< Leviticus 25 >

1 Olúwa sọ fún Mose ní orí òkè Sinai pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa Kĩrĩma-inĩ gĩa Sinai atĩrĩ,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín, ilẹ̀ náà gbọdọ̀ sinmi fún Olúwa.
“Arĩria andũ a Isiraeli, ũmeere atĩrĩ, ‘Hĩndĩ ĩrĩa mũgaatoonya bũrũri ũrĩa ngaamũhe-rĩ, bũrũri ũcio guo mwene no nginya ũkaagĩaga na Thabatũ ĩrĩa yamũrĩirwo Jehova.
3 Ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi gbin oko rẹ, ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ, tí ìwọ ó sì fi kó èso wọn jọ.
Mũkaahaandaga mĩgũnda yanyu mĩaka ĩtandatũ, na mũcehage mĩgũnda yanyu ya thabibũ mũkamĩcehaga mĩaka ĩtandatũ mũgĩcookanagĩrĩria maciaro mayo.
4 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje kí ilẹ̀ náà ní ìsinmi: ìsinmi fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ.
No mwaka wa mũgwanja wakinya, bũrũri ũcio nĩũkagĩa na Thabatũ ya kũhurũka, Thabatũ yamũrĩirwo Jehova; mũtikanahaande kĩndũ mĩgũnda kana mũcehe mĩthabibũ yanyu.
5 Ẹ má ṣe kórè ohun tí ó tìkára rẹ̀ hù, ẹ má ṣe kórè èso àjàrà ọgbà tí ẹ ò tọ́jú. Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ ní ìsinmi fún ọdún kan.
Irio iria ikeemeria, nĩcio cia maitĩka-rĩ, mũtikanacigethe kana mũgethe thabibũ cia mĩthabibũ yanyu ĩyo ĩtarĩ mĩrutĩre wĩra. Bũrũri ũcio no nginya ũkaagĩa na mwaka wa kũhurũka.
6 Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ọdún ìsinmi ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún yín àní fún ẹ̀yin tìkára yín, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín, àwọn alágbàṣe àti àwọn tí ń gbé pẹ̀lú yín fún ìgbà díẹ̀.
Kĩrĩa gĩothe bũrũri ũcio ũgaaciara mwaka-inĩ ũcio wa Thabatũ gĩgaatuĩka irio cianyu, inyuĩ ene na cia ndungata cianyu cia arũme na cia andũ-a-nja, na cia aruti anyu a wĩra wa mũcaara, na mũraarĩrĩri ũrĩa mũikaranĩtie nake,
7 Fún àwọn ohun ọ̀sìn yín, àti àwọn ẹranko búburú ní ilẹ̀ yín. Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ẹ lè jẹ.
o hamwe na mahiũ manyu na nyamũ cia gĩthaka iria itũũraga bũrũri wanyu. Kĩrĩa gĩothe bũrũri ũcio ũgaaciara no kĩrĩĩo.
8 “‘Ọdún ìsinmi méje èyí tí í ṣe ọdún mọ́kàndínláàádọ́ta ni kí ẹ kà.
“‘Tarai Thabatũ mũgwanja cia mĩaka, mĩaka mũgwanja maita mũgwanja, nĩguo Thabatũ icio mũgwanja cia mĩaka ihinge mĩaka mĩrongo ĩna na kenda.
9 Lẹ́yìn náà, kí ẹ fọn fèrè ní gbogbo ibikíbi ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́. Ní ọjọ́ ètùtù yìí, ẹ fọn fèrè yíká gbogbo ilẹ̀ yín.
Ningĩ mũcooke mũhuhe karumbeta kũndũ guothe mũthenya wa ikũmi wa mweri wa mũgwanja; Mũthenya wa Kũhoroherio Mehia, mũkaahuha karumbeta kũndũ guothe bũrũri-inĩ wanyu.
10 Ẹ ya àádọ́ta ọdún náà sọ́tọ̀ kí ẹ sì kéde òmìnira fún gbogbo ẹni tí ń gbé ilẹ̀ náà. Yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Kí olúkúlùkù padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀ àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ̀.
