< Leviticus 23 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
Yahweh said to Moses/me,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, àwọn àjọ̀dún ti Olúwa èyí tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí àjọ̀dún tí a yàn.
“Tell the Israeli people about the festivals that I have chosen, the days when you all must gather together [to worship me].”
3 “‘Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ le fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi. Ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé. Ọjọ́ ìsinmi Olúwa ni.
“You may work for six days [each week], but on the seventh day you must not do any work. You must rest. It is a sacred/holy day when you must gather together [to worship me]. Wherever you live, you must rest on that day.”
4 “‘Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọdún tí Olúwa yàn, àjọ̀dún tí a yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde lákokò wọn.
“There are festivals that I have established for you. Those will also be sacred/holy days when you must gather together [to worship me].
5 Àjọ ìrékọjá Olúwa bẹ̀rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
[The first festival is] (the Passover/when you remember that I spared your ancestors when I killed all the firstborn Egyptian sons). That festival will begin at twilight/dusk/sunset on the chosen day (each spring/in March or April each year), [and end on the following day].
6 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ni àjọ̀dún àkàrà àìwú tí Olúwa yó bẹ̀rẹ̀, fún ọjọ́ méje ni ẹ gbọdọ̀ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
The next day, the Festival of Eating Bread That Has No Yeast will begin. That festival will continue for seven days. During that time, the bread that you eat must be made without yeast.
7 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan nínú rẹ̀.
On the first day of that festival, you all must stop your regular work and you must gather together [to worship me].
8 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa. Ní ọjọ́ keje, ẹ pe ìpàdé àjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.’”
On each of the seven days, you must present to me [several animals to be] an offering/sacrifice to be completely burned [on the altar]. On the seventh day, you all must again stop your regular work and gather to worship me.”
9 Olúwa sọ fún Mose pe,
Yahweh also told Moses/me
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi yóò fún yín, tí ẹ bá ń ṣe ìkórè, kí ẹ mú síírí ọkà àkọ́kọ́ tí ẹ kórè wá fún àlùfáà.
to tell the Israeli people [about other festivals]. He said, “When you arrive in the land which I am giving to you, and you harvest your crops [for the first time] there, bring to the priest some of the first grain that you harvest.
11 Kí ó fi síírí ọkà náà níwájú Olúwa, kí ó le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín: kí àlùfáà fì í ní ọjọ́ kejì ìsinmi.
On the day after the [next] Sabbath/rest day, the priest will lift it up [high to dedicate it] to me, in order that I will accept it as your [gift].
12 Ní ọjọ́ tí ẹ bá fi síírí ọkà náà, kí ẹ mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan láìní àbùkù rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
That same day, you must sacrifice to me a one-year-old male lamb that has no defects. You must burn it [on the altar].
13 Pẹ̀lú ọrẹ ọkà rẹ tí ó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi òróró pò ọrẹ tí a fi iná ṣe fún Olúwa òórùn dídùn pẹ̀lú ọrẹ ohun mímu rẹ̀ tí í ṣe ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì (èyí jẹ́ lita kan).
You must also burn an offering of grain. That offering must consist of (three quarts/3.5 liters) of good flour mixed with [olive] oil. The smell [of those things burning] will be very pleasing to me. Along with that, you must also offer one quart/liter of wine, which will be a liquid offering.
14 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ àkàrà kankan tàbí kí ẹ sun ọkà tuntun títí di ọjọ́ tí ẹ fi mú ọrẹ yín wá fún Ọlọ́run yín. Èyí ni ìlànà ayérayé fún ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Do not eat any bread or any roasted grain or unroasted grain on that day until after you have brought those offerings to me, your God. You must always obey [LIT] those commands, wherever you live.”
15 “‘Ẹ ka ọ̀sẹ̀ méje gbangba, láti ọjọ́ kejì ọjọ́ ìsinmi, àní ọjọ́ tí ẹ mú ìdì ọkà fífì wá.
“Seven weeks after the priest offers that grain to me,
16 Ẹ ka àádọ́ta ọjọ́ títí dé ọjọ́ kejì ọ̀sẹ̀ méjèèje, kí ẹ sì mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Olúwa.
on the next/50th day after he offers it, [each family] must bring to me an offering from the new crop of grain.
17 Láti ibikíbi tí ẹ bá ń gbé, ẹ mú ìṣù àkàrà méjì tí a fi òsùwọ̀n ìdá méjì nínú mẹ́wàá tí efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi ìwúkàrà ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì àkọ́so sí Olúwa.
