< Leviticus 23 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
Och Herren talade med Mose, och sade:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, àwọn àjọ̀dún ti Olúwa èyí tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí àjọ̀dún tí a yàn.
Tala till Israels barn, och säg till dem: Desse äro Herrans högtider, som I skolen kalla heliga och mina högtider, då I sammankommen.
3 “‘Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ le fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi. Ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé. Ọjọ́ ìsinmi Olúwa ni.
Sex dagar skall du göra ditt arbete; men den sjunde dagen är den store helge Sabbathen, då I tillhopakommen. Intet arbete skolen I göra på honom; förty det är Herrans Sabbath, ehvar I bon.
4 “‘Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọdún tí Olúwa yàn, àjọ̀dún tí a yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde lákokò wọn.
Desse äro de Herrans högtider, dem I skolen kalla helga högtider, då I sammankommen:
5 Àjọ ìrékọjá Olúwa bẹ̀rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
På fjortonde dagen i första månadenom om aftonen är Herrans Passah;
6 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ni àjọ̀dún àkàrà àìwú tí Olúwa yó bẹ̀rẹ̀, fún ọjọ́ méje ni ẹ gbọdọ̀ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
Och på den femtonde i samma månadenom är Herrans osyrade bröds högtid; då skolen I äta osyradt bröd i sju dagar.
7 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan nínú rẹ̀.
Den förste dagen skall kallas helig ibland eder, då I sammankommen; då skolen I intet tjenstearbete göra;
8 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa. Ní ọjọ́ keje, ẹ pe ìpàdé àjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.’”
Och offra Herranom i sju dagar. Den sjunde dagen skall ock helig kallas, då I tillhopakommen; på honom skolen I ock intet tjenstearbete göra.
9 Olúwa sọ fún Mose pe,
Och Herren talade med Mose, och sade:
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi yóò fún yín, tí ẹ bá ń ṣe ìkórè, kí ẹ mú síírí ọkà àkọ́kọ́ tí ẹ kórè wá fún àlùfáà.
Tala till Israels barn, och säg till dem: När I kommen i landet, som jag eder gifva skall, och I skolen uppskära, så skolen I föra till Presten en kärfva, förstlingen af edro säd.
11 Kí ó fi síírí ọkà náà níwájú Olúwa, kí ó le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín: kí àlùfáà fì í ní ọjọ́ kejì ìsinmi.
Då skall den kärfven varda veftad för Herranom, att det skall blifva tacknämligit af eder. Och detta skall Presten göra på den andra dagen näst efter Sabbathen.
12 Ní ọjọ́ tí ẹ bá fi síírí ọkà náà, kí ẹ mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan láìní àbùkù rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
Och I skolen på den dagen, då edar kärfve veftad varder, göra Herranom ett bränneoffer af ett lamb, det utan vank och årsgammalt är;
13 Pẹ̀lú ọrẹ ọkà rẹ tí ó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi òróró pò ọrẹ tí a fi iná ṣe fún Olúwa òórùn dídùn pẹ̀lú ọrẹ ohun mímu rẹ̀ tí í ṣe ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì (èyí jẹ́ lita kan).
Samt med spisoffret, två tiungar semlomjöl, blandadt med oljo, till en söt lukts offer Herranom; dertill dryckoffer, en fjerding af ett hin vin;
14 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ àkàrà kankan tàbí kí ẹ sun ọkà tuntun títí di ọjọ́ tí ẹ fi mú ọrẹ yín wá fún Ọlọ́run yín. Èyí ni ìlànà ayérayé fún ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Och skolen intet äta af det nya, hvarken bröd, torkad ax eller korn, intill den dagen, då I bären edrom Gud offer. Det skall vara en evig rätt till edra efterkommande, ehvar I bon.
15 “‘Ẹ ka ọ̀sẹ̀ méje gbangba, láti ọjọ́ kejì ọjọ́ ìsinmi, àní ọjọ́ tí ẹ mú ìdì ọkà fífì wá.
Sedan skolen I räkna ifrå den andra Sabbathsdagen, då I båren veftekärfvan fram, sju hela Sabbather;
16 Ẹ ka àádọ́ta ọjọ́ títí dé ọjọ́ kejì ọ̀sẹ̀ méjèèje, kí ẹ sì mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Olúwa.
