< Leviticus 25 >

1 Olúwa sọ fún Mose ní orí òkè Sinai pé,
Yahweh said to Moses/me on Sinai Mountain,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín, ilẹ̀ náà gbọdọ̀ sinmi fún Olúwa.
“Tell the Israelis [that I, Yahweh, say this]: When you enter the land that I am about to give you, every seventh year you must honor me by [not planting any seeds. You will be] allowing the ground to rest.
3 Ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi gbin oko rẹ, ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ, tí ìwọ ó sì fi kó èso wọn jọ.
For six years you are to plant seeds in your fields and prune your grapevines and harvest the crops.
4 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje kí ilẹ̀ náà ní ìsinmi: ìsinmi fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ.
But the seventh/next year you must [dedicate] to me, and allow your fields to rest. Do not plant seeds in your fields or prune your grapevines [during that year].
5 Ẹ má ṣe kórè ohun tí ó tìkára rẹ̀ hù, ẹ má ṣe kórè èso àjàrà ọgbà tí ẹ ò tọ́jú. Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ ní ìsinmi fún ọdún kan.
Do not reap [the grain] that grows in your fields without having been planted, or harvest the grapes that grow [without the vines being pruned]; you must allow the land to rest for that one year.
6 Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ọdún ìsinmi ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún yín àní fún ẹ̀yin tìkára yín, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín, àwọn alágbàṣe àti àwọn tí ń gbé pẹ̀lú yín fún ìgbà díẹ̀.
But you are permitted to eat whatever crops grow by themselves during that year without having been planted. You and your male and female servants, and workers whom you have hired, and people who are living among you temporarily are permitted to eat it.
7 Fún àwọn ohun ọ̀sìn yín, àti àwọn ẹranko búburú ní ilẹ̀ yín. Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ẹ lè jẹ.
Also, [during that year] your livestock and the wild animals in your land are permitted to eat it.’
8 “‘Ọdún ìsinmi méje èyí tí í ṣe ọdún mọ́kàndínláàádọ́ta ni kí ẹ kà.
‘Also, after every 49 years has ended, you must do this: (On the tenth day of the seventh month/At the end of September) [of the next/50th year], blow trumpets throughout the country, to declare that it will be a day on which you request that I forgive you for the sins that you have committed.
9 Lẹ́yìn náà, kí ẹ fọn fèrè ní gbogbo ibikíbi ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́. Ní ọjọ́ ètùtù yìí, ẹ fọn fèrè yíká gbogbo ilẹ̀ yín.
10 Ẹ ya àádọ́ta ọdún náà sọ́tọ̀ kí ẹ sì kéde òmìnira fún gbogbo ẹni tí ń gbé ilẹ̀ náà. Yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Kí olúkúlùkù padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀ àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ̀.
Set apart that year, and proclaim that throughout the country, it will be a year of restoring the land and freeing people: All the people [who sold their property] will receive back the property that they previously owned, and slaves must be (freed/allowed to return to [their property and] their families).
11 Àádọ́ta ọdún ni yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Ẹ má ṣe gbin ohunkóhun, ẹ kò sì gbọdọ̀ kórè ohun tí ó hù fúnra rẹ̀ tàbí kí ẹ kórè ọgbà àjàrà tí ẹ kò dá.
That year will be a Year of Celebration; [during that year] do not plant anything, and do not harvest [in the usual way] the grain/wheat that grows without having been planted, or the grapes that grow without the vines being pruned.
12 Torí pé ọdún ìdásílẹ̀ ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún yín. Ẹ jẹ ohun tí ẹ mú jáde nínú oko náà.
It will be a Year of Celebration, so eat [only] what grows in the fields (by itself/without any work being done to produce anything).
13 “‘Ní ọdún ìdásílẹ̀ yìí, kí olúkúlùkù gbà ohun ìní rẹ̀ padà.
‘In that Year of Celebration, everyone must return to their own property.
14 “‘Bí ẹ bá ta ilẹ̀ fún ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín tàbí bí ẹ bá ra èyíkéyìí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ.
‘If you sell some of your land to a fellow Israeli or if you buy some land from one of them, you must treat that person fairly:
15 Kí ẹ ra ilẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn yín ní gẹ́gẹ́ bí iye owó tí ó kù kí ọdún ìdásílẹ̀ pé, kí òun náà sì ta ilẹ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí iye ọdún rẹ̀ tókù láti kórè.
