< Leviticus 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I rzekł Pan do Mojżesza mówiąc:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ láìmọ̀, tí ó ṣe ohun tí kò yẹ kó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa.
Mów do synów Izraelskich, a rzecz: Gdyby kto zgrzeszył z niewiadomości, przeciw któremu ze wszystkich przykazań Pańskich, czyniąc, czego by czynić nie miał, a przestąpiłby jedno z nich,
3 “‘Bí àlùfáà tí a fi òróró yàn bá ṣẹ̀, tí ó sì mú ẹ̀bi wá sórí àwọn ènìyàn, ó gbọdọ̀ mú ọmọ akọ màlúù tí kò lábùkù wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
Jeźliby kapłan pomazany zgrzeszył jako jeden z ludu pospolitego, tedy niech ofiaruje za grzech swój, którego się dopuścił, cielca młodego zupełnego Panu na ofiarę za grzech.
4 Kí ó mú ọ̀dọ́ màlúù wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú Olúwa.
I przywiedzie cielca onego do drzwi namiotu zgromadzenia przed obliczność Pańską, a włoży rękę swoję na głowę onego cielca, i zabije go przed obliczem Pańskiem.
5 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, kí ó sì gbé e lọ sínú àgọ́ ìpàdé.
Tedy weźmie kapłan pomazany ze krwi onego cielca, i wniesie ją do namiotu zgromadzenia.
6 Kí ó ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa, níwájú aṣọ títa ibi mímọ́.
Potem omoczy kapłan palec swój we krwi, a kropić będzie oną krwią siedem kroć przed obliczem Pańskiem przed zasłoną świątnicy.
7 Àlùfáà yóò tún mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tùràrí tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Kí ó da gbogbo ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
I pomaże kapłan krwią oną rogi ołtarza kadzenia wonnego, przed obliczem Pańskiem, który jest w namiocie zgromadzenia, a ostatek krwi onego cielca wyleje u spodku ołtarza całopalenia, który jest u drzwi namiotu zgromadzenia.
8 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ nínú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú àti gbogbo ohun tó so mọ́ wọn.
Wszystkę zaś tłustość cielca tego za grzech ofiarowanego wyjmie z niego tłustość okrywającą wnętrzności i wszystkę tłustość, która jest na wnętrznościach.
9 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá wọn tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú kíndìnrín.
Obie też nerki z tłustością, która jest na nich, i na polędwicach, i odzieczkę, która jest na wątrobie i na nerkach, odejmie.
10 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń yọ ọ̀rá kúrò lára màlúù tí a fi rú ẹbọ àlàáfíà; àlùfáà yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ ẹbọ sísun.
Jako odejmują z wołu ofiary spokojnej, i zapali to kapłan na ołtarzu całopalonych ofiar.
11 Ṣùgbọ́n awọ màlúù àti gbogbo ara rẹ̀, àti ẹsẹ̀, gbogbo nǹkan inú àti ìgbẹ́ rẹ̀.
Skórę zaś cielca tego, i wszystko mięso jego z głową jego i z nogami jego i z wnętrznościami jego i z gnojem jego
12 Èyí túmọ̀ sí pé gbogbo ìyókù akọ màlúù náà ni kí ẹ gbé jáde síta lẹ́yìn ibùdó sí ibi tí a sọ di mímọ́ níbi tí à ń da eérú sí, kí ẹ sì sun wọ́n lórí iná igi, níbi eérú tí a kójọ.
Owa, całego cielca wyniesie precz za obóz na miejsce czyste, tam gdzie się wysypuje popiół, i spali go na drwach ogniem, gdzie wysypują popiół, tam spalony będzie.
13 “‘Bí gbogbo àpapọ̀ ènìyàn Israẹli bá ṣèèṣì ṣẹ̀, tí wọ́n sì ṣe ohun tí kò yẹ kí wọ́n ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àpapọ̀ ènìyàn náà kò mọ̀ sí ọ̀rọ̀ náà, wọ́n jẹ̀bi.
Jeźliby też wszystko zgromadzenie Izraelskie z nieobaczenia zgrzeszyło, a byłaby rzecz zakryta od oczu zgromadzenia tego, i uczyniliby przeciw któremu ze wszystkich przykazań Pańskich, coby być nie miało, a byliby winni,
14 Nígbà tí wọ́n bá mọ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn yóò mú akọ màlúù wá sí àgọ́ ìpàdé gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
I poznaliby grzech, którym zgrzeszyli, ofiarować będzie ono zgromadzenie cielca młodego na ofiarę za grzech, a przywiodą go przed namiot zgromadzenia,
15 Kí àwọn àgbàgbà ìjọ Israẹli gbé ọwọ́ lórí akọ ọmọ màlúù náà níwájú Olúwa.
I położą starsi zgromadzenia ręce swe na głowę cielca onego przed obliczem Pańskiem i zabiją tegoż cielca przed obliczem Pańskiem.
16 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn sì mú díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ akọ ọmọ màlúù náà wá sínú àgọ́ ìpàdé.
Tedy wniesie kapłan pomazany, ze krwi cielca onego do namiotu zgromadzenia,
17 Kí ó ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọn ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa níbi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà.
I omoczy kapłan palec swój w onej krwi, a będzie nią kropił siedem kroć przed obliczem Pańskiem, przed zasłoną.
