< Leviticus 24 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara olifi wá láti fi tan iná, kí fìtílà lè máa jò láì kú.
Poruncește copiilor lui Israel, ca ei să îți aducă untdelemn pur de măsline bătute, pentru lumină, pentru a face ca lămpile să ardă continuu.
3 Lẹ́yìn aṣọ ìkélé ti ibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Aaroni ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójoojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀.
În afara perdelei mărturiei, în tabernacolul întâlnirii, Aaron să le pună în ordine de seara până dimineața înaintea DOMNULUI, continuu; acesta să fie un statut veșnic în toate generațiile voastre.
4 Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá fìtílà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójoojúmọ́.
Să pună în ordine lămpile pe sfeșnicul cel pur, continuu înaintea DOMNULUI.
5 “Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan.
Și să iei floarea făinii și să coci douăsprezece turte din ea, două zecimi să fie într-o turtă.
6 Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fà mẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó wúrà bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa.
Și să le pui pe două rânduri, șase pe un rând, pe masa pură înaintea DOMNULUI.
7 Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ sísun sí Olúwa.
Și să pui tămâie pură pe fiecare rând, ca aceasta să fie pe pâine ca o amintire, o ofrandă făcută prin foc DOMNULUI.
8 Àkàrà yìí ni kí ẹ gbé wá síwájú Olúwa nígbàkígbà, lọ́ṣọ̀ọ̀ṣẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé.
În fiecare sabat să o pună în ordine înaintea DOMNULUI, continuu, fiind luată de la copiii lui Israel printr-un legământ veșnic.
9 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni í. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojoojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”
Și aceasta să fie a lui Aaron și a fiilor săi; și ei să o mănânce în locul sfânt, pentru că aceasta este preasfântă pentru el dintre ofrandele făcute prin foc DOMNULUI, printr-un statut veșnic.
10 Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Israẹli baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Ejibiti. Ó jáde lọ láàrín àwọn ọmọ Israẹli, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrín òun àti ọmọ Israẹli kan.
Și fiul unei femei israelite, al cărui tată era egiptean, a ieșit dintre copiii lui Israel; și acest fiu al femeii israelite și un bărbat al lui Israel s-au luptat în tabără;
11 Ọmọkùnrin arábìnrin Israẹli náà sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè, wọ́n sì mú un tọ Mose wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Ṣelomiti, ọmọbìnrin Debiri, ti ẹ̀yà Dani.)
Și fiul femeii israelite a blasfemiat numele DOMNULUI și a blestemat. Iar ei l-au adus la Moise (și numele mamei sale era Șelomit, fiica lui Dibri, din tribul lui Dan);
12 Wọ́n fi í sínú túbú kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.
Și l-au pus sub pază, ca mintea DOMNULUI să le fie arătată.
13 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
14 “Mú asọ̀rọ̀-òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fihàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa.
Scoate pe cel ce a blestemat în afara taberei; și toți cei ce l-au auzit să își pună mâinile pe capul lui și toată adunarea să îl ucidă cu pietre.
15 Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Și să vorbești copiilor lui Israel, spunând: Oricine blestemă pe Dumnezeul său să își poarte păcatul.
16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọ bíbí Israẹli, bí ó bá ti sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.
Și cel ce a blasfemiat numele DOMNULUI, acela cu siguranță să fie dat morții și toată adunarea să îl ucidă negreșit cu pietre; cel străin în același fel ca cel născut în țară, când el blasfemiază numele DOMNULUI, să fie dat morții.
17 “‘Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.
Și cel ce ucide vreun om să fie cu siguranță dat morții.
18 Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.
Și cel ce ucide un animal va plăti; animal pentru animal.
19 Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára, ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.
Și dacă un bărbat provoacă o vătămare aproapelui său; precum a făcut, astfel să îi fie făcut;
20 Ẹ̀yà fún ẹ̀yà, ojú fún ojú, eyín fún eyín; bí òun ti ṣe àbùkù sí ara ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kí a ṣe sí i.
Spărtură pentru spărtură, ochi pentru ochi, dinte pentru dinte, precum a provocat o vătămare într-un om, astfel să îi fie făcut.
21 Ẹni tí ó bá sì lu ẹran pa, kí ó sán an padà; ẹni tí ó bá sì lu ènìyàn pa, a ó pa á.
Și cel ce ucide o vită, va plăti vita; și cel ce ucide un om, să fie dat morții.
22 Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Să aveți un singur fel de lege, pentru străin în același fel ca pentru unul din țara voastră, pentru că eu sunt DOMNUL Dumnezeul vostru.
23 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀-òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.
Și Moise a vorbit copiilor lui Israel, ca ei să scoată pe cel ce a blestemat în afara taberei și să îl ucidă cu pietre. Și copiii lui Israel au făcut precum DOMNUL i-a poruncit lui Moise.

< Leviticus 24 >