If you buy land, the price that you will pay will depend on the number of years there will be until the next Year of Celebration. If someone sells land to you, he will charge a price that is determined by the number of years until the next Year of Celebration.
16 Bí iye ọdún rẹ̀ bá gùn, kí iye owó rẹ̀ pọ̀, bí iye ọdún rẹ̀ bá kúrú, kí iye owó rẹ̀ kéré, torí pé ohun tí ó tà gan an ní iye èso rẹ̀.
If there will be many years before the next Year of Celebration, the price will be higher; if there will be only a few years until the next Year of Celebration, the price will be lower. [You could say that] what he is really selling you is the number of crops [which you can harvest before the next Year of Celebration].
17 Ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ, ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Do not cheat each other; instead, revere me. I, Yahweh your God, [am the one who am commanding this].
18 “‘Ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà mi, kí ẹ sì kíyèsi láti pa òfin mi mọ́, kí ẹ ba à le máa gbé láìléwu ní ilẹ̀ náà.
‘Obey all my laws [DOU] carefully. If you do that, you will continue to live safely in your country [DOU].
19 Nígbà yìí ni ilẹ̀ náà yóò so èso rẹ̀, ẹ ó sì jẹ àjẹyó, ẹ ó sì máa gbé láìléwu.
And crops will grow well on the land, and you will have plenty to eat.
20 Ẹ le béèrè pé, “Kí ni àwa ó jẹ ní ọdún keje, bí a kò bá gbin èso tí a kò sì kórè?”
But you may ask, “If we do not plant or harvest our crops during the seventh year, what will we have to eat?”
21 Èmi ó pèsè ìbùkún sórí yín tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ yín yóò so èso tó tó fún ọdún mẹ́ta lẹ́yìn rẹ̀.
[My answer is that] I will bless you very much during the sixth/previous year, with the result that during that year there will be enough crops to provide food for you for three years!
22 Bí ẹ bá gbin èso yín ní ọdún kẹjọ, àwọn èso ti tẹ́lẹ̀ ní ẹ ó máa jẹ, títí tí ìkórè ti ọdún kẹsànán yóò fi dé.
Then, after you plant seed during the eighth/next year [and wait for the crops to grow], you will eat the food grown in the sixth year, and continue to eat it until more food is harvested in the ninth year!
23 “‘Ẹ má ṣe ta ilẹ̀ yín ní àtàpa torí pé ẹ̀yin kọ́ lẹ ni ín, ti Ọlọ́run ni, ẹ̀yin jẹ́ àjèjì àti ayálégbé.
‘You must not sell any of your land to belong to someone else permanently, because the land [is not yours, it]; is really mine, and you are only living on it temporarily and (farming/taking care of) it for me.
24 Ní gbogbo orílẹ̀-èdè ìní yín, ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìràpadà ilẹ̀ náà.
Throughout the country that you will possess, you must remember that if someone sells some of his land to you, he is permitted to buy it back from you [if he wants to].
25 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín bá tálákà, dé bi pé ó ta ara àwọn ẹrù rẹ̀, kí ará ilé rẹ̀ tí ó súnmọ́ ọ ra ohun tí ó tà padà.
‘So, if one of your fellow Israelis becomes poor and sells some of his property [to obtain some money], the person who is most closely related to him is permitted to come and buy that land for him.
26 Ẹni tí kò ní ẹni tó lè rà á padà fún un, tí òun fúnra rẹ̀ sì ti lọ́rọ̀, tí ó sì ní ànító láti rà á.
However, if a man has no one to buy the land for him, and he himself prospers again and saves enough money to buy that land back,
27 Kí ó mọ iye owó tí ó jẹ fún iye ọdún tí ó tà á, kí ó dá iye tí ó kù padà fún ẹni tí ó tà á fún, lẹ́yìn náà, ó lè padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
he must calculate how many years there will be until the next Year of Celebration. Then he must pay to the man who bought the land the money that he would have earned by continuing to grow crops on that land for those years.
28 Ṣùgbọ́n bí kò bá rí ọ̀nà àti san án padà fún un. Ohun tí ó tà wà ní ìkáwọ́ ẹni tí ó rà á títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ó dá a padà fún ẹni tí ó ni i ní ọdún ìdásílẹ̀, ẹni tí ó ni í tẹ́lẹ̀ lè tún padà gbà ohun ìní rẹ̀.