Intill den andra dagen efter den sjunde Sabbathen; det är, femtio dagar skolen I räkna och offra Herranom nytt spisoffer;
17 Láti ibikíbi tí ẹ bá ń gbé, ẹ mú ìṣù àkàrà méjì tí a fi òsùwọ̀n ìdá méjì nínú mẹ́wàá tí efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi ìwúkàrà ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì àkọ́so sí Olúwa.
Och skolen offra det af alla edra boningar, nämliga tu veftebröd af två tiungar semlomjöl, syradt och bakadt Herranom till en förstling;
18 Ẹ fi akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù, ọmọ màlúù kan àti àgbò méjì kún àkàrà yìí, wọn yóò jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu wọn, àní ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn ni sí Olúwa.
Och skolen frambära med edor bröd sju årsgamla lamb utan vank, och en ung stut, och två vädrar. Det skall vara Herrans bränneoffer, spisoffer och dryckoffer; det är en söt lukts offer Herranom.
19 Lẹ́yìn náà kí ẹ fi akọ ewúrẹ́ kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan fún ọrẹ àlàáfíà.
Dertill skolen I göra en getabock till syndoffer, och tu årsgamla lamb till tackoffer.
20 Kí àlùfáà fi ọ̀dọ́-àgùntàn méjèèjì náà níwájú Olúwa bí i ọrẹ fífì pẹ̀lú oúnjẹ àkọ́so wọn jẹ́ ọrẹ mímọ́ sí Olúwa fún àlùfáà.
Och Presten skall vefta det med förstlingsbrödena för Herranom till de tu lamben; och skall vara Herranom heligt, och höra Presten till.
21 Ní ọjọ́ yìí náà ni kí ẹ kéde ìpàdé àjọ mímọ́: ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀ níbi yówù tí ẹ ń gbé.
Och I skolen utropa denna dagen; ty han skall kallas helig ibland eder, då I sammankommen; intet tjenstearbete skolen I göra. En evig rätt skall det vara, till edra efterkommande, ehvar I bon.
22 “‘Nígbà tí ẹ bá kórè ilẹ̀ yín ẹ má ṣe kórè dé ìkangun oko yín, tàbí kí ẹ padà gé èyí tí ó ṣẹ́kù sílẹ̀ nínú ìkórè yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn tálákà àti àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
När I uppskären sädena i edro lande, skolen I icke allt uppskära på åkren, och icke alltför noga upphemta; utan skolen det låta dem fattigom, och främlingom. Jag är Herren edar Gud.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och Herren talade med Mose, och sade:
24 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, kí ẹ ní ọjọ́ ìsinmi, ìpàdé àjọ mímọ́ tí a fi fèrè fífọn ṣe ìrántí.
Tala med Israels barnom, och säg: På första dagen i sjunde månadenom skolen I hålla blåsandens helga Sabbath till åminnelse, då I sammankommen.
25 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojúmọ́, ṣùgbọ́n ẹ mú ọrẹ tí a fi iná sun wá síwájú Olúwa.’”
Då skolen I intet tjenstearbete göra; och skolen göra Herranom offer.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och Herren talade med Mose, och sade:
27 “Ọjọ́ kẹwàá oṣù keje yìí ni ọjọ́ ètùtù. Ẹ ni ìpàdé àjọ mímọ́, kí ẹ sì ṣẹ́ ara yín kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa.
På tionde dagen i denna sjunde månadenom är Försonedagen; den skall ibland eder kallas helig, att I tillhopakommen. Då skolen I späka edra kroppar, och offra Herranom.
28 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà, torí pé ọjọ́ ètùtù ni, nínú èyí tí a ń ṣe ètùtù fún yín níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
Och skolen intet arbete göra på denna dagen; ty det är en försonedag, att I skolen försonade varda för Herranom edrom Gud.
29 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣẹ́ ara rẹ̀ ní ọjọ́ náà ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ty hvilken icke späker sin kropp på denna dagen, den skall utrotad varda utu hans folk.
30 Èmi yóò pa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà run kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Och hvilken på denna dagen något arbete gör, den skall jag förgöra utu hans folk.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan rárá. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Derföre skolen I intet arbete göra. Det skall vara en evig rätt till edra efterkommande, ehvar I bon.
