< Leviticus 25 >

1 Olúwa sọ fún Mose ní orí òkè Sinai pé,
Rzekł nad to Pan do Mojżesza na górze Synaj, mówiąc:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín, ilẹ̀ náà gbọdọ̀ sinmi fún Olúwa.
Powiedz synom Izraelskim, a mów do nich: Gdy wnijdziecie do ziemi, którą Ja wam daję, tedy święcić będzie ziemia sabat Panu.
3 Ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi gbin oko rẹ, ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ, tí ìwọ ó sì fi kó èso wọn jọ.
Przez sześć lat osiewać będziesz pole twoje, i przez sześć lat winnice twoje obrzynać będziesz, zbierając urodzaje z niej;
4 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje kí ilẹ̀ náà ní ìsinmi: ìsinmi fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ.
Ale roku siódmego sabat odpocznienia mieć będzie ziemia, sabat Pański; pola twego nie będziesz osiewał, ani winnicy twojej obrzynał.
5 Ẹ má ṣe kórè ohun tí ó tìkára rẹ̀ hù, ẹ má ṣe kórè èso àjàrà ọgbà tí ẹ ò tọ́jú. Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ ní ìsinmi fún ọdún kan.
Co się samo przez się zrodzi zboża twego, nie będziesz żął, i jagód zaniechanej winnicy twojej nie będziesz zbierał; rok odpocznienia będzie miała ziemia.
6 Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ọdún ìsinmi ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún yín àní fún ẹ̀yin tìkára yín, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín, àwọn alágbàṣe àti àwọn tí ń gbé pẹ̀lú yín fún ìgbà díẹ̀.
I będzie, co się urodzi w onem odpocznieniu ziemi, tobie na pokarm, i słudze twemu, i służebnicy twej, i najemnikowi twemu i przychodniowi twemu, który mieszka z tobą.
7 Fún àwọn ohun ọ̀sìn yín, àti àwọn ẹranko búburú ní ilẹ̀ yín. Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ẹ lè jẹ.
Także bydłu twemu, i zwierzowi, który jest w ziemi twojej, będzie wszystek urodzaj jej na pokarm.
8 “‘Ọdún ìsinmi méje èyí tí í ṣe ọdún mọ́kàndínláàádọ́ta ni kí ẹ kà.
Naliczysz też sobie siedem tygodni lat, to jest siedem kroć siedem lat; i uczyniąć dni siedmiu tygodni lat czterdzieści i dziewięć lat.
9 Lẹ́yìn náà, kí ẹ fọn fèrè ní gbogbo ibikíbi ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́. Ní ọjọ́ ètùtù yìí, ẹ fọn fèrè yíká gbogbo ilẹ̀ yín.
Tedy każesz zatrąbić w trąbę huczną miesiąca siódmego, dnia dziesiątego tegoż miesiąca; w dzień oczyszczenia każecie zatrąbić po wszystkiej ziemi waszej.
10 Ẹ ya àádọ́ta ọdún náà sọ́tọ̀ kí ẹ sì kéde òmìnira fún gbogbo ẹni tí ń gbé ilẹ̀ náà. Yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Kí olúkúlùkù padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀ àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ̀.
I święcić będziecie rok pięćdziesiąty, a obwołacie wolność w ziemi wszystkim obywatelom jej. Lato miłościwe mieć będziecie; i wróci się każdy do osiadłości swojej, i każdy do rodziny swojej wróci się.
11 Àádọ́ta ọdún ni yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Ẹ má ṣe gbin ohunkóhun, ẹ kò sì gbọdọ̀ kórè ohun tí ó hù fúnra rẹ̀ tàbí kí ẹ kórè ọgbà àjàrà tí ẹ kò dá.
To miłościwe lato pięćdziesiątego roku miewać będziecie; nie będziecie siać, i nie będziecie żąć tego, co się samo przez się zrodzi, ani zbierać będziecie gron z winnic zaniechanych.
12 Torí pé ọdún ìdásílẹ̀ ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún yín. Ẹ jẹ ohun tí ẹ mú jáde nínú oko náà.
Bo miłościwy rok jest, święty wam będzie; co się na polu przedtem zrodziło, to jeść będziecie.
13 “‘Ní ọdún ìdásílẹ̀ yìí, kí olúkúlùkù gbà ohun ìní rẹ̀ padà.
W ten miłościwy rok wróci się każdy do osiadłości swojej.
14 “‘Bí ẹ bá ta ilẹ̀ fún ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín tàbí bí ẹ bá ra èyíkéyìí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ.
Jeźli co sprzedasz bliźniemu twemu, albo co kupisz od bliźniego twego, niech nie oszukiwa jeden drugiego.