18 Kí ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó dà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
A oną krwią pomaże rogi ołtarza, który jest przed obliczem Pańskiem, w namiocie zgromadzenia; a ostatek krwi wyleje u spodku ołtarza całopalenia, który jest u drzwi namiotu zgromadzenia.
19 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá kúrò lára rẹ̀, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ.
Wszystkę też tłustość jego wyjmie z niego, i zapali na ołtarzu.
20 Kí ó sì ṣe akọ ọmọ màlúù yìí gẹ́gẹ́ bí ó ṣe ṣe akọ màlúù tó wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ṣe ètùtù fún wọn, á ó sì dáríjì wọ́n.
I uczyni z tem cielcem, jako uczynił z cielcem, za grzech ofiarowanym, tak uczyni z nim; a tak oczyści je kapłan, i będzie im odpuszczono.
21 Lẹ́yìn náà ni yóò sun màlúù yìí lẹ́yìn ibùdó, yóò sì sun ún gẹ́gẹ́ bó ṣe sun màlúù àkọ́kọ́. Èyí ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli.
Potem wyniesie cielca onego precz za obóz, i spali go, jako spalił cielca pierwszego. Tać jest ofiara za grzech zgromadzenia.
22 “‘Bí olórí kan bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ kí ó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó jẹ̀bi.
Jeźliby książę zgrzeszył, i uczynił przeciw któremu ze wszystkich przykazań Pana Boga swego, coby być nie miało, a to z nieobaczenia, a byłby winien:
23 Nígbà tí a bá sì sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú akọ ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀.
I byłby jawny grzech jego, którym zgrzeszył, przywiedzie na ofiarę swoję kozła z kóz, samca zupełnego;
24 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ náà, kí ó sì pa á níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun níwájú Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
I położy rękę swoję na głowę tegoż kozła, i zabije go na miejscu, gdzie biją ofiary na całopalenie, przed obliczem Pańskiem. Ofiara to jest za grzech.
25 Lẹ́yìn èyí, kí àlùfáà ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ẹ̀jẹ̀ yòókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
I weźmie kapłan ze krwi ofiary za grzech na palec swój, a pomaże rogi ołtarza całopalonych ofiar, a ostatek krwi jego wyleje u spodku ołtarza całopalenia.
26 Kí ó sun gbogbo ọ̀rá rẹ̀ lórí pẹpẹ bí ó ṣe sun ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin náà, a ó sì dáríjì í.
Wszystkę zaś tłustość jego zapali na ołtarzu, jako i tłustość ofiary spokojnej; a tak oczyści go kapłan od grzechu jego i będzie mu odpuszczony.
27 “‘Bí ènìyàn nínú àwọn ará ìlú bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, ó jẹ̀bi.
A jeźliby kto zgrzeszył z ludu pospolitego z nieobaczenia, a uczyniłby przeciw któremu z przykazań Pańskich, coby być nie miało, i byłby winien,
28 Nígbà tí a bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú abo ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
A byłby znajomy grzech jego, którym zgrzeszył, przywiedzie ofiarę swoję, kozę z kóz, zupełną samicę, za grzech swój, którego się dopuścił.
29 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó sì pa á níbi ẹbọ sísun.
A położywszy rękę swą na głowę tej ofiary za grzech, zabije tę ofiarę za grzech na miejscu ofiar całopalonych.
30 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ́ ẹ̀jẹ̀ náà, yóò fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Potem wziąwszy kapłan ze krwi onej na palec swój, pomaże rogi ołtarza całopalonych ofiar, a ostatek krwi jej wyleje u spodku onegoż ołtarza.
31 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá ẹran náà gẹ́gẹ́ bó ṣe yọ ọ̀rá ẹran fún ọrẹ àlàáfíà. Kí àlùfáà sì sun ọ̀rá yìí lórí pẹpẹ bí òórùn dídùn sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, a ó sì dáríjì í.
Wszystkę także tłustość jej odejmie, jako się odejmuje tłustość od ofiary spokojnej, i spali to kapłan na ołtarzu ku wdzięcznej wonności Panu; a tak oczyści go kapłan, i będzie mu odpuszczono.
32 “‘Bí ó bá mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ó mú abo tí kò lábùkù.
A jeźliby owcę przywiódł na ofiarę swoję za grzech, samicę zupełną niech przywiedzie.
33 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun.
I włoży rękę swą na głowę onej ofiary za grzech, i zabije ją na ofiarę za grzech na miejscu, gdzie zabijają ofiary całopalenia.
34 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, yóò sì fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, yóò sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Potem weźmie kapłan onej krwi z ofiary za grzech na palec swój, i pomaże rogi u ołtarza palonych ofiar, a ostatek krwi jej wyleje u spodku onego ołtarza.
35 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá rẹ̀ bó ti yọ ọ̀rá lára ọ̀dọ́-àgùntàn ọrẹ àlàáfíà, àlùfáà yóò sì sun ún ní orí pẹpẹ, lórí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀, a ó sì dáríjì í.
I wszystkę tłustość jej odejmie, jako odejmują tłustość baranka z ofiary spokojnej, i spali ją kapłan na ołtarzu na całopaloną ofiarę Panu. A tak oczyści go kapłan od grzechu jego, którym zgrzeszył, i będzie mu odpuszczony.

< Leviticus 4 >