< Luke 11 >

1 Bí ó ti ń gbàdúrà ní ibi kan, bí ó ti dákẹ́, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Olúwa, kọ́ wa bí a ti ń gbàdúrà, bí Johanu ti kọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.”
អនន្តរំ ស កស្មិំឝ្ចិត៑ ស្ថានេ ប្រាត៌្ហយត តត្សមាប្តៅ សត្យាំ តស្យៃកះ ឝិឞ្យស្តំ ជគាទ ហេ ប្រភោ យោហន៑ យថា ស្វឝិឞ្យាន៑ ប្រាត៌្ហយិតុម៑ ឧបទិឞ្ដវាន៑ តថា ភវានប្យស្មាន៑ ឧបទិឝតុ។
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbàdúrà, ẹ máa wí pé: “‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ yín. Kí ìjọba yín dé, ìfẹ́ tiyín ni kí a ṣe, bí i ti ọrun, bẹ́ẹ̀ ni ní ayé.
តស្មាត៑ ស កថយាមាស, ប្រាត៌្ហនកាលេ យូយម៑ ឥត្ថំ កថយធ្វំ, ហេ អស្មាកំ ស្វគ៌ស្ថបិតស្តវ នាម បូជ្យំ ភវតុ; តវ រាជត្វំ ភវតុ; ស្វគ៌េ យថា តថា ប្ឫថិវ្យាមបិ តវេច្ឆយា សវ៌្វំ ភវតុ។
3 Fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa lójoojúmọ́.
ប្រត្យហម៑ អស្មាកំ ប្រយោជនីយំ ភោជ្យំ ទេហិ។
4 Kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá; nítorí àwa tìkára wa pẹ̀lú a máa dáríjì olúkúlùkù ẹni tí ó jẹ wá ní gbèsè, Má sì fà wá sínú ìdánwò, ṣùgbọ́n gbà wá lọ́wọ́ ẹni búburú ni.’”
យថា វយំ សវ៌្វាន៑ អបរាធិនះ ក្ឞមាមហេ តថា ត្វមបិ បាបាន្យស្មាកំ ក្ឞមស្វ។ អស្មាន៑ បរីក្ឞាំ មានយ កិន្តុ បាបាត្មនោ រក្ឞ។
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí yóò ní ọ̀rẹ́ kan, tí yóò sì tọ̀ ọ́ lọ láàrín ọ̀gànjọ́, tí yóò sì wí fún un pé, ‘Ọ̀rẹ́, yá mi ní ìṣù àkàrà mẹ́ta.
បឝ្ចាត៑ សោបរមបិ កថិតវាន៑ យទិ យុឞ្មាកំ កស្យចិទ៑ ពន្ធុស្តិឞ្ឋតិ និឝីថេ ច តស្យ សមីបំ ស គត្វា វទតិ,
6 Nítorí ọ̀rẹ́ mi kan ti àjò dé sọ́dọ̀ mi, èmi kò sì ní nǹkan tí èmi ó gbé kalẹ̀ níwájú rẹ̀.’
ហេ ពន្ធោ បថិក ឯកោ ពន្ធុ រ្មម និវេឝនម៑ អាយាតះ កិន្តុ តស្យាតិថ្យំ កត៌្តុំ មមាន្តិកេ កិមបិ នាស្តិ, អតឯវ បូបត្រយំ មហ្យម៑ ឫណំ ទេហិ;
7 Tí òun ó sì gbé inú ilé dáhùn wí fún un pé, ‘Má yọ mí lẹ́nu, a ti sé ìlẹ̀kùn, àwọn ọmọ mi si ń bẹ lórí ẹní pẹ̀lú mi: èmi kò lè dìde fi fún ọ!’
តទា ស យទិ គ្ឫហមធ្យាត៑ ប្រតិវទតិ មាំ មា ក្លិឝាន, ឥទានីំ ទ្វារំ រុទ្ធំ ឝយនេ មយា សហ ពាលកាឝ្ច តិឞ្ឋន្តិ តុភ្យំ ទាតុម៑ ឧត្ថាតុំ ន ឝក្នោមិ,
8 Mo wí fún yín, bí òun kò tilẹ̀ ti fẹ́ dìde kí ó fi fún un nítorí tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n nítorí àwíìyánnu rẹ̀, yóò dìde, yóò sì fún un tó bí ó ti ń fẹ́.
