< Leviticus 5 >

1 “‘Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé kò sọ̀rọ̀ nígbà tí a bi í ní gbangba pé kó jẹ́rìí nípa nǹkan tó rí tàbí nǹkan tó mọ̀ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ kan, a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù ú.
Ki te hara tetahi, mona i rongo ki te reo whakaoati, he kaiwhakaatu nei ia mo tana i kite ai, i mohio ai ranei, ki te kahore e whakaaturia e ia, na me waha e ia tona hara:
2 “‘Tàbí bí ẹnìkan bá fọwọ́ kan ohun tí a kà sí àìmọ́ yálà òkú ẹranko aláìmọ́ tàbí òkú ẹran ọ̀sìn aláìmọ́ tàbí òkú ẹ̀dá yówù tó ń rìn lórí ilẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, ó ti di aláìmọ́, ó sì ti jẹ̀bi.
Ki te pa tetahi ki te mea poki, ki te tinana ranei o te kirehe poke, ki te tinana ranei o te kararehe poki, ki te tinana ranei o nga mea ngoki, ara o nga mea poki, a e huna ana i a ia, a ka poki ia, na ka whai hara ia.
3 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ohunkóhun tó lè mú ènìyàn di aláìmọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, nígbà tí ó bá mọ̀ nípa rẹ̀ yóò jẹ̀bi.
Ki te pa ranei ia ki te poki tangata, ki nga tini poke e poke ai te tangata, a ka huna i a ia; ina mohiotia e ia, ka whai hara ia:
4 Tàbí bí ẹni kan bá búra láti ṣe ohun kan láì ronú lé e lórí, yálà ohun tó dára tàbí ohun búburú, nínú ọ̀rọ̀ yówù tó ti búra láì kíyèsi ara, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò mọ̀ nípa rẹ̀ tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kó rí, nígbà tó bá mọ̀ yóò jẹ̀bi.
Ki te oati ranei tetahi, he mea puta ohorere i ona ngutu, kia mahi i te kino, i te pai ranei, i nga tini mea ranei e puaki ohorere mai i te tangata ina oati, a e huna ana i a ia; ina mohiotia e ia, na, ka whai hara ia i tetahi o enei mea:
5 Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ̀bi ọ̀kan nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí, ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ irú ọ̀nà tó ti dẹ́ṣẹ̀
A ki te mea kua whai hara ia i tetahi o enei mea, na me whaki tona hara i taua mea;
6 àti pé gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ó gbọdọ̀ mú wa fún Olúwa, abo àgùntàn tàbí abo ewúrẹ́ láti inú agbo ẹran wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
A me kawe e ia tana whakahere mo te he ki a Ihowa, mo tona hara i hara ai, he uha no te kahui, he reme, he kuao koati ranei, hei whakahere hara; a ma te tohunga e whakamarie mona, mo tona hara.
7 “‘Bí kò bá lágbára àti mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá, kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀—ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, èkejì fún ẹbọ sísun.
A, ki te kahore e taea e ia i ona rawa he reme, me kawe e ia ki a Ihowa mo tona he i he ai, kia rua nga kukupa, kia rua ranei nga pi kukupa; ko tetahi hei whakahere hara, ko tetahi hei tahunga tinana.
8 Kí ó kó wọn wá fún àlùfáà tí yóò kọ́kọ́ rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ kí ó yín in lọ́rùn, ṣùgbọ́n kí ó má já orí rẹ̀ tan,
Me kawe raua e ia ki te tohunga, ka whakahere ai e ia, ko te mea mo te whakahere hara ki mua, ka kikini ai i tona pane i te ritenga o tona kaki, otiia kaua e motuhia rawatia.
9 kí ó sì wọ́n díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ, ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó ro sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Na ka tauhiuhi ai ia i tetahi wahi o nga toto o te whakahere hara ki te taha o te aata; ka whakate ai i te toenga o te toto ki te turanga o te aata: he whakahere hara tena.
