, yóò sì mú ẹ̀mí méje mìíràn tí ó burú ju òun tìkára rẹ̀ lọ wá, wọn yóò wọlé, wọn yóò sì máa gbé níbẹ̀, ìgbẹ̀yìn ọkùnrin náà yóò sì burú ju ìṣáájú rẹ̀ lọ.”
Bunun üzerine gider, kendisinden kötü yedi ruh daha alır ve eve girip yerleşirler. Böylece o kişinin son durumu ilkinden beter olur.”
27 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, obìnrin kan gbóhùn rẹ̀ sókè nínú ìjọ, ó sì wí fún un pé, “Ìbùkún ni fún inú tí ó bí ọ, àti ọmú tí ìwọ mu!”
İsa bu sözleri söylerken kalabalığın içinden bir kadın O'na, “Ne mutlu seni taşımış olan rahme, emzirmiş olan memelere!” diye seslendi.
28 Ṣùgbọ́n òun wí pé, nítòótọ́, kí ó kúkú wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn tí ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì pa á mọ́!”
İsa, “Daha doğrusu, ne mutlu Tanrı'nın sözünü dinleyip uygulayanlara!” dedi.
29 Nígbà tí ìjọ ènìyàn sì ṣùjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, “Ìran búburú ni èyí, wọ́n ń wá àmì; a kì yóò sì fi àmì kan fún un bí kò ṣe àmì Jona wòlíì!
Çevredeki kalabalık büyürken İsa konuşmaya başladı. “Şimdiki kuşak kötü bir kuşaktır” dedi. “Doğaüstü bir belirti istiyor, ama ona Yunus'un belirtisinden başka bir belirti gösterilmeyecek.
30 Nítorí bí Jona ti jẹ́ àmì fún àwọn ará Ninefe, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò ṣe jẹ́ àmì fún ìran yìí.
Yunus nasıl Ninova halkına bir belirti olduysa, İnsanoğlu da bu kuşak için öyle olacaktır.
31 Ọbabìnrin gúúsù yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ìran yìí, yóò sì dá wọn lẹ́bi: nítorí tí ó ti ìhà ìpẹ̀kun ayé wá láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni: sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Solomoni lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
Güney Kraliçesi, yargı günü bu kuşağın adamlarıyla birlikte kalkıp onları yargılayacak. Çünkü kraliçe, Süleyman'ın bilgece sözlerini dinlemek için dünyanın ta öbür ucundan gelmişti. Bakın, Süleyman'dan daha üstün olan buradadır.
32 Àwọn ará Ninefe yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú ìran yìí, wọn ó sì dá a lẹ́bi: nítorí tí wọn ronúpìwàdà nípa ìwàásù Jona; sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Jona lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
Ninova halkı, yargı günü bu kuşakla birlikte kalkıp bu kuşağı yargılayacak. Çünkü Ninovalılar, Yunus'un çağrısı üzerine tövbe ettiler. Bakın, Yunus'tan daha üstün olan buradadır.”
33 “Kò sí ẹnìkan, nígbà tí ó bá tan fìtílà tan, tí gbé e sí ìkọ̀kọ̀, tàbí sábẹ́ òsùwọ̀n, bí kò ṣe sórí ọ̀pá fìtílà, kí àwọn tí ń wọlé ba à lè máa rí ìmọ́lẹ̀.
“Hiç kimse kandil yakıp onu gizli yere ya da tahıl ölçeğinin altına koymaz. Tersine, içeri girenler ışığı görsünler diye onu kandilliğe koyar.
34 Ojú ni fìtílà ara: bí ojú rẹ bá mọ́lẹ̀ kedere, gbogbo ara rẹ a mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n bí ojú rẹ bá ṣókùnkùn, ara rẹ pẹ̀lú a kún fún òkùnkùn.
Bedenin ışığı gözdür. Gözün sağlamsa, bütün bedenin de aydınlık olur. Gözün bozuksa, bedenin de karanlık olur.
