< Leviticus 1 >

1 Olúwa sì pe Mose, ó sì bá a sọ̀rọ̀ láti inú àgọ́ àjọ. Ó wí pé,
Aa le kinanji’Iehovà t’i Mosè vaho nisaontsia’e boak’ amy kibohom-pamantañañey ty hoe:
2 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, kí ọrẹ ẹbọ yín jẹ́ ẹran ọ̀sìn láti inú agbo ẹran tàbí láti inú ọ̀wọ́ ẹran.
Misaontsia amo ana’ Israeleo le ano ty hoe: Naho ama’ areo ty hañenga soroñe am’ Iehovà, le añandeso amo hare’ areoo: he amo lia-raikeo ke amo añombeo.
3 “‘Bí ọrẹ ẹbọ náà bá jẹ́ ẹbọ sísun láti inú agbo ẹran kí òun kí ó mú akọ màlúù tí kò lábùkù. Ó sì gbọdọ̀ mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà níwájú Olúwa
Aa ie hañenga soroñe boak’ am-pirai-trokey, le lahi’e tsy aman-kandra, an-tsatrin-tro’e t’ie hañenga añatrefa’Iehovà an-dalan-kibohom-pamantañañe eo.
4 kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé orí ẹbọ sísun náà yóò sì jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà dípò o rẹ̀, yóò sì jẹ́ ètùtù fún un.
Hasampe’e an-doha’ i hisoroñañey o fità’eo, soa te ho rambeseñe ama’e ho fijebańañe aze.
5 Kí ó pa ọ̀dọ́ akọ màlúù náà níwájú Olúwa, lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà tí í ṣe ọmọ Aaroni yóò gbé ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà yí pẹpẹ tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ ká.
Ho lentae’e añatrefa’Iehovà i baniay; le hendese’ o ana’ i Aharone mpisoroñeo ty lio’e vaho hada­si’ iareo añariary i kitrely an-dalan-kibohom-pamantañañey ty lio’e.
6 Òun yóò bó awọ ara ẹbọ sísun náà, òun yóò sì gé e sí wẹ́wẹ́.
Le ho holire’e i hisoroñañey vaho ho patepatere’e.
7 Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò fi iná sí orí pẹpẹ, wọn yóò sì to igi sórí pẹpẹ náà.
Le hampipok’ afo amy kitreliy o ana’i Aharone, Mpisoroñeo, vaho handahatse ty hatae amy afoy.
8 Lẹ́yìn náà ni àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò tó ègé ẹran náà, pẹ̀lú orí àti ọ̀rá rẹ̀ sí orí igi tó ń jó lórí pẹpẹ.
Ho hajarie’ o mpisoroñe, ana’ i Aharoneo, amo hatae añ’ afo ambone’ i kitreliio o tori-henao naho i lohay vaho i safots-ènay;
9 Kí ó fi omi sàn nǹkan inú àti àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀, kí àlùfáà sì sun gbogbo rẹ̀ lórí pẹpẹ, ó jẹ́ ọrẹ ẹbọ sísun, ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
le ho sasà’e an-drano o aova’eo naho o tombo’eo, naho ho forototoe’ i mpisoroñey irezay ho hatoeñe ambone’ i kitreliy, ho soroñe, enga oroañe añ’ afo, ­hàñim-pañanintsiñe am’ Iehovà.
10 “‘Bí ọrẹ ẹbọ náà bá jẹ́ ẹbọ sísun láti inú ọ̀wọ́ ẹran, láti ara àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ tàbí àgùntàn, kí ó mú akọ tí kò lábùkù,
Aa naho boak’ amo mpirai-liao—ke añondry he ose—ty hisoroñañe, le ho lahi’e tsy aman-kandra ty hengae’e.
11 kí ó pa á ní apá àríwá pẹpẹ níwájú Olúwa, kí àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí gbogbo ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ náà ká.
Ho lentà’e avara’ i kitrely añatrefa’ Iehovày, vaho hadàsi’ o ana’ i Aharone mpisoroñeo añ’ariari’ i kitreliy ty lio’e.
12 Kí ó gé e sí wẹ́wẹ́, kí àlùfáà sì to ègé ẹran náà; orí àti ọ̀rá rẹ̀ sí orí igi tó ń jó lórí pẹpẹ.
Ho lilie’e i henay; vaho halaha’ i mpisoroñey ami’ty hatae amy afo ambone’ i kitreliiy ty loha’e naho ty safo’e,
13 Kí ó fi omi ṣan nǹkan inú àti àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀, kí àlùfáà sì gbé gbogbo rẹ̀ wá láti sun lórí pẹpẹ. Ó jẹ́ ẹbọ sísun tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
le ho sasà’e rano o ova’eo naho o tombo’eo naho ho fonga engae’ i mpisoroñey, hengae’e an-katoeñe amy kitreliy ho soroñe, enga oroañe añ’ afo, hàñim-pañanintsiñe am’ Iehovà.
14 “‘Bí ó bá sì ṣe pé ti ẹyẹ ni ẹbọ sísun ọrẹ ẹbọ rẹ̀ sí Olúwa, ǹjẹ́ kí ó mú ọrẹ ẹbọ rẹ̀ wá nínú àdàbà tàbí ọmọ ẹyẹlé.
Aa naho voroñe ty hengae’e ho soroñañe am’ Iehovà; he deho ke ana-boromahilala ty ho banabanae’e.
15 Kí àlùfáà mu wá sí ibi pẹpẹ, kí ó yín in lọ́rùn, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ, kí ó sì ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ.
Hendese’ i mpisoroñey mb’ amy kitreliy mb’eo, le haola’e i lohay, naho hengae’e an-katoeñe amy kitreliy; vaho hampiorihe’e añ’ila’ i kitreliy o lio’eo.
16 Kí ó yọ àjẹsí ẹyẹ náà pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀, kí ó gbe lọ ṣí apá ìlà-oòrùn pẹpẹ níbi tí eérú wà.
Hafaha’e ty tsibokò’e naho o volo’eo vaho hahi­fi’e ami’ty ila atiñana’ i kitreliy mb’amy toen-davenokey.
17 Kí ó gbá apá rẹ̀ méjèèjì mú, kí ó fà á ya, ṣùgbọ́n kí ó má ya á tan pátápátá. Lẹ́yìn náà ni àlùfáà yóò sun ún lórí igi tí ó ń jó lórí pẹpẹ, ẹbọ sísun ni ọrẹ tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
Ho vorahe’e amo ela’eo fe tsy ho riate’e roe, le hengae’ i mpisoroñey ho hatoeñe amy kitreliy amy hatae ambone’ i afoiy; ho soroñe, enga oroañe añ’afo, hàñim-pañanintsiñe am’ Iehovà.

< Leviticus 1 >