< Luke 10 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
Дупэ ачея, Домнул а май рындуит алць шаптезечь де ученичь ши й-а тримис дой кыте дой ынаинтя Луй, ын тоате четэциле ши ын тоате локуриле пе унде авя сэ трякэ Ел.
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
Ши ле-а зис: „Маре есте сечеришул, дар пуцинь сунт лукрэторий! Ругаць дарпе Домнул сечеришулуй сэ скоатэ лукрэторь ла сечеришул Сэу.
3 Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
Дучеци-вэ; ятэ, вэ тримит ка пе ниште мей ын мижлокул лупилор.
4 Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
Сэну луаць ку вой нич пунгэ, нич трайстэ, нич ынкэлцэминте ши сэ ну ынтребаць пе нименьде сэнэтате пе друм.
5 “Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
Ынорьче касэ вець интра, сэ зичець ынтый: ‘Пачя сэ фие песте каса ачаста!’
6 Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
Ши дакэ ва фи аколо ун фиу ал пэчий, пачя воастрэ ва рэмыне песте ел, алтминтерь, еа се ва ынтоарче ла вой.
7 Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
Сэрэмынець ын каса ачея ши сэ мынкацьши сэ бець че ви се ва да, кэч вредник есте лукрэторулде плата са. Сэ ну умблаць дин касэ ын касэ.
8 “Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
Ын орькаре четате вець интра ши унде вэ вор прими оамений, сэ мынкаць че ви се ва пуне ынаинте,
9 Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
сэвиндекаць пе болнавий каре вор фи аколо ши сэ ле зичець: ‘Ымпэрэция луй Думнезеу с-аапропият де вой.’
10 Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
Дар, ын орькаре четате вець интра ши ну вэ вор прими, сэ вэ дучець пе улицеле ей ши сэ зичець:
11 ‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
‘Скутурэм ымпотрива воастрэ кяр шипрафул дин четатя воастрэ, каре с-а липит де пичоареле ноастре; тотушь сэ штиць кэ Ымпэрэция луй Думнезеу с-а апропият де вой.’
12 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
Еу вэ спун кэ, ын зиуа жудекэций, ва фи майушор пентру Содома декыт пентру четатя ачея.
13 “Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
Вайде тине, Хоразине! Вай де тине, Бетсаидо! Кэч, дакэ ар фи фост фэкуте ын Тир ши Сидон лукрэриле путерниче каре ау фост фэкуте ын вой, демулт с-ар фи покэит стынд ын сак ши ченушэ.
14 Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
Де ачея, ын зиуа жудекэций, ва фи май ушор пентру Тир ши Сидон декыт пентру вой.
15 Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
Шиту, Капернауме, вей фи ынэлцатоаре пынэ ла чер? Вей фи коборыт пынэын Локуинца морцилор. (Hadēs g86)
16 “Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
Чиневэ аскултэ пе вой пе Мине Мэ аскултэ шичине вэ несокотеште пе вой пе Мине Мэ несокотеште, ярчине Мэ несокотеште пе Мине несокотеште пе Чел че М-а тримис пе Мине.”
17 Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
Чей шаптезечь с-ау ынторс плинь де букурие ши ау зис: „Доамне, кяр ши драчий не сунт супушь ын Нумеле Тэу.”
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
Исус ле-а зис: „Амвэзут пе Сатана кэзынд ка ун фулӂер дин чер.
19 Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
Ятэ кэ в-амдат путере сэ кэлкаць песте шерпь ши песте скорпий ши песте тоатэ путеря врэжмашулуй: ши нимик ну вэ ва путя вэтэма.
20 Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
Тотушь, сэ ну вэ букураць де фаптул кэ духуриле вэ сунт супусе, чи букураци-вэ кэ нумелевоастре сунт скрисе ын черурь.”
21 Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
Ын часул ачела, Исус С-а букурат ын Духул Сфынт ши а зис: „Татэ, Доамне ал черулуй ши ал пэмынтулуй, Те лауд пентру кэ ай аскунс ачесте лукрурь де чей ынцелепць ши причепуць ши ле-ай дескоперит прунчилор. Да, Татэ, фииндкэ аша ай гэсит ку кале Ту.”
