< Luke 1 >

1 Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa,
Ponieważ wielu podjęło się sporządzić opis tych wydarzeń, co do których mamy zupełną pewność;
2 àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́.
Tak jak nam [je] przekazali ci, którzy od początku byli naocznymi świadkami i sługami słowa;
3 Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ,
Postanowiłem i ja, który to wszystko od początku dokładnie wybadałem, opisać ci [to] po kolei, zacny Teofilu;
4 kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.
Abyś nabrał pewności co do tego, czego cię nauczono.
5 Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti.
Za dni Heroda, króla Judei, żył pewien kapłan imieniem Zachariasz, ze zmiany Abiasza. Miał on za żonę [jedną] z córek Aarona, której na imię było Elżbieta.
6 Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn.
Oboje byli sprawiedliwi w oczach Boga, postępując nienagannie według wszystkich przykazań i nakazów Pana.
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.
Nie mieli jednak dziecka, ponieważ Elżbieta była niepłodna, i oboje byli w podeszłym wieku.
8 Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀.
A gdy pełnił służbę kapłańską przed Bogiem w kolejności swojej zmiany;
9 Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
Zgodnie ze zwyczajem urzędu kapłańskiego padł na niego los, aby wejść do świątyni Pana i palić kadzidło.
10 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.
A cała rzesza ludzi modliła się na zewnątrz w czasie kadzenia.
11 Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí.
Wtedy ukazał mu się anioł Pana stojący po prawej stronie ołtarza kadzenia.
12 Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á.
I przeraził się Zachariasz na jego widok, i ogarnął go strach.
13 Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu.
Lecz anioł powiedział do niego: Nie bój się, Zachariaszu, bo twoja modlitwa została wysłuchana. Elżbieta, twoja żona, urodzi ci syna, któremu nadasz imię Jan.
14 Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ, ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ.
Będzie to dla ciebie radość i wesele; i wielu będzie się radować z jego narodzin.
15 Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá.
Będzie bowiem wielki w oczach Pana. Nie będzie pił wina ani mocnego napoju i zostanie napełniony Duchem Świętym już w łonie swojej matki.
16 Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
I wielu z synów Izraela nawróci do Pana, ich Boga.
17 Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”
On bowiem pójdzie przed nim w duchu i mocy Eliasza, aby zwrócić serca ojców ku dzieciom, a opornych ku roztropności sprawiedliwych, aby przygotować Panu lud gotowy.
18 Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Àmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”
I powiedział Zachariasz do anioła: Po czym to poznam? Bo ja jestem stary i moja żona jest w podeszłym wieku.
19 Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá.
A anioł mu odpowiedział: Ja jestem Gabriel, który stoi przed Bogiem. Zostałem posłany, aby mówić do ciebie i przynieść ci tę radosną nowinę.
20 Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”
I będziesz niemy, i nie będziesz mógł mówić aż do dnia, kiedy się to stanie, dlatego że nie uwierzyłeś moim słowom, które się wypełnią w swoim czasie.
21 Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili.
A ludzie czekali na Zachariasza i dziwili się, że tak długo przebywa w świątyni.
22 Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.
Kiedy wyszedł, nie mógł do nich mówić. I zrozumieli, że miał widzenie w świątyni, bo dawał im znaki, i pozostał niemy.
23 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀.
A gdy skończyły się dni jego posługi, wrócił do swego domu.
24 Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún,
Po tych dniach Elżbieta, jego żona, poczęła i ukrywała się przez pięć miesięcy, mówiąc:
25 Ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó síjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”
Tak mi uczynił Pan w dniach, kiedy wejrzał [na mnie], aby zdjąć moją hańbę w oczach ludzi.
26 Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti,
A w szóstym miesiącu Bóg posłał anioła Gabriela do miasta w Galilei, zwanego Nazaret;
27 sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria.
Do dziewicy zaślubionej mężczyźnie, któremu na imię było Józef, z rodu Dawida; a dziewicy było na imię Maria.
28 Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”
Kiedy anioł przyszedł do niej, powiedział: Witaj, obdarowana łaską, Pan jest z tobą. Błogosławiona jesteś między kobietami.
29 Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí.
Ale ona, ujrzawszy [go], zlękła się z powodu jego słów i zastanawiała się, co miałoby znaczyć to pozdrowienie.
30 Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Wtedy anioł powiedział do niej: Nie bój się, Mario, znalazłaś bowiem łaskę u Boga.
31 Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu.
Oto poczniesz w [swym] łonie i urodzisz syna, któremu nadasz imię Jezus.
32 Òun ó pọ̀, ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é, Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún.
Będzie on wielki i będzie nazwany Synem Najwyższego, a Pan Bóg da mu tron jego ojca Dawida.
33 Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.” (aiōn g165)
I będzie królował nad domem Jakuba na wieki, a jego królestwu nie będzie końca. (aiōn g165)
34 Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”
Wtedy Maria powiedziała do anioła: Jak to się stanie, skoro nie obcowałam z mężczyzną?
35 Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò síji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é.
A anioł jej odpowiedział: Duch Święty zstąpi na ciebie i moc Najwyższego zacieni cię. Dlatego też to święte, co się z ciebie narodzi, będzie nazwane Synem Bożym.
36 Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀, èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.
A oto Elżbieta, twoja krewna, także poczęła syna w swojej starości i jest w szóstym miesiącu ta, którą nazywano niepłodną.
37 Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”
Dla Boga bowiem nie ma nic niemożliwego.