តហ៌ិ យុឞ្មានហំ វទាមិ, ស យទិ មិត្រតយា តស្មៃ កិមបិ ទាតុំ នោត្តិឞ្ឋតិ តថាបិ វារំ វារំ ប្រាត៌្ហនាត ឧត្ថាបិតះ សន៑ យស្មិន៑ តស្យ ប្រយោជនំ តទេវ ទាស្យតិ។
9 “Èmí sì wí fún yín, ẹ béèrè, a ó sì fi fún un yín; ẹ wá kiri, ẹ̀yin ó sì rí; ẹ kànkùn, a ó sì ṣí i sílẹ̀ fún yín.
អតះ ការណាត៑ កថយាមិ, យាចធ្វំ តតោ យុឞ្មភ្យំ ទាស្យតេ, ម្ឫគយធ្វំ តត ឧទ្ទេឝំ ប្រាប្ស្យថ, ទ្វារម៑ អាហត តតោ យុឞ្មភ្យំ ទ្វារំ មោក្ឞ្យតេ។
10 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá béèrè, ó rí gbà; ẹni tí ó sì ń wá kiri, ó rí; àti ẹni tí ó kànkùn ni a ó ṣí i sílẹ̀ fún.
យោ យាចតេ ស ប្រាប្នោតិ, យោ ម្ឫគយតេ ស ឯវោទ្ទេឝំ ប្រាប្នោតិ, យោ ទ្វារម៑ អាហន្តិ តទត៌្ហំ ទ្វារំ មោច្យតេ។
11 “Ta ni baba nínú yín tí ọmọ rẹ̀ yóò béèrè àkàrà lọ́dọ̀ rẹ̀, tí yóò fún un ní òkúta? Tàbí bí ó béèrè ẹja, tí yóò fún un ní ejò?
បុត្រេណ បូបេ យាចិតេ តស្មៃ បាឞាណំ ទទាតិ វា មត្ស្យេ យាចិតេ តស្មៃ សប៌ំ ទទាតិ
12 Tàbí bí ó sì béèrè ẹ̀yin, tí yóò fún un ní àkéekèe?
វា អណ្ឌេ យាចិតេ តស្មៃ វ្ឫឝ្ចិកំ ទទាតិ យុឞ្មាកំ មធ្យេ ក ឯតាទ្ឫឝះ បិតាស្តេ?
13 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin tí ó jẹ́ ènìyàn búburú bá mọ bí a ti í fi ẹ̀bùn dáradára fún àwọn ọmọ yín, mélòó mélòó ha ni Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ fún àwọn tí ó béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀!”
តស្មាទេវ យូយមភទ្រា អបិ យទិ ស្វស្វពាលកេភ្យ ឧត្តមានិ ទ្រវ្យាណិ ទាតុំ ជានីថ តហ៌្យស្មាកំ ស្វគ៌ស្ថះ បិតា និជយាចកេភ្យះ កិំ បវិត្រម៑ អាត្មានំ ន ទាស្យតិ?
14 Ó sì ń lé ẹ̀mí èṣù kan jáde, tí ó sì yadi. Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà jáde, odi sọ̀rọ̀; ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn.
អនន្តរំ យីឝុនា កស្មាច្ចិទ៑ ឯកស្មិន៑ មូកភូតេ ត្យាជិតេ សតិ ស ភូតត្យក្តោ មានុឞោ វាក្យំ វក្តុម៑ អារេភេ; តតោ លោកាះ សកលា អាឝ្ចយ៌្យំ មេនិរេ។
15 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn nínú wọn wí pé, “Nípa Beelsebulu olórí àwọn ẹ̀mí èṣù ni ó fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”
កិន្តុ តេឞាំ កេចិទូចុ រ្ជនោយំ ពាលសិពូពា អត៌្ហាទ៑ ភូតរាជេន ភូតាន៑ ត្យាជយតិ។
16 Àwọn ẹlòmíràn sì ń dán an wò, wọ́n ń fẹ́ àmì lọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọ̀run wá.
តំ បរីក្ឞិតុំ កេចិទ៑ អាកាឝីយម៑ ឯកំ ចិហ្នំ ទឝ៌យិតុំ តំ ប្រាត៌្ហយាញ្ចក្រិរេ។
17 Ṣùgbọ́n òun mọ èrò inú wọn, ó wí fún wọn pé, “Gbogbo ìjọba tí ó ya ara rẹ̀ ní ipá, ni a ń sọ di ahoro; ilé tí ó sì ya ara rẹ̀ nípá yóò wó.
