< Leviticus 7 >

1 “‘Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún rírú ẹbọ ẹ̀bi, tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
Och detta är lagen om skuldoffret: Det är högheligt.
2 Níbi tí wọn ti ń pa ẹran ẹbọ sísun ni kí ẹ ti pa ẹran ẹbọ ẹ̀bi, kí ẹ sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
På samma plats där man slaktar brännoffersdjuret skall man slakta skuldoffersdjuret. Och man skall stänka dess blod på altaret runt omkring.
3 Gbogbo ọ̀rá rẹ̀ ni kí ẹ sun, ọ̀rá ìrù rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú rẹ̀.
Och allt dess fett skall man offra, svansen och det fett som omsluter inälvorna,
4 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lẹ́bàá ìhà rẹ̀, àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú àwọn kíndìnrín.
och båda njurarna med det fett som sitter på dem invid länderna, så ock leverfettet, vilket man skall frånskilja invid njurarna.
5 Àlùfáà yóò sun wọ́n lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
Och prästen skall förbränna det på altaret till ett eldsoffer åt HERREN. Det är ett skuldoffer.
6 Gbogbo ọkùnrin ní ìdílé àlùfáà ló lè jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́, ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
Allt mankön bland prästerna må äta det; på en helig plats skall det ätas; det är högheligt.
7 “‘Òfin yìí kan náà ló wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ ẹ̀bi: méjèèjì jẹ́ tí àlùfáà, tó fi wọ́n ṣe ètùtù.
Vad som gäller om syndoffret skall ock gälla om skuldoffret; samma lag skall gälla för dem båda. Den präst som bringar försoning därmed, honom skall det tillhöra.
8 Àlùfáà tó rú ẹbọ sísun fún ẹnikẹ́ni le è mú awọ ẹran ìrúbọ náà.
Och när en präst bär fram brännoffer for någon, skall huden av det framburna brännoffersdjuret tillhöra den prästen.
9 Gbogbo ẹbọ ohun jíjẹ tí a bá yan lórí ààrò, àti gbogbo èyí tí a yan nínú apẹ, àti nínú àwopẹ̀tẹ́, ni kí ó jẹ́ ti àlùfáà tí ó rú ẹbọ náà.
Och ett spisoffer som är bakat i ugn, eller som är tillrett i panna eller på plåt, skall alltid tillfalla den präst som bär fram det.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ẹbọ ohun jíjẹ yálà a fi òróró pò ó tàbí èyí tó jẹ́ gbígbẹ, wọ́n jẹ́ ti gbogbo ọmọ Aaroni.
Men ett spisoffer som är begjutet med olja, eller som frambäres torrt, skall alltid tillfalla Arons söner gemensamt, den ene likaväl som den andre.
11 “‘Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún ọrẹ àlàáfíà tí ẹnikẹ́ni bá gbé wá síwájú Olúwa.
Och detta är lagen om tackoffret, när ett sådant bäres fram åt HERREN:
12 “‘Bí ẹni náà bá gbé e wá gẹ́gẹ́ bí àfihàn ọkàn ọpẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọpẹ́ yìí, ó gbọdọ̀ mú àkàrà aláìwú tí a fi òróró pò wá àti àkàrà aláìwú fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a dà òróró sí àti àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò ṣe.
Om någon vill bära fram ett sådant till lovoffer, så skall han, förutom det till lovoffret hörande slaktdjuret, bära fram osyrade kakor, begjutna med olja, och osyrade tunnkakor, smorda med olja, och fint mjöl, hopknådat, i form av kakor, begjutna med olja.
13 Pẹ̀lú ọrẹ àlàáfíà rẹ̀, kí ó tún mú àkàrà wíwú wá fún ọpẹ́,
Jämte kakor av syrat bröd skall han bära fram detta sitt offer, förutom det slaktdjur som hör till det tackoffer han bär fram såsom lov offer.