35 Nítorí náà kíyèsi i, kí ìmọ́lẹ̀ tí ń bẹ nínú rẹ má ṣe di òkùnkùn.
Öyleyse dikkat et, sendeki ‘ışık’ karanlık olmasın.
36 Ǹjẹ́ bí gbogbo ara rẹ bá kún fún ìmọ́lẹ̀, tí kò ní apá kan tí ó ṣókùnkùn, gbogbo rẹ̀ ni yóò ní ìmọ́lẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí fìtílà bá fi ìtànṣán rẹ̀ fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
Eğer bütün bedenin aydınlık olur ve hiçbir yanı karanlık kalmazsa, kandilin seni ışınlarıyla aydınlattığı zamanki gibi, bedenin tümden aydınlık olur.”
37 Bí ó sì ti ń wí, Farisi kan bẹ̀ ẹ́ kí ó bá òun jẹun: ó sì wọlé, ó jókòó láti jẹun.
İsa konuşmasını bitirince bir Ferisi O'nu evine yemeğe çağırdı. O da içeri girerek sofraya oturdu.
38 Nígbà tí Farisi náà sì rí i, ẹnu yà á nítorí tí kò kọ́kọ́ wẹ ọwọ́ kí ó tó jẹun.
İsa'nın yemekten önce yıkanmadığını gören Ferisi şaştı.
39 Olúwa sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin Farisi a máa ń fọ òde ago àti àwopọ̀kọ́: ṣùgbọ́n, inú yín kún fún ìwà búburú àti ìrẹ́jẹ.
Rab ona şöyle dedi: “Siz Ferisiler, bardağın ve tabağın dışını temizlersiniz, ama içiniz açgözlülük ve kötülükle doludur.
40 Ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹni tí ó ṣe èyí tí ń bẹ lóde, òun kò ha ṣe èyí tí ń bẹ nínú pẹ̀lú?
Ey akılsızlar! Dışı yapanla içi yapan aynı değil mi?
41 Nípa ohun ti inú yin, ki ẹ̀yin kúkú máa ṣe ìtọrẹ àánú nínú ohun tí ẹ̀yin ní, sì kíyèsi i, ohun gbogbo ni ó di mímọ́ fún yín.
Siz kaplarınızın içindekini sadaka olarak verin, o zaman sizin için her şey temiz olur.
42 “Ṣùgbọ́n ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, nítorí tí ẹ̀yin a máa san ìdámẹ́wàá minti àti irúgbìn, àti gbogbo ewébẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kọ ìdájọ́ àti ìfẹ́ Ọlọ́run: wọ̀nyí jẹ́ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe, láìsí fi àwọn ìyókù sílẹ̀ láìṣe.
“Ama vay halinize, ey Ferisiler! Siz nanenin, sedefotunun ve her tür sebzenin ondalığını verirsiniz de, adaleti ve Tanrı sevgisini ihmal edersiniz. Ondalık vermeyi ihmal etmeden esas bunları yerine getirmeniz gerekirdi.
43 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, àgàbàgebè! Nítorí tí ẹ̀yin fẹ́ ipò ọlá nínú Sinagọgu, àti ìkíni ní ọjà.
Vay halinize, ey Ferisiler! Havralarda en seçkin yerlere kurulmaya, meydanlarda selamlanmaya bayılırsınız.
44 “Ègbé ni fún un yín, nítorí ẹ̀yin dàbí ibojì tí kò farahàn, tí àwọn ènìyàn sì ń rìn lórí rẹ̀ láìmọ̀.”
Vay halinize! İnsanların, farkında olmadan üzerlerinde gezindiği belirsiz mezarlara benziyorsunuz.”
45 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn amòfin dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, nínú èyí tí ìwọ ń wí yìí ìwọ ń gan àwa pẹ̀lú.”
Kutsal Yasa uzmanlarından biri söz alıp İsa'ya, “Öğretmenim, bunları söylemekle bize de hakaret etmiş oluyorsun” dedi.