But if the original owner does not have any money to buy the land that he sold, it will continue to belong to the man who bought it, until the next Year of Celebration. In that year it must be returned to its original owner, and he will be able to live on it again.
29 “‘Bí arákùnrin kan bá ta ilé gbígbé kan ní ìlú olódi, kí ó rà á padà ní ìwọ̀n ọdún kan sí àkókò tí ó tà á, ní ìwọ̀n ọdún kan ni kí ó rà á padà.
‘If someone who lives in a city that has a wall around it sells a house there, during the next year he will be permitted to buy it from the man who bought it.
30 Ṣùgbọ́n bí kò bá rà á padà láàrín ọdún náà ilé náà tí ó wà láàrín ìlú ni kí ó yọ̀ǹda pátápátá fún ẹni tí ó rà á, àti àwọn ìdílé rẹ̀. Kí wọ́n má da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
If he does not buy it during that year, it will belong permanently to the man who bought it and to his descendants. It must not be returned to the original owner in the Year of Celebration.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ilé tí ó wà ní abúlé láìní odi ni kí a kà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ oko, a lè rà wọ́n padà, kí wọ́n sì da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
But houses that are in villages that do not have walls around them are considered to be as though they are in a field. So if someone sells one of those houses, he is permitted to buy it back at any time. And [if he does not buy it], it must be returned to him in the Year of Celebration.
32 “‘Àwọn ọmọ Lefi ní ẹ̀tọ́, nígbàkígbà láti ra ilẹ̀ wọn, tí ó jẹ́ ohun ìní wọn ní àwọn ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Lefi.
‘If any descendants of Levi sell their houses in the towns in which they live, they are permitted to buy them back at any time.
33 Torí náà ohun ìní àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n rà padà, fún àpẹẹrẹ, èyí ni pé ilẹ̀ tí a bá tà ní ìlúkílùú tí ó jẹ́ tiwọn, ó sì gbọdọ̀ di dídápadà ní ọdún ìdásílẹ̀, torí pé àwọn ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú àwọn Lefi ni ìní wọn láàrín àwọn ará Israẹli.
And because the houses in their towns are on land that [was given to them by] other Israelis, that land will become theirs again in the Year of Celebration [if they do not buy it back before then].
34 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí wọ́n ti ń da ẹran tí ó jẹ́ ti ìlú wọn, wọn kò gbọdọ̀ tà wọ́n, ilẹ̀ ìní wọn láéláé ni.
But the pastureland near their towns must not be sold. It must belong to the original owners permanently/forever.
35 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà tí kò sì le è pèsè fún àìní ara rẹ̀, ẹ pèsè fún un bí ẹ ti ń ṣe fún àwọn àlejò tàbí àwọn tí ẹ gbà sílé: kí ó ba à le è máa gbé láàrín yín.
‘If one of your fellow Israelis becomes poor and is unable to buy what he needs [IDM], others of you must help him like you would help a foreigner who is living among you [DOU] temporarily.
36 Ẹ kò gbọdọ̀ gba èlé kankan lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ bẹ̀rù Olúwa kí arákùnrin yín le è máa gbé láàrín yín.
[If you lend money to him], do not charge any kind of interest [DOU]. Instead, [show by what you do that you] revere me, your God, and help that man, in order that he will be able to continue to live among you.
37 Ẹ má ṣe gba èlé lórí owó tí ẹ yá a bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ èrè lórí oúnjẹ tí ẹ tà fún un.
If you lend him money, do not charge interest; and if you sell food to him, [charge him only what you paid for it]; do not get a profit from it.
38 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti láti fún yín ní ilẹ̀ Kenaani àti láti jẹ́ Ọlọ́run yín.
[Do not forget that] I am Yahweh your God, who brought you out of Egypt to be your God and to give you the land of Canaan, [and I did not charge you for doing that].
39 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ fún ọ bí ẹrú. Má ṣe lò ó bí ẹrú.
‘If one of your fellow Israelis becomes poor and sells himself to you, do not force him to work like a slave.
40 Jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ rẹ bí alágbàṣe tàbí àlejò láàrín yín, kí ó máa ṣiṣẹ́ sìn ọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀.
Treat him like you treat workers that you hire or like someone who is living on your land temporarily. But he must work for you [only] until the Year of Celebration.
