< Leviticus 25 >

1 Olúwa sọ fún Mose ní orí òkè Sinai pé,
Господ говори още на Моисея на Синайската планина, казвайки:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín, ilẹ̀ náà gbọdọ̀ sinmi fún Olúwa.
Говори на израилтяните, като им кажеш: Когато влезете в земята, която Аз ви давам, тогава земята да пази една събота за Господа.
3 Ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi gbin oko rẹ, ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ, tí ìwọ ó sì fi kó èso wọn jọ.
Шест години да сееш нивите си и шест години да режеш лозето си и да събираш плода му;
4 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje kí ilẹ̀ náà ní ìsinmi: ìsinmi fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ.
а седмата година да бъде събота за тържествена почивка на земята, събота на Господа; в нея да не сееш нивата си и да не режеш лозето си.
5 Ẹ má ṣe kórè ohun tí ó tìkára rẹ̀ hù, ẹ má ṣe kórè èso àjàrà ọgbà tí ẹ ò tọ́jú. Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ ní ìsinmi fún ọdún kan.
Да не жънеш и саморасла жетва, нито да обираш гроздето от нерязано лозе: година за тържествена почивка да бъде на земята.
6 Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ọdún ìsinmi ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún yín àní fún ẹ̀yin tìkára yín, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín, àwọn alágbàṣe àti àwọn tí ń gbé pẹ̀lú yín fún ìgbà díẹ̀.
Произведеното през тая събота на земята ще ви бъде за храна: на тебе, на слугата ти, на слугинята ти, на наемника ти и на чужденеца, който се е заселел при тебе;
7 Fún àwọn ohun ọ̀sìn yín, àti àwọn ẹranko búburú ní ilẹ̀ yín. Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ẹ lè jẹ.
на добитъка ти, и на животните, които са в земята ти, всичкото нейно произведение ще бъде за храна.
8 “‘Ọdún ìsinmi méje èyí tí í ṣe ọdún mọ́kàndínláàádọ́ta ni kí ẹ kà.
Да си изброиш седем седмици от години, седем пъти по седем години, та, като ти мине времето на седем седмици от години,
9 Lẹ́yìn náà, kí ẹ fọn fèrè ní gbogbo ibikíbi ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́. Ní ọjọ́ ètùtù yìí, ẹ fọn fèrè yíká gbogbo ilẹ̀ yín.
тогава, на десетия ден от седмия месец, да накараш да се затръби с възклицание; в деня на умилостивението да накарате да се затръби из цялата ви земя.
10 Ẹ ya àádọ́ta ọdún náà sọ́tọ̀ kí ẹ sì kéde òmìnira fún gbogbo ẹni tí ń gbé ilẹ̀ náà. Yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Kí olúkúlùkù padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀ àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ̀.
И да осветите петдесетата година и да прогласите освобождение из цялата земя на всичките й жители; това ще ви бъде юбилей, когато ще се върнете, всеки на на притежанието си, и ще се върнете, всеки при семейството си.
11 Àádọ́ta ọdún ni yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Ẹ má ṣe gbin ohunkóhun, ẹ kò sì gbọdọ̀ kórè ohun tí ó hù fúnra rẹ̀ tàbí kí ẹ kórè ọgbà àjàrà tí ẹ kò dá.
Петдесетата година да ви бъде юбилейна година; през нея да не сеете, нито да жънете самораслото, нито да берете нерязаното лозе.
12 Torí pé ọdún ìdásílẹ̀ ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún yín. Ẹ jẹ ohun tí ẹ mú jáde nínú oko náà.
Защото това е юбилей; той нека ви бъде свет; от полето да се храните с произведеното от него.
13 “‘Ní ọdún ìdásílẹ̀ yìí, kí olúkúlùkù gbà ohun ìní rẹ̀ padà.
В тая юбилейна година да се върнете, всеки на притежанието си.
14 “‘Bí ẹ bá ta ilẹ̀ fún ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín tàbí bí ẹ bá ra èyíkéyìí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ.
И ако продадеш нещо на ближния си, или купиш нещо от ближния си, да се не онеправдавате едни други;
15 Kí ẹ ra ilẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn yín ní gẹ́gẹ́ bí iye owó tí ó kù kí ọdún ìdásílẹ̀ pé, kí òun náà sì ta ilẹ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí iye ọdún rẹ̀ tókù láti kórè.
