< Leviticus 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Hoe ty nitsara’Iehovà amy Mosè,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ láìmọ̀, tí ó ṣe ohun tí kò yẹ kó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa.
Misaontsia amo ana’ Israeleo ty hoe, Naho eo t’indaty manao hakeo tsy nisatrie’e amo hene raha linili’Iehovà tsy ano­eñeo, vaho anoe’e ty raike;
3 “‘Bí àlùfáà tí a fi òróró yàn bá ṣẹ̀, tí ó sì mú ẹ̀bi wá sórí àwọn ènìyàn, ó gbọdọ̀ mú ọmọ akọ màlúù tí kò lábùkù wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
aa naho manao hakeo ty norizan-ko mpisoroñe, ie mañakeo ondatio, le bania tsy aman-kandra ty hengae’e ty amy tahiñe nanoe’ey, ho engan-kakeo am’ Iehovà, ty amy hakeo’ey.
4 Kí ó mú ọ̀dọ́ màlúù wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú Olúwa.
Hendese’e mb’an-dalan-kibohom-pamantañañe mb’añatrefa’Iehovà mb’eo i baniay le hanampeza’e fitàñe ty loha’ i baniay; vaho ho lentae’e aolo’Iehovà i baniay.
5 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, kí ó sì gbé e lọ sínú àgọ́ ìpàdé.
Hangalà’ i mpisoroñe norizañey ty lio’ i baniay vaho hendese’e mb’amy kibohom-pamantañañey mb’eo.
6 Kí ó ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa, níwájú aṣọ títa ibi mímọ́.
Le halò’ i mpisoroñey amy lioy ty rambo-pità’e naho hafitse’e im-pito añatrefa’Iehovà aolo’ i lamba fañefe’ i toe-miavakeiy i lioy
7 Àlùfáà yóò tún mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tùràrí tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Kí ó da gbogbo ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
naho ha­ten­te’ i mpisoroñey amo tsifa’ i kitrelin-emboke mañitse amy kibohom-pamantañañey añatrefa’ Iehovàio ty ila’ i lioy; le hadoa’e am-poto’ i kitrelim-pisoroñañe an-dalan-kibohom-pamantañañey ty tsy ri’ i lio’ i baniaiy.
8 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ nínú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú àti gbogbo ohun tó so mọ́ wọn.
Hafaha’e ze hene safo’ i banian-engan-kakeoy: ty safo’e misaroñe o ova’eo naho ze safo’e iaby amo ova’eo;
9 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá wọn tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú kíndìnrín.
naho ty voa’e roe mitraok’ amo safo’e an-demeo, naho i kambinatey ze hafaha’e rekets’ i voa’e rey,
10 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń yọ ọ̀rá kúrò lára màlúù tí a fi rú ẹbọ àlàáfíà; àlùfáà yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ ẹbọ sísun.
hambañe amy nañafahañ’ aze amy banian-tsorom-pañanintsiñey, vaho hengae’ i mpisoroñey an-katoeñe amy kitrelim-pisoroñañey.
11 Ṣùgbọ́n awọ màlúù àti gbogbo ara rẹ̀, àti ẹsẹ̀, gbogbo nǹkan inú àti ìgbẹ́ rẹ̀.
Le ty amy holi’ i baniay naho o hena’e iabio mitraok’ ami’ty loha’e, miharo amo tombo’eo naho o ova’eo vaho ty tai’e,
12 Èyí túmọ̀ sí pé gbogbo ìyókù akọ màlúù náà ni kí ẹ gbé jáde síta lẹ́yìn ibùdó sí ibi tí a sọ di mímọ́ níbi tí à ń da eérú sí, kí ẹ sì sun wọ́n lórí iná igi, níbi eérú tí a kójọ.
toe i tsi-ri’ i baniay iabiy, ro hendese’e mb’an-diolio alafe’ i tobey, mb’amy fañarian-davenokey mb’eo ho forototoeñe añ’afo an-katae; amy fañarian-davenokey ty hañoroañ’ aze.
