< Luke 1 >

1 Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa,
Întrucât mulți s-au angajat să pună în ordine o istorisire despre acele lucruri care sunt pe deplin crezute printre noi,
2 àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́.
Chiar așa cum ni le-au încredințat cei care au fost de la început martori oculari și servitori ai cuvântului,
3 Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ,
Mi s-a părut bine și mie, înțelegând toate cu acuratețe de la început, să ți le scriu în ordine, preaalesule Teofil,
4 kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.
Ca să cunoști certitudinea lucrurilor în care ai fost învățat.
5 Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti.
A fost în zilele lui Irod, împăratul Iudeii, un anumit preot numit Zaharia, din rândul lui Abia; și soția lui era dintre fiicele lui Aaron, și numele ei era Elisabeta.
6 Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn.
Și amândoi erau drepți înaintea lui Dumnezeu, umblând ireproșabil în toate poruncile și rânduielile Domnului.
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.
Și ei nu aveau copil, pentru că Elisabeta era stearpă; și amândoi erau mult înaintați în vârstă.
8 Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀.
Dar s-a întâmplat, pe când el împlinea serviciul de preot înaintea lui Dumnezeu, la rândul grupului său,
9 Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
Conform obiceiului serviciului preoțesc, i-a venit rândul să ardă tămâie când intra în templul Domnului.
10 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.
Și toată mulțimea poporului se ruga afară în timpul tămâierii.
11 Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí.
Și i s-a arătat un înger al Domnului, stând în picioare la dreapta altarului tămâierii.
12 Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á.
Și când Zaharia l-a văzut, s-a tulburat și frică a căzut peste el.
13 Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu.
Dar îngerul i-a spus: Nu te teme Zaharia; fiindcă rugăciunea ta este ascultată; și soția ta Elisabeta îți va naște un fiu și îi vei pune numele Ioan.
14 Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ, ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ.
Și tu vei avea bucurie și veselie; și mulți se vor bucura la nașterea lui.
15 Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá.
Fiindcă va fi mare înaintea Domnului și nicidecum nu va bea nici vin, nici băutură tare; și va fi umplut cu Duhul Sfânt, chiar din pântecele mamei sale.
16 Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Și pe mulți dintre copiii lui Israel îi va întoarce la Domnul Dumnezeul lor.
17 Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”
Și el va merge înaintea lui, în duhul și puterea lui Ilie, să întoarcă inimile părinților la copii și pe cei neascultători la înțelepciunea celor drepți; să pregătească un popor înzestrat pentru Domnul.
18 Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Àmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”
Și Zaharia i-a spus îngerului: Prin ce voi ști aceasta? Fiindcă eu sunt bătrân și soția mea este mult înaintată în anii ei.
19 Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá.
Și îngerul, răspunzând, i-a zis: Eu sunt Gabriel, care stau în picioare în prezența lui Dumnezeu; și sunt trimis să vorbesc cu tine și să îți anunț aceste vești îmbucurătoare.
20 Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”
Și iată, vei fi mut și nu vei fi în stare să vorbești, până în ziua când se vor face acestea, pentru că nu crezi cuvintele mele, care vor fi împlinite la timpul lor.
21 Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili.
Și poporul îl aștepta pe Zaharia și se mira că el întârzia atât în templu.
22 Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.
Și când a ieșit nu a putut să vorbească cu ei; și au priceput că văzuse o viziune în templu; fiindcă el le făcea semne și a rămas fără cuvinte.
23 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀.
Și s-a întâmplat că, imediat ce s-au împlinit zilele serviciului său, s-a dus acasă.
24 Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún,
Iar după zilele acelea Elisabeta, soția lui, a rămas însărcinată și s-a ascuns cinci luni, spunând:
25 Ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó síjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”
Astfel s-a purtat cu mine Domnul în zilele în care s-a uitat spre mine, ca să îmi ia ocara dintre oameni.
26 Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti,
Iar în luna a șasea, îngerul Gabriel a fost trimis de Dumnezeu într-o cetate din Galileea, numită Nazaret,
27 sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria.
La o fecioară logodită cu un bărbat al cărui nume era Iosif, din casa lui David; și numele fecioarei era Maria.
28 Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”
Și îngerul a intrat la ea și a spus: Bucură-te, cea privilegiată: Domnul este cu tine; binecuvântată ești tu între femei.
29 Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí.
Iar când l-a văzut, ea a fost tulburată de cuvintele lui și cugeta ce fel de salutare ar fi aceasta.
30 Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Și îngerul i-a spus: Nu te teme, Maria; fiindcă ai găsit favoare la Dumnezeu.
31 Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu.
Și iată, vei rămâne însărcinată în pântecele tău și vei naște un fiu și îi vei pune numele Isus.
32 Òun ó pọ̀, ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é, Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún.
El va fi mare și va fi chemat Fiul Celui Preaînalt; și Domnul Dumnezeu îi va da tronul tatălui său David.
33 Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.” (aiōn g165)
Și va domni peste casa lui Iacob pentru totdeauna; și cât despre împărăția lui, ea nu va avea sfârșit. (aiōn g165)
34 Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”
Atunci Maria i-a spus îngerului: Cum va fi aceasta, fiindcă eu nu știu de bărbat?
35 Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò síji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é.
Și îngerul a răspuns și i-a zis: Duhul Sfânt va veni peste tine și puterea Celui Preaînalt te va umbri; de aceea și cel sfânt care se va naște din tine, va fi chemat Fiul lui Dumnezeu.
36 Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀, èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.
Și iată, Elisabeta, ruda ta, a rămas și ea însărcinată cu un fiu la bătrânețea ei; și aceasta este a șasea lună pentru ea, care era numită stearpă.
