< Leviticus 8 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
2 “Mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, aṣọ wọn, òróró ìtasórí, akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò méjì àti apẹ̀rẹ̀ tí a kó àkàrà aláìwú sínú rẹ̀.
“Rehe Harũni na ariũ ake, na nguo ciao, na maguta ma gũitanĩrĩrio, na ndegwa ya iruta rĩa kũhoroherio mehia, na ndũrũme igĩrĩ, na gĩkabũ kĩa mĩgate ĩrugĩtwo ĩtarĩ na ndawa ya kũimbia,
3 Kí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.”
ũcooke ũcookanĩrĩrie kĩũngano gĩothe kĩa andũ a Isiraeli mũromo-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.”
4 Mose sì ṣe bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un, gbogbo ènìyàn sì péjọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
Musa agĩĩka o ta ũrĩa Jehova aamwathĩte, nakĩo kĩũngano kĩu gĩgĩcookanĩrĩra mũromo-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
5 Mose sì sọ fún ìjọ ènìyàn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ pé kí á ṣe.”
Nake Musa akĩĩra kĩũngano kĩu atĩrĩ, “Ũũ nĩguo Jehova aathanĩte gwĩkwo”
6 Nígbà náà ni Mose mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá síwájú, ó sì fi omi wẹ̀ wọ́n.
Nake Musa akĩrehe Harũni na ariũ ake hau mbere, akĩmathambia na maaĩ.
7 Ó sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ Aaroni, ó fi àmùrè dì í, ó wọ̀ ọ́ ní efodu; aṣọ ìgúnwà, ó sì tún wọ̀ ọ́ ni aṣọ ìlekè oyè àlùfáà tí ó ní ìgbànú tí a ṣe ọnà dáradára sí.
Agĩcooka akĩhumba Harũni kanjũ, na akĩmuoha mũcibi, na akĩmũhumba nguo ĩrĩa ya igũrũ ndaaya, na akĩmwĩkĩra ebodi. Ningĩ akĩmuoherera ebodi na mũcibi wa njohero ũrĩa watumĩtwo wega; nĩ ũndũ ũcio ũkĩohererwo harĩ we, akĩmũhotora naguo.
8 Ó fi ìgbàyà sí àyà rẹ̀, ó sì fi Urimu àti Tumimu sí ibi ìgbàyà náà.
Agĩcooka akĩmwĩkĩra gakuo ga gĩthũri, na gakuo-inĩ kau agĩĩkĩra Urimu na Thumimu.
9 Ó dé e ní fìlà, ó sì fi àwo wúrà tí í ṣe adé mímọ́ síwájú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Ningĩ akĩoha Harũni kĩremba mũtwe, na agĩĩkĩra gathuuma ga thahabu, nako nĩ tanji nyamũre, akĩmĩĩkĩra mwena wa mbere wa kĩremba o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
10 Mose sì fi òróró ìtasórí ya àgọ́ àti ohun gbogbo tó wà nínú rẹ̀ sí mímọ́.
Ningĩ Musa akĩoya maguta marĩa ma gũitanĩrĩrio na akĩmaitĩrĩria Hema-ĩrĩa-Nyamũre na kĩrĩa gĩothe kĩarĩ thĩinĩ wayo, na nĩ ũndũ ũcio agĩciamũra.
11 Ó wọ́n díẹ̀ nínú òróró yìí sórí pẹpẹ lẹ́ẹ̀méje, ó ta òróró sórí pẹpẹ àti gbogbo ohun èlò àti agbada pẹ̀lú ohun tó gbé agbada yìí dúró láti lè yà á sí mímọ́,
Nĩaminjaminjĩirie kĩgongona kĩu maguta mamwe ma macio maita mũgwanja, agĩitĩrĩria kĩgongona kĩu maguta hamwe na indo ciakĩo ciothe, na mbakũri hamwe na mĩrũgamo yakĩo, agĩciamũra.