តទា ស តេឞាំ មនះកល្បនាំ ជ្ញាត្វា កថយាមាស, កស្យចិទ៑ រាជ្យស្យ លោកា យទិ បរស្បរំ វិរុន្ធន្តិ តហ៌ិ តទ៑ រាជ្យម៑ នឝ្យតិ; កេចិទ៑ គ្ឫហស្ថា យទិ បរស្បរំ វិរុន្ធន្តិ តហ៌ិ តេបិ នឝ្យន្តិ។
18 Bí Satani ba yapa sí ara rẹ̀, ìjọba rẹ̀ yóò ha ṣe dúró? Nítorí ẹ̀yin wí pé, nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.
តថៃវ ឝៃតានបិ ស្វលោកាន៑ យទិ វិរុណទ្ធិ តទា តស្យ រាជ្យំ កថំ ស្ថាស្យតិ? ពាលសិពូពាហំ ភូតាន៑ ត្យាជយាមិ យូយមិតិ វទថ។
19 Bí ó ba ṣe pé nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, nípa ta ni àwọn ọmọ yín fi ń lé wọn jáde, nítorí náà àwọn ni yóò ṣe onídàájọ́ yín.
យទ្យហំ ពាលសិពូពា ភូតាន៑ ត្យាជយាមិ តហ៌ិ យុឞ្មាកំ សន្តានាះ កេន ត្យាជយន្តិ? តស្មាត៑ តឯវ កថាយា ឯតស្យា វិចារយិតារោ ភវិឞ្យន្តិ។
20 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe pé nípa ìka ọwọ́ Ọlọ́run ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, ǹjẹ́ ìjọba Ọlọ́run dé bá yín tán.
កិន្តុ យទ្យហម៑ ឦឝ្វរស្យ បរាក្រមេណ ភូតាន៑ ត្យាជយាមិ តហ៌ិ យុឞ្មាកំ និកដម៑ ឦឝ្វរស្យ រាជ្យមវឝ្យម៑ ឧបតិឞ្ឋតិ។
21 “Nígbà tí alágbára ọkùnrin tí ó ni ìhámọ́ra bá ń ṣọ́ ààfin rẹ̀, ẹrù rẹ̀ yóò wà ní àlàáfíà.
ពលវាន៑ បុមាន៑ សុសជ្ជមានោ យតិកាលំ និជាដ្ដាលិកាំ រក្ឞតិ តតិកាលំ តស្យ ទ្រវ្យំ និរុបទ្រវំ តិឞ្ឋតិ។
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹni tí ó ní agbára jù ú bá kọlù ú, tí ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ a gba gbogbo ìhámọ́ra rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé lọ́wọ́ rẹ̀, a sì pín ìkógun rẹ̀.
កិន្តុ តស្មាទ៑ អធិកពលះ កឝ្ចិទាគត្យ យទិ តំ ជយតិ តហ៌ិ យេឞុ ឝស្ត្រាស្ត្រេឞុ តស្យ វិឝ្វាស អាសីត៑ តានិ សវ៌្វាណិ ហ្ឫត្វា តស្យ ទ្រវ្យាណិ គ្ឫហ្លាតិ។
23 “Ẹni tí kò bá wà pẹ̀lú mi, ó lòdì sí mi, ẹni tí kò bá sì bá mi kójọpọ̀, ó fọ́nká.
អតះ ការណាទ៑ យោ មម សបក្ឞោ ន ស វិបក្ឞះ, យោ មយា សហ ន សំគ្ឫហ្លាតិ ស វិកិរតិ។
24 “Nígbà tí ẹ̀mí àìmọ́ bá jáde kúrò lára ènìyàn, a máa rìn kiri ní ibi gbígbẹ, a máa wá ibi ìsinmi; nígbà tí kò bá sì rí, a wí pé, ‘Èmi yóò padà lọ sí ilé mi ní ibi tí mo gbé ti jáde wá.’
