< Leviticus 5 >

1 “‘Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé kò sọ̀rọ̀ nígbà tí a bi í ní gbangba pé kó jẹ́rìí nípa nǹkan tó rí tàbí nǹkan tó mọ̀ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ kan, a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù ú.
Jeźliby też człowiek zgrzeszył, żeby słyszał głos bluźnierstwa, a byłby świadkiem tego, co albo widział, albo słyszał, a nie oznajmiłby, poniesie karanie za nieprawość swoję.
2 “‘Tàbí bí ẹnìkan bá fọwọ́ kan ohun tí a kà sí àìmọ́ yálà òkú ẹranko aláìmọ́ tàbí òkú ẹran ọ̀sìn aláìmọ́ tàbí òkú ẹ̀dá yówù tó ń rìn lórí ilẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, ó ti di aláìmọ́, ó sì ti jẹ̀bi.
Albo jeźliby się kto dotknął rzeczy nieczystej, bądź ścierwu zwierza nieczystego, bądź ścierwu bydlęcia nieczystego, bądź ścierwu gadziny nieczystej, a byłoby to zakryto przed nim, przecię nieczysty będzie, i winien jest.
3 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ohunkóhun tó lè mú ènìyàn di aláìmọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, nígbà tí ó bá mọ̀ nípa rẹ̀ yóò jẹ̀bi.
Albo jeźliby się kto dotknął nieczystości człowieczej, jakażbykolwiek była nieczystość jego, przez którą się nieczystym stawa, a byłoby to skryto przed nim, i dowiedziałby się, winien jest.
4 Tàbí bí ẹni kan bá búra láti ṣe ohun kan láì ronú lé e lórí, yálà ohun tó dára tàbí ohun búburú, nínú ọ̀rọ̀ yówù tó ti búra láì kíyèsi ara, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò mọ̀ nípa rẹ̀ tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kó rí, nígbà tó bá mọ̀ yóò jẹ̀bi.
Albo jeźliby kto przysiągł wymówiwszy usty, że źle albo dobrze uczynił, o wszystko, co wymawia człowiek z przysięgą, a byłoby to skryto przed nim i dowiedziałby się potem, że winien jest w jednej rzeczy z tych:
5 Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ̀bi ọ̀kan nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí, ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ irú ọ̀nà tó ti dẹ́ṣẹ̀
Będąc tedy winien w jednej rzeczy z tych, wyzna grzech swój;
6 àti pé gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ó gbọdọ̀ mú wa fún Olúwa, abo àgùntàn tàbí abo ewúrẹ́ láti inú agbo ẹran wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
I przywiedzie ofiarę za winę swoję Panu za grzech swój, którym zgrzeszył, samicę z drobnego bydła, owcę, albo kozę za grzech, a oczyści go kapłan od grzechu jego.
7 “‘Bí kò bá lágbára àti mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá, kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀—ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, èkejì fún ẹbọ sísun.
A jeźliby nie przemógł ofiarować bydlątka, tedy przyniesie ofiarę za występek swój, którym zgrzeszył, parę synogarlic, albo parę gołąbiąt Panu, jedno na ofiarę za grzech, a drugie na ofiarę całopalenia;
8 Kí ó kó wọn wá fún àlùfáà tí yóò kọ́kọ́ rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ kí ó yín in lọ́rùn, ṣùgbọ́n kí ó má já orí rẹ̀ tan,
I przyniesie je do kapłana, a on naprzód ofiarować będzie to, co ma być na ofiarę za grzech, i paznogciem nadrze głowę jego ku szyi, ale jej nie oderwie.
9 kí ó sì wọ́n díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ, ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó ro sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
I pokropi krwią z ofiary za grzech stronę ołtarza, a ostatek onej krwi wyciśnie u spodku ołtarza. Ofiara to za grzech jest.
