< Leviticus 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹjọ, Mose pe Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Israẹli.
Mũthenya wa ĩnana wakinya, Musa agĩĩta Harũni na ariũ ake, na athuuri a Isiraeli.
2 Ó sọ fún Aaroni pé, “Mú akọ ọmọ màlúù kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti àgbò kan fún ẹbọ sísun, kí méjèèjì jẹ́ aláìlábùkù, kí o sì mú wọn wá sí iwájú Olúwa.
Akĩĩra Harũni atĩrĩ, “Oya njaũ ya ndegwa ya iruta rĩaku rĩa kũhoroherio mehia na ndũrũme ya iruta rĩaku rĩa njino, cierĩ itigakorwo na kaũũgũ, ũcineane hau mbere ya Jehova.
3 Kí o sì sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹ mú òbúkọ kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ọmọ màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí méjèèjì jẹ́ ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun,
Ũcooke wĩre andũ a Isiraeli atĩrĩ: ‘Oyai thenge ya iruta rĩa kũhoroherio mehia, na gacaũ na gatũrũme, twerĩ twa ũkũrũ wa mwaka ũmwe na tũtarĩ na kaũũgũ, tũtuĩke iruta rĩa njino,
4 àti akọ màlúù kan àti àgbò kan fún ẹbọ àlàáfíà àti ẹbọ ohun jíjẹ tí a fi òróró pò láti fi rú ẹbọ ní iwájú Olúwa. Nítorí pé Olúwa yóò farahàn yín ní òní.’”
na muoye ndegwa na ndũrũme cia iruta rĩa ũiguano irutwo igongona mbere ya Jehova, hamwe na iruta rĩa mũtu ũtukanĩtio na maguta. Nĩgũkorwo ũmũthĩ Jehova nĩekũmuumĩrĩra.’”
5 Wọ́n kó gbogbo àwọn nǹkan tí Mose pàṣẹ wá sí iwájú àgọ́ ìpàdé, gbogbo ìjọ ènìyàn sì súnmọ́ tòsí, wọ́n sì dúró níwájú Olúwa.
Nao magĩtwara indo icio Musa aathanĩte irutwo mbere ya Hema-ya-Gũtũnganwo, nakĩo kĩũngano kĩa andũ a Isiraeli gĩothe gĩgĩkuhĩrĩria, gĩkĩrũgama hau mbere ya Jehova.
6 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ohun tí Olúwa pàṣẹ fún yín láti ṣe nìyìí, kí ògo Olúwa bá à lè farahàn yín.”
Musa agĩcooka akĩmeera atĩrĩ, “Ũũ nĩguo Jehova aathanĩte mwĩke, nĩguo riiri wa Jehova ũmuumĩrĩre.”
7 Mose sọ fún Aaroni pé, “Wá sí ibi pẹpẹ kí o sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti ẹbọ sísun rẹ, kí o sì ṣe ètùtù fún ara rẹ àti fún àwọn ènìyàn; rú ẹbọ ti àwọn ènìyàn náà, kí o sì ṣe ètùtù fún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ.”
Musa akĩĩra Harũni atĩrĩ, “Ũka kĩgongona-inĩ ũrute igongona rĩaku rĩa kũhoroherio mehia na iruta rĩaku rĩa njino, wĩhoroherie wee mwene na ũhoroherie andũ aya; ũcooke ũrute igongona rĩa indo iria andũ marehete ũmahoroherie, o ta ũrĩa Jehova aathanĩte.”
8 Aaroni sì wá sí ibi pẹpẹ, ó pa akọ ọmọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Harũni agĩũka kĩgongona-inĩ, agĩthĩnja gacaũ ka iruta rĩa kũhoroherio mehia, nĩ ũndũ wake mwene.
9 Àwọn ọmọ Aaroni sì mú ẹ̀jẹ̀ náà tọ̀ ọ́ wá, ó sì ti ìka ọwọ́ rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà, ó fi sí orí ìwo pẹpẹ, ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Ariũ ake makĩmũrehere thakame ĩyo, nake agĩtobokia kĩara gĩake thakame-inĩ ĩyo, akĩmĩhaka hĩa cia kĩgongona; nayo thakame ĩyo ĩngĩ akĩmĩita hau gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona.
10 Ó sun ọ̀rá, kíndìnrín àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, èyí tó mú láti inú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, lórí pẹpẹ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Agĩcooka agĩcinĩra maguta hau kĩgongona igũrũ, na higo cierĩ na maguta marĩa mahumbĩire ini, ma kuuma iruta-inĩ rĩu rĩa kũhoroherio mehia, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa;
11 Ó sì sun ara ẹran àti awọ rẹ̀ ní ẹ̀yìn ibùdó.
nacio nyama cia iruta rĩu na rũũa agĩcicinĩra nja ya kambĩ.
12 Lẹ́yìn èyí ó pa ẹran tó wà fún ẹbọ sísun. Àwọn ọmọ Aaroni sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wọn yí pẹpẹ náà ká.
Ningĩ agĩthĩnja iruta rĩa njino. Nao ariũ ake makĩmũnengera thakame ĩyo, nake akĩmĩminjaminjĩria kĩgongona mĩena yothe.