អបរញ្ច អមេធ្យភូតោ មានុឞស្យាន្តន៌ិគ៌ត្យ ឝុឞ្កស្ថានេ ភ្រាន្ត្វា វិឝ្រាមំ ម្ឫគយតេ កិន្តុ ន ប្រាប្យ វទតិ មម យស្មាទ៑ គ្ឫហាទ៑ អាគតោហំ បុនស្តទ៑ គ្ឫហំ បរាវ្ឫត្យ យាមិ។
25 Nígbà tí ó bá sì dé, tí ó sì rí tí a gbá a, tí a sì ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
តតោ គត្វា តទ៑ គ្ឫហំ មាជ៌ិតំ ឝោភិតញ្ច ទ្ឫឞ្ដ្វា
26 Nígbà náà ni yóò lọ, yóò sì mú ẹ̀mí méje mìíràn tí ó burú ju òun tìkára rẹ̀ lọ wá, wọn yóò wọlé, wọn yóò sì máa gbé níbẹ̀, ìgbẹ̀yìn ọkùnrin náà yóò sì burú ju ìṣáájú rẹ̀ lọ.”
តត្ក្ឞណម៑ អបគត្យ ស្វស្មាទបិ ទុម៌្មតីន៑ អបរាន៑ សប្តភូតាន៑ សហានយតិ តេ ច តទ្គ្ឫហំ បវិឝ្យ និវសន្តិ។ តស្មាត៑ តស្យ មនុឞ្យស្យ ប្រថមទឝាតះ ឝេឞទឝា ទុះខតរា ភវតិ។
27 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, obìnrin kan gbóhùn rẹ̀ sókè nínú ìjọ, ó sì wí fún un pé, “Ìbùkún ni fún inú tí ó bí ọ, àti ọmú tí ìwọ mu!”
អស្យាះ កថាយាះ កថនកាលេ ជនតាមធ្យស្ថា កាចិន្នារី តមុច្ចៃះស្វរំ ប្រោវាច, យា យោឞិត៑ ត្វាំ គព៌្ភេៜធារយត៑ ស្តន្យមបាយយច្ច សៃវ ធន្យា។
28 Ṣùgbọ́n òun wí pé, nítòótọ́, kí ó kúkú wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn tí ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì pa á mọ́!”
កិន្តុ សោកថយត៑ យេ បរមេឝ្វរស្យ កថាំ ឝ្រុត្វា តទនុរូបម៑ អាចរន្តិ តឯវ ធន្យាះ។
29 Nígbà tí ìjọ ènìyàn sì ṣùjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, “Ìran búburú ni èyí, wọ́n ń wá àmì; a kì yóò sì fi àmì kan fún un bí kò ṣe àmì Jona wòlíì!
តតះ បរំ តស្យាន្តិកេ ពហុលោកានាំ សមាគមេ ជាតេ ស វក្តុមារេភេ, អាធុនិកា ទុឞ្ដលោកាឝ្ចិហ្នំ ទ្រឞ្ដុមិច្ឆន្តិ កិន្តុ យូនស្ភវិឞ្យទ្វាទិនឝ្ចិហ្នំ វិនាន្យត៑ កិញ្ចិច្ចិហ្នំ តាន៑ ន ទឝ៌យិឞ្យតេ។
30 Nítorí bí Jona ti jẹ́ àmì fún àwọn ará Ninefe, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò ṣe jẹ́ àmì fún ìran yìí.
យូនស៑ តុ យថា នីនិវីយលោកានាំ សមីបេ ចិហ្នរូបោភវត៑ តថា វិទ្យមានលោកានាម៑ ឯឞាំ សមីបេ មនុឞ្យបុត្រោបិ ចិហ្នរូបោ ភវិឞ្យតិ។
31 Ọbabìnrin gúúsù yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ìran yìí, yóò sì dá wọn lẹ́bi: nítorí tí ó ti ìhà ìpẹ̀kun ayé wá láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni: sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Solomoni lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
វិចារសមយេ ឥទានីន្តនលោកានាំ ប្រាតិកូល្យេន ទក្ឞិណទេឝីយា រាជ្ញី ប្រោត្ថាយ តាន៑ ទោឞិណះ ករិឞ្យតិ, យតះ សា រាជ្ញី សុលេមាន ឧបទេឝកថាំ ឝ្រោតុំ ប្ឫថិវ្យាះ សីមាត អាគច្ឆត៑ កិន្តុ បឝ្យត សុលេមានោបិ គុរុតរ ឯកោ ជនោៜស្មិន៑ ស្ថានេ វិទ្យតេ។
32 Àwọn ará Ninefe yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú ìran yìí, wọn ó sì dá a lẹ́bi: nítorí tí wọn ronúpìwàdà nípa ìwàásù Jona; sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Jona lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
អបរញ្ច វិចារសមយេ នីនិវីយលោកា អបិ វត៌្តមានកាលិកានាំ លោកានាំ វៃបរីត្យេន ប្រោត្ថាយ តាន៑ ទោឞិណះ ករិឞ្យន្តិ, យតោ ហេតោស្តេ យូនសោ វាក្យាត៑ ចិត្តានិ បរិវត៌្តយាមាសុះ កិន្តុ បឝ្យត យូនសោតិគុរុតរ ឯកោ ជនោៜស្មិន៑ ស្ថានេ វិទ្យតេ។
33 “Kò sí ẹnìkan, nígbà tí ó bá tan fìtílà tan, tí gbé e sí ìkọ̀kọ̀, tàbí sábẹ́ òsùwọ̀n, bí kò ṣe sórí ọ̀pá fìtílà, kí àwọn tí ń wọlé ba à lè máa rí ìmọ́lẹ̀.
