< Luke 10 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
ⲁ̅ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲀ ⲚⲀⲒ ⲆⲈ ⲀⲠϬⲞⲒⲤ ⲞⲨⲰⲚϨ ⲚⲔⲈⲞ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲞⲢⲠⲞⲨ ⲚⲂ ⲂⲈⲂⲞⲖ ϦⲀϪⲰϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲞⲨⲂⲀⲔⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲈⲘ ⲘⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲚⲀϤⲚⲀϢⲈ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
ⲃ̅ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ⲠⲈ ϪⲈ ⲠⲒⲰⲤϦ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲠⲈ ⲚⲒⲈⲢⲄⲀⲦⲎⲤ ⲆⲈ ϨⲀⲚⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲈⲦⲰⲂϨ ⲞⲨⲚ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲘⲠⲒⲰⲤϦ ϨⲞⲠⲰⲤ ⲚⲦⲈϤϨⲒⲞⲨⲒ ⲚϨⲀⲚⲈⲢⲄⲀⲦⲎⲤ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲠⲈϤⲰⲤϦ.
3 Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
ⲅ̅ⲘⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲞⲨⲰⲢⲠ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚϨⲀⲚϨⲒⲎⲂ ϦⲈⲚⲐⲘⲎϮ ⲚϨⲀⲚⲞⲨⲰⲚϢ.
4 Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
ⲇ̅ⲘⲠⲈⲢϤⲀⲒ ⲚⲀⲤⲞⲨⲒ ⲞⲨⲆⲈ ⲠⲎⲢⲀ ⲞⲨⲆⲈ ⲐⲰⲞⲨⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢⲀⲤⲠⲀⲌⲈⲤⲐⲈ ⲚϨⲖⲒ ϨⲒ ⲪⲘⲰⲒⲦ.
5 “Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
ⲉ̅ⲠⲒⲎⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲢⲞϤ ⲀϪⲞⲤ ⲚϢⲞⲢⲠ ϪⲈ ⲦϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲘⲠⲀⲒⲎⲒ
6 Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈϢⲰⲠ ⲈⲠϢⲎⲢⲒ ⲚϮϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲘⲘⲀⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲈⲤⲈⲘⲦⲞⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲈϪⲰϤ ⲈϢⲰⲠ ⲘⲘⲞⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲈⲤⲈⲔⲞⲦⲤ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ.
7 Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
ⲍ̅ϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲎⲒ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲰ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲈⲚⲦⲰⲞⲨ ⲠⲒⲈⲢⲄⲀⲦⲎⲤ ⲄⲀⲢ ϤⲘⲠϢⲀ ⲚⲦⲈϤϦⲢⲈ ⲘⲠⲈⲢⲞⲨⲰⲦⲈⲂ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲎⲒ ⲈⲎⲒ.
8 “Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ϮⲂⲀⲔⲒ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲢⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲞⲨϢⲈⲠ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲰⲘ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲞⲨⲚⲀⲬⲀⲨ ϦⲀⲢⲰⲦⲈⲚ
9 Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲎ ⲈⲦϢⲰⲚⲒ ⲚϦⲎⲦⲤ ⲀⲢⲒⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϪⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲤϦⲰⲚⲦ ⲚϪⲈϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
10 Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
ⲓ̅ϮⲂⲀⲔⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲢⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲞⲨϢⲦⲈⲘϢⲈⲠ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲈⲤⲠⲖⲀⲦⲒⲀ ⲀϪⲞⲤ
11 ‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
ⲓ̅ⲁ̅ϪⲈ ⲠⲒⲔⲈϢⲰⲒϢ ⲈⲦⲀϤⲦⲰⲘⲒ ⲈⲚⲈⲚϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲂⲀⲔⲒ ⲦⲈⲚⲚⲀⲚⲈϨϤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲠⲖⲎⲚ ⲪⲀⲒ ⲀⲢⲒⲈⲘⲒ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲀⲤϦⲰⲚⲦ ⲚϪⲈϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
12 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
ⲓ̅ⲃ̅ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲈⲘⲦⲞⲚ ⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲚⲤⲞⲆⲞⲘⲀ ϦⲈⲚⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲈϨⲞⲦⲈ ϮⲂⲀⲔⲒ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.
