< Leviticus 25 >

1 Olúwa sọ fún Mose ní orí òkè Sinai pé,
Szóla ismét az Úr Mózesnek a Sinai hegyen, mondván:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín, ilẹ̀ náà gbọdọ̀ sinmi fún Olúwa.
Szólj Izráel fiainak és mondd meg nékik: Mikor bementek a földre, a melyet én adok néktek, nyugodjék meg a föld az Úrnak szombatja szerint.
3 Ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi gbin oko rẹ, ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ, tí ìwọ ó sì fi kó èso wọn jọ.
Hat esztendőn át vesd a te szántóföldedet, és hat esztendőn át messed a te szőlődet, és takarítsd be annak termését;
4 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje kí ilẹ̀ náà ní ìsinmi: ìsinmi fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ.
A hetedik esztendőben pedig szombati nyugodalma legyen a földnek, az Úrnak szombatja: szántóföldedet ne vesd be, és szőlődet meg ne mesd.
5 Ẹ má ṣe kórè ohun tí ó tìkára rẹ̀ hù, ẹ má ṣe kórè èso àjàrà ọgbà tí ẹ ò tọ́jú. Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ ní ìsinmi fún ọdún kan.
A mi a te tarló földeden magától terem, le ne arasd, és a mi a te metszetlen szőlődön terem, meg ne szedjed; mert nyugalom esztendeje lesz az a földnek.
6 Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ọdún ìsinmi ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún yín àní fún ẹ̀yin tìkára yín, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín, àwọn alágbàṣe àti àwọn tí ń gbé pẹ̀lú yín fún ìgbà díẹ̀.
És a mit a föld az ő szombatján terem, legyen az eledelül néktek: néked, szolgádnak, szolgáló leányodnak, béresednek és zsellérednek, a kik nálad tartózkodnak;
7 Fún àwọn ohun ọ̀sìn yín, àti àwọn ẹranko búburú ní ilẹ̀ yín. Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ẹ lè jẹ.
A te barmodnak is és a vadnak, a mely a te földeden van, legyen annak minden termése eledelül.
8 “‘Ọdún ìsinmi méje èyí tí í ṣe ọdún mọ́kàndínláàádọ́ta ni kí ẹ kà.
Számlálj azután hét szombat-esztendőt, hétszer hét esztendőt, úgy hogy a hét szombat-esztendőnek ideje negyvenkilencz esztendő legyen:
9 Lẹ́yìn náà, kí ẹ fọn fèrè ní gbogbo ibikíbi ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́. Ní ọjọ́ ètùtù yìí, ẹ fọn fèrè yíká gbogbo ilẹ̀ yín.
Akkor fúvasd végig a riadó kürtöt a hetedik hónapban, a hónap tizedikén; az engesztelés napján fúvasd végig a kürtöt a ti egész földeteken.
10 Ẹ ya àádọ́ta ọdún náà sọ́tọ̀ kí ẹ sì kéde òmìnira fún gbogbo ẹni tí ń gbé ilẹ̀ náà. Yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Kí olúkúlùkù padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀ àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ̀.
És szenteljétek meg az ötvenedik esztendőt, és hirdessetek szabadságot a földön, annak minden lakójának; kürtölésnek esztendeje legyen ez néktek, és kapja vissza kiki az ő birtokát, és térjen vissza kiki az ő nemzetségéhez.
11 Àádọ́ta ọdún ni yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Ẹ má ṣe gbin ohunkóhun, ẹ kò sì gbọdọ̀ kórè ohun tí ó hù fúnra rẹ̀ tàbí kí ẹ kórè ọgbà àjàrà tí ẹ kò dá.
Kürtölésnek esztendeje ez, az legyen néktek az ötvenedik esztendő; ne vessetek és le se arassátok, a mit önként terem a föld, és a metszetlen szőlőjét se szedjétek meg annak.
