< Leviticus 23 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
Rzekł jeszcze Pan do Mojżesza, mówiąc:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, àwọn àjọ̀dún ti Olúwa èyí tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí àjọ̀dún tí a yàn.
Powiedz synom Izraelskim, a mów im: Święta uroczyste Pańskie, które nazywać będziecie zgromadzenia święte, te są święta uroczyste moje.
3 “‘Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ le fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi. Ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé. Ọjọ́ ìsinmi Olúwa ni.
Przez sześć dni robić będziecie; ale w dzień siódmy sabat odpocznienia, zgromadzenie święte, żadnej roboty czynić nie będziecie; sabat Pański jest we wszystkich mieszkaniach waszych.
4 “‘Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọdún tí Olúwa yàn, àjọ̀dún tí a yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde lákokò wọn.
A teć są uroczyste święta Pańskie, zgromadzenia święte, które obchodzić będziecie pewnego ich czasu.
5 Àjọ ìrékọjá Olúwa bẹ̀rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
Miesiąca pierwszego, dnia czternastego tegoż miesiąca, między dwoma wieczorami święto przejścia Pańskiego.
6 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ni àjọ̀dún àkàrà àìwú tí Olúwa yó bẹ̀rẹ̀, fún ọjọ́ méje ni ẹ gbọdọ̀ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
Potem dnia piętnastego tegoż miesiąca, święto przaśników będzie Panu; przez siedem dni chleby przaśne jeść będziecie.
7 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan nínú rẹ̀.
A dnia pierwszego zgromadzenie święte mieć będziecie; żadnej roboty służebniczej czynić nie będziecie.
8 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa. Ní ọjọ́ keje, ẹ pe ìpàdé àjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.’”
Ale będziecie ofiarowali ofiarę ognistą Panu przez siedem dni. Dnia także siódmego zgromadzenie święte będzie; żadnej roboty służebniczej czynić nie będziecie.
9 Olúwa sọ fún Mose pe,
I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi yóò fún yín, tí ẹ bá ń ṣe ìkórè, kí ẹ mú síírí ọkà àkọ́kọ́ tí ẹ kórè wá fún àlùfáà.
Powiedz synom Izraelskim, i rzecz im: Gdy wnijdziecie do ziemi którą Ja wam dawam, a będziecie żąć zboże wasze, tedy przyniesiecie snop pierwiastek żniwa waszego do kapłana.
11 Kí ó fi síírí ọkà náà níwájú Olúwa, kí ó le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín: kí àlùfáà fì í ní ọjọ́ kejì ìsinmi.
I będzie tam i sam obracał on snop przed obliczem Pańskiem, aby był przyjemny za was; nazajutrz po sabacie podnosić go będzie kapłan.
12 Ní ọjọ́ tí ẹ bá fi síírí ọkà náà, kí ẹ mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan láìní àbùkù rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
Zabijecie też dnia, którego obracać będziecie on snop, baranka zupełnego, rocznego na ofiarę całopalenia Panu;
13 Pẹ̀lú ọrẹ ọkà rẹ tí ó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi òróró pò ọrẹ tí a fi iná ṣe fún Olúwa òórùn dídùn pẹ̀lú ọrẹ ohun mímu rẹ̀ tí í ṣe ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì (èyí jẹ́ lita kan).
Przy tem ofiarę jego śniedną ze dwu dziesiątych części efy mąki pszennej, zadziałanej z oliwą na paloną ofiarę Panu dla wdzięcznej wonności; także ofiarę jego mokrą, wina czwartą część hynu.
14 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ àkàrà kankan tàbí kí ẹ sun ọkà tuntun títí di ọjọ́ tí ẹ fi mú ọrẹ yín wá fún Ọlọ́run yín. Èyí ni ìlànà ayérayé fún ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
A chleba i prażma, i nowego zboża jeść nie będziecie aż do dnia, którego przyniesiecie ofiarę Bogu waszemu; ustawa to wieczna będzie w narodziech waszych, we wszystkich mieszkaniach waszych.
15 “‘Ẹ ka ọ̀sẹ̀ méje gbangba, láti ọjọ́ kejì ọjọ́ ìsinmi, àní ọjọ́ tí ẹ mú ìdì ọkà fífì wá.
Naliczycie także sobie od dnia pierwszego po sabacie, od dnia, któregoście ofiarowali snop podnoszenia, siedem tygodni zupełnych niech będzie.
16 Ẹ ka àádọ́ta ọjọ́ títí dé ọjọ́ kejì ọ̀sẹ̀ méjèèje, kí ẹ sì mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Olúwa.
Aż do pierwszego dnia po siódmym tygodniu naliczycie pięćdziesiąt dni; tedy ofiarować będziecie ofiarę śniedną nową Panu.
