< Luke 11 >

1 Bí ó ti ń gbàdúrà ní ibi kan, bí ó ti dákẹ́, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Olúwa, kọ́ wa bí a ti ń gbàdúrà, bí Johanu ti kọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.”
Undată kănd Isus u fost gata ku molitva, unu dăm učenici aluj u vinjit la jăl šă ju zăs: “Domnu, ănvacănji să nji arugănj, kum ănvăca Ivan Krstitelj pă učenici aluj.”
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbàdúrà, ẹ máa wí pé: “‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ yín. Kí ìjọba yín dé, ìfẹ́ tiyín ni kí a ṣe, bí i ti ọrun, bẹ́ẹ̀ ni ní ayé.
Isus lju zăs alor: “Kănd vă arugăc zăšjec: ‘Tata, la să fijă svănt numilje atov, la să vijă kraljevstva ata, ka kum ăj pă nor la să fijă pă pămănt!
3 Fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa lójoojúmọ́.
Pita anostră kari ăj ăm totă ză, dă nji astăs.
4 Kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá; nítorí àwa tìkára wa pẹ̀lú a máa dáríjì olúkúlùkù ẹni tí ó jẹ wá ní gbèsè, Má sì fà wá sínú ìdánwò, ṣùgbọ́n gbà wá lọ́wọ́ ẹni búburú ni.’”
Šă jartănji grehurlje anoštri, ka kum noj jartănj alu eje kari grešilešći protiv dă noj. Nu nji da să kăđenj ăm ănšjirkalur.’”
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí yóò ní ọ̀rẹ́ kan, tí yóò sì tọ̀ ọ́ lọ láàrín ọ̀gànjọ́, tí yóò sì wí fún un pé, ‘Ọ̀rẹ́, yá mi ní ìṣù àkàrà mẹ́ta.
Isus u zăs alor: “Haj să zăšjenj kă avec urtak la kari măržjec ăm miržuku dă nopći šă ăj zăšjec: ‘Urtaku amnjov, dăm kečinj tri dărabur dă pită.
6 Nítorí ọ̀rẹ́ mi kan ti àjò dé sọ́dọ̀ mi, èmi kò sì ní nǹkan tí èmi ó gbé kalẹ̀ níwájú rẹ̀.’
Urtaku u vinjit dă pă kalji la minji, šă nam šje să ăj puj dădănenći.’
7 Tí òun ó sì gbé inú ilé dáhùn wí fún un pé, ‘Má yọ mí lẹ́nu, a ti sé ìlẹ̀kùn, àwọn ọmọ mi si ń bẹ lórí ẹní pẹ̀lú mi: èmi kò lè dìde fi fún ọ!’
A jăl ăm nontru aj zăšji: ‘O nu mă gnjavali! Uša ăj mar ănkujetă, kupiji amej šă ju ăščenj ăm pat, šă jednostavno, nu mă pot skula să ac dov pită.’
8 Mo wí fún yín, bí òun kò tilẹ̀ ti fẹ́ dìde kí ó fi fún un nítorí tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n nítorí àwíìyánnu rẹ̀, yóò dìde, yóò sì fún un tó bí ó ti ń fẹ́.
Ju vă zăk: šă dakă nu u meržji daje kă ăs urtašj, u fašji aje să nu să rušunji.
9 “Èmí sì wí fún yín, ẹ béèrè, a ó sì fi fún un yín; ẹ wá kiri, ẹ̀yin ó sì rí; ẹ kànkùn, a ó sì ṣí i sílẹ̀ fún yín.
Šă ju vă zăk: Arugăcăvă, šă vu fi dat! Kutăc, šă vic afla! Kukunjec, šă vu fi dăsvkut.
10 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá béèrè, ó rí gbà; ẹni tí ó sì ń wá kiri, ó rí; àti ẹni tí ó kànkùn ni a ó ṣí i sílẹ̀ fún.
Kă šjinji gođ să arogă, kapătă! Kari kotă, află! A šjinji gođ kukunješći aluje ju su dăsvašji.
11 “Ta ni baba nínú yín tí ọmọ rẹ̀ yóò béèrè àkàrà lọ́dọ̀ rẹ̀, tí yóò fún un ní òkúta? Tàbí bí ó béèrè ẹja, tí yóò fún un ní ejò?
Kari ăj tata ăntri voj: kănd kupilu šjeri pešći dali ăm lok dă pešći dă šarpi?
12 Tàbí bí ó sì béèrè ẹ̀yin, tí yóò fún un ní àkéekèe?
Ili kănd šjeri să ăj đe škorpion ăm lok dă ov?