но според числото на годините след юбилея да купуваш от ближния си, и според числото на годините на плодосъбирането да ти продава.
16 Bí iye ọdún rẹ̀ bá gùn, kí iye owó rẹ̀ pọ̀, bí iye ọdún rẹ̀ bá kúrú, kí iye owó rẹ̀ kéré, torí pé ohun tí ó tà gan an ní iye èso rẹ̀.
Според колкото са по-много годините, ще повишиш цената му, и според колкото са по-малко годините, ще понижиш цената му; защото той ти продава според числото на плодосъбиранията.
17 Ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ, ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Да се не онеправдавате един други; но да се боиш от своя Бог; защото Аз съм Иеова вашият Бог.
18 “‘Ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà mi, kí ẹ sì kíyèsi láti pa òfin mi mọ́, kí ẹ ba à le máa gbé láìléwu ní ilẹ̀ náà.
И тъй, да държите повеленията Ми, да пазите съдбите Ми и да ги вършите, та да живеете безопасно на земята.
19 Nígbà yìí ni ilẹ̀ náà yóò so èso rẹ̀, ẹ ó sì jẹ àjẹyó, ẹ ó sì máa gbé láìléwu.
Земята ще дава плодовете си; и вие ще ядете до насита и ще живеете безопасно на нея.
20 Ẹ le béèrè pé, “Kí ni àwa ó jẹ ní ọdún keje, bí a kò bá gbin èso tí a kò sì kórè?”
И ако речете: Какво ще ядем в седмата година, като не посеем, нито съберем плодовете си?
21 Èmi ó pèsè ìbùkún sórí yín tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ yín yóò so èso tó tó fún ọdún mẹ́ta lẹ́yìn rẹ̀.
Тогава ще заповядам така да се благослови за вас шестата година, щото ще роди плод за три години.
22 Bí ẹ bá gbin èso yín ní ọdún kẹjọ, àwọn èso ti tẹ́lẹ̀ ní ẹ ó máa jẹ, títí tí ìkórè ti ọdún kẹsànán yóò fi dé.
А в осмата година ще сеете и ще ядете от старите плодове до деветата година; догдето се съберат нейните плодове ще ядете старите запаси.
23 “‘Ẹ má ṣe ta ilẹ̀ yín ní àtàpa torí pé ẹ̀yin kọ́ lẹ ni ín, ti Ọlọ́run ni, ẹ̀yin jẹ́ àjèjì àti ayálégbé.
Земята да се не продава за всегда, понеже земята е Моя; защото вие сте чужденци и пришелци при Мене.
24 Ní gbogbo orílẹ̀-èdè ìní yín, ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìràpadà ilẹ̀ náà.
За това в цялата земя, която притежавате, позволявайте откупуване на земята.
25 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín bá tálákà, dé bi pé ó ta ara àwọn ẹrù rẹ̀, kí ará ilé rẹ̀ tí ó súnmọ́ ọ ra ohun tí ó tà padà.
Ако осиромашее брат ти и продаде нещо от притежанието си, нека дойде на-близкият му сродник и да купи онова, което брат му е продал.
26 Ẹni tí kò ní ẹni tó lè rà á padà fún un, tí òun fúnra rẹ̀ sì ti lọ́rọ̀, tí ó sì ní ànító láti rà á.
Но ако човекът няма сродник да го откупи, и, като се улесни, сам намери с какво да го откупи,
27 Kí ó mọ iye owó tí ó jẹ fún iye ọdún tí ó tà á, kí ó dá iye tí ó kù padà fún ẹni tí ó tà á fún, lẹ́yìn náà, ó lè padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
тогава нека сметне годините от продажбата му, и нека повърне излишъка на онзи, комуто го е продал, и нека се върне на притежанието си.
28 Ṣùgbọ́n bí kò bá rí ọ̀nà àti san án padà fún un. Ohun tí ó tà wà ní ìkáwọ́ ẹni tí ó rà á títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ó dá a padà fún ẹni tí ó ni i ní ọdún ìdásílẹ̀, ẹni tí ó ni í tẹ́lẹ̀ lè tún padà gbà ohun ìní rẹ̀.