17 Láti ibikíbi tí ẹ bá ń gbé, ẹ mú ìṣù àkàrà méjì tí a fi òsùwọ̀n ìdá méjì nínú mẹ́wàá tí efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi ìwúkàrà ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì àkọ́so sí Olúwa.
Z domów waszych przyniesiecie chleby na obracanie tam i sam; dwa chleby, ze dwu dziesiątych części pszennej mąki z kwasem upieczone będą; pierwiastki to Panu.
18 Ẹ fi akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù, ọmọ màlúù kan àti àgbò méjì kún àkàrà yìí, wọn yóò jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu wọn, àní ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn ni sí Olúwa.
A ofiarować z tym chlebem będziecie siedem baranków rocznych zupełnych, i cielca jednego, i dwu baranów; na ofiarę całopalenia będą Panu z ofiarą śniedną ich i z mokremi ofiarami ich; ofiara to ognista na wdzięczną wonność Panu.
19 Lẹ́yìn náà kí ẹ fi akọ ewúrẹ́ kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan fún ọrẹ àlàáfíà.
Zabijecie też kozła jednego za grzech, i dwa baranki roczne na ofiarę spokojną.
20 Kí àlùfáà fi ọ̀dọ́-àgùntàn méjèèjì náà níwájú Olúwa bí i ọrẹ fífì pẹ̀lú oúnjẹ àkọ́so wọn jẹ́ ọrẹ mímọ́ sí Olúwa fún àlùfáà.
I będzie je obracał tam i sam kapłan z chlebem pierwiastek na ofiarę sam i tam obracania przed obliczem Pańskiem, i ze dwiema barankami; i będą święte rzeczy Panu dla kapłana.
21 Ní ọjọ́ yìí náà ni kí ẹ kéde ìpàdé àjọ mímọ́: ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀ níbi yówù tí ẹ ń gbé.
I ogłosicie w ten dzień święto; zgromadzenie święte mieć będziecie; żadnej roboty służebniczej czynić nie będziecie; ustawa to będzie wieczna we wszystkich mieszkaniach waszych, w narodziech waszych.
22 “‘Nígbà tí ẹ bá kórè ilẹ̀ yín ẹ má ṣe kórè dé ìkangun oko yín, tàbí kí ẹ padà gé èyí tí ó ṣẹ́kù sílẹ̀ nínú ìkórè yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn tálákà àti àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
A gdy żąć będziecie zboże ziemi waszej, nie będziesz do końca pola twego dożynał, i kłosów pozostałych żniwa twego zbierać nie będziesz: ubogiemu, i przychodniowi zostawisz je; Jam Pan Bóg wasz.
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
Zatem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
24 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, kí ẹ ní ọjọ́ ìsinmi, ìpàdé àjọ mímọ́ tí a fi fèrè fífọn ṣe ìrántí.
Powiedz synom Izraelskim, mówiąc: Miesiąca siódmego, pierwszego dnia tegoż miesiąca, będziecie mieli sabat, pamiątkę trąbienia, zgromadzenie święte.
25 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojúmọ́, ṣùgbọ́n ẹ mú ọrẹ tí a fi iná sun wá síwájú Olúwa.’”
Żadnej roboty służebniczej nie będziecie czynili, lecz ofiarować będziecie ofiarę ognistą Panu.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
Rzekł jeszcze Pan do Mojżesza, mówiąc:
27 “Ọjọ́ kẹwàá oṣù keje yìí ni ọjọ́ ètùtù. Ẹ ni ìpàdé àjọ mímọ́, kí ẹ sì ṣẹ́ ara yín kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa.
Lecz dziesiątego dnia tegoż miesiąca siódmego, dzień oczyszczania jest; zgromadzenie święte mieć będziecie, a będziecie trapić dusze wasze, ofiarując ognistą ofiarę Panu.
28 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà, torí pé ọjọ́ ètùtù ni, nínú èyí tí a ń ṣe ètùtù fún yín níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
Żadnej roboty nie będziecie czynili w ten dzień; bo dzień oczyszczania jest na oczyszczenie was przed obliczem Pana, Boga waszego.
29 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣẹ́ ara rẹ̀ ní ọjọ́ náà ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
A wszelka dusza, która by się nie trapiła tego dnia, wytracona będzie z ludu swego.
30 Èmi yóò pa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà run kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Także, ktobykolwiek czynił robotę jaką w tenże dzień, wytracę człowieka tego z pośrodku ludu jego.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan rárá. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Żadnej roboty nie czyńcie; ustawa to będzie wieczna w narodziech waszych.