12 Torí pé ọdún ìdásílẹ̀ ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún yín. Ẹ jẹ ohun tí ẹ mú jáde nínú oko náà.
Mert kürtölésnek esztendeje ez, szent legyen néktek, a mezőről egyétek meg annak termését.
13 “‘Ní ọdún ìdásílẹ̀ yìí, kí olúkúlùkù gbà ohun ìní rẹ̀ padà.
A kürtölésnek ebben az esztendejében, kapja vissza ismét kiki az ő birtokát.
14 “‘Bí ẹ bá ta ilẹ̀ fún ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín tàbí bí ẹ bá ra èyíkéyìí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ.
Ha pedig eladsz valami eladni valót a te felebarátodnak, vagy vásárolsz valamit a te felebarátodtól: egymást meg ne csaljátok.
15 Kí ẹ ra ilẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn yín ní gẹ́gẹ́ bí iye owó tí ó kù kí ọdún ìdásílẹ̀ pé, kí òun náà sì ta ilẹ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí iye ọdún rẹ̀ tókù láti kórè.
A kürtölés esztendejét követő esztendők száma szerint vásárolj a te felebarátodtól; a terméses esztendők száma szerint adjon el néked.
16 Bí iye ọdún rẹ̀ bá gùn, kí iye owó rẹ̀ pọ̀, bí iye ọdún rẹ̀ bá kúrú, kí iye owó rẹ̀ kéré, torí pé ohun tí ó tà gan an ní iye èso rẹ̀.
Az esztendők nagyobb számához képest nagyobb árt adj azért, a mit veszesz, az esztendők kisebb számához képest pedig kisebb árt adj azért, a mit veszesz, mert a termések számát adja ő el néked.
17 Ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ, ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Egymást azért meg ne csaljátok, hanem félj a te Istenedtől: mert én vagyok az Úr, a ti Istenetek.
18 “‘Ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà mi, kí ẹ sì kíyèsi láti pa òfin mi mọ́, kí ẹ ba à le máa gbé láìléwu ní ilẹ̀ náà.
Ha teljesítitek azért az én rendeléseimet, és megtartjátok végzéseimet, és teljesítitek azokat, bátorságosan lakhattok a földön.
19 Nígbà yìí ni ilẹ̀ náà yóò so èso rẹ̀, ẹ ó sì jẹ àjẹyó, ẹ ó sì máa gbé láìléwu.
És megtermi a föld az ő gyümölcsét, hogy eleget ehessetek, és bátorságosan lakhattok azon.
20 Ẹ le béèrè pé, “Kí ni àwa ó jẹ ní ọdún keje, bí a kò bá gbin èso tí a kò sì kórè?”
Ha pedig azt mondjátok: Mit eszünk a hetedik esztendőben, ha nem vetünk, és termésünket be nem takarítjuk?
21 Èmi ó pèsè ìbùkún sórí yín tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ yín yóò so èso tó tó fún ọdún mẹ́ta lẹ́yìn rẹ̀.
Én rátok bocsátom majd az én áldásomat a hatodik esztendőben, hogy három esztendőre való termés teremjen.
22 Bí ẹ bá gbin èso yín ní ọdún kẹjọ, àwọn èso ti tẹ́lẹ̀ ní ẹ ó máa jẹ, títí tí ìkórè ti ọdún kẹsànán yóò fi dé.
És mikor a nyolczadik esztendőre vettek, akkor is az ó termésből esztek egészen a kilenczedik esztendeig; mindaddig ó gabonát esztek, míg ennek termése be nem jön.
23 “‘Ẹ má ṣe ta ilẹ̀ yín ní àtàpa torí pé ẹ̀yin kọ́ lẹ ni ín, ti Ọlọ́run ni, ẹ̀yin jẹ́ àjèjì àti ayálégbé.
A földet pedig senki el ne adja örökre, mert enyém a föld; csak jövevények és zsellérek vagytok ti nálam.