Но ако не може да намери колкото трябва да плати, тогава продаденото да остане в ръката на купувача му до юбилейната година; и в юбилейната година; и в юбилея да се освободи, и той да се върне на притежанието си.
29 “‘Bí arákùnrin kan bá ta ilé gbígbé kan ní ìlú olódi, kí ó rà á padà ní ìwọ̀n ọdún kan sí àkókò tí ó tà á, ní ìwọ̀n ọdún kan ni kí ó rà á padà.
Ако някой продаде къщата за живеене в ограден град, тогава може да я откупи в разстояние на една година от продажбата й; за една цяла година от продажбата й; за една цяла година той ще има право да я откупи.
30 Ṣùgbọ́n bí kò bá rà á padà láàrín ọdún náà ilé náà tí ó wà láàrín ìlú ni kí ó yọ̀ǹda pátápátá fún ẹni tí ó rà á, àti àwọn ìdílé rẹ̀. Kí wọ́n má da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
Но ако се не откупи до изтичането на една цяла година тогава оная къща, който е в ограден град, да се потвърди за всегда на купувача й във всичките му поколения в юбилей да се не освобождава.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ilé tí ó wà ní abúlé láìní odi ni kí a kà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ oko, a lè rà wọ́n padà, kí wọ́n sì da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
Но същите в неоградените села да се считат, както полетата на земята; те може да се откупуват и да се освобождават в юбилей.
32 “‘Àwọn ọmọ Lefi ní ẹ̀tọ́, nígbàkígbà láti ra ilẹ̀ wọn, tí ó jẹ́ ohun ìní wọn ní àwọn ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Lefi.
Обаче в левитските градове, лавитите могат когато да е да откупуват къщите в градовете, които притежават.
33 Torí náà ohun ìní àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n rà padà, fún àpẹẹrẹ, èyí ni pé ilẹ̀ tí a bá tà ní ìlúkílùú tí ó jẹ́ tiwọn, ó sì gbọdọ̀ di dídápadà ní ọdún ìdásílẹ̀, torí pé àwọn ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú àwọn Lefi ni ìní wọn láàrín àwọn ará Israẹli.
И ако някой купи къща от левитите, тогава продадената къща вътре в града, който притежава да се освободи в юбилей; защото къщите в градовете на левитите са тяхно притежание между израилтяните.
34 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí wọ́n ti ń da ẹran tí ó jẹ́ ti ìlú wọn, wọn kò gbọdọ̀ tà wọ́n, ilẹ̀ ìní wọn láéláé ni.
А полето на пасбището на градовете им да се не продава, защото им е вечно притежание.
35 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà tí kò sì le è pèsè fún àìní ara rẹ̀, ẹ pèsè fún un bí ẹ ti ń ṣe fún àwọn àlejò tàbí àwọn tí ẹ gbà sílé: kí ó ba à le è máa gbé láàrín yín.
Ако осиромашее брат ти, и видиш, че ръката му трепери, тогава да му помогнеш, като на чужденец или пришелец, за да живее при тебе.
36 Ẹ kò gbọdọ̀ gba èlé kankan lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ bẹ̀rù Olúwa kí arákùnrin yín le è máa gbé láàrín yín.
Да не му вземеш лихва или печалба, но да се боиш от своя Бог та да живеете брат ти при тебе.
37 Ẹ má ṣe gba èlé lórí owó tí ẹ yá a bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ èrè lórí oúnjẹ tí ẹ tà fún un.
Парите си да не му дадеш с лихва, нито храната си да му дадеш за печалба.
38 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti láti fún yín ní ilẹ̀ Kenaani àti láti jẹ́ Ọlọ́run yín.
Аз съм Господ вашият Бог, Който ви изведох из Египетската земя, за да ви дам Ханаанската земя, и да бъда ваш Бог.
39 “‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ fún ọ bí ẹrú. Má ṣe lò ó bí ẹrú.
Ако осиромашее брат ти при тебе и ти се продаде, да го не натовариш с робска работа.
40 Jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ rẹ bí alágbàṣe tàbí àlejò láàrín yín, kí ó máa ṣiṣẹ́ sìn ọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀.
Нека бъде той като наемник или пришелец при тебе; нека ти работи до юбилейната година;
41 Nígbà náà ni kí ó yọ̀ǹda òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n padà sí ìdílé wọn àti sí ilẹ̀ ìní baba wọn.
