< Luke 10 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
A potem naznaczył Pan i drugich siedmdziesiąt, i rozesłał je po dwóch przed obliczem swojem do każdego miasta i miejsca, do którego przyjść miał.
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
I mówił im: Żniwoć wprawdzie wielkie, ale robotników mało; proścież tedy Pana żniwa, aby wypchnął robotników na żniwo swoje.
3 Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
Idźcież: Oto ja was posyłam jako baranki wpośród wilków.
4 Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
Nie noścież mieszka, ani taistry, ani obuwia, i nikogo w drodze nie pozdrawiajcie;
5 “Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
A do któregokolwiek domu wnijdziecie, naprzód mówcie: Pokój temu domowi.
6 Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
A jeźliby tam był który syn pokoju, odpocznie nad nim pokój wasz; a jeźliż nie, wróci się do was.
7 Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
A w tymże domu zostańcie, jedząc i pijąc to, co mają; albowiem godzien jest robotnik zapłaty swojej; nie przechodźcie się z domu do domu.
8 “Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
A do któregokolwiek miasta weszlibyście, a przyjęliby was, jedzcie, co przed was położą;
9 Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
I uzdrawiajcie niemocnych, którzy by w niem byli, a mówcie im: Przybliżyło się do was królestwo Boże.
10 Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
A do któregobyściekolwiek miasta weszli, a nie przyjęto by was, wyszedłszy na ulice jego, mówcie:
11 ‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
I proch, który przylgnął do nas z miasta waszego, otrząsamy na was; wszakże to wiedzcie, że się do was przybliżyło królestwo Boże.
12 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
A mówię wam: Iż Sodomie w on dzień lżej będzie, niż onemu miastu.
13 “Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
Biada tobie, Chorazynie! biada tobie, Betsaido! bo gdyby się były w Tyrze i w Sydonie te cuda stały, które się stały w was, dawno by były w worze i w popiele siedząc pokutowały.
14 Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
Dlatego Tyrowi i Sydonowi lżej będzie na sądzie, niżeli wam.
15 Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
A ty, Kapernaum! któreś aż do nieba wywyższone, aż do piekła strącone będziesz. (Hadēs g86)
16 “Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
Kto was słucha, mnie słucha: a kto wami gardzi, mną gardzi; a kto mną gardzi, gardzi onym, który mię posłał.
17 Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
A tak wrócili się oni siedmdziesiąt z weselem, mówiąc: Panie! i dyjablić się nam poddawają w imieniu twojem.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
Tedy im rzekł: Widziałem szatana, jako błyskawicę z nieba spadającego.
19 Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
Oto wam daję moc, abyście deptali po wężach i po niedźwiadkach i po wszystkiej mocy nieprzyjacielskiej, a nic wam nie uszkodzi.
20 Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
Wszakże nie radujcie się z tego, iż się wam duchy poddawają; ale raczej radujcie się, że imiona wasze napisane są w niebiesiech.
21 Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
Onejże godziny rozradował się Jezus w duchu, i rzekł: Wysławiam cię, Ojcze, Panie nieba i ziemi! żeś te rzeczy zakrył przed mądrymi i roztropnymi, a objawiłeś je niemowlątkom; zaprawdę, Ojcze! że się tak upodobało tobie.
22 “Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
Wszystkie rzeczy dane mi są od Ojca mego, a nikt nie zna, kto jest Syn, tylko Ojciec, i kto jest Ojciec, tylko Syn, a komu by chciał Syn objawić.
23 Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
Tedy obróciwszy się do uczniów, rzekł im z osobna: Błogosławione oczy, które widzą, co wy widzicie.
24 Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
Bo powiadam wam, iż wiele proroków i królów żądali widzieć, co wy widzicie, ale nie widzieli; i słyszeć, co wy słyszycie, ale nie słyszeli.
25 Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
A oto niektóry zakonnik powstał, kusząc go i mówiąc: Nauczycielu! co czyniąc odziedziczę żywot wieczny? (aiōnios g166)
26 Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
A on rzekł do niego: W zakonie co napisano, jako czytasz?
27 Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
A on odpowiadając rzekł: Będziesz miłował Pana, Boga twego, ze wszystkiego serca twego, i ze wszystkiej duszy twojej, i ze wszystkiej siły twojej, i ze wszystkiej myśli twojej; a bliźniego twego, jako samego siebie.
28 Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
I rzekł mu: Dobrześ odpowiedział; to czyń, a będziesz żył.
29 Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
A on chcąc samego siebie usprawiedliwić, rzekł do Jezusa: I któż jest mi bliźni?
30 Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
Ale Jezus odpowiadając rzekł: Człowiek niektóry zstępował z Jeruzalemu do Jerycha, i wpadł między zbójców, którzy złupiwszy go i rany mu zadawszy, odeszli, na pół umarłego zostawiwszy.
31 Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
I przydało się, że kapłan niektóry szedł tą drogą, a ujrzawszy go, pominął.
32 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
Także i Lewita, dostawszy się na ono miejsce, a przyszedłszy i ujrzawszy go, pominął.
33 Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
Ale Samarytanin niektóry jadąc, przyjechał do niego, a ujrzawszy, użalił się go.
34 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
A przystąpiwszy zawiązał rany jego, a nalawszy oliwy i wina, i włożywszy go na bydlę swoje, wiódł go do gospody, i miał staranie o nim.
35 Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
A nazajutrz odjeżdżając, wyjął dwa grosze, i dał gospodarzowi, mówiąc: Miej o nim staranie, a cokolwiek nadto wyłożysz, ja, gdy się wrócę, oddam ci.
36 “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
Któryż tedy z tych trzech zda się tobie bliźnim być onemu, co był wpadł między zbójców?
37 Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
A on rzekł: Ten, który uczynił miłosierdzie nad nim. Rzekł mu tedy Jezus: Idźże, i ty uczyń także.
38 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
I stało się, gdy oni szli, że on wszedł do niektórego miasteczka, a niewiasta niektóra, imieniem Marta, przyjęła go do domu swego.
39 Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
A ta miała siostrę, którą zwano Maryją, która usiadłszy u nóg Jezusowych, słuchała słów jego.
40 Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
Ale Marta roztargniona była około rozmaitej posługi; która przystąpiwszy, rzekła: Panie! i nie dbasz, że siostra moja mnie samą zostawiła, abym posługiwała? Rzeczże jej, aby mi pomogła.
41 Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
A odpowiadając Jezus rzekł jej: Marto, Marto! troszczysz się i kłopoczesz się około wielu rzeczy;
42 Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”
Aleć jednego potrzeba. Lecz Maryja dobrą cząstkę obrała, która od niej odjęta nie będzie.

< Luke 10 >