22 “Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
„Тоателукруриле Мь-ау фост дате ын мынь де Татэл Меу; шинимень ну штие чине есте Фиул, афарэ де Татэл, нич чине есте Татэл, афарэ де Фиул ши ачела кэруя вря Фиул сэ и-Л дескопере.”
23 Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
Апой, С-а ынторс спре ученичь ши ле-а спус деопарте: „Феричеде окий каре вэд лукруриле пе каре ле ведець вой!
24 Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
Кэч вэ спун кэмулць пророчь ши ымпэраць ау воит сэ вадэ че ведець вой, ши н-ау вэзут, сэ аудэ че аузиць вой, ши н-ау аузит.”
25 Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
Ун ынвэцэтор ал Леӂий с-а скулат сэ испитяскэ пе Исус ши Й-а зис: „Ынвэцэторуле, че сэ фак ка сэ моштенеск вяца вешникэ?” (aiōnios g166)
26 Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
Исус й-а зис: „Че есте скрис ын Леӂе? Кум читешть ын еа?”
27 Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
Ел а рэспунс: „Сэ юбешть пе Домнул Думнезеул тэу ку тоатэ инима та, ку тот суфлетул тэу, ку тоатэ путеря та ши ку тот куӂетул тэу ши пе апроапеле тэу ка пе тине ынсуць.”
28 Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
„Бине ай рэспунс”, й-а зис Исус; „фэ аша ши вейавя вяца вешникэ.”
29 Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
Дар ел, каре воя сэ се ындрептэцяскэ, а зис луй Исус: „Ши чине есте апроапеле меу?”
30 Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
Исус а луат дин ноу кувынтул ши а зис: „Ун ом се кобора дин Иерусалим ла Иерихон. А кэзут ынтре ниште тылхарь, каре л-ау дезбрэкат, л-ау жефуит де тот, л-ау бэтут здравэн, ау плекат ши л-ау лэсат апроапе морт.
31 Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
Дин ынтымпларе, се кобора пе ачелашь друм ун преот ши, кынд а вэзут пе омул ачеста, атрекут ынаинте пе алэтурь.
32 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
Ун левит тречя ши ел прин локул ачела ши, кынд л-а вэзут, а трекут ынаинте пе алэтурь.
33 Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
Дар ун самаритян, каре ера ын кэлэторие, а венит ын локул унде ера ел ши, кынд л-а вэзут, и с-а фэкут милэ де ел.
34 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
С-а апропият де й-а легат рэниле ши а турнат песте еле унтделемн ши вин, апой л-а пус пе добитокул луй, л-а дус ла ун хан ши а ынгрижит де ел.
35 Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
А доуа зи, кынд а порнит ла друм, а скос дой лей, й-а дат ханӂиулуй ши й-а зис: ‘Ай грижэ де ел, ши орьче вей май келтуи, ыць вой да ынапой ла ынтоарчере.’
36 “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
Каре динтре ачештя трей ци се паре кэ а дат довадэ кэ есте апроапеле челуй че кэзусе ынтре тылхарь?”
37 Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
„Чел че шь-а фэкут милэ ку ел”, а рэспунс ынвэцэторул Леӂий. „Ду-те де фэ ши ту ла фел”, й-а зис Исус.
38 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
Пе кынд ера пе друм ку ученичий Сэй, Исус а интрат ынтр-ун сат. Ши о фемее, нумитэ Марта, Л-а примит ын каса ей.
39 Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Еа авя о сорэ нумитэ Мария, каре с-а ашезат жос, ла пичоареле Домнулуй, ши аскулта кувинтеле Луй.
40 Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
Марта ера ымпэрцитэ ку мултэ служире, а венит репеде ла Ел ши Й-а зис: „Доамне, ну-Ць пасэ кэ сорэ-мя м-а лэсат сэ служеск сингурэ? Зи-й дар сэ-мь ажуте.”
41 Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
Дрепт рэспунс, Исус й-а зис: „Марто, Марто, пентру мулте лукрурь те ынгрижорезь ши те фрэмынць ту,
42 Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”
дар унсингур лукру требуе. Мария шь-а алес партя чя бунэ, каре ну и се ва луа.”

< Luke 10 >