< Leviticus 23 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
HERREN talede fremdeles til Moses og sagde:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, àwọn àjọ̀dún ti Olúwa èyí tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí àjọ̀dún tí a yàn.
Tal til Israeliterne og sig til dem: Hvad angår HERRENs Festtider, hvilke I skal udråbe som Højtidsstævner, da er mine Festtider følgende:
3 “‘Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ le fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi. Ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé. Ọjọ́ ìsinmi Olúwa ni.
I seks Dage skal der arbejdes, men den syvende Dag skal være en fuldkommen Hviledag med Højtidsstævne; I må intet Arbejde gøre, det er Sabbat for HERREN, overalt hvor I bor.
4 “‘Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọdún tí Olúwa yàn, àjọ̀dún tí a yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde lákokò wọn.
Følgende er HERRENs Festtider med Højtidsstævner, som I skal udråbe, hver til sin Tid:
5 Àjọ ìrékọjá Olúwa bẹ̀rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
På den fjortende Dag i den første Måned ved Aftenstid er det Påske for HERREN.
6 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ni àjọ̀dún àkàrà àìwú tí Olúwa yó bẹ̀rẹ̀, fún ọjọ́ méje ni ẹ gbọdọ̀ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
På den femtende Dag i samme Måned er det de usyrede Brøds Højtid for HERREN; i syv Dage skal I spise usyret Brød.
7 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan nínú rẹ̀.
På den første Dag skal I bolde Højtidsstævne, I må intet Arbejde gøre.
8 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa. Ní ọjọ́ keje, ẹ pe ìpàdé àjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.’”
I skal bringe HERREN Ildoffer i syv Dage. På den syvende Dag skal der holdes Højtidsstævne, I må intet Arbejde gøre.
9 Olúwa sọ fún Mose pe,
HERREN talede fremdeles til Moses og sagde:
10 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi yóò fún yín, tí ẹ bá ń ṣe ìkórè, kí ẹ mú síírí ọkà àkọ́kọ́ tí ẹ kórè wá fún àlùfáà.
Tal til Israeliterne og sig til dem: Når I kommer til det Land, jeg vil give eder, og høster dets Høst, skal I bringe Præsten Førstegrødeneget af eders Høst.
11 Kí ó fi síírí ọkà náà níwájú Olúwa, kí ó le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín: kí àlùfáà fì í ní ọjọ́ kejì ìsinmi.
Han skal udføre Svingningen med Neget for HERRENs Åsyn for at vinde eder Guds Velbehag; Dagen efter Sabbaten skal Præsten udføre Svingningen dermed.
12 Ní ọjọ́ tí ẹ bá fi síírí ọkà náà, kí ẹ mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan láìní àbùkù rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
Og på den Dag I udfører Svingningen med Neget, skal I ofre et lydefrit, årgammelt Lam som Brændoffer til HERREN,
13 Pẹ̀lú ọrẹ ọkà rẹ tí ó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi òróró pò ọrẹ tí a fi iná ṣe fún Olúwa òórùn dídùn pẹ̀lú ọrẹ ohun mímu rẹ̀ tí í ṣe ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì (èyí jẹ́ lita kan).
og der skal høre to Tiendedele Eta fint Hvedemel, rørt i Olie, dertil som Afgrødeoffer, et Ildoffer for HERREN til en liflig Duft, og ligeledes en Fjerdedel Hin Vin som Drikoffer.
14 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ àkàrà kankan tàbí kí ẹ sun ọkà tuntun títí di ọjọ́ tí ẹ fi mú ọrẹ yín wá fún Ọlọ́run yín. Èyí ni ìlànà ayérayé fún ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Brød, ristede Aks eller nyhøstet Horn må I ikke spise før denne Dag, før I har frembåret eders Guds Offergave. Det skal være eder en evig gyldig Anordning fra Slægt til Slægt, overalt hvor I bor.
15 “‘Ẹ ka ọ̀sẹ̀ méje gbangba, láti ọjọ́ kejì ọjọ́ ìsinmi, àní ọjọ́ tí ẹ mú ìdì ọkà fífì wá.
Så skal I fra Dagen efter Sabbaten, fra den dag I bringer Svingningsneget, tælle syv Uger frem - det skal være hele Uger -
16 Ẹ ka àádọ́ta ọjọ́ títí dé ọjọ́ kejì ọ̀sẹ̀ méjèèje, kí ẹ sì mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Olúwa.
til Dagen efter den syvende Sabbat, I skal tælle halvtredsinds tyve bage frem; da skal I frembære et nyt Afgrødeoffer for HERREN.