14 kí ó mú ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú oríṣìíríṣìí ọrẹ àlàáfíà rẹ wá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún Olúwa, ó jẹ́ tí àlùfáà tí ó wọ́n ẹ̀jẹ̀ ọrẹ àlàáfíà.
Av detta offer skall han bära fram en kaka av vart slag, såsom en gärd åt HERREN; den präst som stänker tackoffrets blod på altaret, honom skall den tillhöra.
15 Ẹran ọrẹ àlàáfíà ti ọpẹ́ yìí ni wọ́n gbọdọ̀ jẹ ní ọjọ́ gan an tí wọ́n rú ẹbọ, kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ẹran kankan kù di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
Och köttet av det slaktdjur, som hör till det tackoffer som bäres fram såsom lovoffer, skall ätas samma dag det har offrats; intet därav må lämnas kvar till följande morgon.
16 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ó mú ọrẹ wá, nítorí ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ tàbí kí ó jẹ́ ọrẹ àtinúwá, wọn yóò jẹ ẹbọ náà ní ọjọ́ tí wọ́n rú ẹbọ yìí, ṣùgbọ́n wọ́n lè jẹ èyí tó ṣẹ́kù ní ọjọ́ kejì.
Om däremot det slaktoffer som någon vill bära fram år ett löftesoffer eller ett frivilligt offer, så skall offerdjuret likaledes ätas samma dag det har offrats; dock må det som har blivit över därav ätas den följande dagen.
17 Gbogbo ẹran tó bá ṣẹ́kù di ọjọ́ kẹta ní ẹ gbọdọ̀ sun.
Bliver ändå något över av offerköttet, skall detta på tredje dagen brännas upp i eld.
18 Bí ẹ bá jẹ ọ̀kankan nínú ẹran ọrẹ àlàáfíà ní ọjọ́ kẹta, kò ni jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà. A kò ní í kà á sí fún ẹni tó rú ẹbọ náà, nítorí pé ó jẹ́ àìmọ́, ẹnikẹ́ni tó bá sì jẹ ẹ́, ni a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù.
Om någon på tredje dagen äter av tackoffersköttet, så bliver offret icke välbehagligt; honom som har burit fram det skall det då icke räknas till godo, det skall anses såsom en vederstygglighet. Den som äter därav kommer att bära på missgärning.
19 “‘Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tí ó bá ti kan ohun tí a kà sí àìmọ́, sísun ni kí ẹ sun ún. Ẹnikẹ́ni tí a ti kà sí mímọ́ le è jẹ nínú ẹran tí ó kù.
Ej heller må det kött ätas, som har kommit vid något orent, utan det skall brännas upp i eld. För övrigt må köttet ätas av var och en som är ren.
20 Ṣùgbọ́n bí ẹni tí kò mọ́ bá jẹ́ ẹran ọrẹ àlàáfíà tí ó jẹ́ tí Olúwa, a ó gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Men den som äter kött av HERRENS tackoffer, medan orenhet låder vid honom, han skall utrotas ur sin släkt.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá fọwọ́ kan ohun aláìmọ́ yálà ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ẹranko aláìmọ́, ohun àìmọ́ yówù kí ó jẹ́ tàbí ohunkóhun tí ó jẹ́ ìríra, tí ó sì tún jẹ́ ẹran ọrẹ àlàáfíà tó jẹ́ ti Olúwa, a ó gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ.’”
Och om någon har kommit vid något orent -- vare sig en människas orenhet, eller ett orent djur, eller vilken oren styggelse det vara må -- och han likväl äter kött av HERRENS tackoffer, så skall han utrotas ur sin släkt.
22 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
23 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ má ṣe jẹ ọ̀rá màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́.
Tala till Israels barn och säg: Intet fett av fäkreatur, får eller getter skolen I äta.
24 Ẹ lè lo ọ̀rá ẹran tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko igbó pa, fún nǹkan mìíràn, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́.
Fettet av ett självdött eller ihjälrivet djur må eljest användas till alla slags behov, men äta det skolen I icke.