24 Ní gbogbo orílẹ̀-èdè ìní yín, ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìràpadà ilẹ̀ náà.
Azért a ti birtokotoknak egész földén megengedjétek, hogy a föld kiváltható legyen.
25 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín bá tálákà, dé bi pé ó ta ara àwọn ẹrù rẹ̀, kí ará ilé rẹ̀ tí ó súnmọ́ ọ ra ohun tí ó tà padà.
Ha elszegényedik a te atyádfia, és elad valamit az ő birtokából, akkor álljon elő az ő rokona, a ki közel van ő hozzá, és váltsa ki, a mit eladott az ő atyjafia.
26 Ẹni tí kò ní ẹni tó lè rà á padà fún un, tí òun fúnra rẹ̀ sì ti lọ́rọ̀, tí ó sì ní ànító láti rà á.
Ha pedig nincs valakinek kiváltó rokona, de maga tesz szert annyira, hogy elege van annak megváltásához:
27 Kí ó mọ iye owó tí ó jẹ fún iye ọdún tí ó tà á, kí ó dá iye tí ó kù padà fún ẹni tí ó tà á fún, lẹ́yìn náà, ó lè padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Számlálja meg az eladása óta eltelt esztendőket, a felül lévőt pedig térítse meg annak, a kinek eladta volt, és újra övé legyen az ő birtoka.
28 Ṣùgbọ́n bí kò bá rí ọ̀nà àti san án padà fún un. Ohun tí ó tà wà ní ìkáwọ́ ẹni tí ó rà á títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ó dá a padà fún ẹni tí ó ni i ní ọdún ìdásílẹ̀, ẹni tí ó ni í tẹ́lẹ̀ lè tún padà gbà ohun ìní rẹ̀.
Ha pedig nincsen módjában, hogy visszatéríthesse annak, akkor maradjon az ő eladott birtoka annál, a ki megvette azt, egészen a kürtölésnek esztendejéig: a kürtölésnek esztendejében pedig szabaduljon fel, és újra övé legyen az ő birtoka.
29 “‘Bí arákùnrin kan bá ta ilé gbígbé kan ní ìlú olódi, kí ó rà á padà ní ìwọ̀n ọdún kan sí àkókò tí ó tà á, ní ìwọ̀n ọdún kan ni kí ó rà á padà.
Ha valaki lakó-házat ad el kerített városban, az kiválthatja azt az eladás esztendejének elteléséig; egy esztendőn át válthatja ki azt.
30 Ṣùgbọ́n bí kò bá rà á padà láàrín ọdún náà ilé náà tí ó wà láàrín ìlú ni kí ó yọ̀ǹda pátápátá fún ẹni tí ó rà á, àti àwọn ìdílé rẹ̀. Kí wọ́n má da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
Ha pedig ki nem váltják az esztendőnek teljes elteléséig, akkor a ház, a mely kerített városban van, örökre azé és annak nemzetségeié marad, a ki megvette azt; nem szabadul fel a kürtölésnek esztendejében.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ilé tí ó wà ní abúlé láìní odi ni kí a kà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ oko, a lè rà wọ́n padà, kí wọ́n sì da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
Az olyan falvak házai pedig, a melyek nincsenek körülkerítve, mezei földek gyanánt számíttassanak, kiválthatók legyenek, és a kürtölésnek esztendejében felszabaduljanak.
32 “‘Àwọn ọmọ Lefi ní ẹ̀tọ́, nígbàkígbà láti ra ilẹ̀ wọn, tí ó jẹ́ ohun ìní wọn ní àwọn ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Lefi.
A mi pedig a léviták városait illeti, az ő birtokukban lévő városok házai a léviták által mindenkor kiválthatók legyenek,
33 Torí náà ohun ìní àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n rà padà, fún àpẹẹrẹ, èyí ni pé ilẹ̀ tí a bá tà ní ìlúkílùú tí ó jẹ́ tiwọn, ó sì gbọdọ̀ di dídápadà ní ọdún ìdásílẹ̀, torí pé àwọn ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú àwọn Lefi ni ìní wọn láàrín àwọn ará Israẹli.