13 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin tí ó jẹ́ ènìyàn búburú bá mọ bí a ti í fi ẹ̀bùn dáradára fún àwọn ọmọ yín, mélòó mélòó ha ni Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ fún àwọn tí ó béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀!”
Dakă voj grešni ominj šćijec să dăđec bunji stvarur alu kupiji avoštri, kit maj mult vu da Tata avostru dăm nor Duh Svănt alu alor kari ăl ăntrabă!”
14 Ó sì ń lé ẹ̀mí èṣù kan jáde, tí ó sì yadi. Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà jáde, odi sọ̀rọ̀; ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn.
Isus undată u vărljit afară pă unu drak kari are mut, šă kănd u fost drakula vărljit afară dăm ala om kari are mut, puće să svitaskă, šă alčilje ominji kari u văzut aje asre ămirac.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn nínú wọn wí pé, “Nípa Beelsebulu olórí àwọn ẹ̀mí èṣù ni ó fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”
A orikic dăm jej u zăs: “Jăl u vărljit afară pă drašj afară ku ažutala alu Beelzebul princu dă demonur!”
16 Àwọn ẹlòmíràn sì ń dán an wò, wọ́n ń fẹ́ àmì lọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọ̀run wá.
Akulo asre alci kari ănšjirka pă Isus, šă jej u šjirut znak dăm nor să đe.
17 Ṣùgbọ́n òun mọ èrò inú wọn, ó wí fún wọn pé, “Gbogbo ìjọba tí ó ya ara rẹ̀ ní ipá, ni a ń sọ di ahoro; ilé tí ó sì ya ara rẹ̀ nípá yóò wó.
Ali Isus šćije găndurlje alor, šă lju zăs: “Totă kraljevstva kari să borulešči una ku alt, jej ur uništili kraljevstva alor. Dakă familija una ku alt să borulešči, jej šur uništili familija alor.
18 Bí Satani ba yapa sí ara rẹ̀, ìjọba rẹ̀ yóò ha ṣe dúró? Nítorí ẹ̀yin wí pé, nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.
Dakă Sotona să borulešči protiv dă jăl săngur, kum kraljevstvo aluj su cănje?, šje rămănje dăm kraljestva aluj? Kum voj zăšjec kă ju vărljesk afară pă drašji dăm lume ku ažutala alu Beelzebul.
19 Bí ó ba ṣe pé nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, nípa ta ni àwọn ọmọ yín fi ń lé wọn jáde, nítorí náà àwọn ni yóò ṣe onídàájọ́ yín.
Ali dakă ju vărljesk pă drašji afară dăm lumi ku ažutala alu Beelzebul, atunšje učenici avoštri vărlješći isto afară pă drašj ku ažutală alu Beelzebul? Jej săngur u dokazali kă nus točni.
20 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe pé nípa ìka ọwọ́ Ọlọ́run ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, ǹjẹ́ ìjọba Ọlọ́run dé bá yín tán.
Ali dakă ju măj pă drašji afără ku žejtu alu Dimizov, atunšje u vinjit kraljevstva alu Dimizov la voj.
21 “Nígbà tí alágbára ọkùnrin tí ó ni ìhámọ́ra bá ń ṣọ́ ààfin rẹ̀, ẹrù rẹ̀ yóò wà ní àlàáfíà.
Kănd om bălour ăj naoružan šă păzešći kasa hunđi kustă, atunšje pămăntu aluj ăj sigurnă.
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹni tí ó ní agbára jù ú bá kọlù ú, tí ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ a gba gbogbo ìhámọ́ra rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé lọ́wọ́ rẹ̀, a sì pín ìkógun rẹ̀.
Ali kănd bălour om ăl napadalešći šă ăl mănănkă ku bătaje, ăj je oružje dă kari ovisilešći, šă ăj ămparcă šje u furat dă la slab om.
23 “Ẹni tí kò bá wà pẹ̀lú mi, ó lòdì sí mi, ẹni tí kò bá sì bá mi kójọpọ̀, ó fọ́nká.
Kari nu ăj ku minji, ala ăj protiv dă minji šă šjinji gođe nu akulježi ku minji, ala răsăpă.
24 “Nígbà tí ẹ̀mí àìmọ́ bá jáde kúrò lára ènìyàn, a máa rìn kiri ní ibi gbígbẹ, a máa wá ibi ìsinmi; nígbà tí kò bá sì rí, a wí pé, ‘Èmi yóò padà lọ sí ilé mi ní ibi tí mo gbé ti jáde wá.’
