< Leviticus 23 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, àwọn àjọ̀dún ti Olúwa èyí tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí àjọ̀dún tí a yàn.
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Uroczyste święta PANA, które będziecie ogłaszać jako święte zgromadzenia. One są moimi uroczystymi świętami.
3 “‘Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ le fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi. Ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé. Ọjọ́ ìsinmi Olúwa ni.
Przez sześć dni będziecie wykonywać pracę, ale siódmy dzień będzie szabatem odpoczynku, świętym zgromadzeniem, nie będziecie wykonywać [wtedy] żadnej pracy. Jest to szabat PANA we wszystkich waszych domach.
4 “‘Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọdún tí Olúwa yàn, àjọ̀dún tí a yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde lákokò wọn.
Oto uroczyste święta PANA, święte zgromadzenia, które będziecie ogłaszać w ich oznaczonych porach:
5 Àjọ ìrékọjá Olúwa bẹ̀rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
W pierwszym miesiącu, czternastego dnia [tego miesiąca], o zmierzchu, jest Pascha PANA.
6 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ni àjọ̀dún àkàrà àìwú tí Olúwa yó bẹ̀rẹ̀, fún ọjọ́ méje ni ẹ gbọdọ̀ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
A piętnastego dnia tego miesiąca [będzie] Święto Przaśników dla PANA. Przez siedem dni będziecie jeść przaśne chleby.
7 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan nínú rẹ̀.
Pierwszego dnia będziecie mieć święte zgromadzenie. Nie będziecie wykonywać żadnej uciążliwej pracy.
8 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa. Ní ọjọ́ keje, ẹ pe ìpàdé àjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.’”
Lecz będziecie składali PANU ofiarę spalaną przez siedem dni. Siódmego dnia będzie święte zgromadzenie. Nie będziecie wykonywać żadnej ciężkiej pracy.
9 Olúwa sọ fún Mose pe,
I PAN powiedział do Mojżesza:
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi yóò fún yín, tí ẹ bá ń ṣe ìkórè, kí ẹ mú síírí ọkà àkọ́kọ́ tí ẹ kórè wá fún àlùfáà.
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Gdy wejdziecie do ziemi, którą wam daję, i będziecie zbierać plony, wtedy przyniesiecie do kapłana snop z pierwocin waszego plonu.
11 Kí ó fi síírí ọkà náà níwájú Olúwa, kí ó le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín: kí àlùfáà fì í ní ọjọ́ kejì ìsinmi.
I on będzie kołysał tym snopem przed PANEM, aby był przyjęty za was. Nazajutrz po sabacie kapłan będzie nim kołysał.
12 Ní ọjọ́ tí ẹ bá fi síírí ọkà náà, kí ẹ mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan láìní àbùkù rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
W dniu kołysania tym snopem złożycie w ofierze rocznego baranka bez skazy jako całopalenie dla PANA;
13 Pẹ̀lú ọrẹ ọkà rẹ tí ó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi òróró pò ọrẹ tí a fi iná ṣe fún Olúwa òórùn dídùn pẹ̀lú ọrẹ ohun mímu rẹ̀ tí í ṣe ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì (èyí jẹ́ lita kan).
Wraz z nim na ofiarę pokarmową dwie dziesiąte efy mąki pszennej zmieszanej z oliwą jako ofiarę spalaną PANU na miłą woń, a do tego także ofiarę z płynów, jedną czwartą hinu wina.
14 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ àkàrà kankan tàbí kí ẹ sun ọkà tuntun títí di ọjọ́ tí ẹ fi mú ọrẹ yín wá fún Ọlọ́run yín. Èyí ni ìlànà ayérayé fún ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Nie będziecie jeść chleba ani prażonego ziarna, ani świeżych kłosów aż do dnia, w którym przyniesiecie ofiarę waszemu Bogu. Będzie to wieczna ustawa przez wszystkie wasze pokolenia, we wszystkich waszych mieszkaniach.
15 “‘Ẹ ka ọ̀sẹ̀ méje gbangba, láti ọjọ́ kejì ọjọ́ ìsinmi, àní ọjọ́ tí ẹ mú ìdì ọkà fífì wá.
I odliczycie sobie od pierwszego dnia po szabacie, od dnia, w którym przynieśliście snop kołysania, siedem pełnych tygodni.
16 Ẹ ka àádọ́ta ọjọ́ títí dé ọjọ́ kejì ọ̀sẹ̀ méjèèje, kí ẹ sì mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Olúwa.
Aż do pierwszego dnia po siódmym szabacie odliczycie pięćdziesiąt dni i wtedy złożycie PANU nową ofiarę pokarmową.