38 Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
I powiedziała Maria: Oto służebnica Pana, niech mi się stanie według twego słowa. Wtedy odszedł od niej anioł.
39 Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea;
W tych dniach Maria wstała i poszła z pośpiechem w góry do miasta w Judei.
40 Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti.
Weszła do domu Zachariasza i pozdrowiła Elżbietę.
41 Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́,
A gdy Elżbieta usłyszała pozdrowienie Marii, poruszyło się dziecko w jej łonie i Elżbieta została napełniona Duchem Świętym.
42 Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.
I zawołała donośnym głosem: Błogosławiona jesteś między kobietami i błogosławiony jest owoc twego łona.
43 Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?
A skądże mi to, że matka mego Pana przyszła do mnie?
44 Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.
Gdy bowiem głos twego pozdrowienia zabrzmiał w moich uszach, poruszyło się z radości dziecko w moim łonie.
45 Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́, nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”
A błogosławiona, która uwierzyła. Spełni się bowiem to, co zostało jej powiedziane przez Pana.
46 Maria sì dáhùn, ó ní: “Ọkàn mi yin Olúwa lógo.
Wtedy Maria powiedziała: Wielbi moja dusza Pana;
47 Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
I rozradował się mój duch w Bogu, moim Zbawicielu;
48 Nítorí tí ó síjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀. Sá wò ó, láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
Bo wejrzał na uniżenie swojej służebnicy. Oto bowiem wszystkie pokolenia będą mnie odtąd nazywać błogosławioną.
49 Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi; Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.
Bo uczynił mi wielkie rzeczy ten, który jest mocny, i święte jest jego imię.
50 Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ìrandíran.
A jego miłosierdzie z pokolenia na pokolenie nad tymi, którzy się go boją.
51 Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀; o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.
Okazał moc swoim ramieniem i rozproszył pysznych w myślach ich serc.
52 Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.
Strącił mocarzy z tronów, a wywyższył pokornych.
53 Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.
Głodnych napełnił dobrami, a bogaczy odprawił z niczym.
54 Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;
Ujął się za Izraelem, swym sługą, pomny na [swoje] miłosierdzie;
55 sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.” (aiōn g165)
Jak mówił do naszych ojców, [do] Abrahama i jego potomstwa na wieki. (aiōn g165)
56 Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
I została z nią Maria około trzech miesięcy, a potem wróciła do swego domu.
57 Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.
Dla Elżbiety zaś nadszedł czas porodu i urodziła syna.
58 Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.
A gdy jej sąsiedzi i krewni usłyszeli, że Pan okazał jej swoje wielkie miłosierdzie, cieszyli się razem z nią.
59 Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.
A ósmego dnia przyszli, aby obrzezać dziecko, i [chcieli] nadać mu imię jego ojca, Zachariasza.
60 Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”
Ale jego matka powiedziała: Nie tak, lecz będzie się nazywał Jan.
61 Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”
I powiedzieli do niej: Nie ma nikogo w twoim rodzie, kogo by nazwano tym imieniem.
62 Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.
Pytali więc znakami jego ojca, jak chce go nazwać.
63 Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.
A on poprosił o tabliczkę i napisał: Jan jest jego imię. I dziwili się wszyscy.
64 Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.
Natychmiast otworzyły się jego usta i [rozwiązał się] jego język, i mówił, wielbiąc Boga.
65 Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.
I padł strach na wszystkich ich sąsiadów, i po całej górskiej krainie judzkiej rozgłoszone zostały wszystkie te słowa.
66 Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
Wszyscy zaś, którzy o tym słyszeli, brali to sobie do serca i mówili: Cóż to będzie za dziecko? I była z nim ręka Pańska.
67 Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:
A Zachariasz, jego ojciec, będąc napełniony Duchem Świętym, prorokował:
68 “Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,
Błogosławiony niech będzie Pan, Bóg Izraela, bo nawiedził i odkupił swój lud;
69 Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;
I wzbudził nam róg zbawienia w domu Dawida, swego sługi;
70 (bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́), (aiōn g165)
Jak mówił przez usta swoich świętych proroków, którzy byli od wieków; (aiōn g165)
71 Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.
[Że nas] wybawi od naszych nieprzyjaciół i z ręki wszystkich, którzy nas nienawidzą;
72 Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,
Aby okazać miłosierdzie naszym ojcom i przypomnieć swoje święte przymierze;
73 ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,
I przysięgę, którą złożył Abrahamowi, naszemu ojcu;
74 láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,
Że nam da, [abyśmy] mu służyli bez lęku, wybawieni z ręki naszych nieprzyjaciół;
75 ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
W świętości i sprawiedliwości przed nim po wszystkie dni naszego życia.
76 “Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;
A ty, dziecko, będziesz nazwane prorokiem Najwyższego, bo pójdziesz przed obliczem Pana, aby przygotować jego drogi;
77 láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
I żeby jego ludowi dać poznać zbawienie przez przebaczenie mu grzechów;
78 nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà; nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,
Dzięki serdecznemu miłosierdziu naszego Boga, przez które nawiedził nas wschód [słońca] z wysoka;
79 Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní òkùnkùn àti ní òjìji ikú, àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”
Aby oświecić siedzących w ciemności i w cieniu śmierci, aby skierować nasze kroki na drogę pokoju.
80 Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.
A dziecko rosło i umacniało się w duchu, i przebywało na pustyniach aż do dnia ukazania się przed Izraelem.

< Luke 1 >