32 Ọjọ́ ìsinmi ni fún un yín, ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹsànán oṣù náà, títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó tẹ̀lé e, ni kí ẹ fi sinmi.”
Det är edar store Sabbath, att I skolen späka edra kroppar. På nionde dagen i månadenom om aftonen skolen I hålla denna Sabbath, ifrån aftonen och åter intill aftonen.
33 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och Herren talade med Mose, och sade:
34 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje ni kí àjọ̀dún ọdún àgọ́ ti Olúwa bẹ̀rẹ̀ kí ó sì wà títí di ọjọ́ méje.
Tala med Israels barn, och säg: På femtonde dagen i denna sjunde månadenom är löfhyddohögtid i sju dagar Herranom.
35 Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìpàdé mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ ojúmọ́.
Den förste dagen skall kallas helig, att I sammankommen; intet tjenstearbete skolen I göra.
36 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá, ní ọjọ́ kẹjọ, ẹ pe ìpàdé mímọ́ kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa, èyí jẹ́ ìpàdé tí ó gbẹ̀yìn; ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojoojúmọ́.
I sju dagar skolen I offra Herranom. Den åttonde dagen skall ock kallas helig, att I sammankommen. Och I skolen göra edart offer Herranom; ty det är samlingesdag; intet tjenstearbete skolen I göra.
37 (“‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí Olúwa ti yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí i àjọ̀dún tí a yàn fún mímu àwọn ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa wá—ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà, ọrẹ ẹbọ àti ọrẹ ohun mímu, fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Desse äro Herrans helgedagar, de I skolen heliga hålla, att I sammankommen, och gören Herranom offer, bränneoffer, spisoffer, dryckoffer, och annor offer, hvart efter sin dag.
38 Àwọn ọrẹ wọ̀nyí wà ní àfikún pẹ̀lú àwọn ọrẹ ọjọ́ ìsinmi Olúwa, àti pẹ̀lú ẹ̀bùn yín àti ohunkóhun tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ àti gbogbo ọrẹ àtinúwá yín fún Olúwa.)
Förutan det Herrans Sabbath, och edra gåfvor och löfte, och friviljoga gåfvor äro, som I gifven Herranom;
39 “‘Torí náà, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti kórè ilẹ̀ náà, ẹ ṣe àjọ̀dún yìí fún Olúwa ní ọjọ́ méje. Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ọjọ́ kẹjọ pẹ̀lú si tún jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
Så skolen I nu på femtonde dagen i sjunde månadenom, när I hafven i hus samlat årsväxten af landena, hålla Herrans högtid i sju dagar. På första dagenom är Sabbath, och på åttonde dagenom är ock Sabbath.
40 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, kí ẹ mú àṣàyàn èso láti orí igi dáradára, imọ̀ ọ̀pẹ, àti ẹ̀ka igi tó rúwé, àti igi wílò odò, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín fún ọjọ́ méje.
Och I skolen på första dagenom taga frukt af skön trä, palmtelningar, och qvistar af tjockqvistadt trä, och pilträ; och vara glade i sju dagar för Herranom edrom Gud;
41 Ẹ ṣe èyí ní àjọ̀dún sí Olúwa fún ọjọ́ méje lọ́dọọdún. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, ẹ ṣe é ní oṣù keje.
Och skolen alltså hålla Herranom den högtiden om året i sju dagar; det skall vara en evig rätt till edra efterkommande, att de så skola hålla helg uti den sjunde månaden.
42 Ẹ gbé inú àgọ́ fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ọmọ bíbí Israẹli gbé nínú àgọ́.
Sju dagar skolen I bo i löfhyddor. Den en inländning är i Israel, han skall bo i löfhyddor;
43 Kí àwọn ìran yín le mọ̀ pé mo mú kí Israẹli gbé nínú àgọ́, nígbà tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Att edra efterkommande skola veta, huru jag hafver låtit Israels barn bo i hyddor, då jag förde dem utur Egypti land. Jag är Herren edar Gud.
44 Báyìí ni Mose kéde àwọn àjọ̀dún tí a yàn Olúwa fún àwọn ọmọ Israẹli.
Och Mose sade Israels barnom om denna Herrans helg.

< Leviticus 23 >