17 Láti ibikíbi tí ẹ bá ń gbé, ẹ mú ìṣù àkàrà méjì tí a fi òsùwọ̀n ìdá méjì nínú mẹ́wàá tí efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi ìwúkàrà ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì àkọ́so sí Olúwa.
Fra eders Boliger skal I bringe Svingningsbrød, to Brød, som skal laves af to Tiendedele Efa fint Hvedemel og bages syrede, en Førstegrødegave til HERREN.
18 Ẹ fi akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù, ọmọ màlúù kan àti àgbò méjì kún àkàrà yìí, wọn yóò jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu wọn, àní ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn ni sí Olúwa.
Og foruden Brødet skal I bringe syv lydefri, årgamle Lam, en ung Tyr og to Vædre, de skal være til Brændoffer for HERREN med tilhørende Afgrødeoffer og Drikoffer, et Ildoffer for HERREN til en liflig Duft.
19 Lẹ́yìn náà kí ẹ fi akọ ewúrẹ́ kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan fún ọrẹ àlàáfíà.
Og I skal ofre en Gedebuk som Syndoffer og to årgamle Lam som Takoffer.
20 Kí àlùfáà fi ọ̀dọ́-àgùntàn méjèèjì náà níwájú Olúwa bí i ọrẹ fífì pẹ̀lú oúnjẹ àkọ́so wọn jẹ́ ọrẹ mímọ́ sí Olúwa fún àlùfáà.
Og Præsten skal udføre Svingningen med dem, med de to Lam, for HERRENs Åsyn sammen med Førstegrødebrødet, de skal være HERREN helligede og tilfalde Præsten.
21 Ní ọjọ́ yìí náà ni kí ẹ kéde ìpàdé àjọ mímọ́: ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀ níbi yówù tí ẹ ń gbé.
På denne Dag skal I udråbe og holde et Højtidsstævne; I må intet Arbejde gøre. Det skal være eder en evig gyldig Anordning, overalt hvor I bor, fra Slægt til Slægt.
22 “‘Nígbà tí ẹ bá kórè ilẹ̀ yín ẹ má ṣe kórè dé ìkangun oko yín, tàbí kí ẹ padà gé èyí tí ó ṣẹ́kù sílẹ̀ nínú ìkórè yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn tálákà àti àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Når I høster eders Lands Høst, må du ikke høste helt hen til Kanten af din Mark, ej heller må du sanke Efterslætten efter din Høst; til den fattige og den fremmede skal du lade det blive tilbage. Jeg er HERREN eders Gud!
23 Olúwa sọ fún Mose pé,
HERREN talede fremdeles til Moses og sagde:
24 “Sọ fún àwọn ará Israẹli, ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, kí ẹ ní ọjọ́ ìsinmi, ìpàdé àjọ mímọ́ tí a fi fèrè fífọn ṣe ìrántí.
Tal til Israeliterne og sig: Den første dag i den syvende Måned skal I holde Hviledag med Hornblæsning til Ihukommelse og med Højtidsstævne;
25 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojúmọ́, ṣùgbọ́n ẹ mú ọrẹ tí a fi iná sun wá síwájú Olúwa.’”
I må intet Arbejde gøre, og I skal bringe HERREN Ildofre.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
HERREN talede fremdeles til Moses og sagde:
27 “Ọjọ́ kẹwàá oṣù keje yìí ni ọjọ́ ètùtù. Ẹ ni ìpàdé àjọ mímọ́, kí ẹ sì ṣẹ́ ara yín kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa.
På den tiende Dag i samme syvende Måned falder Forsoningsdagen; da skal I holde Højtidsstævne, faste og bringe HERREN Ildofre;
28 Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà, torí pé ọjọ́ ètùtù ni, nínú èyí tí a ń ṣe ètùtù fún yín níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
I må intet Arbejde gøre på denne Dag, thi det er Forsoningsdagen, den skal skaffe eder Soning for HERREN eders Guds Åsyn.
29 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣẹ́ ara rẹ̀ ní ọjọ́ náà ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Thi enhver, som ikke faster på denne Dag, skal udryddes af sin Slægt;
30 Èmi yóò pa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà run kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
og enhver, der gør noget som helst Arbejde på denne Dag, det Menneske vil jeg udslette af hans Folk.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan rárá. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
I må intet Arbejde gøre. Det skal være eder en evig Anordning fra Slægt til Slægt, overalt hvor I bor.