13 “‘Bí gbogbo àpapọ̀ ènìyàn Israẹli bá ṣèèṣì ṣẹ̀, tí wọ́n sì ṣe ohun tí kò yẹ kí wọ́n ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àpapọ̀ ènìyàn náà kò mọ̀ sí ọ̀rọ̀ náà, wọ́n jẹ̀bi.
Aa naho manao hakeo tsy nisatrie’e ty valobohò’ Israele, ie nietak’ am-pihaino’ i fivoribeiy, ie nandilatse aman-dra’ inoñ’ inoñe linili’ Iehovà tsy hanoeñe vaho voa hakeo
14 Nígbà tí wọ́n bá mọ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn yóò mú akọ màlúù wá sí àgọ́ ìpàdé gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
aa naho rendreke i tahiñe nanoe’ iereoy, le hañenga bania ho soron-kakeo i fivoribeiy vaho hendesa’ iereo aolo’ i kibohom-pamantañañey eo.
15 Kí àwọn àgbàgbà ìjọ Israẹli gbé ọwọ́ lórí akọ ọmọ màlúù náà níwájú Olúwa.
Hanampeza’ o roandria’ i tobeio fitàñe añatrefa’Iehovà ty loha’ i baniay, le ho lentaeñe añatrefa’Iehovà i baniay.
16 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn sì mú díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ akọ ọmọ màlúù náà wá sínú àgọ́ ìpàdé.
Hañandesa’ i mpisoroñe norizañey mb’amy kibohom-pamantañañey mb’eo ty lio’ i baniay,
17 Kí ó ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọn ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa níbi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà.
le handò i mpisoroñey amy lioy ty rambo-pità’e vaho ha­mitse aze im-pito añatrefa’Iehovà aolo’ i lamba fañefetsey.
18 Kí ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó dà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Le hatente’e amo tsifa’ i kitreliio amy kibohom-pamantañañey añatrefa’Iehovà ty ila’ i lioy vaho hadoa’e ampoto’ i kitrelim-pisoroñañe an-dalambem-kibohom-pamantañañey ty sisa’ i lioy.
19 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá kúrò lára rẹ̀, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ.
Hafaha’e iaby ty safo’e naho hengae’e an-katoeñe amy kitreliy;
20 Kí ó sì ṣe akọ ọmọ màlúù yìí gẹ́gẹ́ bí ó ṣe ṣe akọ màlúù tó wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ṣe ètùtù fún wọn, á ó sì dáríjì wọ́n.
le hanoe’e hambañe amy nanoe’e i bania soron-kakeoiy i baniay, izay ty hanoe’e ty bania toy. Izay ty hijebaña’ i mpisoroñey vaho ho votsotse amy hakeoy iereo.
21 Lẹ́yìn náà ni yóò sun màlúù yìí lẹ́yìn ibùdó, yóò sì sun ún gẹ́gẹ́ bó ṣe sun màlúù àkọ́kọ́. Èyí ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli.
Hendese’e alafe’ i tobey i baniay vaho ho forototoe’e manahake ty nañoroa’e i bania valo­ha’ey, soron-kakeo’ i valobohòkey izay.
22 “‘Bí olórí kan bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ kí ó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó jẹ̀bi.
Ie manao hakeo ty mpifehe’ ondaty, vaho mandilatse tsy satrie’e aman-dra’ inoñ’ inoñe linili’Iehovà Andria­nañahare’e tsy hanoeñe naho voa-tahiñe,
23 Nígbà tí a bá sì sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú akọ ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀.
ie ampandrendreheñe i hakeo nililare’ey, le hendese’e ho enga ty vik’oselahy tsy aman-kandra.
24 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ náà, kí ó sì pa á níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun níwájú Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Le hanampeza’e fitàñe i ose-lahiy vaho ho lentae’e amy toem-pandentàn-tsoroñey am’ Iehovày, soron-kakeo izay.