тогава да си излезе от тебе, той и чадата му с него, и да се върне при семейството си, и нека ти работи до юбилейната година;
42 Torí pé ìránṣẹ́ mi ni àwọn ará Israẹli jẹ́. Ẹni tí mo mú jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, torí èyí ẹ kò gbọdọ̀ tà wọ́n lẹ́rú.
Защото те са Мои слуги, които изведох из Египетската земя; да се не продават като роби;
43 Ẹ má ṣe rorò mọ́ wọn: ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run yín.
да не господаруваш над него жестоко, но да се боиш от своя Бог.
44 “‘Àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín lè jẹ́ láti orílẹ̀-èdè tí ó yí yín ká, ẹ lè ra àwọn ẹrú wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn.
А колкото за робите и робините, които ще имаш, - от народите, които са около вас, от тях да купуваш роби и робини.
45 Bákan náà, ẹ sì le è ra àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín, àti àwọn ìdílé wọn tí a bí sáàrín yín. Wọn yóò sì di ohun ìní yín.
Още и от чадата на чужденците, които са пришелци между вас, от тях да купувате, и от техните семейства, които са между вас, които те са родили в земята ви; те да ви бъдат притежание.
46 Ẹ lè fi wọ́n sílẹ̀ bí ogún fún àwọn ọmọ yín, wọ́n sì lè sọ wọ́n di ẹrú títí láé. Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rorò mọ́ ọmọ Israẹli kankan.
И да ги оставите в наследство на чадата си; те да ги наследяват подир вас, като притежание; винаги от тях да бъдат вашите роби; но над братята си, израилтяните, да не господарувате един над друг жестоко.
47 “‘Bí àlejò kan láàrín yín tàbí ẹni tí ń gbé àárín yín fún ìgbà díẹ̀ bá lọ́rọ̀ tí ọmọ Israẹli sì tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ lẹ́rú fún àlejò tàbí ìdílé àlejò náà.
Ако чужденец или пришелецът, който живее при тебе, се замогне, а брат ти осиромашее при него, та се продаде на чужденеца или на пришелеца при тебе, или на кого да е от семейството на чужденеца,
48 Ó lẹ́tọ̀ọ́ si ki a rà á padà lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ta ara rẹ̀. Ọ̀kan nínú ìbátan rẹ̀ le è rà á padà.
то, след като се продаде, той може да се откупи; един от братята му може да го откупи;
49 Àbúrò baba rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá tan nínú ìdílé rẹ̀ le è rà wọ̀n padà. Bí ó bá sì ti lọ́rọ̀, ó lè ra ara rẹ̀ padà.
или стрикът му или стриковият му син може да го откупи, или някой близък сродник от семейството му може да го откупи, или ако той се е улеснил, може сам да откупи сабе си.
50 Kí òun àti olówó rẹ̀ ka iye ọdún tí ó ta ara rẹ̀ títí dé ọdún ìdásílẹ̀ kí iye owó ìdásílẹ̀ rẹ̀ jẹ́ iye tí wọ́n ń san lórí alágbàṣe fún iye ọdún náà.
Тогава нека сметне с купувача си от годината, когато му се е продал до юбилейната година, така, че цената, за която се е продал, да бъде съразмерно с с числото на годините; да му се сметне свързано с времето на наемник.
51 Bí iye ọdún rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù bá pọ̀, kí iye owó fún ìràpadà rẹ̀ pọ̀.
Ако остават още много години, съразмерно с тях да възвърне за откупването си от парите, с които е бил купен.
52 Bí ó bá sì ṣe pé kìkì ọdún díẹ̀ ni ó kù títí di ọdún jubili, kí ó ṣe ìṣirò rẹ̀, kí ó sì san owó náà bí iye ìṣirò rẹ̀ padà.
Но ако остават малко години до юбилейната година, нека пресметне и съразмерно с годините да възвърне за откупуването си.
53 Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
Като годишен наемник да бъде при него; той да не господарува над него жестоко пред тебе.
54 “‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
Но ако така се не откупи, тогава да си излезе в юбилейната година, той и чадата му с него,
55 Nítorí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Ejibiti wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
защото израилтяните са Мои слуги; те са Мои слуги, които изведох из Египетската земя. Аз съм Господ вашият Бог.

< Leviticus 25 >