41 Nígbà náà ni kí ó yọ̀ǹda òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n padà sí ìdílé wọn àti sí ilẹ̀ ìní baba wọn.
During that year, you must free him, and he will go back to his family and to the property that his ancestors owned.
42 Torí pé ìránṣẹ́ mi ni àwọn ará Israẹli jẹ́. Ẹni tí mo mú jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, torí èyí ẹ kò gbọdọ̀ tà wọ́n lẹ́rú.
[It is as though] you Israelis are my slaves/servants, whom I [freed from being slaves] in Egypt. So none of you should be sold to become slaves.
43 Ẹ má ṣe rorò mọ́ wọn: ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run yín.
And do not treat the Israelis whom you buy cruelly; instead, revere me, your God.
44 “‘Àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín lè jẹ́ láti orílẹ̀-èdè tí ó yí yín ká, ẹ lè ra àwọn ẹrú wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn.
‘If you want to have slaves, you are permitted to buy them from nearby countries.
45 Bákan náà, ẹ sì le è ra àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín, àti àwọn ìdílé wọn tí a bí sáàrín yín. Wọn yóò sì di ohun ìní yín.
You are also permitted to buy some of the foreigners who are living among you, and members of their clans that were born in your country. Then you will own them.
46 Ẹ lè fi wọ́n sílẹ̀ bí ogún fún àwọn ọmọ yín, wọ́n sì lè sọ wọ́n di ẹrú títí láé. Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rorò mọ́ ọmọ Israẹli kankan.
They will be your slaves for the remaining years of your life, and after you die, it is permitted for your children to own them. But you must not act in brutal ways toward your fellow Israelis.
47 “‘Bí àlejò kan láàrín yín tàbí ẹni tí ń gbé àárín yín fún ìgbà díẹ̀ bá lọ́rọ̀ tí ọmọ Israẹli sì tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ lẹ́rú fún àlejò tàbí ìdílé àlejò náà.
‘If a foreigner who is living among you [DOU] becomes rich, and if one of your fellow Israelis becomes poor and sells himself to that foreigner or to a member of his clan/family,
48 Ó lẹ́tọ̀ọ́ si ki a rà á padà lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ta ara rẹ̀. Ọ̀kan nínú ìbátan rẹ̀ le è rà á padà.
it is permitted for someone to pay for him to be freed. It is permitted for one of his relatives to pay for him to be released:
49 Àbúrò baba rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá tan nínú ìdílé rẹ̀ le è rà wọ̀n padà. Bí ó bá sì ti lọ́rọ̀, ó lè ra ara rẹ̀ padà.
An uncle or a cousin or another relative in his clan may pay for him to be released. Or, if he prospers [and gets enough money], he is permitted to pay for his own release.
50 Kí òun àti olówó rẹ̀ ka iye ọdún tí ó ta ara rẹ̀ títí dé ọdún ìdásílẹ̀ kí iye owó ìdásílẹ̀ rẹ̀ jẹ́ iye tí wọ́n ń san lórí alágbàṣe fún iye ọdún náà.
The man who wants to pay for his own release must count the number of years until the next Year of Celebration. The price he pays to the man who bought him will depend on the pay that would be given to a hired worker for that number of years.
51 Bí iye ọdún rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù bá pọ̀, kí iye owó fún ìràpadà rẹ̀ pọ̀.
If there are a lot of years that remain until the Year of Celebration, he must pay for his release a larger amount of the money.
52 Bí ó bá sì ṣe pé kìkì ọdún díẹ̀ ni ó kù títí di ọdún jubili, kí ó ṣe ìṣirò rẹ̀, kí ó sì san owó náà bí iye ìṣirò rẹ̀ padà.
If there are only a few years that remain until the Year of Celebration, he must pay a smaller amount to be released.
53 Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
During the years that he is working for the man who bought him, the man who bought him must treat him like he would treat a hired worker, and all of you must make sure that his owner does not treat him cruelly.
54 “‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
‘And even if a fellow Israeli who has sold himself to a rich man is not able to pay for himself to be freed by any of these ways, he and his children must be freed in the Year of Celebration,
55 Nítorí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Ejibiti wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
because [it is as though] you Israelis are my slaves/servants, whom I, Yahweh your God, freed from [being slaves in] Egypt.’”

< Leviticus 25 >