< Luke 1 >

1 Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa,
prathamatō yē sākṣiṇō vākyapracārakāścāsan tē'smākaṁ madhyē yadyat sapramāṇaṁ vākyamarpayanti sma
2 àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́.
tadanusāratō'nyēpi bahavastadvr̥ttāntaṁ racayituṁ pravr̥ttāḥ|
3 Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ,
ataēva hē mahāmahimathiyaphil tvaṁ yā yāḥ kathā aśikṣyathāstāsāṁ dr̥ḍhapramāṇāni yathā prāpnōṣi
4 kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.
tadarthaṁ prathamamārabhya tāni sarvvāṇi jñātvāhamapi anukramāt sarvvavr̥ttāntān tubhyaṁ lēkhituṁ matimakārṣam|
5 Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti.
yihūdādēśīyahērōdnāmakē rājatvaṁ kurvvati abīyayājakasya paryyāyādhikārī sikhariyanāmaka ēkō yājakō hārōṇavaṁśōdbhavā ilīśēvākhyā
6 Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn.
tasya jāyā dvāvimau nirdōṣau prabhōḥ sarvvājñā vyavasthāśca saṁmanya īśvaradr̥ṣṭau dhārmmikāvāstām|
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.
tayōḥ santāna ēkōpi nāsīt, yata ilīśēvā bandhyā tau dvāvēva vr̥ddhāvabhavatām|
8 Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀.
yadā svaparyyānukramēṇa sikhariya īśvāsya samakṣaṁ yājakīyaṁ karmma karōti
9 Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
tadā yajñasya dinaparipāyyā paramēśvarasya mandirē pravēśakālē dhūpajvālanaṁ karmma tasya karaṇīyamāsīt|
10 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.
taddhūpajvālanakālē lōkanivahē prārthanāṁ kartuṁ bahistiṣṭhati
11 Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí.
sati sikhariyō yasyāṁ vēdyāṁ dhūpaṁ jvālayati taddakṣiṇapārśvē paramēśvarasya dūta ēka upasthitō darśanaṁ dadau|
12 Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á.
taṁ dr̥ṣṭvā sikhariya udvivijē śaśaṅkē ca|
13 Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu.
tadā sa dūtastaṁ babhāṣē hē sikhariya mā bhaistava prārthanā grāhyā jātā tava bhāryyā ilīśēvā putraṁ prasōṣyatē tasya nāma yōhan iti kariṣyasi|
14 Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ, ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ.
kiñca tvaṁ sānandaḥ saharṣaśca bhaviṣyasi tasya janmani bahava ānandiṣyanti ca|
15 Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá.
yatō hētōḥ sa paramēśvarasya gōcarē mahān bhaviṣyati tathā drākṣārasaṁ surāṁ vā kimapi na pāsyati, aparaṁ janmārabhya pavitrēṇātmanā paripūrṇaḥ
16 Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
san isrāyēlvaṁśīyān anēkān prabhōḥ paramēśvarasya mārgamānēṣyati|
17 Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”
santānān prati pitr̥ṇāṁ manāṁsi dharmmajñānaṁ pratyanājñāgrāhiṇaśca parāvarttayituṁ, prabhōḥ paramēśvarasya sēvārtham ēkāṁ sajjitajātiṁ vidhātuñca sa ēliyarūpātmaśaktiprāptastasyāgrē gamiṣyati|
18 Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Àmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”
tadā sikhariyō dūtamavādīt kathamētad vētsyāmi? yatōhaṁ vr̥ddhō mama bhāryyā ca vr̥ddhā|
19 Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá.
tatō dūtaḥ pratyuvāca paśyēśvarasya sākṣādvarttī jibrāyēlnāmā dūtōhaṁ tvayā saha kathāṁ gadituṁ tubhyamimāṁ śubhavārttāṁ dātuñca prēṣitaḥ|
20 Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”
kintu madīyaṁ vākyaṁ kālē phaliṣyati tat tvayā na pratītam ataḥ kāraṇād yāvadēva tāni na sētsyanti tāvat tvaṁ vaktuṁmaśaktō mūkō bhava|
21 Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili.
