< Leviticus 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ láìmọ̀, tí ó ṣe ohun tí kò yẹ kó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa.
“Ĩra andũ a Isiraeli ũũ: ‘Rĩrĩa mũndũ o na ũrĩkũ angĩĩhia atekwenda, na eke ũndũ ũrĩa mũkananie thĩinĩ wa maathani mothe ma Jehova:
3 “‘Bí àlùfáà tí a fi òróró yàn bá ṣẹ̀, tí ó sì mú ẹ̀bi wá sórí àwọn ènìyàn, ó gbọdọ̀ mú ọmọ akọ màlúù tí kò lábùkù wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
“‘Kũngĩkorwo nĩ mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũitĩrĩrie maguta wĩhĩtie na atũme andũ mahĩtie-rĩ, no nginya arehere Jehova ndegwa ĩtarĩ ngũrũ na ĩtarĩ na kaũũgũ, ĩrĩ iruta rĩa kũhoroheria mehia macio ekĩte.
4 Kí ó mú ọ̀dọ́ màlúù wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú Olúwa.
No nginya aneane ndegwa ĩyo mũromo-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo arĩ mbere ya Jehova. Nĩakaigĩrĩra guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wayo, na acooke amĩthĩnjĩre hau mbere ya Jehova.
5 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, kí ó sì gbé e lọ sínú àgọ́ ìpàdé.
Ningĩ mũthĩnjĩri-Ngai ũcio mũitĩrĩrie maguta nĩakoya thakame ĩmwe ya ndegwa ĩyo amĩtware thĩinĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
6 Kí ó ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa, níwájú aṣọ títa ibi mímọ́.
Na nĩagatobokia kĩara gĩake thakame-inĩ ĩyo, aminjaminje ĩmwe yayo mbere ya Jehova maita mũgwanja, hau mbere ya gĩtambaya kĩrĩa gĩa gũcuurio kĩa handũ-harĩa-haamũre.
7 Àlùfáà yóò tún mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tùràrí tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Kí ó da gbogbo ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Ningĩ mũthĩnjĩri-Ngai ũcio nĩakoya thakame ĩmwe ahake hĩa cia kĩgongona kĩa ũbani ũrĩa mũnungi wega kĩrĩa kĩrĩ mbere ya Jehova kũu Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo. Thakame ya ndegwa ĩyo ĩrĩa ĩgaatigara nĩakamĩita thĩ gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona kĩa iruta rĩa njino hau mũromo-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
8 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ nínú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú àti gbogbo ohun tó so mọ́ wọn.
Nĩakaruta maguta mothe ma ndegwa ĩyo ya igongona rĩa kũhoroherio mehia, namo nĩmo rũambũ rũrĩa ruothe rũhumbĩire nyama cia nda na rũrĩa rũnyiitaine nacio,
9 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá wọn tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú kíndìnrín.
higo cierĩ hamwe na maguta marĩa macihumbĩire hakuhĩ na honge, na maguta marĩa mahumbĩire ini, amarutanĩrie na higo icio,
10 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń yọ ọ̀rá kúrò lára màlúù tí a fi rú ẹbọ àlàáfíà; àlùfáà yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ ẹbọ sísun.
akaaruta maguta macio o ta ũrĩa marutagwo ndegwa ĩrĩa ĩthĩnjagwo ĩrĩ iruta rĩa ũiguano. Nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩagacicinĩra kĩgongona-inĩ kĩa igongona rĩa njino,
11 Ṣùgbọ́n awọ màlúù àti gbogbo ara rẹ̀, àti ẹsẹ̀, gbogbo nǹkan inú àti ìgbẹ́ rẹ̀.
na rũũa rwa ndegwa ĩyo, na nyama ciayo ciothe hamwe, na mũtwe na mathagiro, na nyama cia nda na mahu,
12 Èyí túmọ̀ sí pé gbogbo ìyókù akọ màlúù náà ni kí ẹ gbé jáde síta lẹ́yìn ibùdó sí ibi tí a sọ di mímọ́ níbi tí à ń da eérú sí, kí ẹ sì sun wọ́n lórí iná igi, níbi eérú tí a kójọ.
ũguo nĩ ta kuuga nyama icio ingĩ ciothe cia ndegwa ĩyo, no nginya agaaciruta nja ya kambĩ, acitware handũ hatarĩ thaahu, harĩa mũhu ũitagwo, na acicinĩre na mwaki wa ngũ hau mũhu-inĩ ũcio.