12 ó da díẹ̀ lára òróró ìtasórí yìí sórí Aaroni, ó sì yà á sí mímọ́.
Nĩaitĩrĩirie Harũni maguta mamwe mũtwe akĩmũitĩrĩria maguta nĩgeetha amwamũre.
13 Lẹ́yìn èyí ló mú àwọn ọmọ Aaroni wá síwájú, ó sì fi ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n, ó fi àmùrè dìwọ́n lára, ó fi fìlà dé wọn lórí gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Ningĩ akĩrehe ariũ a Harũni hau mbere na akĩmahumba kanjũ, akĩmooha mĩcibi na akĩmekĩra tũkũbia mũtwe, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
14 Ó sì mú akọ màlúù wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé orí ẹran náà.
Ningĩ akĩneana ndegwa ya iruta rĩa kũhoroherio mehia, nake Harũni na ariũ ake makĩigĩrĩra moko mao igũrũ rĩa mũtwe wa ndegwa ĩyo.
15 Mose pa akọ màlúù náà, ó sì ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà, ó fi sí orí gbogbo ìwo pẹpẹ láti wẹ pẹpẹ náà mọ́. Ó da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ ní ó ṣe yà á sí mímọ́ láti ṣe ètùtù fún un.
Musa agĩthĩnja ndegwa ĩyo, na akĩoya thakame ĩmwe yayo na kĩara gĩake, akĩmĩhaka hĩa ciothe cia kĩgongona nĩgeetha atherie kĩgongona. Agĩcooka agĩita thakame ĩyo ĩngĩ gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona. Nĩ ũndũ ũcio agĩkĩamũra nĩguo akĩhoroherie.
16 Mose tún mú gbogbo ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú, èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀, kíndìnrín méjèèjì àti ọ̀rá wọn, ó sì sun gbogbo rẹ̀ lórí pẹpẹ.
Ningĩ Musa akĩoya maguta mothe marĩa maahumbĩire nyama cia nda, na marĩa maahumbĩire ini, na higo cierĩ na maguta ma cio, akĩmacinĩra kĩgongona-inĩ.
17 Ṣùgbọ́n akọ màlúù yìí pẹ̀lú awọ àti ara ẹran àti ìgbẹ́ rẹ̀ ní ó sun lẹ́yìn ibùdó gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mose.
No ndegwa ĩyo, hamwe na rũũa rwayo na nyama ciayo na mahu mayo agĩcicinĩra nja ya kambĩ, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
18 Lẹ́yìn náà ló mú àgbò wá fún ẹbọ sísun Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé orí àgbò náà.
Agĩcooka akĩneana ndũrũme ya iruta rĩa njino, nake Harũni na ariũ ake makĩigĩrĩra moko mao igũrũ rĩa mũtwe wa ndũrũme ĩyo.
19 Mose sì pa àgbò náà, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
Musa agĩcooka agĩthĩnja ndũrũme ĩyo, na akĩminjaminjĩria thakame yayo mĩena yothe ya kĩgongona.
20 Ó gé àgbò náà sí wẹ́wẹ́, Mose sì sun orí àti àwọn ègé àti ọ̀rá rẹ̀.
Agĩcooka agĩtinangia ndũrũme ĩyo icunjĩ, na agĩcina mũtwe na icunjĩ icio na maguta.
21 Ó fi omi fọ gbogbo nǹkan inú àti ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì sun odidi àgbò náà lórí pẹpẹ bí ẹbọ sísun òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa gẹ́gẹ́ bí Olúwa tí pàṣẹ fún Mose.
Musa nĩathambirie nyama cia nda na mathagiro na maaĩ, na agĩcinĩra ndũrũme ĩyo yothe kĩgongona-inĩ, ĩgĩtuĩka iruta rĩa njino rĩrĩ na mũtararĩko mwega, narĩo nĩ iruta rĩrutĩirwo Jehova rĩa gũcinwo na mwaki, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
22 Ó sì mú àgbò kejì wa, èyí ni àgbò ìfinijoyè àlùfáà, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé e lórí.