15 Kí ẹ ra ilẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn yín ní gẹ́gẹ́ bí iye owó tí ó kù kí ọdún ìdásílẹ̀ pé, kí òun náà sì ta ilẹ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí iye ọdún rẹ̀ tókù láti kórè.
Według liczby lat po miłościwym roku kupisz od bliźniego twego; i według liczby lat dochody sprzeda tobie.
16 Bí iye ọdún rẹ̀ bá gùn, kí iye owó rẹ̀ pọ̀, bí iye ọdún rẹ̀ bá kúrú, kí iye owó rẹ̀ kéré, torí pé ohun tí ó tà gan an ní iye èso rẹ̀.
Jeźli więcej będzie lat, tem drożej oszacujesz kupno ono; a jeźli mniej będzie lat, tedy też taniej oszacujesz kupno ono, ponieważ tylko liczba dochodów sprzedawa się tobie.
17 Ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ, ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
A tak nie oszukiwajcie żaden bliźniego swego, ale się bój każdy Boga swego; bom Ja Pan, Bóg wasz.
18 “‘Ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà mi, kí ẹ sì kíyèsi láti pa òfin mi mọ́, kí ẹ ba à le máa gbé láìléwu ní ilẹ̀ náà.
Przestrzegajcie ustaw moich, i sądy moje zachowywajcie, i czyńcie je, abyście mieszkać mogli w ziemi onej bezpiecznie.
19 Nígbà yìí ni ilẹ̀ náà yóò so èso rẹ̀, ẹ ó sì jẹ àjẹyó, ẹ ó sì máa gbé láìléwu.
Tedy wyda ziemia owoc swój, a będziecie jeść aż do sytości, i będziecie mieszkać bezpiecznie w niej.
20 Ẹ le béèrè pé, “Kí ni àwa ó jẹ ní ọdún keje, bí a kò bá gbin èso tí a kò sì kórè?”
A jeźlibyście rzekli: Cóż będziemy jeść roku siódmego, jeźli nie będziem siać ani zbierać urodzajów naszych?
21 Èmi ó pèsè ìbùkún sórí yín tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ yín yóò so èso tó tó fún ọdún mẹ́ta lẹ́yìn rẹ̀.
Tedy rozkażę błogosławieństwu memu przyjść na was roku szóstego, i przyniesie urodzaj na trzy lata.
22 Bí ẹ bá gbin èso yín ní ọdún kẹjọ, àwọn èso ti tẹ́lẹ̀ ní ẹ ó máa jẹ, títí tí ìkórè ti ọdún kẹsànán yóò fi dé.
I będziecie siać roku ósmego, a będziecie jeść urodzaj stary aż do roku dziewiątego; póki nie nadejdą pożytki jego, stare jeść będziecie.
23 “‘Ẹ má ṣe ta ilẹ̀ yín ní àtàpa torí pé ẹ̀yin kọ́ lẹ ni ín, ti Ọlọ́run ni, ẹ̀yin jẹ́ àjèjì àti ayálégbé.
Ziemia tedy nie będzie sprzedawana na wieczność; bo moja jest ziemia, a wyście gośćmi i przychodniami u mnie.
24 Ní gbogbo orílẹ̀-èdè ìní yín, ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìràpadà ilẹ̀ náà.
A po wszystkiej ziemi osiadłości waszej pozwolicie wykupywać ziemię.
25 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín bá tálákà, dé bi pé ó ta ara àwọn ẹrù rẹ̀, kí ará ilé rẹ̀ tí ó súnmọ́ ọ ra ohun tí ó tà padà.
Gdyby zubożał brat twój, a sprzedałby nieco z majętności swojej, i przyszedłby mający prawo odkupienia, powinny jego niech wykupi, co sprzedał brat jego.
26 Ẹni tí kò ní ẹni tó lè rà á padà fún un, tí òun fúnra rẹ̀ sì ti lọ́rọ̀, tí ó sì ní ànító láti rà á.
A jeźliby kto nie miał tego coby odkupić mógł, a sam by przemógł, i znalazł dostatek na to wykupno:
27 Kí ó mọ iye owó tí ó jẹ fún iye ọdún tí ó tà á, kí ó dá iye tí ó kù padà fún ẹni tí ó tà á fún, lẹ́yìn náà, ó lè padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Tedy obrachowawszy lata od sprzedania swego, wróci co zbywa temu, któremu sprzedał: a wróci się do majętności swojej.
28 Ṣùgbọ́n bí kò bá rí ọ̀nà àti san án padà fún un. Ohun tí ó tà wà ní ìkáwọ́ ẹni tí ó rà á títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ó dá a padà fún ẹni tí ó ni i ní ọdún ìdásílẹ̀, ẹni tí ó ni í tẹ́lẹ̀ lè tún padà gbà ohun ìní rẹ̀.