Pă lok făr dă apă rov duhu fužji afară dăm om, să lutulaskă šă să koći lok să să odmaralskă. Dakă nu află njiš šjefălj lok, zăšji: ‘Ju uj meržji ăm napoj ăm kasa ame dăm ala om hunđi am fužjit.’
25 Nígbà tí ó bá sì dé, tí ó sì rí tí a gbá a, tí a sì ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
Kănd draku u vinjit ăm napoj u aflat kă aje kasa ăj čistilită, šă măturată.
26 Nígbà náà ni yóò lọ, yóò sì mú ẹ̀mí méje mìíràn tí ó burú ju òun tìkára rẹ̀ lọ wá, wọn yóò wọlé, wọn yóò sì máa gbé níbẹ̀, ìgbẹ̀yìn ọkùnrin náà yóò sì burú ju ìṣáájú rẹ̀ lọ.”
Atunšje meržji šă adušji maj šapči rov duhur maj rej dă jăl săngur, šă jej u vinji napoj ăm om šă kustă akulo. Aša alu omula are tari urăt dă kit dăm elši.”
27 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, obìnrin kan gbóhùn rẹ̀ sókè nínú ìjọ, ó sì wí fún un pé, “Ìbùkún ni fún inú tí ó bí ọ, àti ọmú tí ìwọ mu!”
Kum Isus svite, mujeri ăm gărmadă dă ominj u mužjit tari dăm tot graju šă su apukat să svitaskă: “Blagoslovulită ăj aje kari ću purtat ăm injimă, kari ću rănjit šă ću păzăt!”
28 Ṣùgbọ́n òun wí pé, nítòótọ́, kí ó kúkú wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn tí ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì pa á mọ́!”
Isus u ăntors vorba: “Anume, ali maj blagoslovulit ăs eje kari auđi vorba alu Dimizov šă u cănji!”
29 Nígbà tí ìjọ ènìyàn sì ṣùjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, “Ìran búburú ni èyí, wọ́n ń wá àmì; a kì yóò sì fi àmì kan fún un bí kò ṣe àmì Jona wòlíì!
Kănd u vinjit tari mulc ominj akulo, Isus su apukat să svitaskă: “Voj ominj kari kustăc ăm asta vremi, voj ščec rej ominj. Kotă znak, ali njišj šjefălj altu znak no fi dat ka kum u făkut Dimizov čudo păntru prorok Jona.
30 Nítorí bí Jona ti jẹ́ àmì fún àwọn ará Ninefe, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò ṣe jẹ́ àmì fún ìran yìí.
Šje su dogodulit alu Jona aje are znak alu Ninivljanur kari kusta ăm varuš Niniva, kă Dimizov lu mănat. Aša šje mu su dogoduli, ju uj fi znak kă pă minji, Fišjoru alu Om kari Dimizov u mănat alu asta narod.
31 Ọbabìnrin gúúsù yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ìran yìí, yóò sì dá wọn lẹ́bi: nítorí tí ó ti ìhà ìpẹ̀kun ayé wá láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni: sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Solomoni lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
Pă zuva kănd Dimizov u suduli, kraljica kari dă kănva vladale pă pămănt dă jug ăm Seba, su răđika una šă je u suduli pă heje kari kustă astăs. Je u vinjit dă pă kraju dă svijet, să slušulaskă pă Car Salomon kari are tari mudar. A aišje ăj šjinjiva maj mari dă Salomon a voj nu gănđec să punjec ureči!
32 Àwọn ará Ninefe yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú ìran yìí, wọn ó sì dá a lẹ́bi: nítorí tí wọn ronúpìwàdà nípa ìwàásù Jona; sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Jona lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
Ăm zua kănd Dimizov u suduli, ominji kari kusta ăm varuš Niniva su răđika šă ljur suduli ominji kari aku kustă, kă jej nu sur ănkăjit kănd Jona lji propovijedale. A ajišje ăj šjinjiva maj mari dă kit Jona a voj nu vac pokajalit!”
33 “Kò sí ẹnìkan, nígbà tí ó bá tan fìtílà tan, tí gbé e sí ìkọ̀kọ̀, tàbí sábẹ́ òsùwọ̀n, bí kò ṣe sórí ọ̀pá fìtílà, kí àwọn tí ń wọlé ba à lè máa rí ìmọ́lẹ̀.