Ningĩ Musa akĩneana ndũrũme ĩyo ĩngĩ, nĩyo ndũrũme ya kĩamũrano, nake Harũni na ariũ ake makĩigĩrĩra moko mao igũrũ rĩa mũtwe wayo.
23 Mose sì pa àgbò náà, ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀, ó tọ́ ọ sí etí ọ̀tún Aaroni, sórí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti ti ẹsẹ̀ ọ̀tún rẹ̀.
Musa agĩthĩnja ndũrũme ĩyo, na akĩoya thakame ĩmwe yayo akĩmĩhaka moni ya gũtũ kwa ũrĩo kwa Harũni, na kĩara gĩake kĩrĩa kĩnene gĩa guoko gwake kwa ũrĩo, na kĩara gĩake kĩrĩa kĩnene gĩa kũgũrũ gwake kwa ũrĩo.
24 Mose sì tún mú àwọn ọmọ Aaroni wá síwájú, ó sì mú ẹ̀jẹ̀ díẹ̀ ó fi sí etí ọ̀tún wọn, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún wọn, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
Ningĩ Musa akĩrehe ariũ a Harũni hau mbere, na akĩmahaka thakame ĩmwe moni cia matũ mao ma ũrĩo, na ciara ciao iria nene cia moko mao ma ũrĩo, na ciara ciao iria nene cia magũrũ mao ma ũrĩo. Ningĩ akĩminjaminjĩria kĩgongona thakame mĩena yothe.
25 Ó mú ọ̀rá ẹran náà, ìrù rẹ̀ tí ó lọ́ràá, gbogbo ọ̀rá tó wà lára nǹkan inú àti èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀, kíndìnrín méjèèjì àti ọ̀rá wọn pẹ̀lú itan ọ̀tún.
Agĩcooka akĩoya maguta, maguta ma mũtingʼoe mũnoru, na maguta mothe marĩa mahumbĩire nyama cia nda, na marĩa mahumbĩire ini, na higo cierĩ na maguta ma cio, o na kĩero kĩa mwena wa ũrĩo.
26 Lẹ́yìn náà ló mú àkàrà aláìwú sí, èyí tó wà níwájú Olúwa àti àkàrà tí a fi òróró ṣe, àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, ó sì kó gbogbo rẹ̀ sórí ọ̀rá àti itan ọ̀tún ẹran náà.
Ningĩ kuuma gĩkabũ-inĩ kĩa mĩgate ĩrĩa yarugĩtwo ĩtarĩ ndawa ya kũimbia, kĩrĩa kĩarĩ hau mbere ya Jehova, akĩoya kamũgate, na kamũgate kangĩ kaarugĩtwo na maguta, na kamũgate kangĩ kahũthũ; agĩtũigĩrĩra igũrũ rĩa icunjĩ cia maguta macio na kĩero-inĩ kĩu kĩa ũrĩo.
27 Ó kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí lé Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́, wọ́n sì fì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì níwájú Olúwa.
Indo icio ciothe agĩciigĩrĩra moko-inĩ ma Harũni na ma ariũ ake, agĩcithũngũthĩria mbere ya Jehova ituĩke iruta rĩa gũthũngũthio.
28 Lẹ́yìn náà, Mose gba gbogbo rẹ̀ lọ́wọ́ wọn, ó sì sun wọn lórí ẹbọ sísun tó wà lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìfinijoyè àlùfáà òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa.
Ningĩ Musa agĩcooka agĩcioya kuuma moko-inĩ mao, agĩcicinĩra kĩgongona-inĩ igũrũ rĩa iruta rĩa njino, irĩ iruta rĩa kĩamũrano rĩrĩ na mũtararĩko mwega, nĩrĩo iruta rĩrutĩirwo Jehova rĩa gũcinwo na mwaki.