13 Wọ́n sì ń mú ẹbọ sísun náà fún un ní ègé kọ̀ọ̀kan, pẹ̀lú orí rẹ̀, ó sun gbogbo rẹ̀ lórí pẹpẹ.
Nao makĩmũnengera iruta rĩu rĩa njino gĩcunjĩ kĩmwe gwa kĩmwe, o hamwe na mũtwe, nake agĩcicinĩra kĩgongona-inĩ.
14 Ó fọ nǹkan inú rẹ̀ àti ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sun wọ́n lórí ẹbọ sísun tó wà lórí pẹpẹ.
Ningĩ agĩthambia nyama cia nda na mathagiro na agĩcicinĩra igũrũ rĩa iruta rĩa njino hau kĩgongona-inĩ.
15 Aaroni mú ẹbọ tó jẹ́ ti àwọn ènìyàn wá. Ó mú òbúkọ èyí tó dúró fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn ó sì pa á, ó fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ti àkọ́kọ́.
Ningĩ Harũni akĩrehe iruta rĩrĩa rĩarĩ rĩa kũrutĩrwo andũ. Akĩoya thenge ĩrĩa ya kũrutĩrwo andũ ĩrĩ iruta rĩa kũmahoroheria mehia akĩmĩthĩnja akĩmĩruta nĩ ũndũ wa iruta rĩa kũhoroheria mehia, o ta ũrĩa ekĩte ĩyo ya mbere.
16 Ó mú ẹbọ sísun wá, ó sì rú u gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a fi lélẹ̀.
Harũni akĩrehe iruta rĩu rĩa njino akĩrĩruta o ta ũrĩa gwatuĩtwo.
17 Ó tún mu ẹbọ ohun jíjẹ wá, ó bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú rẹ̀, ó sì sun ún lórí pẹpẹ ní àfikún ẹbọ sísun tí àárọ̀.
Agĩcooka akĩrehe iruta rĩa mũtu, akĩrũma ngundi yaguo, na akĩũcinĩra igũrũ rĩa kĩgongona hamwe na iruta rĩa njino rĩa rũciinĩ.
18 Ó pa akọ màlúù àti àgbò bí ẹbọ àlàáfíà fún àwọn ènìyàn. Àwọn ọmọ Aaroni sì mú ẹ̀jẹ̀ ẹran náà tọ̀ ọ́ wá, ó sì wọn yí pẹpẹ náà ká.
Ningĩ agĩthĩnja ndegwa na ndũrũme irĩ iruta rĩa ũiguano nĩ ũndũ wa andũ. Ariũ ake makĩmũnengera thakame yacio, nake akĩmĩminjaminjĩria kĩgongona mĩena yothe.
19 Ṣùgbọ́n ọ̀rá akọ màlúù àti àgbò náà: ìrù rẹ̀ tí ó lọ́ràá, básí ọ̀rá, ọ̀rá kíndìnrín, àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀:
No maguta ma ndegwa, na ma ndũrũme, na ma mũtingʼoe mũnoru, na ma rũambũ, na higo cierĩ na maguta marĩa mahumbĩire ini,
20 gbogbo rẹ̀ ni wọ́n kó lórí igẹ̀ ẹran náà. Aaroni sì sun ọ̀rá náà lórí pẹpẹ.
icio magĩciigĩrĩra ithũri-inĩ, nake Harũni agĩcinĩra maguta macio kĩgongona-inĩ.
21 Aaroni fi igẹ̀ àti itan ọ̀tún ẹran náà níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì bí Mose ṣe pa á láṣẹ.
Harũni agĩcooka agĩthũngũthia ithũri icio na kĩero kĩa mwena wa ũrĩo mbere ya Jehova ĩrĩ iruta rĩa gũthũngũthio, o ta ũrĩa Musa aathanĩte.
22 Aaroni sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn ènìyàn, ó sì súre fún wọn. Lẹ́yìn tó sì ti rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà, ó sọ̀kalẹ̀.
Ningĩ Harũni akĩambararia moko make amaroretie na kũrĩ andũ akĩmarathima. Na tondũ nĩarĩkĩtie kũruta iruta rĩu rĩa kũhoroherio mehia, na iruta rĩa njino, na iruta rĩa ũiguano, agĩikũrũka kuuma kĩgongona-inĩ.
23 Mose àti Aaroni sì wọ inú àgọ́ ìpàdé. Nígbà tí wọ́n jáde, wọ́n súre fún àwọn ènìyàn, ògo Olúwa sì farahàn sí gbogbo ènìyàn.
Musa na Harũni magĩthiĩ magĩtoonya Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo. Rĩrĩa moimire nja, makĩrathima andũ; naguo riiri wa Jehova ũkiumĩrĩra andũ othe.
24 Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì jó ẹbọ sísun àti ọ̀rá orí pẹpẹ. Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì rí èyí wọ́n hó ìhó ayọ̀, wọ́n sì dojúbolẹ̀.
Mwaki ũkiuma harĩ Jehova ũgĩcina iruta rĩu rĩa njino na maguta marĩa maarĩ kĩgongona-inĩ. Na rĩrĩa andũ othe maawoonire makĩanĩrĩra nĩ gũkena, makĩinamĩrĩra maturumithĩtie mothiũ mao thĩ.

< Leviticus 9 >