10 Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wá rú ẹbọ sísun gẹ́gẹ́ bí ìlànà, yóò sì ṣe ètùtù fún un nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, a ó sì dáríjì í.
A ko te rua me tuku hei tahunga tinana, kia rite ki te tikanga: a ka whakamarie to tohunga mona, mo tona hara i hara ai, a ka murua.
11 “‘Bí ó bá sì jẹ́ pé kò ní agbára àti mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì wá, kí ó mú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ, kò gbọdọ̀ fi òróró tàbí tùràrí sí i nítorí pé ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
A, ki te kahore e taea e ia i ona rawa te kawe nga kukupa e rua, nga pi kukupa ranei e rua, na me kawe tana whakahere e te tangata i hara, te whakatekau epa paraoa, hei whakahere hara; kaua e meatia ki te hinu, kaua ano e meatia he parakihe ki r unga: he whakahere hara hoki.
12 Kí ó gbé e wá sí ọ̀dọ̀ àlùfáà, àlùfáà yóò sì bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Na me kawe e ia ki te tohunga, a ka aohia ake e te tohunga, kia ki tona ringa, he whakamahara no taua mea, ka tahu ai ki runga ki te aata, ki runga ki nga whakahere ahi ki a Ihowa: he whakahere hara tena.
13 Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà fún èyíkéyìí nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá, a ó sì dáríjì í: ìyókù sì jẹ́ ti àlùfáà, bí ẹbọ ohun jíjẹ.’”
A ka whakamarie te tohunga mona, mo tona hara i hara ai ki tetahi o enei mea, a ka murua: a ma te tohunga te toenga, ano he whakahere totokore.
14 Olúwa sọ fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
15 “Nígbà tí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ ìrékọjá tí ó sì ṣe láìmọ̀ ní ti àwọn ohun mímọ́ Olúwa, kí ó mú àgbò láti inú agbo ẹran wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn, àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
Ki te kino te mahi a tetahi, he hara pohehe, ki nga mea tapu a Ihowa; na, me kawe e ia tana whakahere mo te he ki a Ihowa, kia kotahi hipi toa, hei te mea kohakore, no te kahui hipi, me whakarite ano e koe ona utu ki te hekere hiriwa, hekere o t e wahi tapu, hei whakahere mo te he:
16 Kí ó ṣe àtúnṣe nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀ nínú ti àwọn ohun mímọ́, kí ó sì fi ìdámárùn-ún kún iye rẹ̀, kí ó sì kó gbogbo rẹ̀ fún àlùfáà. Àlùfáà yóò sì fi àgbò ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ṣe ètùtù fún, a ó sì dáríjì í.
Ka utu ai i tona hara ki te mea tapu, me tapiri ano ki te wahi whakarima, ka homai ki te tohunga: a ka whakamarie te tohunga mona ki te hipi toa e whakaherea ana mo te he, a ka murua tona.
17 “Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kó yẹ ko ṣe sí ọ̀kan nínú òfin Olúwa, bí kò tilẹ̀ mọ̀, ó jẹ̀bi, yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
A ki te hara tetahi, ki te poka ke i tetahi o nga whakahau a Ihowa, he mahi poka noa; ahakoa e kore e mohiotia e ia, kua hara ia, a ka waha ia i tona kino.
18 kí ó mú àgbò kan láti inú agbo ẹran wá sọ́dọ̀ àlùfáà, fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí bí iye owó ibi mímọ́. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, fún àṣìṣe tí ó ṣe láìmọ̀, a ó sì dáríjì í.
A me kawe e ia he hipi toa ki te tohunga, he kohakore, no te kahui, kei tau te utu, hei whakahere mo te he: a ka whakamarie te tohunga mona, mo tona pohehe i pohehe ai ia, a kihai nei i matau, a ka murua tona he.
19 Ẹbọ ẹ̀bi ni, ó ti jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀ sí Olúwa.”
He whakahere tena mo te he: he pono tona he ki a Ihowa.

< Leviticus 5 >