ប្រទីបំ ប្រជ្វាល្យ ទ្រោណស្យាធះ កុត្រាបិ គុប្តស្ថានេ វា កោបិ ន ស្ថាបយតិ កិន្តុ គ្ឫហប្រវេឝិភ្យោ ទីប្តិំ ទាតំ ទីបាធារោបយ៌្យេវ ស្ថាបយតិ។
34 Ojú ni fìtílà ara: bí ojú rẹ bá mọ́lẹ̀ kedere, gbogbo ara rẹ a mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n bí ojú rẹ bá ṣókùnkùn, ara rẹ pẹ̀lú a kún fún òkùnkùn.
ទេហស្យ ប្រទីបឝ្ចក្ឞុស្តស្មាទេវ ចក្ឞុ រ្យទិ ប្រសន្នំ ភវតិ តហ៌ិ តវ សវ៌្វឝរីរំ ទីប្តិមទ៑ ភវិឞ្យតិ កិន្តុ ចក្ឞុ រ្យទិ មលីមសំ តិឞ្ឋតិ តហ៌ិ សវ៌្វឝរីរំ សាន្ធការំ ស្ថាស្យតិ។
35 Nítorí náà kíyèsi i, kí ìmọ́lẹ̀ tí ń bẹ nínú rẹ má ṣe di òkùnkùn.
អស្មាត៑ ការណាត៑ តវាន្តះស្ថំ ជ្យោតិ រ្យថាន្ធការមយំ ន ភវតិ តទត៌្ហេ សាវធានោ ភវ។
36 Ǹjẹ́ bí gbogbo ara rẹ bá kún fún ìmọ́lẹ̀, tí kò ní apá kan tí ó ṣókùnkùn, gbogbo rẹ̀ ni yóò ní ìmọ́lẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí fìtílà bá fi ìtànṣán rẹ̀ fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
យតះ ឝរីរស្យ កុត្រាប្យំឝេ សាន្ធការេ ន ជាតេ សវ៌្វំ យទិ ទីប្តិមត៑ តិឞ្ឋតិ តហ៌ិ តុភ្យំ ទីប្តិទាយិប្រោជ្ជ្វលន៑ ប្រទីប ឥវ តវ សវវ៌ឝរីរំ ទីប្តិមទ៑ ភវិឞ្យតិ។
37 Bí ó sì ti ń wí, Farisi kan bẹ̀ ẹ́ kí ó bá òun jẹun: ó sì wọlé, ó jókòó láti jẹun.
ឯតត្កថាយាះ កថនកាលេ ផិរុឝ្យេកោ ភេជនាយ តំ និមន្ត្រយាមាស, តតះ ស គត្វា ភោក្តុម៑ ឧបវិវេឝ។
38 Nígbà tí Farisi náà sì rí i, ẹnu yà á nítorí tí kò kọ́kọ́ wẹ ọwọ́ kí ó tó jẹun.
កិន្តុ ភោជនាត៑ បូវ៌្វំ នាមាង្ក្ឞីត៑ ឯតទ៑ ទ្ឫឞ្ដ្វា ស ផិរុឝ្យាឝ្ចយ៌្យំ មេនេ។
39 Olúwa sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin Farisi a máa ń fọ òde ago àti àwopọ̀kọ́: ṣùgbọ́n, inú yín kún fún ìwà búburú àti ìrẹ́jẹ.