Amũrai mwaka ũcio wa mĩrongo ĩtano, na mũhunjanĩrie ũhoro wa kũohorwo kwa andũ othe arĩa matũũraga bũrũri ũcio wothe. Mwaka ũcio ũgaatuĩka wa Jubilii nĩ ũndũ wanyu; o mũndũ wanyu nĩagacooka kũrĩa ithaka cia nyũmba yao irĩ, na kũrĩa andũ a mũhĩrĩga wao marĩ.
11 Àádọ́ta ọdún ni yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Ẹ má ṣe gbin ohunkóhun, ẹ kò sì gbọdọ̀ kórè ohun tí ó hù fúnra rẹ̀ tàbí kí ẹ kórè ọgbà àjàrà tí ẹ kò dá.
Mwaka ũcio wa mĩrongo ĩtano ũgaatuĩka wa Jubilii kũrĩ inyuĩ; mũtikanahaande na mũtikanagethe kĩrĩa gĩĩkũrĩtie kĩo kĩene, kana mũgethe mĩthabibũ ĩrĩa ĩtarĩ mĩrutĩre wĩra.
12 Torí pé ọdún ìdásílẹ̀ ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún yín. Ẹ jẹ ohun tí ẹ mú jáde nínú oko náà.
Nĩgũkorwo ĩyo nĩ Jubilii, na nĩyo ĩgaatuĩka theru kũrĩ inyuĩ; rĩĩagai o kĩrĩa gĩĩkũrĩtie mĩgũnda-inĩ.
13 “‘Ní ọdún ìdásílẹ̀ yìí, kí olúkúlùkù gbà ohun ìní rẹ̀ padà.
“‘Mwaka-inĩ ũyũ wa Jubilii, o mũndũ no nginya acooke gĩthaka-inĩ gĩake.
14 “‘Bí ẹ bá ta ilẹ̀ fún ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín tàbí bí ẹ bá ra èyíkéyìí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ.
“‘Mũngĩkenderia mũndũ wa bũrũri wanyu mũgũnda kana mũgũre mũgũnda kũrĩ we, mũtikanaheenanie mũndũ na ũrĩa ũngĩ.
15 Kí ẹ ra ilẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn yín ní gẹ́gẹ́ bí iye owó tí ó kù kí ọdún ìdásílẹ̀ pé, kí òun náà sì ta ilẹ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí iye ọdún rẹ̀ tókù láti kórè.
Mũrĩgũraga mũgũnda wa mũndũ wa bũrũri wanyu kũringana na ũrĩa mĩaka ĩthirĩte thuutha wa Jubilii. Nake mwendia akaawendagia kũringana na mĩaka ĩrĩa ĩgakorwo ĩtigarĩte ya magetha.
16 Bí iye ọdún rẹ̀ bá gùn, kí iye owó rẹ̀ pọ̀, bí iye ọdún rẹ̀ bá kúrú, kí iye owó rẹ̀ kéré, torí pé ohun tí ó tà gan an ní iye èso rẹ̀.
Mĩaka ĩngĩkorwo ĩtigarĩte mĩingĩ, mũkongerera thogora, na mĩaka ĩngĩkorwo ĩtigarĩte mĩnini, mũkanyiihia thogora, nĩ ũndũ kĩrĩa arakwenderia nĩ mũigana wa magetha.
17 Ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ, ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Mũtikanaheenanie mũndũ na ũrĩa ũngĩ, no mwĩtigagĩre Ngai wanyu. Niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu.
18 “‘Ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà mi, kí ẹ sì kíyèsi láti pa òfin mi mọ́, kí ẹ ba à le máa gbé láìléwu ní ilẹ̀ náà.
“‘Rũmagĩrĩrai kĩrĩra kĩa watho wakwa na mwĩmenyagĩrĩre nĩguo mwathĩkagĩre mawatho makwa, na inyuĩ nĩ mũgaatũũra bũrũri ũcio mũrĩ na thayũ.