17 Láti ibikíbi tí ẹ bá ń gbé, ẹ mú ìṣù àkàrà méjì tí a fi òsùwọ̀n ìdá méjì nínú mẹ́wàá tí efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi ìwúkàrà ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì àkọ́so sí Olúwa.
Przyniesiecie z waszych domów dwa chleby na [ofiarę] kołysania. Będą one z dwóch dziesiątych efy mąki pszennej, upieczone na zakwasie; [to] będą pierwociny dla PANA.
18 Ẹ fi akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù, ọmọ màlúù kan àti àgbò méjì kún àkàrà yìí, wọn yóò jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu wọn, àní ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn ni sí Olúwa.
Razem z tym chlebem złożycie w ofierze siedem rocznych baranków bez skazy, jednego młodego cielca i dwa barany. Będą one na ofiarę całopalenia dla PANA wraz z ich ofiarą pokarmową i ofiarami z płynów. Będzie to ofiara spalana na miłą woń dla PANA.
19 Lẹ́yìn náà kí ẹ fi akọ ewúrẹ́ kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan fún ọrẹ àlàáfíà.
Złożycie też jednego kozła na ofiarę za grzech i dwa roczne baranki na ofiarę pojednawczą.
20 Kí àlùfáà fi ọ̀dọ́-àgùntàn méjèèjì náà níwájú Olúwa bí i ọrẹ fífì pẹ̀lú oúnjẹ àkọ́so wọn jẹ́ ọrẹ mímọ́ sí Olúwa fún àlùfáà.
I kapłan będzie je kołysał razem z chlebem pierwocin na ofiarę kołysania przed PANEM wraz z dwoma barankami. One będą poświęcone PANU, [przeznaczone] dla kapłana.
21 Ní ọjọ́ yìí náà ni kí ẹ kéde ìpàdé àjọ mímọ́: ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀ níbi yówù tí ẹ ń gbé.
I ogłosicie w tym dniu święto; będzie to dla was święte zgromadzenie. Nie będziecie wykonywać żadnej uciążliwej pracy. [To będzie] wieczysta ustawa we wszystkich waszych domach, przez wszystkie wasze pokolenia.
22 “‘Nígbà tí ẹ bá kórè ilẹ̀ yín ẹ má ṣe kórè dé ìkangun oko yín, tàbí kí ẹ padà gé èyí tí ó ṣẹ́kù sílẹ̀ nínú ìkórè yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn tálákà àti àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
A gdy będziecie zbierać plony waszej ziemi, nie będziesz wycinać doszczętnie skraju twego pola i nie będziesz zbierać pokłosia twoich plonów. Zostawisz je dla ubogiego i przybysza. Ja jestem PAN, wasz Bóg.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
PAN dalej mówił do Mojżesza:
24 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, kí ẹ ní ọjọ́ ìsinmi, ìpàdé àjọ mímọ́ tí a fi fèrè fífọn ṣe ìrántí.
Przemów do synów Izraela i powiedz im: W siódmym miesiącu, pierwszego [dnia] tego miesiąca, będziecie mieli szabat, upamiętnienie przez trąbienie, święte zgromadzenie.
25 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojúmọ́, ṣùgbọ́n ẹ mú ọrẹ tí a fi iná sun wá síwájú Olúwa.’”
Nie będziecie wykonywać żadnej uciążliwej pracy, lecz złożycie PANU ofiarę spalaną.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
PAN powiedział jeszcze do Mojżesza:
27 “Ọjọ́ kẹwàá oṣù keje yìí ni ọjọ́ ètùtù. Ẹ ni ìpàdé àjọ mímọ́, kí ẹ sì ṣẹ́ ara yín kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa.
Lecz dziesiątego dnia tego siódmego miesiąca będzie Dzień Przebłagania. Będzie to dla was święte zgromadzenie; będziecie trapić swoje dusze i składać PANU ofiarę spalaną.
28 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà, torí pé ọjọ́ ètùtù ni, nínú èyí tí a ń ṣe ètùtù fún yín níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
W tym dniu nie będziecie wykonywać żadnej pracy, gdyż jest to Dzień Przebłagania, żeby dokonano dla was przebłagania przed PANEM, waszym Bogiem.
29 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣẹ́ ara rẹ̀ ní ọjọ́ náà ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Każdy bowiem człowiek, który nie będzie trapił swojej duszy tego dnia, zostanie wykluczony ze swego ludu.
30 Èmi yóò pa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà run kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Także każdego, kto będzie wykonywał jakąkolwiek pracę w tym dniu, zgładzę spośród jego ludu.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan rárá. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Nie będziecie wykonywać żadnej pracy; będzie to wieczysta ustawa przez wszystkie wasze pokolenia, we wszystkich waszych domach.