10 Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wá rú ẹbọ sísun gẹ́gẹ́ bí ìlànà, yóò sì ṣe ètùtù fún un nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, a ó sì dáríjì í.
Z drugiego zasię uczyni ofiarę całopalenia według zwyczaju. A tak oczyści go kapłan od grzechu jego, którym zgrzeszył, a będzie mu odpuszczony.
11 “‘Bí ó bá sì jẹ́ pé kò ní agbára àti mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì wá, kí ó mú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ, kò gbọdọ̀ fi òróró tàbí tùràrí sí i nítorí pé ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
A jeźliby nie przemógł ofiarować parę synogarlic, albo parę gołąbiąt, tedy przyniesie ofiarę swoję za to, co zgrzeszył, dziesiątą część efy mąki pszennej na ofiarę za grzech, nie naleje na nię oliwy, ani włoży na nię kadzidła; bo jest ofiara za grzech.
12 Kí ó gbé e wá sí ọ̀dọ̀ àlùfáà, àlùfáà yóò sì bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
A gdy ją przyniesie do kapłana, tedy nabrawszy kapłan z niej pełną garść swoję na pamiątkę jego, spali ją na ołtarzu mimo ofiarę ognistą Panu; ofiara to za grzech jest.
13 Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà fún èyíkéyìí nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá, a ó sì dáríjì í: ìyókù sì jẹ́ ti àlùfáà, bí ẹbọ ohun jíjẹ.’”
I oczyści go kapłan od grzechu jego, którym zgrzeszył w którejkolwiek z tych rzeczy, a będzie mu odpuszczony; a ostatek będzie kapłanowi, jako przy ofierze śniednej.
14 Olúwa sọ fún Mose pé,
Nad to rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
15 “Nígbà tí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ ìrékọjá tí ó sì ṣe láìmọ̀ ní ti àwọn ohun mímọ́ Olúwa, kí ó mú àgbò láti inú agbo ẹran wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn, àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
Gdyby człowiek przestąpił przestępstwem, a zgrzeszyłby z niewiadomości, ujmując rzeczy poświęconych Panu, tedy przywiedzie ofiarę za występek swój Panu, barana zupełnego z drobnego bydła według oszacowania twego, za dwa sykle srebra według sykla świątnicy, na ofiarę za występek.
16 Kí ó ṣe àtúnṣe nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀ nínú ti àwọn ohun mímọ́, kí ó sì fi ìdámárùn-ún kún iye rẹ̀, kí ó sì kó gbogbo rẹ̀ fún àlùfáà. Àlùfáà yóò sì fi àgbò ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ṣe ètùtù fún, a ó sì dáríjì í.
A to, coby wziął z poświęconych rzeczy, wróci, i piątą część nadto przyda i odda kapłanowi; a kapłan go oczyści przez barana ofiary za grzech, a będzie mu odpuszczono.
17 “Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kó yẹ ko ṣe sí ọ̀kan nínú òfin Olúwa, bí kò tilẹ̀ mọ̀, ó jẹ̀bi, yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
Jeźliby też człowiek zgrzeszył, uczyniwszy przeciw któremukolwiek z przykazań Pańskich, coby nie miało być, z niewiadomości, a byłby winien, poniesie karanie za nieprawość swoję.
18 kí ó mú àgbò kan láti inú agbo ẹran wá sọ́dọ̀ àlùfáà, fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí bí iye owó ibi mímọ́. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, fún àṣìṣe tí ó ṣe láìmọ̀, a ó sì dáríjì í.
Tedy przywiedzie barana zupełnego z drobnego bydła według szacunku twojego, na ofiarę za występek do kapłana; i oczyści go kapłan od niewiadomości jego, której się dopuścił nie wiedząc, a będzie mu odpuszczono.
19 Ẹbọ ẹ̀bi ni, ó ti jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀ sí Olúwa.”
Ofiara to za występek jest, którym wystąpił przeciwko Panu.

< Leviticus 5 >