19 Nígbà yìí ni ilẹ̀ náà yóò so èso rẹ̀, ẹ ó sì jẹ àjẹyó, ẹ ó sì máa gbé láìléwu.
Naguo bũrũri ũcio nĩũgaciaraga maciaro maguo, na inyuĩ nĩmũkarĩĩaga mũkahũũna na mũtũũre kuo mũrĩ na thayũ.
20 Ẹ le béèrè pé, “Kí ni àwa ó jẹ ní ọdún keje, bí a kò bá gbin èso tí a kò sì kórè?”
Mwahota kũũria atĩrĩ, “Tũkaarĩa kĩ mwaka wa mũgwanja aakorwo tũtikahaanda kana tũgethe?”
21 Èmi ó pèsè ìbùkún sórí yín tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ yín yóò so èso tó tó fún ọdún mẹ́ta lẹ́yìn rẹ̀.
Nĩngamũtũmĩra kĩrathimo mwaka-inĩ ũcio wa gatandatũ nĩguo mĩgũnda yanyu ĩgaaciara maciaro ma kũmũigana mĩaka ĩtatũ.
22 Bí ẹ bá gbin èso yín ní ọdún kẹjọ, àwọn èso ti tẹ́lẹ̀ ní ẹ ó máa jẹ, títí tí ìkórè ti ọdún kẹsànán yóò fi dé.
Mũkĩhaanda mwaka-inĩ wa kanana, mũkaarĩĩaga irio iria mwaigĩte mũthiithũ, na mũgaacirĩa nginya mũgethe maciaro ma mwaka wa kenda.
23 “‘Ẹ má ṣe ta ilẹ̀ yín ní àtàpa torí pé ẹ̀yin kọ́ lẹ ni ín, ti Ọlọ́run ni, ẹ̀yin jẹ́ àjèjì àti ayálégbé.
“‘Mĩgũnda ndĩkanendio biũ, tondũ bũrũri nĩ wakwa na inyuĩ mũrĩ o ageni kuo, na nĩ niĩ ndĩmũkomborithĩtie.
24 Ní gbogbo orílẹ̀-èdè ìní yín, ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìràpadà ilẹ̀ náà.
Bũrũri wothe ũrĩa mwĩnyiitĩire ũgaatuĩka wanyu, no nginya kũgĩe na mweke wa gũkũũraga mĩgũnda ĩyo.
25 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín bá tálákà, dé bi pé ó ta ara àwọn ẹrù rẹ̀, kí ará ilé rẹ̀ tí ó súnmọ́ ọ ra ohun tí ó tà padà.
“‘Mũndũ wa bũrũri wanyu angĩthĩĩna na endie gĩcunjĩ kĩa mũgũnda wake, mũndũ ũrĩa wa hakuhĩ mũno wa nyũmba yake nĩagooka na akũũre mũgũnda ũcio mũndũ wao eendetie.
26 Ẹni tí kò ní ẹni tó lè rà á padà fún un, tí òun fúnra rẹ̀ sì ti lọ́rọ̀, tí ó sì ní ànító láti rà á.
No rĩrĩ, mũndũ angĩkorwo ndarĩ na mũndũ wa kũmũkũũrĩra mũgũnda, na we mwene atonge agĩe na indo ciiganĩte kũũkũũra,
27 Kí ó mọ iye owó tí ó jẹ fún iye ọdún tí ó tà á, kí ó dá iye tí ó kù padà fún ẹni tí ó tà á fún, lẹ́yìn náà, ó lè padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
nĩwe ũgaatua thogora kũringana na mĩaka ĩrĩa mĩthiru kuuma rĩrĩa aawendirie, na acookie mbeeca icio ingĩ kũrĩ mũndũ ũrĩa eendeirie; thuutha ũcio no acooke mũgũnda-inĩ wake.
28 Ṣùgbọ́n bí kò bá rí ọ̀nà àti san án padà fún un. Ohun tí ó tà wà ní ìkáwọ́ ẹni tí ó rà á títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ó dá a padà fún ẹni tí ó ni i ní ọdún ìdásílẹ̀, ẹni tí ó ni í tẹ́lẹ̀ lè tún padà gbà ohun ìní rẹ̀.