25 Lẹ́yìn èyí, kí àlùfáà ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ẹ̀jẹ̀ yòókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Handrambesa’ i mpisoroñey an-drambom-pità’e ty lio’ i soron-kakeoy naho hatente’e amo tsifa’ i kitrelim-pisoroñañeio vaho hadoa’e am-poto’ i kitrelim-pisoroñañey ty lio’e sisa.
26 Kí ó sun gbogbo ọ̀rá rẹ̀ lórí pẹpẹ bí ó ṣe sun ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin náà, a ó sì dáríjì í.
Hengae’e an-katoeñe amy kitreliy ze hene safo’e manahake ty safo’ i engam-pañanintsiñey; le hijebaña’ i mpisoroñey ty amy tahi’ey vaho hapoke i tahi’ey.
27 “‘Bí ènìyàn nínú àwọn ará ìlú bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, ó jẹ̀bi.
Aa naho mandilatse tsy satrie’e ty ndaty amy taney, ndra inoñ’ inoñe linili’Iehovà tsy hanoeñeo vaho voa hakeo,
28 Nígbà tí a bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú abo ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
aa naho fohi’e i hakeo nanoe’ey, le hinday ose ho enga’e, ty vave’e tsy aman-kandra ty amy tahiñe nanoe’ey.
29 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó sì pa á níbi ẹbọ sísun.
Hampitongoà’e fitàñe ty loha’ i engan-kakeoy vaho ho lentae’e amy toem-pisoroñañey i engan-kakeoy.
30 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ́ ẹ̀jẹ̀ náà, yóò fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Handrambesa’ i mpisoroñey an-drambom-pità’e ty lio’e naho hatente’e amo tsifa’ i kitrelim-pisoroñañeio vaho hadoa’e am-poto’ i kitreliy ty sisa’ i lio’ey.
31 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá ẹran náà gẹ́gẹ́ bó ṣe yọ ọ̀rá ẹran fún ọrẹ àlàáfíà. Kí àlùfáà sì sun ọ̀rá yìí lórí pẹpẹ bí òórùn dídùn sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, a ó sì dáríjì í.
Hafaha’e iaby ty safo’e, hambañe amy fañafahañe i safon’ engam-pañanintsiñey, vaho hengae’ i mpisoroñey an-katoeñe amy kitreliy ho hàñim-pañanintsiñe am’ Iehovà. Izay ty hijebaña’ i mpisoroñey aze hañahà’e i tahi’ey.
32 “‘Bí ó bá mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ó mú abo tí kò lábùkù.
Aa naho vik’ añondry ty hendese’e ho engan-kakeo, le ho vàve’e tsy aman-kandra ty hendese’e.
33 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun.
Hanampeza’e fitàñe ty loha’ i engan-kakeoy, vaho ho lentae’e ho soron-kakeo amy toem-pandentà’ iareo o isoroñañeoy.
34 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, yóò sì fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, yóò sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Handrambesa’ i mpisoroñey an-drambom-pità’e ty lio’ i engan-kakeoy le hatente’e amo tsifa’ i kitrelim-pisoroñañeio, vaho hadoa’e am-poto’ i kitreliy ty sisa’ i lio’ey.
35 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá rẹ̀ bó ti yọ ọ̀rá lára ọ̀dọ́-àgùntàn ọrẹ àlàáfíà, àlùfáà yóò sì sun ún ní orí pẹpẹ, lórí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀, a ó sì dáríjì í.
Hafaha’e iaby ty safo’e, hambañe ami’ty nañafahañe ty safo’ i vik’ añondry amy engam-pañanintsiñeiy; le hengae’ i mpisoroñey amy kitreliy amo hisoroñañe am’ Iehovào, izay ty hijebaña’ i mpisoroñey aze ty amy hakeo nanoe’ey vaho ho hahàñe i tahi’ey.

< Leviticus 4 >