13 “‘Bí gbogbo àpapọ̀ ènìyàn Israẹli bá ṣèèṣì ṣẹ̀, tí wọ́n sì ṣe ohun tí kò yẹ kí wọ́n ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àpapọ̀ ènìyàn náà kò mọ̀ sí ọ̀rọ̀ náà, wọ́n jẹ̀bi.
“‘Na kĩrĩndĩ gĩothe kĩa Isiraeli kĩngĩkehia gĩtekwenda, gĩĩke ũndũ ũrĩa mũkananie thĩinĩ wa maathani mothe ma Jehova, o na angĩkorwo kĩrĩndĩ kĩu gĩtiũĩ ũndũ ũcio, nĩkĩhĩtĩtie.
14 Nígbà tí wọ́n bá mọ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn yóò mú akọ màlúù wá sí àgọ́ ìpàdé gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Rĩrĩa gĩkaamenya mehia marĩa gĩĩkĩte, kĩũngano kĩu nĩgĩkaruta gategwa ka igongona rĩa kũhoroherio mehia, kaneanwo mbere ya Hema-ya-Gũtũnganwo.
15 Kí àwọn àgbàgbà ìjọ Israẹli gbé ọwọ́ lórí akọ ọmọ màlúù náà níwájú Olúwa.
Athuuri a kĩrĩndĩ kĩu nĩmakaigĩrĩra moko mao igũrũ rĩa mũtwe wa ndegwa ĩyo mbere ya Jehova, nayo ndegwa ĩyo ĩthĩnjĩrwo o ro hau mbere ya Jehova.
16 Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn sì mú díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ akọ ọmọ màlúù náà wá sínú àgọ́ ìpàdé.
Ningĩ mũthĩnjĩri-Ngai ũcio mũitĩrĩrie maguta nĩakoya thakame ĩmwe ya ndegwa ĩyo amĩtoonyie thĩinĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
17 Kí ó ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọn ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa níbi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà.
Nĩagatobokia kĩara gĩake thakame-inĩ ĩyo, amĩminjaminje mbere ya Jehova maita mũgwanja hau mbere ya gĩtambaya kĩrĩa gĩa gũcuurio.
18 Kí ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó dà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Nĩakoya thakame ĩmwe ahake hĩa cia kĩgongona kĩrĩa kĩrĩ hau mbere ya Jehova kũu Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo. Thakame ĩrĩa ĩgaatigara nĩakamĩita thĩ gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona kĩa iruta rĩa njino hau mũromo-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
19 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá kúrò lára rẹ̀, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ.
Nĩakamĩruta maguta mayo mothe amacinĩre igũrũ rĩa kĩgongona,
20 Kí ó sì ṣe akọ ọmọ màlúù yìí gẹ́gẹ́ bí ó ṣe ṣe akọ màlúù tó wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ṣe ètùtù fún wọn, á ó sì dáríjì wọ́n.
na eke ndegwa ĩyo o ta ũrĩa eekire ndegwa ya iruta rĩa kũhoroherio mehia. Ũguo nĩguo mũthĩnjĩri-Ngai akamahoroheria mehia mao, nao nĩmakarekerwo.
21 Lẹ́yìn náà ni yóò sun màlúù yìí lẹ́yìn ibùdó, yóò sì sun ún gẹ́gẹ́ bó ṣe sun màlúù àkọ́kọ́. Èyí ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli.
Ningĩ nĩakoimia ndegwa ĩyo amĩtware nja ya kambĩ na amĩcine o ta ũrĩa aacinire ndegwa ĩrĩa ya mbere. Rĩu nĩrĩo igongona rĩa kũhoroheria mehia ma kĩrĩndĩ kĩu.
22 “‘Bí olórí kan bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ kí ó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó jẹ̀bi.
“‘Rĩrĩa mũtongoria angĩĩhia atekwenda, na eke ũndũ ũrĩa mũkananie thĩinĩ wa maathani mothe ma Jehova Ngai wake, nĩahĩtĩtie.
23 Nígbà tí a bá sì sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú akọ ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀.
Rĩrĩa angĩmenyithio mehia marĩa ekĩte, no nginya arehe thenge ĩtarĩ na kaũũgũ ĩrĩ iruta rĩake.
24 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ náà, kí ó sì pa á níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun níwájú Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Nĩakaigĩrĩra guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wa thenge ĩyo na acooke amĩthĩnjĩre harĩa iruta rĩa njino rĩthĩnjagĩrwo hau mbere ya Jehova. Rĩĩrĩ nĩrĩo iruta rĩa kũhoroherio mehia.