តទា ប្រភុស្តំ ប្រោវាច យូយំ ផិរូឝិលោកាះ បានបាត្រាណាំ ភោជនបាត្រាណាញ្ច ពហិះ បរិឞ្កុរុថ កិន្តុ យុឞ្មាកមន្ត រ្ទៅរាត្ម្យៃ រ្ទុឞ្ក្រិយាភិឝ្ច បរិបូណ៌ំ តិឞ្ឋតិ។
40 Ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹni tí ó ṣe èyí tí ń bẹ lóde, òun kò ha ṣe èyí tí ń bẹ nínú pẹ̀lú?
ហេ សវ៌្វេ និព៌ោធា យោ ពហិះ សសជ៌ ស ឯវ កិមន្ត រ្ន សសជ៌?
41 Nípa ohun ti inú yin, ki ẹ̀yin kúkú máa ṣe ìtọrẹ àánú nínú ohun tí ẹ̀yin ní, sì kíyèsi i, ohun gbogbo ni ó di mímọ́ fún yín.
តត ឯវ យុឞ្មាភិរន្តះករណំ (ឦឝ្វរាយ) និវេទ្យតាំ តស្មិន៑ ក្ឫតេ យុឞ្មាកំ សវ៌្វាណិ ឝុចិតាំ យាស្យន្តិ។
42 “Ṣùgbọ́n ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, nítorí tí ẹ̀yin a máa san ìdámẹ́wàá minti àti irúgbìn, àti gbogbo ewébẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kọ ìdájọ́ àti ìfẹ́ Ọlọ́run: wọ̀nyí jẹ́ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe, láìsí fi àwọn ìyókù sílẹ̀ láìṣe.
កិន្តុ ហន្ត ផិរូឝិគណា យូយំ ន្យាយម៑ ឦឝ្វរេ ប្រេម ច បរិត្យជ្យ បោទិនាយា អរុទាទីនាំ សវ៌្វេឞាំ ឝាកានាញ្ច ទឝមាំឝាន៑ ទត្ថ កិន្តុ ប្រថមំ បាលយិត្វា ឝេឞស្យាលង្ឃនំ យុឞ្មាកម៑ ឧចិតមាសីត៑។
43 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, àgàbàgebè! Nítorí tí ẹ̀yin fẹ́ ipò ọlá nínú Sinagọgu, àti ìkíni ní ọjà.
ហា ហា ផិរូឝិនោ យូយំ ភជនគេហេ ប្រោច្ចាសនេ អាបណេឞុ ច នមស្ការេឞុ ប្រីយធ្វេ។
44 “Ègbé ni fún un yín, nítorí ẹ̀yin dàbí ibojì tí kò farahàn, tí àwọn ènìyàn sì ń rìn lórí rẹ̀ láìmọ̀.”
វត កបដិនោៜធ្យាបកាះ ផិរូឝិនឝ្ច លោកាយត៑ ឝ្មឝានម៑ អនុបលភ្យ តទុបរិ គច្ឆន្តិ យូយម៑ តាទ្ឫគប្រកាឝិតឝ្មឝានវាទ៑ ភវថ។
45 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn amòfin dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, nínú èyí tí ìwọ ń wí yìí ìwọ ń gan àwa pẹ̀lú.”
តទានីំ វ្យវស្ថាបកានាម៑ ឯកា យីឝុមវទត៑, ហេ ឧបទេឝក វាក្យេនេទ្ឫឝេនាស្មាស្វបិ ទោឞម៑ អារោបយសិ។
46 Ó sì wí pé, “Ègbé ni fún ẹ̀yin amòfin pẹ̀lú, nítorí tí ẹ̀yin di ẹrù tí ó wúwo láti rù lé ènìyàn lórí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin tìkára yín kò jẹ́ fi ìka yín kan ẹrù náà.
តតះ ស ឧវាច, ហា ហា វ្យវស្ថាបកា យូយម៑ មានុឞាណាម៑ ឧបរិ ទុះសហ្យាន៑ ភារាន៑ ន្យស្យថ កិន្តុ ស្វយម៑ ឯកាង្គុល្យាបិ តាន៑ ភារាន៑ ន ស្ប្ឫឝថ។
47 “Ègbé ni fún yín, nítorí tí ẹ̀yin kọ́ ibojì àwọn wòlíì, tí àwọn baba yín pa.