From your homes, bring two loaves of bread [to the priest]. He will lift them up [high to dedicate them] as an offering to me. Those loaves must be baked from three quarts/liters of good flour that has yeast mixed with it. That bread will be an offering to me from the first wheat that you harvest [each year].
18 Ẹ fi akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù, ọmọ màlúù kan àti àgbò méjì kún àkàrà yìí, wọn yóò jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu wọn, àní ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn ni sí Olúwa.
Along with this bread, you must present to me seven one-year-old lambs with no defects, one young bull, and two rams. They must all be completely burned [on the altar]. All those offerings, with the grain offering and the wine offering, will be burned, and the smell [of all those things burning] will be very pleasing to me.
19 Lẹ́yìn náà kí ẹ fi akọ ewúrẹ́ kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan fún ọrẹ àlàáfíà.
Then you must also kill one male goat to be an offering/sacrifice for your sins, and two one-year-old male lambs to be an offering to enable you to maintain fellowship with me.
20 Kí àlùfáà fi ọ̀dọ́-àgùntàn méjèèjì náà níwájú Olúwa bí i ọrẹ fífì pẹ̀lú oúnjẹ àkọ́so wọn jẹ́ ọrẹ mímọ́ sí Olúwa fún àlùfáà.
The priest will lift up these offerings [high to dedicate them] to me. He will also offer the loaves of bread that were baked from the first wheat that you harvest. Those offerings are sacred to me, but they are for the priests [to eat].
21 Ní ọjọ́ yìí náà ni kí ẹ kéde ìpàdé àjọ mímọ́: ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀ níbi yówù tí ẹ ń gbé.
On that day, you must stop your regular work and gather to worship me. You must always obey those instructions/commands, and you must obey them wherever you live.
22 “‘Nígbà tí ẹ bá kórè ilẹ̀ yín ẹ má ṣe kórè dé ìkangun oko yín, tàbí kí ẹ padà gé èyí tí ó ṣẹ́kù sílẹ̀ nínú ìkórè yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn tálákà àti àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
“When you harvest the grain in your fields, do not harvest the grain along the edges of the fields, and do not pick up the grain that the harvesters drop. Leave that grain for the poor people and for the foreigners who are living among you. [Do not forget that it is] I, Yahweh your God, [who am commanding those things]!”
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh also told Moses/me
24 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, kí ẹ ní ọjọ́ ìsinmi, ìpàdé àjọ mímọ́ tí a fi fèrè fífọn ṣe ìrántí.
to give these instructions/commands to the Israeli people: “[Each year] in September, on the day that I have chosen, you all must celebrate it by completely resting. You must not do any work on that day. When [the priests] blow their trumpets loudly, you all must gather together to worship me.
25 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojúmọ́, ṣùgbọ́n ẹ mú ọrẹ tí a fi iná sun wá síwájú Olúwa.’”
All of you must not do your regular work on that day. Instead, you must present offerings to me that will be burned [on the altar].”
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh also said to Moses/me,
27 “Ọjọ́ kẹwàá oṣù keje yìí ni ọjọ́ ètùtù. Ẹ ni ìpàdé àjọ mímọ́, kí ẹ sì ṣẹ́ ara yín kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa.
“You must celebrate a day [on which you request that I] forgive you for the sins that you have committed. That day will be nine days after the festival [when the priests blow] the trumpets. On that day you must (fast/abstain from eating food). You must gather together to worship me and present offerings to me that will be burned [on the altar].
28 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà, torí pé ọjọ́ ètùtù ni, nínú èyí tí a ń ṣe ètùtù fún yín níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
You must not do any work on that day, because it is the day when the priests will offer sacrifices to me to (atone for/ask me to forgive) your sins.
29 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣẹ́ ara rẹ̀ ní ọjọ́ náà ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
You must expel from your group anyone who does not (fast/abstain from eating food) on that day.
30 Èmi yóò pa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà run kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
I will get rid of anyone who does any kind of work on that day.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan rárá. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
You must not work at all! You must always obey those instructions/commands, and you must obey them wherever you live.
32 Ọjọ́ ìsinmi ni fún un yín, ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹsànán oṣù náà, títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó tẹ̀lé e, ni kí ẹ fi sinmi.”