25 Ẹnikẹ́ni tó bá jẹ ọ̀rá ẹran tí a fi rú ẹbọ sísun sí Olúwa ni ẹ gbọdọ̀ gé kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ty var och en som äter fettet av något djur varav man bär fram eldsoffer åt HERREN, vem det vara må som äter därav, han skall utrotas ur sin släkt.
26 Ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ tàbí ẹran ní gbogbo ibi tí ẹ bá ń gbé.
Och intet blod skolen I förtära varken av fåglar eller av boskap, var I än ären bosatta.
27 Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀, a ó gé ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
Var och en som förtär något blod, han skall utrotas ur sin släkt.
28 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
29 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni tó bá mú ọrẹ àlàáfíà wá fún Olúwa.
Tala till Israels barn och säg: Den som vill offra ett tackoffer åt HERREN, han skall av detta sitt tackoffer bära fram åt HERREN den vederbörliga offergåvan.
30 Pẹ̀lú ọwọ́ ara rẹ̀ ni kí ó fi mú ọrẹ tí a fi iná sun wá fún Olúwa, kí ó mú ọ̀rá àti igẹ̀, kí ó sì fi igẹ̀ yìí níwájú Olúwa bí ọrẹ fífì.
Med egna händer skall han bära fram HERRENS eldsoffer; fettet jämte bringan skall han bära fram, bringan till att viftas såsom ett viftoffer inför HERRENS ansikte.
31 Àlùfáà yóò sun ọ̀rá náà lórí pẹpẹ ṣùgbọ́n igẹ̀ ẹran náà jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀,
Och prästen skall förbränna fettet på altaret, men bringan skall tillhöra Aron och hans söner.
32 kí ẹ fún àlùfáà ní itan ọ̀tún lára ọrẹ àlàáfíà yín gẹ́gẹ́ bí ìpín tiyín fún àlùfáà.
Också det högra lårstycket skolen I giva åt prästen, såsom en gärd av edra tackoffer.
33 Ọmọ Aaroni ẹni tí ó rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ àti ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà ni kí ó ni itan ọ̀tún gẹ́gẹ́ bí ìpín tirẹ̀.
Den bland Arons söner, som offrar tackoffrets blod och fettet, han skall hava det högra lårstycket till sin del.
34 Nínú ọrẹ àlàáfíà àwọn ọmọ Israẹli, mo ti ya igẹ̀ tí a fi àti itan tí ẹ mú wá sọ́tọ̀ fún Aaroni àlùfáà àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní gbogbo ìgbà láti ọ̀dọ̀ ara Israẹli.’”
Ty av Israels barns tackoffer tager jag viftoffersbringan och offergärdslåret och giver dem åt prästen Aron och åt hans söner till en evärdlig rätt av Israels barn.
35 Èyí ni ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa lọ́jọ́ tí wọ́n mú wọn wá láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Detta är Arons och hans söners ämbetslott av HERRENS eldsoffer, den lott som gavs dem den dag de fördes fram till att bliva HERRENS präster
36 Lọ́jọ́ tí a fi òróró yàn wọ́n, ni Olúwa ti pa á láṣẹ pé kí àwọn ọmọ Israẹli máa fún wọn ní àwọn nǹkan wọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ìgbà gbogbo fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
vilken lott, efter HERRENS befallning på den dag då han smorde dem, skulle givas dem av Israels barn, till en evärdlig rätt, släkte efter släkte.
37 Nítorí náà, àwọn nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìlànà fún ẹbọ sísun, ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ ẹ̀bi, ìfinijoyè àlùfáà àti ẹbọ àlàáfíà
Detta är lagen om brännoffret, spisoffret, syndoffret, skuldoffret, handfyllningsoffret och tackoffret,
38 èyí tí Olúwa fún Mose lórí òkè Sinai lọ́jọ́ tí Olúwa pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa mú ọrẹ wọn wá fún Olúwa ni ijù Sinai.
vilken HERREN på Sinai berg gav Mose, på den dag då han bjöd Israels barn att de skulle offra sina offer åt HERREN, i Sinais öken.

< Leviticus 7 >