ហន្ត យុឞ្មាកំ បូវ៌្វបុរុឞា យាន៑ ភវិឞ្យទ្វាទិនោៜវធិឞុស្តេឞាំ ឝ្មឝានានិ យូយំ និម៌្មាថ។
48 Ǹjẹ́ ẹ̀yin jẹ́ ẹlẹ́rìí, ẹ sì ní inú dídùn sí iṣẹ́ àwọn baba yín, nítorí tí wọn pa wọ́n, ẹ̀yin sì kọ́ ibojì wọn.
តេនៃវ យូយំ ស្វបូវ៌្វបុរុឞាណាំ កម៌្មាណិ សំមន្យធ្វេ តទេវ សប្រមាណំ កុរុថ ច, យតស្តេ តានវធិឞុះ យូយំ តេឞាំ ឝ្មឝានានិ និម៌្មាថ។
49 Nítorí èyí ni ọgbọ́n Ọlọ́run sì ṣe wí pé, ‘Èmi ni ó rán àwọn wòlíì àti àwọn aposteli sí wọn, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí wọn.’
អតឯវ ឦឝ្វរស្យ ឝាស្ត្រេ ប្រោក្តមស្តិ តេឞាមន្តិកេ ភវិឞ្យទ្វាទិនះ ប្រេរិតាំឝ្ច ប្រេឞយិឞ្យាមិ តតស្តេ តេឞាំ កាំឝ្ចន ហនិឞ្យន្តិ កាំឝ្ចន តាឌឝ្ឞ្យិន្តិ។
50 Kí a lè béèrè ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì gbogbo, tí a ti ta sílẹ̀ láti ìgbà ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá, lọ́wọ́ ìran yìí;
ឯតស្មាត៑ ការណាត៑ ហាពិលះ ឝោណិតបាតមារភ្យ មន្ទិរយជ្ញវេទ្យោ រ្មធ្យេ ហតស្យ សិខរិយស្យ រក្តបាតបយ៌្យន្តំ
51 láti ẹ̀jẹ̀ Abeli wá, títí ó sì fi dé ẹ̀jẹ̀ Sekariah, tí ó ṣègbé láàrín pẹpẹ àti tẹmpili. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín ìran yìí ni yóò ru gbogbo ẹ̀bi àwọn nǹkan wọ̀nyí.
ជគតះ ស្ឫឞ្ដិមារភ្យ ប្ឫថិវ្យាំ ភវិឞ្យទ្វាទិនាំ យតិរក្តបាតា ជាតាស្តតីនាម៑ អបរាធទណ្ឌា ឯឞាំ វត៌្តមានលោកានាំ ភវិឞ្យន្តិ, យុឞ្មានហំ និឝ្ចិតំ វទាមិ សវ៌្វេ ទណ្ឌា វំឝស្យាស្យ ភវិឞ្យន្តិ។
52 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin amòfin, nítorí tí ẹ̀yin ti mú kọ́kọ́rọ́ ìmọ̀ kúrò; ẹ̀yin tìkára yín kò wọlé, àwọn tí sì ń wọlé, ni ẹ̀yin ń dí lọ́wọ́.”
ហា ហា វ្យវស្ថបកា យូយំ ជ្ញានស្យ កុញ្ចិកាំ ហ្ឫត្វា ស្វយំ ន ប្រវិឞ្ដា យេ ប្រវេឞ្ដុញ្ច ប្រយាសិនស្តានបិ ប្រវេឞ្ដុំ វារិតវន្តះ។
53 Bí ó ti ń lọ kúrò níbẹ̀, àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi bẹ̀rẹ̀ sí bi í lọ́rọ̀ gidigidi, wọ́n sì ń yọ ọ́ lẹ́nu láti wí nǹkan púpọ̀.
ឥត្ថំ កថាកថនាទ៑ អធ្យាបកាះ ផិរូឝិនឝ្ច សតក៌ាះ
54 Wọ́n ń ṣọ́ ọ, wọ́n ń wá ọ̀nà láti rí nǹkan gbámú lẹ́nu kí wọn bá à lè fi ẹ̀sùn kàn án.
សន្តស្តមបវទិតុំ តស្យ កថាយា ទោឞំ ធត៌្តមិច្ឆន្តោ នានាខ្យានកថនាយ តំ ប្រវត៌្តយិតុំ កោបយិតុញ្ច ប្រារេភិរេ។

< Luke 11 >