No angĩaga kũgĩa na indo cia kũmũrĩha-rĩ, gĩcunjĩ kĩrĩa eendirie gĩgũtũũra kĩrĩ kĩa mũgũri nginya Mwaka wa Jubilii. Gĩgaacookio hĩndĩ ya Jubilii, na hĩndĩ ĩyo no acooke gĩthaka-inĩ gĩake.
29 “‘Bí arákùnrin kan bá ta ilé gbígbé kan ní ìlú olódi, kí ó rà á padà ní ìwọ̀n ọdún kan sí àkókò tí ó tà á, ní ìwọ̀n ọdún kan ni kí ó rà á padà.
“‘Mũndũ angĩkeendia nyũmba ĩrĩ itũũra-inĩ inene rĩirigĩre, nĩarĩkoragwo arĩ na kĩhooto gĩa kũmĩkũũra ihinda rĩa mwaka mũgima kuuma amĩendia. Thĩinĩ wa ihinda rĩu no amĩkũũre.
30 Ṣùgbọ́n bí kò bá rà á padà láàrín ọdún náà ilé náà tí ó wà láàrín ìlú ni kí ó yọ̀ǹda pátápátá fún ẹni tí ó rà á, àti àwọn ìdílé rẹ̀. Kí wọ́n má da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
Ĩngĩaga gũkũũrwo mwaka ũmwe ũtanathira, nyũmba ĩyo ĩrĩ itũũra-inĩ inene rĩirigĩre nĩĩgatuĩka ya mũmĩgũri na njiaro ciake nginya tene. Nyũmba ĩyo ndĩgaacookerio mwene Mwaka wa Jubilii.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ilé tí ó wà ní abúlé láìní odi ni kí a kà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ oko, a lè rà wọ́n padà, kí wọ́n sì da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
No nyũmba cia tũtũũra-inĩ tũrĩa tũtarĩ tũirigĩre, irĩtuagwo ta mĩgũnda ya kũndũ gũtarĩ kũirige. Icio no ikũũrwo, na nĩ igaacookio Mwaka wa Jubilii.
32 “‘Àwọn ọmọ Lefi ní ẹ̀tọ́, nígbàkígbà láti ra ilẹ̀ wọn, tí ó jẹ́ ohun ìní wọn ní àwọn ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Lefi.
“‘Alawii hĩndĩ ciothe nĩ marĩ na kĩhooto gĩa gũkũũraga nyũmba ciao iria irĩ matũũra-inĩ ma Alawii, marĩa megwatĩire.
33 Torí náà ohun ìní àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n rà padà, fún àpẹẹrẹ, èyí ni pé ilẹ̀ tí a bá tà ní ìlúkílùú tí ó jẹ́ tiwọn, ó sì gbọdọ̀ di dídápadà ní ọdún ìdásílẹ̀, torí pé àwọn ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú àwọn Lefi ni ìní wọn láàrín àwọn ará Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio indo cia Alawii no ikũũrwo, ũguo nĩ ta kuuga atĩ, nyũmba nyendie itũũra-inĩ o rĩothe rĩao, nĩĩgacookio Mwaka wa Jubilii, tondũ nyũmba iria irĩ matũũra-inĩ ma Alawii nĩcio igai rĩao thĩinĩ wa andũ a Isiraeli.
34 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí wọ́n ti ń da ẹran tí ó jẹ́ ti ìlú wọn, wọn kò gbọdọ̀ tà wọ́n, ilẹ̀ ìní wọn láéláé ni.
No ithaka cia ũrĩithio cia matũũra mao itikanendio; icio nĩ ciao nginya tene.
35 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà tí kò sì le è pèsè fún àìní ara rẹ̀, ẹ pèsè fún un bí ẹ ti ń ṣe fún àwọn àlejò tàbí àwọn tí ẹ gbà sílé: kí ó ba à le è máa gbé láàrín yín.