Isus svitešči: “Njime nu acăcă lampă šă atunšje u punji pă lok hunđi nu să veđi ili dăsup košară. Nu, jăl u punji ăm svijećnjak aša toc u viđe lumină kănd vinji ăm nontru.
34 Ojú ni fìtílà ara: bí ojú rẹ bá mọ́lẹ̀ kedere, gbogbo ara rẹ a mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n bí ojú rẹ bá ṣókùnkùn, ara rẹ pẹ̀lú a kún fún òkùnkùn.
Oču ăj ka lampa alu telă. Dakă oču atov ăj sănătos, atunšje tela ata ăntragă u fi ăm lumină, ali kănd ci oču bičag, tela ata ăntragă ăj ăm ăntunjerik.
35 Nítorí náà kíyèsi i, kí ìmọ́lẹ̀ tí ń bẹ nínú rẹ má ṣe di òkùnkùn.
Bagă sama da aje šje smatralešč kă ăj lumina ăm činji să nu fijă făr dă lumină.”
36 Ǹjẹ́ bí gbogbo ara rẹ bá kún fún ìmọ́lẹ̀, tí kò ní apá kan tí ó ṣókùnkùn, gbogbo rẹ̀ ni yóò ní ìmọ́lẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí fìtílà bá fi ìtànṣán rẹ̀ fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
Dakă ăj ăntragă tela ata ăm lumină, njiš unu dio dă telă nu ăj ăm ăntunjerik, atunšje ăj kutotu ăm lumină, ka kum čar svitlăze lumina ata.
37 Bí ó sì ti ń wí, Farisi kan bẹ̀ ẹ́ kí ó bá òun jẹun: ó sì wọlé, ó jókòó láti jẹun.
Kănd Isus u svătit, unu farizej lu čimat să mănănšji la jăl akasă. Isus u mers, šă u lot lok la masă.
38 Nígbà tí Farisi náà sì rí i, ẹnu yà á nítorí tí kò kọ́kọ́ wẹ ọwọ́ kí ó tó jẹun.
Kănd farizeju u văzut kă nu šu spălat mănjilje majnti ka kum ăj običaj alu židov, su apukat să mănănšji a farizeju su začudulit.
39 Olúwa sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin Farisi a máa ń fọ òde ago àti àwopọ̀kọ́: ṣùgbọ́n, inú yín kún fún ìwà búburú àti ìrẹ́jẹ.
Ali Domnu Isus ju zăs: “Aku voj farizeji pă dă nă afară cănjec kljištaru šă teru čišć, ali pă dă nontru voj ščec pljinj dă pulkučală šă relji.
40 Ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹni tí ó ṣe èyí tí ń bẹ lóde, òun kò ha ṣe èyí tí ń bẹ nínú pẹ̀lú?
Voj făr dă firi! Nuj Dimizov kari u stvorulit vanjština, u stvorulit šă nutrina?
41 Nípa ohun ti inú yin, ki ẹ̀yin kúkú máa ṣe ìtọrẹ àánú nínú ohun tí ẹ̀yin ní, sì kíyèsi i, ohun gbogbo ni ó di mímọ́ fún yín.
Maj benj dăđec milostinja avostră dăm tot sufljitu alu heje kari lji potrebno šje voj avec, atunšje vu fi kutotu čist.
42 “Ṣùgbọ́n ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, nítorí tí ẹ̀yin a máa san ìdámẹ́wàá minti àti irúgbìn, àti gbogbo ewébẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kọ ìdájọ́ àti ìfẹ́ Ọlọ́run: wọ̀nyí jẹ́ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe, láìsí fi àwọn ìyókù sílẹ̀ láìṣe.
Ali jao avovă farizejilor! Kă voj tari vă trudulec să dăđec desetina dăm tot začinurlje šă povrčur alu Dimizov, a nu băgăc sama dă pravdă šă ljubav alu Dimizov. Una trăbă să fašjec, a hajelantă să nu propustulešč.
43 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, àgàbàgebè! Nítorí tí ẹ̀yin fẹ́ ipò ọlá nínú Sinagọgu, àti ìkíni ní ọjà.
Ali jao avovă, farizejilor! Kă voj plăšjec lokurlje glavnă pă sastankur ăm sinagogă, šă pozdravalală ku poštovanje ăm varuš pă trgur.
44 “Ègbé ni fún un yín, nítorí ẹ̀yin dàbí ibojì tí kò farahàn, tí àwọn ènìyàn sì ń rìn lórí rẹ̀ láìmọ̀.”