tadānīṁ yē yē lōkāḥ sikhariyamapaikṣanta tē madhyēmandiraṁ tasya bahuvilambād āścaryyaṁ mēnirē|
22 Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.
sa bahirāgatō yadā kimapi vākyaṁ vaktumaśaktaḥ saṅkētaṁ kr̥tvā niḥśabdastasyau tadā madhyēmandiraṁ kasyacid darśanaṁ tēna prāptam iti sarvvē bubudhirē|
23 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀.
anantaraṁ tasya sēvanaparyyāyē sampūrṇē sati sa nijagēhaṁ jagāma|
24 Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún,
katipayadinēṣu gatēṣu tasya bhāryyā ilīśēvā garbbhavatī babhūva
25 Ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó síjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”
paścāt sā pañcamāsān saṁgōpyākathayat lōkānāṁ samakṣaṁ mamāpamānaṁ khaṇḍayituṁ paramēśvarō mayi dr̥ṣṭiṁ pātayitvā karmmēdr̥śaṁ kr̥tavān|
26 Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti,
aparañca tasyā garbbhasya ṣaṣṭhē māsē jātē gālīlpradēśīyanāsaratpurē
27 sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria.
dāyūdō vaṁśīyāya yūṣaphnāmnē puruṣāya yā mariyamnāmakumārī vāgdattāsīt tasyāḥ samīpaṁ jibrāyēl dūta īśvarēṇa prahitaḥ|
28 Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”
sa gatvā jagāda hē īśvarānugr̥hītakanyē tava śubhaṁ bhūyāt prabhuḥ paramēśvarastava sahāyōsti nārīṇāṁ madhyē tvamēva dhanyā|
29 Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí.
tadānīṁ sā taṁ dr̥ṣṭvā tasya vākyata udvijya kīdr̥śaṁ bhāṣaṇamidam iti manasā cintayāmāsa|
30 Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
tatō dūtō'vadat hē mariyam bhayaṁ mākārṣīḥ, tvayi paramēśvarasyānugrahōsti|
31 Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu.
paśya tvaṁ garbbhaṁ dhr̥tvā putraṁ prasōṣyasē tasya nāma yīśuriti kariṣyasi|
32 Òun ó pọ̀, ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é, Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún.
sa mahān bhaviṣyati tathā sarvvēbhyaḥ śrēṣṭhasya putra iti khyāsyati; aparaṁ prabhuḥ paramēśvarastasya piturdāyūdaḥ siṁhāsanaṁ tasmai dāsyati;
33 Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.” (aiōn g165)
tathā sa yākūbō vaṁśōpari sarvvadā rājatvaṁ kariṣyati, tasya rājatvasyāntō na bhaviṣyati| (aiōn g165)
34 Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”
tadā mariyam taṁ dūtaṁ babhāṣē nāhaṁ puruṣasaṅgaṁ karōmi tarhi kathamētat sambhaviṣyati?
35 Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò síji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é.
tatō dūtō'kathayat pavitra ātmā tvāmāśrāyiṣyati tathā sarvvaśrēṣṭhasya śaktistavōpari chāyāṁ kariṣyati tatō hētōstava garbbhād yaḥ pavitrabālakō janiṣyatē sa īśvaraputra iti khyātiṁ prāpsyati|
36 Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀, èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.
aparañca paśya tava jñātirilīśēvā yāṁ sarvvē bandhyāmavadan idānīṁ sā vārddhakyē santānamēkaṁ garbbhē'dhārayat tasya ṣaṣṭhamāsōbhūt|
37 Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”
kimapi karmma nāsādhyam īśvarasya|
38 Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
tadā mariyam jagāda, paśya prabhērahaṁ dāsī mahyaṁ tava vākyānusārēṇa sarvvamētad ghaṭatām; ananataraṁ dūtastasyāḥ samīpāt pratasthē|
39 Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea;
atha katipayadināt paraṁ mariyam tasmāt parvvatamayapradēśīyayihūdāyā nagaramēkaṁ śīghraṁ gatvā
40 Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti.