37 Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”
Căci la Dumnezeu nimic nu va fi imposibil.
38 Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
Iar Maria a spus: Iată, roaba Domnului; fie-mi după cuvântul tău. Și îngerul a plecat de la ea.
39 Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea;
Iar Maria s-a sculat în acele zile și a plecat cu grabă în ținutul muntos, într-o cetate a lui Iuda.
40 Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti.
Și a intrat în casa lui Zaharia și a salutat-o pe Elisabeta.
41 Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́,
Și s-a întâmplat că, de cum a auzit Elisabeta salutul Mariei, pruncul a săltat în pântecele ei; și Elisabeta a fost umplută cu Duhul Sfânt;
42 Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.
Și a vorbit cu voce tare și a spus: Binecuvântată ești tu între femei și binecuvântat este rodul pântecelui tău.
43 Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?
Și de unde îmi este aceasta, ca mama Domnului meu să vină la mine?
44 Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.
Căci iată, de cum a ajuns sunetul salutului tău la urechile mele, pruncul a săltat în pântecele meu de bucurie.
45 Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́, nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”
Și binecuvântată este cea care a crezut, pentru că va fi o împlinire a lucrurilor care i-au fost spuse din partea Domnului.
46 Maria sì dáhùn, ó ní: “Ọkàn mi yin Olúwa lógo.
Și Maria a spus: Sufletul meu preamărește pe Domnul,
47 Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
Și duhul meu s-a bucurat în Dumnezeu, Salvatorul meu.
48 Nítorí tí ó síjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀. Sá wò ó, láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
Pentru că a privit spre starea înjosită a roabei sale; căci, iată, de acum încolo, toate generațiile mă vor numi binecuvântată,
49 Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi; Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.
Pentru că cel puternic mi-a făcut lucruri mari; și sfânt este numele lui.
50 Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ìrandíran.
Și mila lui este peste cei ce se tem de el din generație în generație.
51 Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀; o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.
A arătat putere cu brațul lui; a risipit pe cei mândri în imaginația inimii lor.
52 Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.
A doborât pe cei puternici de pe tronuri și a înălțat pe cei de rând.
53 Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.
A săturat pe cei flămânzi cu bunătăți; și pe cei bogați i-a trimis fără nimic.
54 Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;
A ajutat pe servitorul său Israel, în amintirea milei sale;
55 sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.” (aiōn g165)
După cum le-a vorbit părinților noștri, lui Avraam și seminței sale pentru totdeauna. (aiōn g165)
56 Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
Și Maria a rămas cu ea cam trei luni; și s-a întors acasă.
57 Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.
Iar Elisabetei i s-a împlinit timpul să nască; și a născut un fiu.
58 Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.
Și vecinii și rudele ei au auzit că Domnul a arătat mare milă față de ea; și se bucurau cu ea.
59 Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.
Și s-a întâmplat în a opta zi că au venit să circumcidă copilul; și l-au numit Zaharia, după numele tatălui său.
60 Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”
Și mama lui a răspuns și a zis: Nu, ci se va numi Ioan.
61 Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”
Și i-au spus: Nimeni din rudeniile tale nu este numit așa.
62 Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.
Și făceau semne tatălui său, [despre] cum ar voi să îl numească.
63 Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.
Și a cerut o tăbliță de scris și a scris, spunând: Numele lui este Ioan. Și toți s-au minunat.
64 Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.
Și gura lui a fost deschisă imediat și limba lui dezlegată și a vorbit, lăudând pe Dumnezeu.
65 Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.
Și frică a venit peste toți cei ce locuiau împrejurul lor; și toate aceste cuvinte au fost vestite prin tot ținutul muntos al Iudeii.
66 Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
Și toți cei ce le-au auzit, le-au păstrat în inimile lor, spunând: Ce fel de copil va fi acesta? Și mâna Domnului era cu el.
67 Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:
Și Zaharia, tatăl lui, a fost umplut cu Duhul Sfânt și a profețit, spunând:
68 “Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,
Binecuvântat fie Domnul Dumnezeul lui Israel, pentru că a vizitat și a răscumpărat pe poporul său,
69 Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;
Și ne-a ridicat un corn al salvării în casa servitorului său, David,
70 (bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́), (aiōn g165)
Așa cum vorbise prin gura sfinților săi profeți, care fuseseră de când lumea a început; (aiōn g165)
71 Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.
Ca să fim salvați de dușmanii noștri și din mâna tuturor celor ce ne urăsc;
72 Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,
Să înfăptuiască mila promisă părinților noștri și să își amintească sfântul lui legământ;
73 ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,
Jurământul pe care i l-a jurat tatălui nostru Avraam,
74 láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,
Că ne va da, fiind noi scăpați din mâna dușmanilor noștri, să îi servim fără frică,
75 ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
În sfințenie și dreptate înaintea lui, toate zilele vieții noastre.
76 “Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;
Și tu copile, vei fi chemat profet al celui Preaînalt; fiindcă vei merge înaintea feței Domnului, să pregătești căile lui;
77 láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
Să dai cunoștința salvării poporului său, prin iertarea păcatelor lor,
78 nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà; nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,
Prin blânda milă a Dumnezeului nostru; prin care răsăritul din înalt ne-a vizitat,
79 Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní òkùnkùn àti ní òjìji ikú, àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”
Să dea lumină celor ce șed în întuneric și în umbra morții, să ne îndrepte picioarele pe calea păcii.
80 Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.
Iar copilul a crescut și s-a întărit în duh și a fost în pustiuri până în ziua arătării sale înaintea lui Israel.

< Luke 1 >