32 Ọjọ́ ìsinmi ni fún un yín, ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹsànán oṣù náà, títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó tẹ̀lé e, ni kí ẹ fi sinmi.”
Den skal være eder en fuldkommen Hviledag, og I skal faste; på den niende Dag i Måneden om Aftenen, fra denne Aften til næste Aften skal I holde eders Hviledag.
33 Olúwa sọ fún Mose pé,
HERREN talede fremdeles til Moses og sagde:
34 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje ni kí àjọ̀dún ọdún àgọ́ ti Olúwa bẹ̀rẹ̀ kí ó sì wà títí di ọjọ́ méje.
Tal til Israeliterne og sig: Den femtende Dag i samme syvende Måned skal Løvhyttefesten fejres, den skal fejres i syv Dage for HERREN.
35 Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìpàdé mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ ojúmọ́.
På den første Dag skal der holdes Højtidsstævne, I må intet Arbejde gøre.
36 Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá, ní ọjọ́ kẹjọ, ẹ pe ìpàdé mímọ́ kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa, èyí jẹ́ ìpàdé tí ó gbẹ̀yìn; ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojoojúmọ́.
Syv dage skal I bringe HERREN Ildofre; og på den ottende Dag skal I holde Højtidsstævne og bringe HERREN Ildofre; det er festlig Samling, I må intet Arbejde gøre.
37 (“‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí Olúwa ti yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí i àjọ̀dún tí a yàn fún mímu àwọn ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa wá—ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà, ọrẹ ẹbọ àti ọrẹ ohun mímu, fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Det er HERRENs Festtider, hvilke I skal udråbe som Højtids stævner, ved hvilke der skal bringes HERREN Ildofre, Brændofre og Afgrødeofre, Slagtofre og drikofre, hver Dag de for den bestemte Ofre,
38 Àwọn ọrẹ wọ̀nyí wà ní àfikún pẹ̀lú àwọn ọrẹ ọjọ́ ìsinmi Olúwa, àti pẹ̀lú ẹ̀bùn yín àti ohunkóhun tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ àti gbogbo ọrẹ àtinúwá yín fún Olúwa.)
foruden HERRENs Sabbater og foruden eders Gaver og alle eders Løfteofre og alle eders Frivilligofre, som I giver HERREN.
39 “‘Torí náà, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti kórè ilẹ̀ náà, ẹ ṣe àjọ̀dún yìí fún Olúwa ní ọjọ́ méje. Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ọjọ́ kẹjọ pẹ̀lú si tún jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
Men den femtende Dag i den syvende Måned, når I har indsamlet Landets Afgrøde, skal I fejre HERRENs Højtid, og den skal fejres i syv Dage. På den første Dag skal der holdes Hviledag, og på den ottende dag skal der holdes Hviledag.
40 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, kí ẹ mú àṣàyàn èso láti orí igi dáradára, imọ̀ ọ̀pẹ, àti ẹ̀ka igi tó rúwé, àti igi wílò odò, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín fún ọjọ́ méje.
Den første Dag skal I tage eder smukke Træfrugter, Palmegrene og Kviste af Løvtræer og Vidjer fra Bækkene og i syv Dage være glade for HERREN eders Guds Åsyn.
41 Ẹ ṣe èyí ní àjọ̀dún sí Olúwa fún ọjọ́ méje lọ́dọọdún. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, ẹ ṣe é ní oṣù keje.
I skal fejre den som en Højtid for HERREN syv Dage om Året; det skal være eder en evig gyldig Anordning fra Slægt til Slægt; i den syvende Måned skal I fejre den.
42 Ẹ gbé inú àgọ́ fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ọmọ bíbí Israẹli gbé nínú àgọ́.
I skal bo i Løvhytter i syv Dage, alle indfødte i Israel skal bo i Løvhytter,
43 Kí àwọn ìran yín le mọ̀ pé mo mú kí Israẹli gbé nínú àgọ́, nígbà tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
for at eders Efterkommere kan vide, at jeg lod Israeliterne bo i Løvhytter, da jeg førte dem ud af Ægypten. Jeg er HERREN eders Gud!
44 Báyìí ni Mose kéde àwọn àjọ̀dún tí a yàn Olúwa fún àwọn ọmọ Israẹli.
Og Moses kundgjorde Israeliterne HERRENs Festtider.

< Leviticus 23 >