sikhariyayājakasya gr̥haṁ praviśya tasya jāyām ilīśēvāṁ sambōdhyāvadat|
41 Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́,
tatō mariyamaḥ sambōdhanavākyē ilīśēvāyāḥ karṇayōḥ praviṣṭamātrē sati tasyā garbbhasthabālakō nanartta| tata ilīśēvā pavitrēṇātmanā paripūrṇā satī
42 Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.
prōccairgaditumārēbhē, yōṣitāṁ madhyē tvamēva dhanyā, tava garbbhasthaḥ śiśuśca dhanyaḥ|
43 Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?
tvaṁ prabhōrmātā, mama nivēśanē tvayā caraṇāvarpitau, mamādya saubhāgyamētat|
44 Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.
paśya tava vākyē mama karṇayōḥ praviṣṭamātrē sati mamōdarasthaḥ śiśurānandān nanartta|
45 Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́, nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”
yā strī vyaśvasīt sā dhanyā, yatō hētōstāṁ prati paramēśvarōktaṁ vākyaṁ sarvvaṁ siddhaṁ bhaviṣyati|
46 Maria sì dáhùn, ó ní: “Ọkàn mi yin Olúwa lógo.
tadānīṁ mariyam jagāda| dhanyavādaṁ parēśasya karōti māmakaṁ manaḥ|
47 Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
mamātmā tārakēśē ca samullāsaṁ pragacchati|
48 Nítorí tí ó síjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀. Sá wò ó, láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
akarōt sa prabhu rduṣṭiṁ svadāsyā durgatiṁ prati| paśyādyārabhya māṁ dhanyāṁ vakṣyanti puruṣāḥ sadā|
49 Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi; Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.
yaḥ sarvvaśaktimān yasya nāmāpi ca pavitrakaṁ| sa ēva sumahatkarmma kr̥tavān mannimittakaṁ|
50 Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ìrandíran.
yē bibhyati janāstasmāt tēṣāṁ santānapaṁktiṣu| anukampā tadīyā ca sarvvadaiva sutiṣṭhati|
51 Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀; o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.
svabāhubalatastēna prākāśyata parākramaḥ| manaḥkumantraṇāsārddhaṁ vikīryyantē'bhimāninaḥ|
52 Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.
siṁhāsanagatāllōkān balinaścāvarōhya saḥ| padēṣūccēṣu lōkāṁstu kṣudrān saṁsthāpayatyapi|
53 Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.
kṣudhitān mānavān dravyairuttamaiḥ paritarpya saḥ| sakalān dhaninō lōkān visr̥jēd riktahastakān|
54 Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;
ibrāhīmi ca tadvaṁśē yā dayāsti sadaiva tāṁ| smr̥tvā purā pitr̥ṇāṁ nō yathā sākṣāt pratiśrutaṁ| (aiōn g165)
55 sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.” (aiōn g165)
isrāyēlsēvakastēna tathōpakriyatē svayaṁ||
56 Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
anantaraṁ mariyam prāyēṇa māsatrayam ilīśēvayā sahōṣitvā vyāghuyya nijanivēśanaṁ yayau|
57 Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.
tadanantaram ilīśēvāyāḥ prasavakāla upasthitē sati sā putraṁ prāsōṣṭa|
58 Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.
tataḥ paramēśvarastasyāṁ mahānugrahaṁ kr̥tavān ētat śrutvā samīpavāsinaḥ kuṭumbāścāgatya tayā saha mumudirē|
59 Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.
tathāṣṭamē dinē tē bālakasya tvacaṁ chēttum ētya tasya pitr̥nāmānurūpaṁ tannāma sikhariya iti karttumīṣuḥ|
60 Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”
kintu tasya mātākathayat tanna, nāmāsya yōhan iti karttavyam|
61 Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”
tadā tē vyāharan tava vaṁśamadhyē nāmēdr̥śaṁ kasyāpi nāsti|
62 Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.
tataḥ paraṁ tasya pitaraṁ sikhariyaṁ prati saṅkētya papracchuḥ śiśōḥ kiṁ nāma kāriṣyatē?
