< Leviticus 4 >
И рече Господь к Моисею, глаголя.
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ láìmọ̀, tí ó ṣe ohun tí kò yẹ kó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa.
Рцы к сыном Израилевым, глаголя: душа аще согрешит пред Господем не хотящи от всех повелений Господних, ихже не леть есть творити, и сотворит едино что от них:
3 “‘Bí àlùfáà tí a fi òróró yàn bá ṣẹ̀, tí ó sì mú ẹ̀bi wá sórí àwọn ènìyàn, ó gbọdọ̀ mú ọmọ akọ màlúù tí kò lábùkù wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
аше убо архиерей помазанный согрешит, во еже людем согрешити, и да приведет о гресе своем, имже согрешил, телца от говяд непорочна Господви от гресе:
4 Kí ó mú ọ̀dọ́ màlúù wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú Olúwa.
и да приведет телца к дверем скинии свидения пред Господа, и да возложит руку свою на главу телца пред Господем, и да заколет телца пред Господем:
5 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, kí ó sì gbé e lọ sínú àgọ́ ìpàdé.
и взем жрец помазанный совершен руками от крове телца, и да внесет ю в скинию свидения,
6 Kí ó ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa, níwájú aṣọ títa ibi mímọ́.
и да омочит жрец перст в крови, и да покропит от крове седмижды перстом пред Господем, у завесы святыни:
7 Àlùfáà yóò tún mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tùràrí tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Kí ó da gbogbo ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
и да возложит жрец от крове телчи на роги олтаря фимиама сложения иже пред Господем, иже есть в скинии свидения, и всю кровь телчу да излиет у стояла олтаря всесожжений, иже есть у дверий скинии свидения,
8 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ nínú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú àti gbogbo ohun tó so mọ́ wọn.
и весь тук телца, иже от гресе, да отимет от него, тук покрывающий утробу, и весь тук иже на утробе,
9 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá wọn tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú kíndìnrín.
и обе почки, и тук иже на них, иже есть на стегнах, и препонку, яже на печени, с почками отимет е,
10 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń yọ ọ̀rá kúrò lára màlúù tí a fi rú ẹbọ àlàáfíà; àlùfáà yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ ẹbọ sísun.
якоже отемлется оное от телца жертвы спасения, и да вознесет жрец на олтарь приношения:
11 Ṣùgbọ́n awọ màlúù àti gbogbo ara rẹ̀, àti ẹsẹ̀, gbogbo nǹkan inú àti ìgbẹ́ rẹ̀.
и кожу телчу, и всю его плоть со главою, и с крайними частми, и со утробою, и с мотылы:
12 Èyí túmọ̀ sí pé gbogbo ìyókù akọ màlúù náà ni kí ẹ gbé jáde síta lẹ́yìn ibùdó sí ibi tí a sọ di mímọ́ níbi tí à ń da eérú sí, kí ẹ sì sun wọ́n lórí iná igi, níbi eérú tí a kójọ.
и да изнесут всего телца вне полка на место чисто, идеже изсыпают пепел, и да сожгут его на дровах огнем: на месте изсыпания пепела да сожжен будет.
13 “‘Bí gbogbo àpapọ̀ ènìyàn Israẹli bá ṣèèṣì ṣẹ̀, tí wọ́n sì ṣe ohun tí kò yẹ kí wọ́n ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àpapọ̀ ènìyàn náà kò mọ̀ sí ọ̀rọ̀ náà, wọ́n jẹ̀bi.
Аще же весь сонм сынов Израилевых согрешит не хотящь, и утаится глагол от лица сонма, и сотворят едину от всех заповедий Господних, еяже не леть есть творити, и согрешат,
14 Nígbà tí wọ́n bá mọ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn yóò mú akọ màlúù wá sí àgọ́ ìpàdé gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
и увестся им грех, имже согрешиша в нем: и да приведет сонм телца от волов непорочна от гресе, и приведет и пред двери скинии свидения:
15 Kí àwọn àgbàgbà ìjọ Israẹli gbé ọwọ́ lórí akọ ọmọ màlúù náà níwájú Olúwa.
и да возложат старцы сонма руки своя на главу телца пред Господем, и да заколют телца пред Господем,
16 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn sì mú díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ akọ ọmọ màlúù náà wá sínú àgọ́ ìpàdé.
и да внесет жрец помазанный от крове телчи в скинию свидения,
17 Kí ó ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọn ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa níbi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà.