A jeźliby nie miał dostatku, aby wrócił, tedy zostanie majętność sprzedana w ręku tego, który ją kupił, aż do roku miłościwego, i ustąpi mu jej w rok miłościwy, a on wróci się do majętności swojej.
29 “‘Bí arákùnrin kan bá ta ilé gbígbé kan ní ìlú olódi, kí ó rà á padà ní ìwọ̀n ọdún kan sí àkókò tí ó tà á, ní ìwọ̀n ọdún kan ni kí ó rà á padà.
Jeźliby też sprzedał dom mieszkania w mieście murowanem, będzie miał wolność wykupić go, póki nie wynijdzie rok sprzedania jego, cały rok będzie miał prawo do wykupienia jego.
30 Ṣùgbọ́n bí kò bá rà á padà láàrín ọdún náà ilé náà tí ó wà láàrín ìlú ni kí ó yọ̀ǹda pátápátá fún ẹni tí ó rà á, àti àwọn ìdílé rẹ̀. Kí wọ́n má da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
A jeźli go nie wykupi, póki nie wynijdzie rok cały, tedy zostanie on dom w mieście murowanem temu, który go kupił, dziedzicznie, i potomkom jego
31 Ṣùgbọ́n àwọn ilé tí ó wà ní abúlé láìní odi ni kí a kà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ oko, a lè rà wọ́n padà, kí wọ́n sì da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
I nie ustąpi w miłościwe lato. Ale domy we wsiach, które nie są murem obtoczone, te prawem jako pole ziemi szacowane będą; będą mogły być odkupowane, i w miłościwe lato z rąk obcych wynijdą.
32 “‘Àwọn ọmọ Lefi ní ẹ̀tọ́, nígbàkígbà láti ra ilẹ̀ wọn, tí ó jẹ́ ohun ìní wọn ní àwọn ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Lefi.
Ale miasta Lewitów, i domy w dziedzicznych mieściech ich każdego czasu wykupowane być mogą przez Lewity.
33 Torí náà ohun ìní àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n rà padà, fún àpẹẹrẹ, èyí ni pé ilẹ̀ tí a bá tà ní ìlúkílùú tí ó jẹ́ tiwọn, ó sì gbọdọ̀ di dídápadà ní ọdún ìdásílẹ̀, torí pé àwọn ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú àwọn Lefi ni ìní wọn láàrín àwọn ará Israẹli.
Lecz temu co kupuje od Lewitów, wynijdzie kupno domu, i miejskiej osiadłości jego, w rok miłościwy gdyż domy miast Lewickich są dziedziczne ich, w pośrodku synów Izraelskich.
34 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí wọ́n ti ń da ẹran tí ó jẹ́ ti ìlú wọn, wọn kò gbọdọ̀ tà wọ́n, ilẹ̀ ìní wọn láéláé ni.
Ale pole na przedmieściu ich nie będzie sprzedawane; bo dziedzictwem ich jest wiecznem.
35 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà tí kò sì le è pèsè fún àìní ara rẹ̀, ẹ pèsè fún un bí ẹ ti ń ṣe fún àwọn àlejò tàbí àwọn tí ẹ gbà sílé: kí ó ba à le è máa gbé láàrín yín.
Gdyby też zubożał brat twój, a osłabiałaby ręka jego przy tobie, podeprzesz go; a jako i przychodzień niech się żywi przy tobie.
36 Ẹ kò gbọdọ̀ gba èlé kankan lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ bẹ̀rù Olúwa kí arákùnrin yín le è máa gbé láàrín yín.
Nie bierz od niego lichwy, ani płatu, ale się bój Boga swego, aby się żywił brat twój przy tobie.
37 Ẹ má ṣe gba èlé lórí owó tí ẹ yá a bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ èrè lórí oúnjẹ tí ẹ tà fún un.
Pieniędzy twoich nie dawaj mu na lichwę, ani mu z zysku pożyczaj żywności twojej.
38 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti láti fún yín ní ilẹ̀ Kenaani àti láti jẹ́ Ọlọ́run yín.
Jam Pan, Bóg wasz, którym was wywiódł z ziemi Egipskiej, abym wam dał ziemię Chananejską, a był wam za Boga.
39 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ fún ọ bí ẹrú. Má ṣe lò ó bí ẹrú.
Jeźliby też zubożał brat twój przy tobie, tak żeby się tobie zaprzedał, nie będziesz go dręczył służbą niewolniczą;
40 Jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ rẹ bí alágbàṣe tàbí àlejò láàrín yín, kí ó máa ṣiṣẹ́ sìn ọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀.
Jako najemnik, jako przychodzień będzie u ciebie, aż do roku miłościwego służyć ci będzie.
41 Nígbà náà ni kí ó yọ̀ǹda òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n padà sí ìdílé wọn àti sí ilẹ̀ ìní baba wọn.