13 “Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
ⲓ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞⲒ ⲚⲈⲬⲞⲢⲀⲌⲒⲚ ⲞⲨⲞⲒ ⲚⲈⲂⲎⲐⲤⲀⲒⲆⲀ ϪⲈ ⲚϨⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲦⲨⲢⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲦⲤⲒⲆⲰⲚ ⲈⲚⲈ ⲀⲨϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲈⲚⲀⲒϪⲞⲘ ⲈⲦⲀⲨϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲈⲒⲤⲐⲚⲈⲒ ⲀⲨⲈⲢⲘⲈⲦⲀⲚⲞⲒⲚ ⲈⲨϨⲈⲘⲤⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲞⲔ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲔⲈⲢⲘⲒ.
14 Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
ⲓ̅ⲇ̅ⲠⲖⲎⲚ ⲦⲨⲢⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲦⲤⲒⲆⲰⲚ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲈⲘⲦⲞⲚ ⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲚⲰⲞⲨ ϦⲈⲚϮⲔⲢⲒⲤⲒⲤ ⲈϨⲞⲦⲈⲢⲰⲦⲈⲚ.
15 Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs )
ⲓ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞ ϨⲰⲒ ⲔⲀⲪⲀⲢⲚⲀⲞⲨⲘ ⲘⲎ ⲦⲈⲢⲀϬⲒⲤⲒ ϢⲀ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲦⲪⲈ ⲤⲈⲚⲀⲐⲈⲂⲒⲞ ϢⲀ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲈⲀⲘⲈⲚϮ. (Hadēs )
16 “Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
ⲓ̅ⲋ̅ⲪⲎ ⲈⲦⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚⲤⲰⲦⲈⲚ ⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚⲤⲰⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈⲦϢⲰϢ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲀϤϢⲰϢ ⲘⲘⲞⲒ ⲪⲎ ⲈⲦϢⲰϢ ⲘⲘⲞⲒ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ.
17 Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
ⲓ̅ⲍ̅ⲀⲨⲦⲀⲤⲐⲞ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲒⲞ ϦⲈⲚⲞⲨⲢⲀϢⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲒⲔⲈⲆⲈⲘⲰⲚ ⲤⲈϬⲚⲞ ⲚϪⲰⲞⲨ ⲚⲀⲚ ϦⲈⲚⲠⲈⲔⲢⲀⲚ.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
ⲓ̅ⲏ̅ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲒⲚⲀⲨ ⲈⲠⲤⲀⲦⲀⲚⲀⲤ ⲈⲀϤϨⲈⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲞⲨⲤⲈⲦⲈⲂⲢⲎϪ.
19 Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
ⲓ̅ⲑ̅ϨⲎⲠⲠⲈ ⲀⲒϮ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲘⲠⲒⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲈϨⲰⲘⲒ ⲈϪⲈⲚ ϨⲀⲚϨⲞϤ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚϬⲖⲎ ⲚⲈⲘ ⲈϪⲈⲚ ϮϪⲞⲘ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲦⲈⲠⲒϪⲀϪⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲚⲈϤϬⲒ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚϪⲞⲚⲤ ⲚϨⲖⲒ.
20 Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
ⲕ̅ⲠⲖⲎⲚ ⲘⲠⲈⲢⲢⲀϢⲒ ϦⲈⲚⲪⲀⲒ ϪⲈ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲤⲈϬⲚⲞ ⲚϪⲰⲞⲨ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲢⲀϢⲒ ⲆⲈ ⲚⲐⲞϤ ϪⲈ ⲚⲈⲦⲈⲚⲢⲀⲚ ⲤⲈⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϦⲈⲚⲚⲒⲪⲎ ⲞⲨⲒ.
21 Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
ⲕ̅ⲁ̅ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲀϤⲐⲈⲖⲎⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϮⲞⲨⲰⲚϨ ⲚⲀⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲪⲒⲰⲦ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲦⲪⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲔⲀϨⲒ ϪⲈ ⲀⲔϨⲈⲠ ⲚⲀⲒ ⲈϨⲀⲚⲤⲀⲂⲈⲨ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲔⲀⲦϨⲎⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲔϬⲞⲢⲠⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϨⲀⲚⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲀⲖⲰⲞⲨⲒ ⲀϨⲀ ⲪⲒⲰⲦ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲘⲠⲒϮⲘⲀϮ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲘⲠⲈⲔⲘⲐⲞ.