Jao avovă, kă voj ščec ka askunsă gropă pă kari ominji umblă a nu šćijă kă obredno ăs atunšje nečisti.”
45 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn amòfin dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, nínú èyí tí ìwọ ń wí yìí ìwọ ń gan àwa pẹ̀lú.”
A unu dăm učitelj dă zakonu alu Mojsije u zăs alu Isus: “Učitelju, kănd svitešć aša, tu nji vređălešć šă pă noj.”
46 Ó sì wí pé, “Ègbé ni fún ẹ̀yin amòfin pẹ̀lú, nítorí tí ẹ̀yin di ẹrù tí ó wúwo láti rù lé ènìyàn lórí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin tìkára yín kò jẹ́ fi ìka yín kan ẹrù náà.
Isus u zăs: “Jao šă avovă učitelji dă zakonu alu Mojsije, kă punjec pă ominj maj mult teret dă pravilurlje alu vjera dă kit šje poći om purta, a voj nu gănđec njiš ku žježjitu mik să ažutăc dă teretula să dukă.
47 “Ègbé ni fún yín, nítorí tí ẹ̀yin kọ́ ibojì àwọn wòlíì, tí àwọn baba yín pa.
Jao avovă! Kă voj gradalec spomenikur pă gropă alu proroci šă gănđec kă ku aje fišjec benji, a preci avoštri lju amurăt.
48 Ǹjẹ́ ẹ̀yin jẹ́ ẹlẹ́rìí, ẹ sì ní inú dídùn sí iṣẹ́ àwọn baba yín, nítorí tí wọn pa wọ́n, ẹ̀yin sì kọ́ ibojì wọn.
Aša voj svedočulec šă vă slagalec ku djela alu preci avoštri. Jej lju amurăt, a voj nastavalec ku lukru alor kănd gradalec spomenikur.
49 Nítorí èyí ni ọgbọ́n Ọlọ́run sì ṣe wí pé, ‘Èmi ni ó rán àwọn wòlíì àti àwọn aposteli sí wọn, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí wọn.’
Dimizov ăm mudrostu aluj u zăs: ‘Ju uj măna pă prorokur šă pă apostolur šă orikic dăm jej ur fi amurăc a alci u fi progonulic.’
50 Kí a lè béèrè ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì gbogbo, tí a ti ta sílẹ̀ láti ìgbà ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá, lọ́wọ́ ìran yìí;
Daje dă la asta generacijă u fi tražalită sănžilje dă la toc proroci kari u fost vărsată dăm elši dă kănd su stvorulit svetu:
51 láti ẹ̀jẹ̀ Abeli wá, títí ó sì fi dé ẹ̀jẹ̀ Sekariah, tí ó ṣègbé láàrín pẹpẹ àti tẹmpili. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín ìran yìí ni yóò ru gbogbo ẹ̀bi àwọn nǹkan wọ̀nyí.
su apuka dă la sănžilje alu Abel pănă la sănžilje alu Zaharija, kari u fost amurăt ăntri žrtvenik šă ăm svetinja dă Hram. Ju vă zăk: ‘Kă kutotu asta u fi tražalit dă la asta generacijă!’
52 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin amòfin, nítorí tí ẹ̀yin ti mú kọ́kọ́rọ́ ìmọ̀ kúrò; ẹ̀yin tìkára yín kò wọlé, àwọn tí sì ń wọlé, ni ẹ̀yin ń dí lọ́wọ́.”
Jao avovă učitelji dă zakonu alu Mojsije! Daje kă voj ac lot ăndărăt čejilje dă kraljevstva alu Dimizov. Voj săngur nac mers ăm nontru šă ac sprečilit pă alci să tunji ăm nontru kănd gănđe.”
53 Bí ó ti ń lọ kúrò níbẹ̀, àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi bẹ̀rẹ̀ sí bi í lọ́rọ̀ gidigidi, wọ́n sì ń yọ ọ́ lẹ́nu láti wí nǹkan púpọ̀.
Dă pă šje u fužjit Isus dă pă lokula, učitelji dă zakonu alu Mojsije šă farizeji sur ăngănđit să mergă dă pă jăl să ăl ispitivălaskă.
54 Wọ́n ń ṣọ́ ọ, wọ́n ń wá ọ̀nà láti rí nǹkan gbámú lẹ́nu kí wọn bá à lè fi ẹ̀sùn kàn án.
Gănđe să ăl apušji pă Isus ăm zamkă šje ar puće să zăkă protiv dă jăl numa să ăl dukă pă sud.

< Luke 11 >