29 Mose sì mú igẹ̀ ẹran náà, èyí tó jẹ́ ìpín rẹ̀ nínú àgbò fún ìfinijoyè, ó sì fì í níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, bi Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Musa agĩcooka akĩoya gĩthũri kĩrĩ rwĩga rwake thĩinĩ wa ndũrũme ĩyo ya kĩamũrano, agĩgĩthũngũthĩria mbere ya Jehova gĩtuĩke iruta rĩa gũthũngũthio, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
30 Mose sì mú díẹ̀ lára òróró ìtasórí àti díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ láti orí pẹpẹ, ó wọ́n sára àwọn ọmọ Aaroni àti aṣọ rẹ̀, ó sì tún wọ́n sára àwọn ọmọ Aaroni àti aṣọ wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Mose ya Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ wọn sí mímọ́.
Ningĩ Musa akĩoya maguta mamwe ma macio ma gũitanĩrĩrio, na thakame ĩmwe kuuma kĩgongona-inĩ agĩciminjaminjĩria Harũni hamwe na nguo ciake, na ariũ ake hamwe na nguo ciao. Nĩ ũndũ ũcio akĩamũra Harũni na nguo ciake, na ariũ ake na nguo ciao.
31 Mose sì sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ se ẹran náà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé kí ẹ sì jẹ ẹ́ níbẹ̀ pẹ̀lú àkàrà tí a mú láti inú apẹ̀rẹ̀ ọrẹ ìfinijoyè àlùfáà gẹ́gẹ́ bí mo ti pa á láṣẹ pé, ‘Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó jẹ ẹ́.’
Ningĩ Musa akĩĩra Harũni na ariũ ake atĩrĩ, “Rugĩrai nyama icio itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo na mũcirĩĩre o hau hamwe na mĩgate kuuma gĩkabũ-inĩ kĩa iruta rĩa kĩamũrano, o ta ũrĩa njathanĩte ngoiga atĩrĩ, ‘Harũni na ariũ ake nĩmacirĩĩage.’
32 Kí ẹ fi iná sun ìyókù àkàrà àti ẹran náà.
Ningĩ mũcooke mũcine nyama na mĩgate ĩrĩa ĩgũtigara.
33 Ẹ má ṣe kúrò ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje, títí tí ọjọ́ ìfinijoyè àlùfáà yín yóò fi pé, nítorí pé ìfinijoyè àlùfáà yín yóò gba ọjọ́ méje gbáko.
Mũtikehere itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo ihinda rĩa mĩthenya mũgwanja, nginya matukũ manyu ma kwamũrwo mahinge, nĩ ũndũ kwamũrwo kwanyu gũgaikara mĩthenya mũgwanja.
34 Ohun tí a ṣe lónìí jẹ́ ohun tí Olúwa ti pàṣẹ láti ṣe ètùtù fún yín.
Ũrĩa gwĩkĩtwo ũmũthĩ, gwathanĩtwo nĩ Jehova nĩguo mũhoroherio.
35 Ẹ gbọdọ̀ wà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé lọ́sàn án àti lóru fún ọjọ́ méje kí ẹ sì ṣe ohun tí Olúwa fẹ́, kí ẹ má ba à kú, nítorí ohun tí Olúwa pàṣẹ fún mi ni èyí.”
No nginya mũikare itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo mĩthenya mũgwanja, mũthenya na ũtukũ, nĩguo mũhingie ũrĩa Jehova arenda, nĩguo mũtigakue; nĩgũkorwo ũguo nĩguo njathĩtwo.”
36 Báyìí ni Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ láti ẹnu Mose.
Nĩ ũndũ ũcio Harũni na ariũ ake magĩĩka maũndũ marĩa mothe Jehova aathĩte Musa mekwo.

< Leviticus 8 >