De a mit ki nem vált is valaki a léviták közül, szabaduljon fel a kürtölésnek esztendejében, az eladott ház, és az ő birtokának városa; mert a léviták városainak házai tulajdon birtokuk nékik Izráel fiai között.
34 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí wọ́n ti ń da ẹran tí ó jẹ́ ti ìlú wọn, wọn kò gbọdọ̀ tà wọ́n, ilẹ̀ ìní wọn láéláé ni.
De a városaikhoz tartozó szántóföldeket el ne adják, mert örök birtokuk az nékik.
35 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà tí kò sì le è pèsè fún àìní ara rẹ̀, ẹ pèsè fún un bí ẹ ti ń ṣe fún àwọn àlejò tàbí àwọn tí ẹ gbà sílé: kí ó ba à le è máa gbé láàrín yín.
Ha a te atyádfia elszegényedik, és keze erőtlenné lesz melletted, segítsd meg őt, akár jövevény, akár zsellér, hogy megélhessen melletted.
36 Ẹ kò gbọdọ̀ gba èlé kankan lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ bẹ̀rù Olúwa kí arákùnrin yín le è máa gbé láàrín yín.
Ne végy ő tőle kamatot vagy uzsorát, hanem félj a te Istenedtől, hogy megélhessen melletted a te atyádfia.
37 Ẹ má ṣe gba èlé lórí owó tí ẹ yá a bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ èrè lórí oúnjẹ tí ẹ tà fún un.
Pénzedet ne add néki kamatra, se uzsoráért ne add a te eleségedet.
38 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti láti fún yín ní ilẹ̀ Kenaani àti láti jẹ́ Ọlọ́run yín.
Én vagyok az Úr, a ti Istenetek, a ki kihoztalak titeket Égyiptom földéről, hogy néktek adjam Kanaán földét, és Istenetek legyek néktek.
39 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ fún ọ bí ẹrú. Má ṣe lò ó bí ẹrú.
Ha pedig elszegényedik melletted a te atyádfia, és eladja magát néked: ne szolgáltassad úgy mint rabszolgát.
40 Jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ rẹ bí alágbàṣe tàbí àlejò láàrín yín, kí ó máa ṣiṣẹ́ sìn ọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀.
Mint béres, mint zsellér legyen nálad; a kürtölésnek esztendejéig szolgáljon nálad.
41 Nígbà náà ni kí ó yọ̀ǹda òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n padà sí ìdílé wọn àti sí ilẹ̀ ìní baba wọn.
Azután menjen el tőled ő és vele az ő gyermekei, és térjen vissza az ő nemzetségéhez, és térjen vissza az ő atyáinak örökségébe.
42 Torí pé ìránṣẹ́ mi ni àwọn ará Israẹli jẹ́. Ẹni tí mo mú jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, torí èyí ẹ kò gbọdọ̀ tà wọ́n lẹ́rú.
Mert az én szolgáim ők, a kiket kihoztam Égyiptom földéről: nem adathatnak el, mint rabszolgák.
43 Ẹ má ṣe rorò mọ́ wọn: ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run yín.
Ne uralkodjál rajta kegyetlenül, hanem félj a te Istenedtől.
44 “‘Àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín lè jẹ́ láti orílẹ̀-èdè tí ó yí yín ká, ẹ lè ra àwọn ẹrú wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn.
Mind szolgád, mind szolgálóleányod, a kik lesznek néked, a körületek lévő népek közül legyenek: azokból vásárolj szolgát és szolgálóleányt;
45 Bákan náà, ẹ sì le è ra àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín, àti àwọn ìdílé wọn tí a bí sáàrín yín. Wọn yóò sì di ohun ìní yín.