That day will be a day of complete rest for all of you, and on that day you must (fast/abstain from eating food) [to show that you are sorry for having sinned]. That day of rest and (fasting/abstaining from eating food) will begin on the evening before the day in which you ask me to forgive you for your sins, and it will end on the evening of the following day.”
33 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh also said to Moses/me,
34 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje ni kí àjọ̀dún ọdún àgọ́ ti Olúwa bẹ̀rẹ̀ kí ó sì wà títí di ọjọ́ méje.
“Tell the Israeli people that [each year] they must also celebrate a festival of living in temporary shelters. That festival will begin five days after the day in which they request me to forgive them for their sins. It will last for seven days.
35 Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìpàdé mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ ojúmọ́.
On the first day of that festival, the people must gather together to worship me, and they must not do any regular work on that day.
36 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá, ní ọjọ́ kẹjọ, ẹ pe ìpàdé mímọ́ kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa, èyí jẹ́ ìpàdé tí ó gbẹ̀yìn; ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojoojúmọ́.
On each of the seven days of the festival, they must present to me an offering [of animals] that will be burned [on the altar]. On the next day, they must gather again to worship me and present to me another animal that will be burned [on the altar]. That also will be a sacred gathering, and they must not work on that day, either.
37 (“‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí Olúwa ti yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí i àjọ̀dún tí a yàn fún mímu àwọn ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa wá—ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà, ọrẹ ẹbọ àti ọrẹ ohun mímu, fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
“[To summarize], those are the festivals that I have appointed. Celebrate those sacred festivals by gathering together to present to me all the various offerings that will be burned [on the altar]—animals that will be burned completely, and offerings of grain, and offerings to enable the Israeli people to maintain fellowship with me, and offerings of wine. Each offering must be brought on the day that I have indicated.
38 Àwọn ọrẹ wọ̀nyí wà ní àfikún pẹ̀lú àwọn ọrẹ ọjọ́ ìsinmi Olúwa, àti pẹ̀lú ẹ̀bùn yín àti ohunkóhun tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ àti gbogbo ọrẹ àtinúwá yín fún Olúwa.)
(Those festivals must be celebrated/You must celebrate those festivals) in addition to [worshiping on] the (Sabbath days/days of rest). And all those offerings must be given in addition to the offerings that people personally decide to give, and in addition to the offerings that people make to accompany the solemn promises that they have made, or offerings that people make (voluntarily/because they themselves want to).
39 “‘Torí náà, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti kórè ilẹ̀ náà, ẹ ṣe àjọ̀dún yìí fún Olúwa ní ọjọ́ méje. Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ọjọ́ kẹjọ pẹ̀lú si tún jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
“[Returning to my instructions about] the Festival of Living in Temporary Shelters, you must celebrate this festival after you have harvested all the crops. On the first day and on the last day of that festival, you must rest completely.
40 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, kí ẹ mú àṣàyàn èso láti orí igi dáradára, imọ̀ ọ̀pẹ, àti ẹ̀ka igi tó rúwé, àti igi wílò odò, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín fún ọjọ́ méje.
But on the first day, you are permitted to pick fruit from trees. Cut palm fronds/branches and other leafy branches from trees or from bushes that grow by the streams, [and make shelters/huts to live in for that week]. Then rejoice in my presence for those seven days.
41 Ẹ ṣe èyí ní àjọ̀dún sí Olúwa fún ọjọ́ méje lọ́dọọdún. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, ẹ ṣe é ní oṣù keje.
You must celebrate this festival for seven days every year. You must never stop obeying my commands/instructions for that festival. You must celebrate it in September.
42 Ẹ gbé inú àgọ́ fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ọmọ bíbí Israẹli gbé nínú àgọ́.
During the seven days of that festival, all of you people who have been Israelis your entire lives must live in shelters/huts.
43 Kí àwọn ìran yín le mọ̀ pé mo mú kí Israẹli gbé nínú àgọ́, nígbà tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
That will remind your descendants that their ancestors lived in shelters [for many years] after I rescued them from Egypt. [Do not forget that] I, Yahweh your God, [am the one who is commanding this].”
44 Báyìí ni Mose kéde àwọn àjọ̀dún tí a yàn Olúwa fún àwọn ọmọ Israẹli.
So Moses/I gave to the Israeli people all those instructions concerning the festivals that Yahweh [wanted them to celebrate] each year.

< Leviticus 23 >