32 Ọjọ́ ìsinmi ni fún un yín, ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹsànán oṣù náà, títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó tẹ̀lé e, ni kí ẹ fi sinmi.”
Sabat odpocznienia mieć będziecie, gdy trapić będziecie dusze swe; dziewiątego dnia tegoż miesiąca, wieczór, od wieczora aż do wieczora, obchodzić będziecie sabat wasz.
33 Olúwa sọ fún Mose pé,
Rzekł zaś Pan do Mojżesza, mówiąc:
34 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje ni kí àjọ̀dún ọdún àgọ́ ti Olúwa bẹ̀rẹ̀ kí ó sì wà títí di ọjọ́ méje.
Powiedz synom Izraelskim, i rzecz: Piętnastego dnia tegoż siódmego miesiąca będzie święto kuczek przez siedem dni Panu.
35 Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìpàdé mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ ojúmọ́.
Dnia pierwszego zgromadzenie święte będzie; żadnej roboty służebniczej czynić nie będziecie.
36 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá, ní ọjọ́ kẹjọ, ẹ pe ìpàdé mímọ́ kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa, èyí jẹ́ ìpàdé tí ó gbẹ̀yìn; ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojoojúmọ́.
Przez siedem dni ofiarować będziecie ofiarę ognistą Panu; dnia ósmego zgromadzenie święte mieć będziecie, a będziecie ofiarowali ofiarę ognistą Panu; święto jest, żadnej roboty służebniczej nie będziecie czynili.
37 (“‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí Olúwa ti yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí i àjọ̀dún tí a yàn fún mímu àwọn ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa wá—ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà, ọrẹ ẹbọ àti ọrẹ ohun mímu, fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Teć są święta uroczyste Pańskie, które obchodzić będziecie, zgromadzenia święte, abyście ofiarowali ofiarę ognistą Panu, całopalenie, i ofiarę śniedną, i ofiarę spokojną i ofiary mokre, każdą w dzień swój.
38 Àwọn ọrẹ wọ̀nyí wà ní àfikún pẹ̀lú àwọn ọrẹ ọjọ́ ìsinmi Olúwa, àti pẹ̀lú ẹ̀bùn yín àti ohunkóhun tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ àti gbogbo ọrẹ àtinúwá yín fún Olúwa.)
Oprócz sabatów Pańskich, i oprócz darów waszych, i oprócz wszystkich ślubów waszych, i oprócz wszystkich dobrowolnych podarków waszych, które oddawać będziecie Panu.
39 “‘Torí náà, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti kórè ilẹ̀ náà, ẹ ṣe àjọ̀dún yìí fún Olúwa ní ọjọ́ méje. Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ọjọ́ kẹjọ pẹ̀lú si tún jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
Wszakże piętnastego dnia miesiąca siódmego, gdy zbierzecie urodzaj ziemi, będziecie obchodzili święto Panu przez siedem dni; dnia pierwszego odpocznienie, także dnia ósmego odpocznienie będzie.
40 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, kí ẹ mú àṣàyàn èso láti orí igi dáradára, imọ̀ ọ̀pẹ, àti ẹ̀ka igi tó rúwé, àti igi wílò odò, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín fún ọjọ́ méje.
Tedy weźmiecie sobie pierwszego dnia owocu z drzewa co najpiękniejszego, i gałązek palmowych, i gałązek drzewa gęstego, i wierzbiny od potoku, i weselić się będziecie przed Panem Bogiem waszym przez siedem dni.
41 Ẹ ṣe èyí ní àjọ̀dún sí Olúwa fún ọjọ́ méje lọ́dọọdún. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, ẹ ṣe é ní oṣù keje.
A obchodzić będziecie to święto Panu przez siedem dni na każdy rok. Ustawa to wieczna w narodziech waszych; każdego miesiąca siódmego obchodzić je będziecie.
42 Ẹ gbé inú àgọ́ fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ọmọ bíbí Israẹli gbé nínú àgọ́.
W kuczkach mieszkać będziecie przez siedem dni; każdy zrodzony w Izraelu mieszkać będzie w kuczkach,
43 Kí àwọn ìran yín le mọ̀ pé mo mú kí Israẹli gbé nínú àgọ́, nígbà tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Aby wiedzieli potomkowie wasi, iżem w namiotach kazał mieszkać synom Izraelskim, gdym je wywiódł z ziemi Egipskiej; Ja Pan, Bóg wasz.
44 Báyìí ni Mose kéde àwọn àjọ̀dún tí a yàn Olúwa fún àwọn ọmọ Israẹli.
I opowiedział Mojżesz święta uroczyste Pańskie synom Izraelskim.

< Leviticus 23 >