< Leviticus 3 >
1 “‘Bí ọrẹ ẹnìkan bá jẹ́ ọrẹ àlàáfíà, tí ó sì mú ẹran wá láti inú agbo màlúù yálà akọ tàbí abo, kí ó mú èyí tí kò ní àbùkù wá síwájú Olúwa.
Aa ie mañenga sorom-pañanintsiñe, le boak’ ampirai-trok’ ao, ke vave he lahy, ie tsy aman-kandra ty hampiatrefa’e am’ Iehovà.
2 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
Hasampe’e an-doha’ i enga’ey ty fità’e vaho ho lentà’e an-dalan-kibohom-pamantañañe ey; le hadasi’ o ana’ i Aharoneo añariari’ i kitreliy ty lio’e;
3 Láti ara ọrẹ àlàáfíà ni kí ẹni náà ti mú ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa, gbogbo ọ̀nà tí ó bo nǹkan inú ẹran náà àti gbogbo ọ̀rá tí ó so mọ́ wọn.
vaho ho soroña’e am’Iehovà ty tsila’ i engam-pañanintsiñey: Ty safo’e manaroñe o ova’eo, toe ze hene safo’e amo ova’eo;
4 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá ara rẹ̀ tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀, àti gbogbo ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
naho ty voa’e roe mitraok’ amo safo’eo, o an-deme’eo, naho i kambinate’ey ze hafaha’e rekets’ i voa’e rey,
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun tí a fi iná sun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
ro hengae’ o ana’ i Aharoneo an-katoeñe amy kitreliy, ambone i soroñañe an-katae añ’afoy, toe enga-koroañe an’ afo ho hàñim-pañanintsiñe am’ Iehovà.
6 “‘Bí ó bá ṣe inú agbo ewúrẹ́ àti àgùntàn ni ó ti mú ọrẹ àlàáfíà wá fún Olúwa kí ó mú akọ tàbí abo tí kò ní àbùkù.
Aa naho boak’amo lia-raikeo ty engam-pañanintsiñe ho soroña’e am’Iehovà ke t’ie lahy he vave, le ty tsy aman-kandra ty hengae’e.
7 Bí ó bá ṣe pé ọ̀dọ́-àgùntàn ni ó mú, kí ó mú un wá síwájú Olúwa.
Ie mibanabana ty vi’e hisoroña’e, le hengae’e añatrefa’ Iehovà,
8 Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú àgọ́ ìpàdé, kí àwọn ọmọ Aaroni wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
naho hampitongoae’e an-doha’ i banabanay ty fità’e le ho lentae’e aolo’ i kibohom-pamantañañey; vaho hadasi’ o ana’ i Aharoneo añariari’ i kitreliy ty lio’e.
9 Kí o sì mú wá nínú ẹbọ àlàáfíà náà, fún ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa; ọ̀rá rẹ̀ àti gbogbo ìrù rẹ̀ tí ó ní ọ̀rá, òun ni kí o mú kúrò súnmọ́ egungun ẹ̀yìn àti ọ̀rá tí ó bo ìfun lórí; àti gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ lára ìfun.
Ho banabanae’e boak’ amy engam-pañanintsiñey ty ho soroñañe am’ Iehovà: o safo’eo, i hofa’e vondrakey ie hafahañe reketse ty lambosim-pohe’e naho ty sabora manaroñe o ova’eo, toe ze hene sabora amo ova’eo,
10 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí o yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
naho ty voa’e roe mitraok’ amo safo’eo, o an-demeo, naho i kambinatey ie hafaha’e rekets’ o voa’eo
11 Kí àlùfáà sun ún lórí pẹpẹ bí oúnjẹ ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.
vaho hengae’ i mpisoroñey an-katoeñe amy kitreliy, fa mahakama, enga oroañe añ’afo am’ Iehovà.
12 “‘Bí ó bá ṣe pé ewúrẹ́ ni ó mú, kí ó mú un wá síwájú Olúwa.
Aa naho ose ty hisoroña’e, le ho banabanae’e añatrefa’ Iehovà;
13 Kí ó gbé ọwọ́ lé e lórí. Kí ó sì pa á ní iwájú àgọ́ ìpàdé. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
hanampeza’e fitàñe i loha’ey, le ho lentae’e aolo’ i kibohom-pamantañañey eo, vaho hadasi’ o ana’ i Aharoneo añariari’ i kitreliy ty lio.
14 Lára ọrẹ tó mú wá, kí ó mú ẹbọ sísun fún Olúwa, gbogbo ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú rẹ̀ àti ohun gbogbo tó so mọ́ ọn.
Le ho soroña’e ho enga oroañe an’ afo am’ Iehovà: ty safo’e manaroñe o ova’eo, toe ze hene safo’e amo ova’eo;
15 Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá ara rẹ̀ tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
naho ty voa’e roe mitraok’ amo safo’e an-demeo, naho hafaha’e i kambinatey rekets’ i voa’e rey,
16 Kí àlùfáà sun ún lórí pẹpẹ bí oúnjẹ, ọrẹ tí a fi iná sun, ní òórùn dídùn. Gbogbo ọ̀rá rẹ̀ jẹ́ ti Olúwa.
vaho hengae’ i mpisoroñey amy kitreliy ho mahakama, enga oroañe añ’afo, hàñim-pañanintsiñe; aIehovà ty safo’e iaby.
17 “‘Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún àwọn ìran tó ń bọ̀, ní gbogbo ibi tí ẹ bá ń gbé, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ọ̀rá tàbí ẹ̀jẹ̀.’”
Ho fañè tsy modo amo hene tarira’ areo mifandimbeo, am-pitobea’ areo iaby, te tsy ho kamae’ areo ty safo’e ndra ty lio.