Meg a zsellérek gyermekei közül is, a kik nálatok tartózkodnak, azokból is vásárolhattok, és azoknak nemzetségéből, a kik veletek vannak, a kiket a ti földeteken nemzettek; és legyenek a ti tulajdonotok.
46 Ẹ lè fi wọ́n sílẹ̀ bí ogún fún àwọn ọmọ yín, wọ́n sì lè sọ wọ́n di ẹrú títí láé. Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rorò mọ́ ọmọ Israẹli kankan.
És örökül hagyhatjátok azokat a ti utánnatok való fiaitoknak, hogy örökségül bírják azokat, örökké dolgoztathattok velük; de a ti atyátokfiain, az Izráel fiain, egyik a másikán senki ne uralkodjék kegyetlenül.
47 “‘Bí àlejò kan láàrín yín tàbí ẹni tí ń gbé àárín yín fún ìgbà díẹ̀ bá lọ́rọ̀ tí ọmọ Israẹli sì tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ lẹ́rú fún àlejò tàbí ìdílé àlejò náà.
És ha a jövevény vagy zsellér vagyonra tesz szert melletted, a te atyádfia pedig elszegényedik mellette, és eladja magát a melletted lévő jövevénynek, zsellérnek, vagy jövevény nemzetségéből való sarjadéknak:
48 Ó lẹ́tọ̀ọ́ si ki a rà á padà lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ta ara rẹ̀. Ọ̀kan nínú ìbátan rẹ̀ le è rà á padà.
Mindamellett is, hogy eladta magát, megváltható legyen; akárki megválthassa azt az ő atyjafiai közül.
49 Àbúrò baba rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá tan nínú ìdílé rẹ̀ le è rà wọ̀n padà. Bí ó bá sì ti lọ́rọ̀, ó lè ra ara rẹ̀ padà.
Vagy nagybátyja, vagy nagybátyjának fia váltsa meg azt, vagy az ő nemzetségéből való vérrokona váltsa meg azt, vagy, ha módja van hozzá, maga váltsa meg őmagát.
50 Kí òun àti olówó rẹ̀ ka iye ọdún tí ó ta ara rẹ̀ títí dé ọdún ìdásílẹ̀ kí iye owó ìdásílẹ̀ rẹ̀ jẹ́ iye tí wọ́n ń san lórí alágbàṣe fún iye ọdún náà.
És vessen számot azzal, a ki megvette őt, attól az esztendőtől kezdve, a melyen eladta magát annak, a kürtölésnek esztendejéig, és az ő eladásának ára az esztendők száma szerint legyen, a béres ideje szerint legyen nála.
51 Bí iye ọdún rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù bá pọ̀, kí iye owó fún ìràpadà rẹ̀ pọ̀.
Ha még sok esztendő van hátra, azokhoz képest térítse meg annak a váltságot az ő megvásárlásának árából.
52 Bí ó bá sì ṣe pé kìkì ọdún díẹ̀ ni ó kù títí di ọdún jubili, kí ó ṣe ìṣirò rẹ̀, kí ó sì san owó náà bí iye ìṣirò rẹ̀ padà.
Ha pedig kevés esztendő van hátra a kürtölésnek esztendejéig, akkor is vessen számot vele, és az évek számához képest fizesse vissza az ő váltságát.
53 Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
Mint esztendőről esztendőre fogadott béres legyen nála; ne uralkodjék kegyetlenül rajta te előtted.
54 “‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
Ha pedig ilyen módon meg nem váltatik, a kürtölésnek esztendejében szabaduljon fel: ő és vele az ő gyermekei.
55 Nítorí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Ejibiti wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Mert az én szolgáim Izráel fiai, az én szolgáim ők, a kiket kihoztam Égyiptom földéről. Én vagyok az Úr, a ti Istenetek.

< Leviticus 25 >