< Leviticus 5 >

1 “‘Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé kò sọ̀rọ̀ nígbà tí a bi í ní gbangba pé kó jẹ́rìí nípa nǹkan tó rí tàbí nǹkan tó mọ̀ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ kan, a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù ú.
Gdyby ktoś zgrzeszył przez to, że usłyszał przekleństwo i był [tego] świadkiem lub widział czy dowiedział się o tym, a tego nie oznajmił, będzie obciążony nieprawością;
2 “‘Tàbí bí ẹnìkan bá fọwọ́ kan ohun tí a kà sí àìmọ́ yálà òkú ẹranko aláìmọ́ tàbí òkú ẹran ọ̀sìn aláìmọ́ tàbí òkú ẹ̀dá yówù tó ń rìn lórí ilẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, ó ti di aláìmọ́, ó sì ti jẹ̀bi.
Albo jeśli ktoś dotknął czegoś nieczystego, czy to padliny nieczystego zwierzęcia, czy padliny nieczystego bydlęcia, czy padliny nieczystego zwierzęcia pełzającego, a nie jest tego świadomy, i tak będzie nieczysty i winny;
3 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ohunkóhun tó lè mú ènìyàn di aláìmọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, nígbà tí ó bá mọ̀ nípa rẹ̀ yóò jẹ̀bi.
Lub jeśli ktoś dotknął jakiejkolwiek nieczystości ludzkiej, przez którą stanie się nieczysty, a nie jest tego świadomy, a potem się o tym dowie, będzie winny;
4 Tàbí bí ẹni kan bá búra láti ṣe ohun kan láì ronú lé e lórí, yálà ohun tó dára tàbí ohun búburú, nínú ọ̀rọ̀ yówù tó ti búra láì kíyèsi ara, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò mọ̀ nípa rẹ̀ tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kó rí, nígbà tó bá mọ̀ yóò jẹ̀bi.
Albo jeśli ktoś przysiągł, mówiąc wargami, że źle lub dobrze uczyni w czymkolwiek, co ów człowiek powie w przysiędze, a nie jest tego świadomy, lecz [potem] sobie uświadomi, będzie winny w jednej z tych rzeczy.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ̀bi ọ̀kan nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí, ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ irú ọ̀nà tó ti dẹ́ṣẹ̀
Jeśli więc jest winny jednej z tych rzeczy, ma wyznać swój grzech;
6 àti pé gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ó gbọdọ̀ mú wa fún Olúwa, abo àgùntàn tàbí abo ewúrẹ́ láti inú agbo ẹran wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
I przyprowadzi PANU ofiarę za przewinienie z powodu swego grzechu, który popełnił: samicę z trzody, owcę albo kozę na ofiarę za grzech, a kapłan dokona za niego przebłagania za jego grzech.
7 “‘Bí kò bá lágbára àti mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá, kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀—ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, èkejì fún ẹbọ sísun.
A jeśli nie stać go na owcę, niech przyniesie PANU jako ofiarę za swoje przewinienie, które popełnił, dwie synogarlice lub dwa młode gołębie: jednego na ofiarę za grzech, a drugiego na całopalenie;
8 Kí ó kó wọn wá fún àlùfáà tí yóò kọ́kọ́ rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ kí ó yín in lọ́rùn, ṣùgbọ́n kí ó má já orí rẹ̀ tan,
I przyniesie je do kapłana, a [on] najpierw złoży [to], co ma być na ofiarę za grzech, i ukręci jego głowę przy szyi, ale jej nie oddzieli.
9 kí ó sì wọ́n díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ, ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó ro sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
I pokropi krwią tej ofiary za grzech ścianę ołtarza, a resztę krwi wyciśnie u podstawy ołtarza. To [jest] ofiara za grzech.
10 Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wá rú ẹbọ sísun gẹ́gẹ́ bí ìlànà, yóò sì ṣe ètùtù fún un nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, a ó sì dáríjì í.
Drugiego zaś złoży jako całopalenie według przepisu. W ten sposób kapłan dokona za niego przebłagania za jego grzech, który popełnił, i będzie mu przebaczony.
11 “‘Bí ó bá sì jẹ́ pé kò ní agbára àti mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì wá, kí ó mú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ, kò gbọdọ̀ fi òróró tàbí tùràrí sí i nítorí pé ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
A jeśli nie stać go na dwie synogarlice lub dwa młode gołębie, niech ten, który zgrzeszył, przyniesie na swoją ofiarę dziesiątą część efy mąki pszennej na ofiarę za swój grzech. Nie naleje jednak na nią oliwy ani nie położy na nią kadzidła, gdyż jest to ofiara za grzech.
12 Kí ó gbé e wá sí ọ̀dọ̀ àlùfáà, àlùfáà yóò sì bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Przyniesie ją do kapłana, a kapłan nabierze z niej pełną garść jako pamiątkę i spali ją na ołtarzu na ofiarach całopalnych dla PANA. To [jest] ofiara za grzech.
13 Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà fún èyíkéyìí nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá, a ó sì dáríjì í: ìyókù sì jẹ́ ti àlùfáà, bí ẹbọ ohun jíjẹ.’”
I kapłan dokona za niego przebłagania za jego grzech, który popełnił w jednej z tych spraw, i będzie mu przebaczony. [Reszta] zaś będzie dla kapłana, jak przy ofierze pokarmowej.
14 Olúwa sọ fún Mose pé,
PAN powiedział jeszcze do Mojżesza:
15 “Nígbà tí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ ìrékọjá tí ó sì ṣe láìmọ̀ ní ti àwọn ohun mímọ́ Olúwa, kí ó mú àgbò láti inú agbo ẹran wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn, àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
Jeśli ktoś popełni przewinienie i zgrzeszy nieświadomie [przy] rzeczach poświęconych PANU, to przyprowadzi PANU jako ofiarę za swoje przewinienie barana bez skazy z trzody oraz twoje oszacowanie w syklach srebra według sykla świątynnego na ofiarę za przewinienie.
16 Kí ó ṣe àtúnṣe nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀ nínú ti àwọn ohun mímọ́, kí ó sì fi ìdámárùn-ún kún iye rẹ̀, kí ó sì kó gbogbo rẹ̀ fún àlùfáà. Àlùfáà yóò sì fi àgbò ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ṣe ètùtù fún, a ó sì dáríjì í.
I odda kapłanowi za to, czym przewinił przy rzeczach poświęconych, i dołoży do tego jedną piątą. I kapłan dokona za niego przebłagania baranem, będącym ofiarą za przewinienie, a będzie mu przebaczone.
17 “Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kó yẹ ko ṣe sí ọ̀kan nínú òfin Olúwa, bí kò tilẹ̀ mọ̀, ó jẹ̀bi, yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
Jeśli ktoś zgrzeszy i przekroczy nieświadomie którekolwiek z przykazań PANA, czyniąc to, czego nie wolno, stanie się winny i będzie obciążony nieprawością.
18 kí ó mú àgbò kan láti inú agbo ẹran wá sọ́dọ̀ àlùfáà, fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí bí iye owó ibi mímọ́. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, fún àṣìṣe tí ó ṣe láìmọ̀, a ó sì dáríjì í.
Przyprowadzi do kapłana barana z trzody bez skazy według twojego oszacowania na ofiarę za przewinienie. A kapłan dokona za niego przebłagania za jego uchybienie, którego nieświadomie się dopuścił, i będzie mu przebaczone.
19 Ẹbọ ẹ̀bi ni, ó ti jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀ sí Olúwa.”
Jest to ofiara za przewinienie, gdyż w istocie zawinił przeciwko PANU.

< Leviticus 5 >