и да омочит жрец перст свой в крови телчи, и да покропит седмижды пред Господем, пред завесою святыни:
18 Kí ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó dà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
и от крове да возложит жрец на роги олтаря фимиамов сложения, иже есть пред Господем, иже есть в скинии свидения: и всю кровь да излиет у стояла олтаря приношений, иже есть у дверий скинии свидения,
19 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá kúrò lára rẹ̀, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ.
и весь тук его да возмет от него, и вознесет на олтарь:
20 Kí ó sì ṣe akọ ọmọ màlúù yìí gẹ́gẹ́ bí ó ṣe ṣe akọ màlúù tó wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ṣe ètùtù fún wọn, á ó sì dáríjì wọ́n.
и сотворит телцу сему, якоже сотвори телцу, иже о гресе, тако сотворится: и да помолится от них жрец, и оставится им грех:
21 Lẹ́yìn náà ni yóò sun màlúù yìí lẹ́yìn ibùdó, yóò sì sun ún gẹ́gẹ́ bó ṣe sun màlúù àkọ́kọ́. Èyí ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli.
и да изнесут телца всего вне полка, и да сожгут телца, якоже сожгоша телца перваго: грех (бо) сонма есть.
22 “‘Bí olórí kan bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ kí ó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó jẹ̀bi.
Аще же князь согрешит, и сотворит едину от всех заповедий Господа Бога своего, не хотя, иже не леть есть творити, и согрешит, и преступит,
23 Nígbà tí a bá sì sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú akọ ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀.
и увестся ему грех, имже согреши в нем: да принесет дар свой козла от коз мужеск пол непорочен греха ради,
24 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ náà, kí ó sì pa á níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun níwájú Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
и возложит руку свою на главу козла: и да заколют его на месте, идеже закалают всесожжения пред Господем: о гресе (бо) есть:
25 Lẹ́yìn èyí, kí àlùfáà ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ẹ̀jẹ̀ yòókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
и да возложит жрец от крове, яже от гресе, перстом на роги олтаря всесожжений, и всю кровь его да излиет у стояла олтаря всесожжений,
26 Kí ó sun gbogbo ọ̀rá rẹ̀ lórí pẹpẹ bí ó ṣe sun ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin náà, a ó sì dáríjì í.
и весь тук его вознесет на олтарь, якоже тук жертвы спасения: и да помолится о нем жрец греха ради его, и оставится ему.
27 “‘Bí ènìyàn nínú àwọn ará ìlú bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, ó jẹ̀bi.
Аще же душа едина согрешит не хотящи от людий земли, внегда сотворити едину от всех заповедий Господних, еже не леть есть творити, и согрешит,
28 Nígbà tí a bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú abo ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
и увестся ему грех, имже согреши в нем, и да принесется дар свой козу от коз женск пол непорочну, да принесет греха ради, имже согреши:
29 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó sì pa á níbi ẹbọ sísun.
и да возложит руку свою на главу греха своего: и заколют козу, яже греха ради, на месте, идеже закалают всесожжения:
30 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ́ ẹ̀jẹ̀ náà, yóò fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
и да возмет жрец от крове ея перстом, и да возложит на роги олтаря всесожжений, и всю кровь ея излиет у стояла олтаря:
31 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá ẹran náà gẹ́gẹ́ bó ṣe yọ ọ̀rá ẹran fún ọrẹ àlàáfíà. Kí àlùfáà sì sun ọ̀rá yìí lórí pẹpẹ bí òórùn dídùn sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, a ó sì dáríjì í.
и весь тук да отимет, якоже отемлется тука от жертвы спасения, и да вознесет жрец на олтарь в воню благовония Господу: и да помолится жрец о нем, и оставится ему.
32 “‘Bí ó bá mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ó mú abo tí kò lábùkù.
Аше же овцу принесет дар свой греха ради, женск пол непорочен да принесет ю:
33 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun.
и да возложит руку свою на главу яже о гресе, и да заколют ю греха ради на месте, на немже закалают всесожжения (на месте святе):
34 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, yóò sì fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, yóò sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
и взем жрец от крове, яже о гресе, перстом своим, да возложит на роги олтаря всесожжения: и всю кровь ея да излиет у стояла олтаря всесожжения,
35 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá rẹ̀ bó ti yọ ọ̀rá lára ọ̀dọ́-àgùntàn ọrẹ àlàáfíà, àlùfáà yóò sì sun ún ní orí pẹpẹ, lórí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀, a ó sì dáríjì í.
и весь тук ея да отимет, якоже отемлется тук овцы от жертвы спасения: и да возложит его жрец на олтарь на всесожжение Господне: и да помолится за него жрец о гресе, имже согреши, и оставится ему.