22 “Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
ⲕ̅ⲃ̅ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲀⲨⲦⲎⲒⲦⲞⲨ ⲚⲎⲒ ⲚⲦⲈⲚ ⲠⲀⲒⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲤⲰⲞⲨⲚ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲪⲒⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈ ⲪⲒⲰⲦ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲈⲘ ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲞⲨⲰϢ ⲈϬⲰⲢⲠ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ.
23 Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
ⲕ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲔⲞⲦϤ ⲈⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲤⲀⲠⲤⲀ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲞⲨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲰⲞⲨⲚⲒⲀⲦⲞⲨ ⲚⲚⲒⲂⲀⲖ ⲈⲐⲚⲀⲨ ⲈⲚⲎ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ
24 Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
ⲕ̅ⲇ̅ϮϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ϨⲀⲚⲘⲎ ϢⲘⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲞⲨⲢⲰⲞⲨ ⲀⲨⲞⲨⲰϢ ⲈⲚⲀⲨ ⲈⲚⲎ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲞⲨⲚⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲚⲎ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲞⲨⲤⲰⲦⲈⲘ.
25 Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios )
ⲕ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲒⲤ ⲞⲨⲚⲞⲘⲒⲔⲞⲤ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲀϤⲈⲢⲠⲒⲢⲀⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲒⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲞⲨ ⲠⲈϮⲚⲀⲚⲀⲒϤ ⲚⲦⲀⲈⲢⲔⲖⲎⲢⲞⲚⲞⲘⲒⲚ ⲚⲞⲨⲰⲚϦ ⲚⲈⲚⲈϨ. (aiōnios )
26 Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
ⲕ̅ⲋ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϦⲈⲚⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲒⲈ ⲀⲔⲰϢ ⲚⲀϢ ⲚⲢⲎϮ.
27 Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
ⲕ̅ⲍ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲈⲔⲈⲘⲈⲚⲢⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈⲔⲚⲞⲨϮ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲈⲔϨⲎ ⲦⲦⲎⲢϤ ⲚⲈⲘ ⲦⲈⲔⲮⲨⲬⲎ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲈⲘ ⲦⲈⲔϪⲞⲘ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲈⲘ ϦⲈⲚⲚⲈⲔⲘⲈⲨⲒ ⲦⲎⲢϤ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲔϢⲪⲎⲢ ⲘⲠⲈⲔⲢⲎϮ.
28 Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲔⲈⲢⲞⲨⲰ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲰⲞⲨⲦⲈⲚ ⲪⲀⲒ ⲀⲢⲒⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲬⲚⲀⲰⲚϦ.
29 Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
ⲕ̅ⲑ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈϤⲞⲨⲰϢ ⲈⲐⲘⲀⲒⲞ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ϨⲰϤ ⲠⲈ ⲠⲀϢⲪⲎⲢ.
30 Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
ⲗ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈϤⲚⲎⲞⲨ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲈⲒⲈⲢⲒⲬⲰ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲤⲒⲚⲰⲞⲨⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲂⲀϢϤ ⲀⲨϮ ⲚϨⲀⲚⲈⲢϦⲰⲦ ⲚⲀϤ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲀⲨⲬⲀϤ ⲈϤⲞⲒ ⲘⲪⲀϢⲘⲞⲨ.
31 Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
ⲗ̅ⲁ̅ⲔⲀⲦⲀ ⲞⲨϮⲘⲀϮ ⲆⲈ ⲞⲨⲞⲨⲎⲂ ⲚⲀϤⲚⲎ ⲞⲨ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲀϤⲤⲈⲚϤ ⲀϤⲬⲀϤ.
32 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
ⲗ̅ⲃ̅ⲔⲈⲖⲈⲨⲒⲦⲎⲤ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒⲘⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲀϤⲬⲀϤ ⲀϤⲤⲈⲚϤ.
33 Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
ⲗ̅ⲅ̅ⲞⲨⲤⲀⲘⲀⲢⲒⲦⲎⲤ ⲆⲈ ⲀϤⲘⲞϢⲒ ⲀϤⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲀϤϢⲈⲚϨⲎ Ⲧ.
