< Leviticus 24 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Gospod je spregovoril Mojzesu, rekoč:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara olifi wá láti fi tan iná, kí fìtílà lè máa jò láì kú.
»Zapovej Izraelovim otrokom, da ti prinesejo čistega olja iz stolčenih oliv za svetlobo, da bi svetilke nenehno gorele.
3 Lẹ́yìn aṣọ ìkélé ti ibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Aaroni ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójoojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀.
Zunaj zagrinjala pričevanja, v šotorskem svetišču skupnosti, bo Aron to nenehno ukazoval od večera do jutra pred Gospodom. To bo zakon na veke v vaših rodovih.
4 Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá fìtílà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójoojúmọ́.
Svetike bo nenehno oskrboval na čistem svečniku pred Gospodom.
5 “Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan.
Vzel boš fino moko in iz nje spekel dvanajst kolačev. Dve desetinki bosta v enem kolaču.
6 Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fà mẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó wúrà bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa.
Postavil jih boš v dve vrsti, šest v vrsto, na čisto mizo pred Gospodom.
7 Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ sísun sí Olúwa.
Nad vsako vrsto boš dal čisto kadilo, da bo ta lahko na kruhu za spomin, torej ognjena daritev Gospodu.
8 Àkàrà yìí ni kí ẹ gbé wá síwájú Olúwa nígbàkígbà, lọ́ṣọ̀ọ̀ṣẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé.
Vsak šabat ga bo nenehno postavljal v vrsto pred Gospodom, vzetega od Izraelovih otrok z večno zavezo.
9 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni í. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojoojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”
To bo Aronovo in od njegovih sinov in to bodo jedli na svetem prostoru, kajti to mu je najsvetejše od daritev Gospodu, narejenih z ognjem, z večnim zakonom.«
10 Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Israẹli baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Ejibiti. Ó jáde lọ láàrín àwọn ọmọ Israẹli, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrín òun àti ọmọ Israẹli kan.
Sin Izraelke, katere oče je bil Egipčan, je odšel ven med Izraelove otroke in ta sin izraelske ženske in mož iz Izraela sta se skupaj prepirala v taboru.
11 Ọmọkùnrin arábìnrin Israẹli náà sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè, wọ́n sì mú un tọ Mose wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Ṣelomiti, ọmọbìnrin Debiri, ti ẹ̀yà Dani.)
Sin Izraelke je izrekal bogokletje proti Gospodovemu imenu in preklinjal. Privedli so ga k Mojzesu. (In ime njegove matere je bilo Šelomíta, hči Dibríja, iz Danovega rodu.)
12 Wọ́n fi í sínú túbú kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.
Dali so ga pod stražo, da bi jim bil lahko pokazan Gospodov um.
13 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
Gospod je spregovoril Mojzesu, rekoč:
14 “Mú asọ̀rọ̀-òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fihàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa.
»Privedite tistega, ki je klel zunaj tabora, in naj vsi, ki so ga slišali, položijo roke na njegovo glavo in naj ga vsa skupnost kamna.
15 Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Izraelovim otrokom boš govoril, rekoč: ›Kdorkoli preklinja svojega Boga, bo nosil svoj greh.
16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọ bíbí Israẹli, bí ó bá ti sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.
Kdor preklinja Gospodovo ime, bo zagotovo usmrčen in zagotovo ga bo vsa skupnost kamnala; tako tujca, kakor tistega, ki je rojen v deželi, ko preklinja Gospodovo ime, bo usmrčen.
17 “‘Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.
Kdor ubija kateregakoli človeka, bo zagotovo usmrčen.
18 Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.
Kdor ubije žival, bo to poplačal; žival za žival.
19 Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára, ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.
Če človek povzroči madež na svojem bližnjem; kakor je storil on, tako naj bo to storjeno njemu;
20 Ẹ̀yà fún ẹ̀yà, ojú fún ojú, eyín fún eyín; bí òun ti ṣe àbùkù sí ara ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kí a ṣe sí i.
zlom za zlom, oko za oko, zob za zob. Kakor je on na človeku povzročil pomanjkljivost, tako naj bo njemu ponovno storjeno.
21 Ẹni tí ó bá sì lu ẹran pa, kí ó sán an padà; ẹni tí ó bá sì lu ènìyàn pa, a ó pa á.
Kdor ubije žival, bo to povrnil, kdor pa ubije človeka, bo usmrčen.
22 Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Imeli boste eno vrsto postave, prav tako za tujca, kakor za nekoga iz svoje lastne dežele, kajti jaz sem Gospod, vaš Bog.‹«
23 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀-òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.
Mojzes je Izraelovim otrokom spregovoril, da naj tistega, ki je preklet, privedejo ven iz tabora in kamnajo s kamni. In Izraelovi otroci so storili tako, kakor je Gospod zapovedal Mojzesu.

< Leviticus 24 >