“‘Mũndũ wa bũrũri wanyu angĩthĩĩna nginya aremwo nĩ kwĩrũgamĩrĩra gatagatĩ kanyu, mũteithagiei o ta ũrĩa mũngĩteithia mũgeni kana mũndũ ũrarĩrĩire kwanyu, nĩgeetha ahote gũtũũrania na inyuĩ.
36 Ẹ kò gbọdọ̀ gba èlé kankan lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ bẹ̀rù Olúwa kí arákùnrin yín le è máa gbé láàrín yín.
Mũtikanamũrĩhie uumithio o na ũrĩkũ, no mwĩtigagĩre Ngai wanyu, nĩgeetha mũndũ wa bũrũri wanyu ahote gũtũũrania na inyuĩ.
37 Ẹ má ṣe gba èlé lórí owó tí ẹ yá a bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ èrè lórí oúnjẹ tí ẹ tà fún un.
Mũtikanamũkombere mbeeca nĩguo acookie na maciaro, kana mũmwenderie irio nĩguo muone uumithio.
38 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti láti fún yín ní ilẹ̀ Kenaani àti láti jẹ́ Ọlọ́run yín.
Niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu, ũrĩa wamũrutire bũrũri wa Misiri nĩguo ndĩmũhe bũrũri wa Kaanani na nduĩke Ngai wanyu.
39 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ fún ọ bí ẹrú. Má ṣe lò ó bí ẹrú.
“‘Mũndũ wa bũrũri wanyu angĩthĩĩna arĩ gatagatĩ kanyu, nake eyendie harĩ inyuĩ, mũtikanamũrutithie wĩra ta ngombo.
40 Jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ rẹ bí alágbàṣe tàbí àlejò láàrín yín, kí ó máa ṣiṣẹ́ sìn ọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀.
Mũkaamũtua ta mũruti wa wĩra wa mũcaara kana ta mũndũ ũrarĩrĩire kwanyu; mũndũ ũcio akaamũrutĩra wĩra nginya Mwaka wa Jubilii.
41 Nígbà náà ni kí ó yọ̀ǹda òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n padà sí ìdílé wọn àti sí ilẹ̀ ìní baba wọn.
Thuutha ũcio mũndũ ũcio na ciana ciake nĩmakarekererio, nake acooke kũrĩ andũ a mũhĩrĩga wake, na gĩthaka-inĩ kĩa maithe make ma tene.
42 Torí pé ìránṣẹ́ mi ni àwọn ará Israẹli jẹ́. Ẹni tí mo mú jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, torí èyí ẹ kò gbọdọ̀ tà wọ́n lẹ́rú.
Tondũ andũ a Isiraeli nĩ ndungata ciakwa, iria ndaarutire bũrũri wa Misiri, matikanendio matuĩke ngombo.
43 Ẹ má ṣe rorò mọ́ wọn: ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run yín.
Mũtikamaathage mũtekũmaiguĩra tha, no mwĩtigagĩrei Ngai wanyu.
44 “‘Àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín lè jẹ́ láti orílẹ̀-èdè tí ó yí yín ká, ẹ lè ra àwọn ẹrú wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn.
“‘Ngombo cianyu cia arũme na cia andũ-a-nja iriumaga ndũrĩrĩ-inĩ iria imũrigiicĩirie; kuuma kũrĩ ndũrĩrĩ icio no mũgũrage ngombo.
45 Bákan náà, ẹ sì le è ra àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín, àti àwọn ìdílé wọn tí a bí sáàrín yín. Wọn yóò sì di ohun ìní yín.
O na ningĩ no mwĩgũrĩre ngombo kuuma kũrĩ andũ arĩa mararĩrĩire kwanyu na kuuma kũrĩ andũ a mĩhĩrĩga yao arĩa maciarĩirwo bũrũri wanyu, nao matuĩke indo cianyu.
46 Ẹ lè fi wọ́n sílẹ̀ bí ogún fún àwọn ọmọ yín, wọ́n sì lè sọ wọ́n di ẹrú títí láé. Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rorò mọ́ ọmọ Israẹli kankan.