34 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
ⲗ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲀϤⲘⲞⲨⲢ ⲚⲚⲈϤⲈⲢϦⲰⲦ ⲀϤϮ ⲚⲈϨ ϨⲒ ⲎⲢⲠ ⲚⲤⲰⲞⲨ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲖⲞϤ ⲈⲠⲈⲦⲈⲪⲰϤ ⲚⲦⲈⲂⲚⲎ ⲀϤⲈⲚϤ ⲈⲞⲨⲠⲀⲚⲦⲞⲬⲒⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϤⲒ ⲠⲈϤⲢⲰⲞⲨϢ.
35 Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
ⲗ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲀϤⲈⲚ ⲆⲎⲚⲀⲢⲒⲞⲚ ⲂⲈⲂⲞⲖ ⲀϤⲦⲎⲒⲦⲞⲨ ⲘⲠⲒⲠⲀⲚⲦⲞⲬⲈⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϤⲒ ⲠⲈϤⲢⲰⲞⲨϢ ϦⲈⲚⲚⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒϨⲞⲨⲞ ⲈⲦⲈⲔⲚⲀϬⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲒϢⲀⲚⲦⲀⲤⲐⲞ ϮⲚⲀⲦⲎⲒϤ ⲚⲀⲔ.
36 “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
ⲗ̅ⲋ̅ⲚⲒⲘ ⲞⲨⲚ ϦⲈⲚⲠⲀⲒⲄ ⲈⲦⲈⲔⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲀϤⲈⲢϢⲪⲎⲢ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲚⲒⲤⲒⲚⲰⲞⲨⲒ.
37 Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
ⲗ̅ⲍ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲒⲢⲒ ⲘⲠⲒⲚⲀⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲀⲢⲒⲞⲨⲒ ϨⲰⲔ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ.
38 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
ⲗ̅ⲏ̅ⲈⲨⲘⲞϢⲒ ⲆⲈ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲞⲨϮⲘⲒ ⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲈⲠⲈⲤⲢⲀⲚ ⲠⲈ ⲘⲀⲢⲐⲀ ⲀⲤϢⲞⲠϤ ⲈⲢⲞⲤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲈⲤⲎⲒ.
39 Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚⲦⲈ ⲐⲀⲒ ⲚⲞⲨⲤⲰⲚⲒ ⲈⲨⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲀⲢⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲤϨⲈⲘⲤⲒ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲚⲈⲚϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲀⲤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲠⲈϤⲤⲀϪⲒ.
40 Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
ⲙ̅ⲘⲀⲢⲐⲀ ⲆⲈ ⲚⲀⲤϬⲒ ⲚϨⲢⲀⲤ ⲠⲈ ⲘⲠⲔⲰϮ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϢⲈⲘϢⲒ ⲈⲦⲀⲤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦⲤ ⲠⲈϪⲀⲤ ϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲤⲈⲢⲘⲈⲖⲒ ⲚⲀⲔ ⲀⲚ ϪⲈ Ⲁ- ⲦⲀⲤⲰⲚⲒ ⲬⲀⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲈⲒϢⲈⲘϢⲒ ⲀϪⲞⲤ ⲞⲨⲚ ⲚⲀⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲤϮⲦⲞⲦⲤ ⲚⲎⲒ.
41 Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
ⲙ̅ⲁ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲘⲀⲢⲐⲀ ⲘⲀⲢⲐⲀ ⲦⲈϤⲒⲢⲰⲞⲨϢ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈϢⲦⲈⲢⲐⲰⲢ ⲈⲐⲂⲈ ⲞⲨⲘⲎϢ.
42 Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”
ⲙ̅ⲃ̅ϨⲀⲚⲔⲞⲨϪⲒ ⲆⲈ ⲠⲈ ϮⲬⲢⲒⲀ ⲒⲈ ⲞⲨⲀⲒ ⲘⲀⲢⲒⲀ ⲆⲈ ⲀⲤⲤⲰⲦⲠ ⲚⲀⲤ ⲚϮⲦⲞⲒ ⲈⲐⲚⲀⲚⲈⲤ ⲐⲎ ⲈⲦⲈⲚⲤⲈⲚⲀϢⲞⲖϤ ⲚⲦⲞⲦⲤ ⲀⲚ.