< Luke 10 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
Iar după acestea, Domnul a mai rânduit [și] alți șaptezeci și i-a trimis doi câte doi înaintea feței lui în fiecare cetate și loc, oriunde avea să vină el însuși
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
De aceea le-a spus: Secerișul, într-adevăr, este mare, dar lucrătorii puțini; implorați, de aceea pe Domnul secerișului să trimită lucrători la secerișul lui.
3 Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
Mergeți; iată, eu vă trimit ca miei în mijlocul lupilor.
4 Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
Nu purtați nici pungă, nici traistă, nici încălțăminte; și nu salutați pe nimeni pe drum.
5 “Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
Iar în orice casă intrați, întâi spuneți: Pace acestei case.
6 Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
Și dacă, într-adevăr, este acolo fiul păcii, pacea voastră se va odihni peste ea; dar dacă nu, ea se va întoarce la voi.
7 Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
Și rămâneți în aceeași casă, mâncând și bând ce [vă] dau ei; fiindcă demn este lucrătorul de plata sa. Nu treceți din casă în casă.
8 “Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
Și în oricare cetate intrați și vă primesc, mâncați ce vi se va pune înainte;
9 Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
Și vindecați pe bolnavii din ea și spuneți-le: Împărăția lui Dumnezeu s-a apropiat de voi.
10 Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
Dar în oricare cetate intrați și nu vă primesc, mergeți pe străzile acesteia și spuneți:
11 ‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
Chiar praful cetății voastre, care se lipește de noi, îl ștergem împotriva voastră; totuși să fiți siguri de aceasta, că împărăția lui Dumnezeu s-a apropiat de voi.
12 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
Dar vă spun că va fi mai ușor de suportat în ziua aceea pentru Sodoma decât pentru acea cetate.
13 “Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
Vai ție, Corazine! Vai ție, Betsaido! Căci, dacă în Tir și Sidon ar fi fost făcute faptele puternice care au fost făcute în voi, de mult s-ar fi pocăit șezând în pânză de sac și cenușă.
14 Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
Dar pentru Tir și Sidon va fi mai ușor de suportat la judecată, decât pentru voi.
15 Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
Și tu, Capernaum, care ești înălțat la cer, vei fi aruncat jos în iad. (Hadēs g86)
16 “Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
Cel ce vă aude, pe mine mă aude; și cel ce vă disprețuiește, pe mine mă disprețuiește; și cel ce mă disprețuiește, disprețuiește pe cel ce m-a trimis.
17 Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
Și cei șaptezeci s-au întors cu bucurie, spunând: Doamne, până și dracii ne sunt supuși prin numele tău.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
Iar el le-a spus: Am privit pe Satan, căzând ca un fulger din cer.
19 Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
Iată, vă dau putere să călcați peste șerpi și scorpioni și peste toată puterea dușmanului; și nimic, în niciun fel, nu vă va vătăma.
20 Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
Totuși nu vă bucurați în aceasta, că duhurile vă sunt supuse; ci, mai degrabă, bucurați-vă pentru că numele voastre sunt scrise în cer.
21 Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
În acea oră Isus s-a bucurat în duh și a spus: Îți mulțumesc, Tată, Domn al cerului și al pământului, pentru că ai ascuns acestea de cei înțelepți și prevăzători și le-ai revelat pruncilor. Da, Tată, pentru că așa este plăcut înaintea ta.
22 “Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
Toate mi-au fost date de Tatăl meu; și nimeni nu știe cine este Fiul, decât Tatăl; și cine este Tatăl, decât Fiul și acela căruia Fiul voiește să îl reveleze.
23 Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
Și s-a întors spre discipoli și a spus deoparte: Binecuvântați sunt ochii care văd cele ce vedeți voi;
24 Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
Fiindcă vă spun că mulți profeți și împărați au dorit să vadă cele ce vedeți voi și nu au văzut; și să audă cele ce auziți și nu au auzit.
25 Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
Și iată, un anumit învățător al legii s-a sculat și l-a ispitit, spunând: Învățătorule, ce să fac să moștenesc viață eternă? (aiōnios g166)
26 Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
Și i-a spus: Ce este scris în lege? Cum citești?
27 Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
Și răspunzând, a zis: Să iubești pe Domnul Dumnezeul tău cu toată inima ta și cu tot sufletul tău și cu toată puterea ta și cu toată mintea ta și pe aproapele tău ca pe tine însuți.
28 Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
Și i-a zis: Drept ai răspuns; fă aceasta și vei trăi.
29 Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
Dar el, voind să se declare drept, i-a spus lui Isus: Și cine este aproapele meu?
30 Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
Și Isus, răspunzând, a zis: Un anumit om s-a coborât din Ierusalim la Ierihon și a căzut printre tâlhari, care l-au dezbrăcat și l-au rănit și au plecat lăsându-l aproape mort.
31 Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
Și din întâmplare, cobora un anumit preot pe acea cale; și când l-a văzut, a trecut înainte pe cealaltă parte.
32 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
Și în același fel și un levit, când a fost la locul acela, a venit și l-a văzut și a trecut înainte pe cealaltă parte.
33 Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
Dar un anumit samaritean, călătorind, a venit unde era el; și când l-a văzut, i s-a făcut milă.
34 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
Și a venit la el și i-a legat rănile, turnând peste ele untdelemn și vin și l-a pus pe animalul lui și l-a adus la un han și a avut grijă de el.
35 Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
Și a doua zi, când a plecat, a scos doi dinari și i-a dat hangiului și i-a spus: Ai grijă de el; și oricât vei mai cheltui, când mă întorc, îți voi înapoia.
36 “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
Atunci, care dintre aceștia trei ți se pare că a fost aproapele celui căzut printre tâlhari?
37 Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
Iar el a spus: Cel ce a arătat milă față de el. Atunci Isus i-a spus: Du-te și fă și tu la fel.
38 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
Și, s-a întâmplat, pe când mergeau ei, că el a intrat într-un sat anume; și o anume femeie numită Marta l-a primit în casa ei.
39 Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Și ea avea o soră numită Maria, care s-a așezat și ea la picioarele lui Isus și asculta cuvântul lui.
40 Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
Dar Marta era copleșită cu multă servire; și, venind la el, a spus: Doamne, nu îți pasă că sora mea m-a lăsat să servesc singură? Spune-i așadar să mă ajute.
41 Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
Dar Isus a răspuns și i-a zis: Marta, Marta, ești îngrijorată și tulburată pentru multe lucruri;
42 Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”
Dar un lucru este necesar; și Maria a ales partea cea bună, care nu i se va lua.

< Luke 10 >