46 Ó sì wí pé, “Ègbé ni fún ẹ̀yin amòfin pẹ̀lú, nítorí tí ẹ̀yin di ẹrù tí ó wúwo láti rù lé ènìyàn lórí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin tìkára yín kò jẹ́ fi ìka yín kan ẹrù náà.
İsa, “Sizin de vay halinize, ey Yasa uzmanları!” dedi. “İnsanlara taşınması güç yükler yüklersiniz, kendiniz ise bu yükleri kaldırmak için parmağınızı bile kıpırdatmazsınız.
47 “Ègbé ni fún yín, nítorí tí ẹ̀yin kọ́ ibojì àwọn wòlíì, tí àwọn baba yín pa.
Vay halinize! Peygamberlerin anıtlarını yaparsınız, oysa onları sizin atalarınız öldürmüştür.
48 Ǹjẹ́ ẹ̀yin jẹ́ ẹlẹ́rìí, ẹ sì ní inú dídùn sí iṣẹ́ àwọn baba yín, nítorí tí wọn pa wọ́n, ẹ̀yin sì kọ́ ibojì wọn.
Böylelikle atalarınızın yaptıklarına tanıklık ederek bunları onaylamış oluyorsunuz. Çünkü onlar peygamberleri öldürdüler, siz de anıtlarını yapıyorsunuz.
49 Nítorí èyí ni ọgbọ́n Ọlọ́run sì ṣe wí pé, ‘Èmi ni ó rán àwọn wòlíì àti àwọn aposteli sí wọn, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí wọn.’
İşte bunun için Tanrı'nın Bilgeliği şöyle demiştir: ‘Ben onlara peygamberler ve elçiler göndereceğim, bunlardan kimini öldürecek, kimine zulmedecekler.’
50 Kí a lè béèrè ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì gbogbo, tí a ti ta sílẹ̀ láti ìgbà ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá, lọ́wọ́ ìran yìí;
Böylece bu kuşak, Habil'in kanından tutun da, sunakla tapınak arasında öldürülen Zekeriya'nın kanına değin, dünyanın kuruluşundan beri akıtılan bütün peygamberlerin kanından sorumlu tutulacaktır. Evet, size söylüyorum, bu kuşak sorumlu tutulacaktır.
51 láti ẹ̀jẹ̀ Abeli wá, títí ó sì fi dé ẹ̀jẹ̀ Sekariah, tí ó ṣègbé láàrín pẹpẹ àti tẹmpili. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín ìran yìí ni yóò ru gbogbo ẹ̀bi àwọn nǹkan wọ̀nyí.
52 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin amòfin, nítorí tí ẹ̀yin ti mú kọ́kọ́rọ́ ìmọ̀ kúrò; ẹ̀yin tìkára yín kò wọlé, àwọn tí sì ń wọlé, ni ẹ̀yin ń dí lọ́wọ́.”
Vay halinize, ey Yasa uzmanları! Bilgi kapısının anahtarını alıp götürdünüz. Kendiniz bu kapıdan girmediniz, girmek isteyenlere de engel oldunuz.”
53 Bí ó ti ń lọ kúrò níbẹ̀, àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi bẹ̀rẹ̀ sí bi í lọ́rọ̀ gidigidi, wọ́n sì ń yọ ọ́ lẹ́nu láti wí nǹkan púpọ̀.
İsa oradan ayrılınca, din bilginleriyle Ferisiler O'nu şiddetle sıkıştırarak birçok konuda ağzını aramaya başladılar.
54 Wọ́n ń ṣọ́ ọ, wọ́n ń wá ọ̀nà láti rí nǹkan gbámú lẹ́nu kí wọn bá à lè fi ẹ̀sùn kàn án.
Ağzından çıkacak bir sözle O'nu tuzağa düşürmek için fırsat kolluyorlardı.

< Luke 11 >