Andũ acio no mũmeegaĩre kũrĩ ciana cianyu matuĩke igai rĩrĩa mũmagaĩire, na no mũmatue ngombo rĩrĩa rĩothe marĩ muoyo, no mũtikanaathe andũ anyu a Isiraeli mũtekũmaiguĩra tha.
47 “‘Bí àlejò kan láàrín yín tàbí ẹni tí ń gbé àárín yín fún ìgbà díẹ̀ bá lọ́rọ̀ tí ọmọ Israẹli sì tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ lẹ́rú fún àlejò tàbí ìdílé àlejò náà.
“‘No rĩrĩ, mũgeni kana mũndũ ũrĩa ũrarĩrĩire kwanyu angĩtonga arĩ gatagatĩ kanyu, nake mũndũ wa bũrũri wanyu athĩĩne na eyendie kũrĩ mũgeni ũrĩa ũtũũranĩtie na inyuĩ, kana kũrĩ mũndũ wa mũhĩrĩga wa mũndũ ũcio mũgeni-rĩ,
48 Ó lẹ́tọ̀ọ́ si ki a rà á padà lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ta ara rẹ̀. Ọ̀kan nínú ìbátan rẹ̀ le è rà á padà.
mũndũ ũcio no arĩkoragwo arĩ na kĩhooto gĩa gũkũũrwo thuutha wa kwĩyendia. Mũndũ wa nyũmba yao no amũkũũre:
49 Àbúrò baba rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá tan nínú ìdílé rẹ̀ le è rà wọ̀n padà. Bí ó bá sì ti lọ́rọ̀, ó lè ra ara rẹ̀ padà.
Ithe mũnini kana ithe mũkũrũ, kana mũrũ wa ithe, kana mũndũ wa rũrĩra rwa mũhĩrĩga wao no amũkũũre; kana we mwene angĩgaacĩra, no ekũũre.
50 Kí òun àti olówó rẹ̀ ka iye ọdún tí ó ta ara rẹ̀ títí dé ọdún ìdásílẹ̀ kí iye owó ìdásílẹ̀ rẹ̀ jẹ́ iye tí wọ́n ń san lórí alágbàṣe fún iye ọdún náà.
Mũndũ ũcio na mũmũgũri magaatara ihinda rĩrĩa rĩthiru kuuma mwaka ũrĩa eyendirie nginya rĩrĩa Mwaka wa Jubilii ũgaakinya. Thogora wa kũrekererio gwake ũkaaringana na irĩhi rĩa mũndũ wa mũcaara thĩinĩ wa mĩaka ĩyo.
51 Bí iye ọdún rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù bá pọ̀, kí iye owó fún ìràpadà rẹ̀ pọ̀.
Angĩkorwo nĩ mĩaka mĩingĩ ĩtigarĩte, nĩakarĩha gĩcunjĩ kĩnene gĩa thogora ũrĩa aagũrĩtwo naguo.
52 Bí ó bá sì ṣe pé kìkì ọdún díẹ̀ ni ó kù títí di ọdún jubili, kí ó ṣe ìṣirò rẹ̀, kí ó sì san owó náà bí iye ìṣirò rẹ̀ padà.
No angĩkorwo no mĩaka mĩnini ĩtigarĩte Mwaka wa Jubilii ũkinye, ĩyo noyo agaatara arĩhe gũkũũranio gwake kũringana na ũrĩa kwagĩrĩire.
53 Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
Agaatuuo ta mũndũ wa mũcaara mwaka o mwaka; na no nginya mũmenyagĩrĩre atĩ mũmũgũri ndarĩmwathaga atekũmũiguĩra tha.
54 “‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
“‘O na angĩaga gũkũũrwo na njĩra ĩmwe ya icio, we na ciana ciake no nginya makaarekererio Mwaka wa Jubilii wakinya,
55 Nítorí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Ejibiti wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
nĩgũkorwo andũ a Isiraeli nĩ ndungata ciakwa. Acio nĩ ndungata ciakwa, iria ndaarutire bũrũri wa Misiri. Niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu.

< Leviticus 25 >