25 Lẹ́yìn èyí, kí àlùfáà ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ẹ̀jẹ̀ yòókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩakoya thakame ĩmwe ya iruta rĩu rĩa mehia na kĩara gĩake, na amĩhake hĩa cia kĩgongona kĩa iruta rĩa njino, nayo thakame ĩyo ĩngĩ amĩite gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona.
26 Kí ó sun gbogbo ọ̀rá rẹ̀ lórí pẹpẹ bí ó ṣe sun ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin náà, a ó sì dáríjì í.
Ningĩ nĩagacinĩra maguta mothe kĩgongona-inĩ igũrũ o ta ũrĩa aacinire maguta ma iruta rĩa ũiguano. Ũguo nĩguo mũthĩnjĩri-Ngai akaahoroheria mehia ma mũndũ ũcio, nake nĩakarekerwo.
27 “‘Bí ènìyàn nínú àwọn ará ìlú bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, ó jẹ̀bi.
“‘Mũndũ ũmwe thĩinĩ wa kĩrĩndĩ angĩĩhia atekwenda na eke ũndũ ũrĩa mũkananie thĩinĩ wa maathani mothe ma Jehova, nĩahĩtĩtie.
28 Nígbà tí a bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú abo ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Rĩrĩa angĩmenyithio amenye mehia marĩa ekĩte, no nginya arehe harika ĩtarĩ na kaũũgũ arĩ iruta rĩake nĩ ũndũ wa mehia macio ekĩte.
29 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó sì pa á níbi ẹbọ sísun.
Nĩakaigĩrĩra guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wa harika ĩyo ya iruta rĩa kũhoroherio mehia, na amĩthĩnjĩre harĩa iruta rĩa njino rĩthĩnjagĩrwo.
30 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ́ ẹ̀jẹ̀ náà, yóò fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩakoya thakame ĩmwe na kĩara gĩake, na amĩhake hĩa cia kĩgongona kĩa iruta rĩa njino, nayo thakame ĩyo ĩngĩ amĩite gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona.
31 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá ẹran náà gẹ́gẹ́ bó ṣe yọ ọ̀rá ẹran fún ọrẹ àlàáfíà. Kí àlùfáà sì sun ọ̀rá yìí lórí pẹpẹ bí òórùn dídùn sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, a ó sì dáríjì í.
Nĩakaruta maguta mothe o ta ũrĩa maguta marutagwo kuuma iruta rĩa ũiguano, nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩakamacinĩra kĩgongona-inĩ igũrũ matuĩke mũtararĩko mwega wa gũkenia Jehova. Ũguo nĩguo mũthĩnjĩri-Ngai akaahoroheria mũndũ ũcio, nake nĩakarekerwo.
32 “‘Bí ó bá mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ó mú abo tí kò lábùkù.
“‘Angĩkaarehe kagondu karĩ iruta rĩake rĩa kũhoroherio mehia, nĩakarehe kamwatĩ gatarĩ na kaũũgũ.
33 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun.
Nĩakaigĩrĩra guoko gwake igũrũ rĩa mũtwe wako, na agathĩnje gatuĩke iruta rĩa kũhoroherio mehia, agathĩnjĩre harĩa iruta rĩa njino rĩthĩnjagĩrwo.
34 Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, yóò sì fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, yóò sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
Nake mũthĩnjĩri-Ngai nĩakoya thakame ĩmwe ya iruta rĩu rĩa mehia na kĩara gĩake, nayo amĩhake hĩa cia kĩgongona kĩa iruta rĩa njino, nayo thakame ĩyo ĩngĩ amĩite gĩtina-inĩ gĩa kĩgongona.
35 Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá rẹ̀ bó ti yọ ọ̀rá lára ọ̀dọ́-àgùntàn ọrẹ àlàáfíà, àlùfáà yóò sì sun ún ní orí pẹpẹ, lórí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀, a ó sì dáríjì í.
Nĩakaruta maguta mothe, o ta ũrĩa maguta marutagwo kuuma kũrĩ kagondu ka iruta rĩa ũiguano, na mũthĩnjĩri-Ngai nĩakamacinĩra kĩgongona-inĩ, maigĩrĩirwo igũrũ rĩa maruta marĩa marutĩirwo Jehova na mwaki. Ũguo nĩguo mũthĩnjĩri-Ngai akaamũhoroheria nĩ ũndũ wa mehia marĩa ekĩte, nake nĩakarekerwo.

< Leviticus 4 >