Potem wynijdzie od ciebie on, i dzieci jego z nim, a wróci się do rodziny swojej, i do dziedzictwa przodków swych wróci się.
42 Torí pé ìránṣẹ́ mi ni àwọn ará Israẹli jẹ́. Ẹni tí mo mú jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, torí èyí ẹ kò gbọdọ̀ tà wọ́n lẹ́rú.
Słudzy bowiem moi są, którem Ja wywiódł z ziemi Egipskiej, niechże nie będą sprzedawani jako niewolnicy.
43 Ẹ má ṣe rorò mọ́ wọn: ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run yín.
Nie będziesz panował nad nimi surowie, ale się będziesz bał Pana Boga twego.
44 “‘Àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín lè jẹ́ láti orílẹ̀-èdè tí ó yí yín ká, ẹ lè ra àwọn ẹrú wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn.
Niewolnik też twój, i niewolnica twoja, które mieć będziesz, będą z narodów tych, które są około was, z nich kupować będziecie niewolnika i niewolnicę.
45 Bákan náà, ẹ sì le è ra àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín, àti àwọn ìdílé wọn tí a bí sáàrín yín. Wọn yóò sì di ohun ìní yín.
Także też syny przychodniów mieszkających między wami kupować będziecie, i z potomstwa tych, którzy są z wami, które spłodzili w ziemi waszej, a ci będą wam za dziedzictwo.
46 Ẹ lè fi wọ́n sílẹ̀ bí ogún fún àwọn ọmọ yín, wọ́n sì lè sọ wọ́n di ẹrú títí láé. Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rorò mọ́ ọmọ Israẹli kankan.
Prawem dziedzicznem trzymać je będziecie, i synowie wasi po was, abyście je dziedzicznie odzierżeli, na wieki służby ich używać będziecie; lecz nad bracią swą, syny Izraelskimi, żaden nad bratem swoim nie będzie panował surowie.
47 “‘Bí àlejò kan láàrín yín tàbí ẹni tí ń gbé àárín yín fún ìgbà díẹ̀ bá lọ́rọ̀ tí ọmọ Israẹli sì tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ lẹ́rú fún àlejò tàbí ìdílé àlejò náà.
Jeźliby się też gość albo przychodzień zbogacił, który mieszka z tobą, a zubożałby brat twój przy nim, tak żeby się zaprzedał gościowi, albo przychodniowi, który jest z tobą, albo potomstwu z domu cudzoziemców,
48 Ó lẹ́tọ̀ọ́ si ki a rà á padà lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ta ara rẹ̀. Ọ̀kan nínú ìbátan rẹ̀ le è rà á padà.
Gdyby się zaprzedał, może być wykupiony; ktokolwiek z braci jego odkupi go;
49 Àbúrò baba rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá tan nínú ìdílé rẹ̀ le è rà wọ̀n padà. Bí ó bá sì ti lọ́rọ̀, ó lè ra ara rẹ̀ padà.
Albo stryj jego, albo syn stryja jego odkupi go, albo z bliskich pokrewnych jego z rodziny jego, odkupi go, albo jeźliby przemógł, wykupi się sam.
50 Kí òun àti olówó rẹ̀ ka iye ọdún tí ó ta ara rẹ̀ títí dé ọdún ìdásílẹ̀ kí iye owó ìdásílẹ̀ rẹ̀ jẹ́ iye tí wọ́n ń san lórí alágbàṣe fún iye ọdún náà.
I porachuje się z onym, co go kupił, od roku, którego mu się sprzedał, aż do miłościwego lata, aby pieniądze, za które się sprzedał, odłożone były według liczby lat, jako z najemnikiem, z nim sobie postąpi.
51 Bí iye ọdún rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù bá pọ̀, kí iye owó fún ìràpadà rẹ̀ pọ̀.
Jeźliby jeszcze nie mało lat zostawało, wedle nich wróci okup swój z pieniędzy, za które kupiony jest.
52 Bí ó bá sì ṣe pé kìkì ọdún díẹ̀ ni ó kù títí di ọdún jubili, kí ó ṣe ìṣirò rẹ̀, kí ó sì san owó náà bí iye ìṣirò rẹ̀ padà.
A jeźliby nie wiele lat zostawało do miłościwego lata, tedy porachuje się z nim, a według onych lat wróci okup swój.
53 Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
Jako najemnik doroczny niech będzie u niego; nie będzie nad nim surowie panował przed oczyma twemi.
54 “‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
A jeźliby się tym obyczajem nie wykupił, tedy wynijdzie w miłościwe lato, on i dzieci jego z nim;
55 Nítorí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Ejibiti wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Albowiem synowie Izraelscy są sługami moimi; sługami moimi są, którem wywiódł z ziemi Egipskiej, Ja Pan, Bóg wasz.

< Leviticus 25 >