32 Ọjọ́ ìsinmi ni fún un yín, ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹsànán oṣù náà, títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó tẹ̀lé e, ni kí ẹ fi sinmi.”
Będzie to dla was szabat odpoczynku i będziecie trapić swoje dusze. Dziewiątego dnia tego miesiąca, wieczorem, od wieczora aż do wieczora, będziecie obchodzić wasz szabat.
33 Olúwa sọ fún Mose pé,
PAN dalej mówił do Mojżesza:
34 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje ni kí àjọ̀dún ọdún àgọ́ ti Olúwa bẹ̀rẹ̀ kí ó sì wà títí di ọjọ́ méje.
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Piętnastego dnia tego siódmego miesiąca będzie Święto Namiotów przez siedem dni dla PANA.
35 Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìpàdé mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ ojúmọ́.
Pierwszego dnia będzie święte zgromadzenie. Nie będziecie wykonywać żadnej uciążliwej pracy.
36 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá, ní ọjọ́ kẹjọ, ẹ pe ìpàdé mímọ́ kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa, èyí jẹ́ ìpàdé tí ó gbẹ̀yìn; ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojoojúmọ́.
Przez siedem dni będziecie składać PANU ofiarę spalaną. Ósmego dnia będziecie mieć święte zgromadzenie i będziecie składać PANU ofiarę spalaną. Jest to święto, żadnej uciążliwej pracy nie będziecie wykonywać.
37 (“‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí Olúwa ti yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí i àjọ̀dún tí a yàn fún mímu àwọn ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa wá—ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà, ọrẹ ẹbọ àti ọrẹ ohun mímu, fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
To są święta PANA, które ogłosicie jako święte zgromadzenia, abyście składali PANU ofiarę spalaną, całopalenie, ofiarę pokarmową, ofiarę [pojednawczą] i ofiary z płynów, każdą w swój dzień;
38 Àwọn ọrẹ wọ̀nyí wà ní àfikún pẹ̀lú àwọn ọrẹ ọjọ́ ìsinmi Olúwa, àti pẹ̀lú ẹ̀bùn yín àti ohunkóhun tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ àti gbogbo ọrẹ àtinúwá yín fún Olúwa.)
Oprócz szabatów PANA, oprócz waszych darów, oprócz wszystkich waszych ślubów i wszystkich waszych dobrowolnych ofiar, które będziecie składać PANU.
39 “‘Torí náà, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti kórè ilẹ̀ náà, ẹ ṣe àjọ̀dún yìí fún Olúwa ní ọjọ́ méje. Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ọjọ́ kẹjọ pẹ̀lú si tún jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
Piętnastego dnia siódmego miesiąca, gdy zbierzecie plony ziemi, będziecie obchodzili święto dla PANA przez siedem dni; w pierwszym dniu będzie odpoczynek, także w ósmym dniu będzie odpoczynek.
40 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, kí ẹ mú àṣàyàn èso láti orí igi dáradára, imọ̀ ọ̀pẹ, àti ẹ̀ka igi tó rúwé, àti igi wílò odò, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín fún ọjọ́ méje.
Pierwszego dnia weźmiecie sobie owoce z najlepszych drzew, gałązki palmowe, gałązki gęstych drzew i wierzbiny znad potoku i będziecie się weselić przed PANEM, waszym Bogiem, przez siedem dni.
41 Ẹ ṣe èyí ní àjọ̀dún sí Olúwa fún ọjọ́ méje lọ́dọọdún. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, ẹ ṣe é ní oṣù keje.
Będziecie obchodzić to święto dla PANA przez siedem dni, co rok. Będzie to wieczysta ustawa przez wszystkie wasze pokolenia. W siódmym miesiącu będziecie je obchodzić.
42 Ẹ gbé inú àgọ́ fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ọmọ bíbí Israẹli gbé nínú àgọ́.
Przez siedem dni będziecie mieszkać w szałasach. Wszyscy urodzeni Izraelici będą mieszkać w szałasach;
43 Kí àwọn ìran yín le mọ̀ pé mo mú kí Israẹli gbé nínú àgọ́, nígbà tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Aby wasze pokolenia wiedziały, że kazałem synom Izraela mieszkać w szałasach, gdy wyprowadziłem ich z ziemi Egiptu. Ja jestem PAN, wasz Bóg.
44 Báyìí ni Mose kéde àwọn àjọ̀dún tí a yàn Olúwa fún àwọn ọmọ Israẹli.
I ogłosił Mojżesz synom Izraela te święta PANA.

< Leviticus 23 >