63 Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.
tataḥ sa phalakamēkaṁ yācitvā lilēkha tasya nāma yōhan bhaviṣyati| tasmāt sarvvē āścaryyaṁ mēnirē|
64 Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.
tatkṣaṇaṁ sikhariyasya jihvājāḍyē'pagatē sa mukhaṁ vyādāya spaṣṭavarṇamuccāryya īśvarasya guṇānuvādaṁ cakāra|
65 Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.
tasmāccaturdiksthāḥ samīpavāsilōkā bhītā ēvamētāḥ sarvvāḥ kathā yihūdāyāḥ parvvatamayapradēśasya sarvvatra pracāritāḥ|
66 Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
tasmāt śrōtārō manaḥsu sthāpayitvā kathayāmbabhūvuḥ kīdr̥śōyaṁ bālō bhaviṣyati? atha paramēśvarastasya sahāyōbhūt|
67 Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:
tadā yōhanaḥ pitā sikhariyaḥ pavitrēṇātmanā paripūrṇaḥ san ētādr̥śaṁ bhaviṣyadvākyaṁ kathayāmāsa|
68 “Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,
isrāyēlaḥ prabhu ryastu sa dhanyaḥ paramēśvaraḥ| anugr̥hya nijāllōkān sa ēva parimōcayēt|
69 Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;
vipakṣajanahastēbhyō yathā mōcyāmahē vayaṁ| yāvajjīvañca dharmmēṇa sāralyēna ca nirbhayāḥ|
70 (bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́), (aiōn g165)
sēvāmahai tamēvaikam ētatkāraṇamēva ca| svakīyaṁ supavitrañca saṁsmr̥tya niyamaṁ sadā|
71 Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.
kr̥payā puruṣān pūrvvān nikaṣārthāttu naḥ pituḥ| ibrāhīmaḥ samīpē yaṁ śapathaṁ kr̥tavān purā|
72 Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,
tamēva saphalaṁ karttaṁ tathā śatrugaṇasya ca| r̥tīyākāriṇaścaiva karēbhyō rakṣaṇāya naḥ|
73 ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,
sr̥ṣṭēḥ prathamataḥ svīyaiḥ pavitrai rbhāvivādibhiḥ| (aiōn g165)
74 láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,
yathōktavān tathā svasya dāyūdaḥ sēvakasya tu|
75 ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
vaṁśē trātāramēkaṁ sa samutpāditavān svayam|
76 “Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;
atō hē bālaka tvantu sarvvēbhyaḥ śrēṣṭha ēva yaḥ| tasyaiva bhāvivādīti pravikhyātō bhaviṣyasi| asmākaṁ caraṇān kṣēmē mārgē cālayituṁ sadā| ēvaṁ dhvāntē'rthatō mr̥tyōśchāyāyāṁ yē tu mānavāḥ|
77 láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
upaviṣṭāstu tānēva prakāśayitumēva hi| kr̥tvā mahānukampāṁ hi yāmēva paramēśvaraḥ|
78 nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà; nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,
ūrdvvāt sūryyamudāyyaivāsmabhyaṁ prādāttu darśanaṁ| tayānukampayā svasya lōkānāṁ pāpamōcanē|
79 Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní òkùnkùn àti ní òjìji ikú, àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”
paritrāṇasya tēbhyō hi jñānaviśrāṇanāya ca| prabhō rmārgaṁ pariṣkarttuṁ tasyāgrāyī bhaviṣyasi||
80 Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.
atha bālakaḥ śarīrēṇa buddhyā ca varddhitumārēbhē; aparañca sa isrāyēlō vaṁśīyalōkānāṁ samīpē yāvanna prakaṭībhūtastāstāvat prāntarē nyavasat|

< Luke 1 >