< Leviticus 22 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, zicând:
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí wọ́n fi ọ̀wọ̀ fún ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli yà sọ́tọ̀ fún mi, kí wọ́n má ba à ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Èmi ni Olúwa.
Spune-i lui Aaron și fiilor săi, să se separe de lucrurile sfinte ale copiilor lui Israel, să nu pângărească numele meu sfânt în acele lucruri pe care ei mi le sfințesc: Eu sunt DOMNUL.
3 “Sọ fún wọn pé, ‘Fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ yín tí kò mọ́ bá wá sí ibi ọrẹ mímọ́ tí àwọn ara Israẹli ti yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, kí ẹ yọ ẹni náà kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà ní iwájú mi. Èmi ni Olúwa.
Să le spui: Oricine din toată sămânța voastră printre generațiile voastre, merge la lucrurile sfinte, pe care copiii lui Israel le sfințesc DOMNULUI, avându-și necurăția asupra sa, acel suflet să fie stârpit din prezența mea: Eu sunt DOMNUL.
4 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Aaroni bá ní ààrùn ara tí ń ran ni, tàbí ìtújáde nínú ara. Ó lè má jẹ ọrẹ mímọ́ náà títí di ìgbà tí a ó fi wẹ̀ ẹ́ mọ́. Òun tún lè di aláìmọ́ bí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí òkú nǹkan bá sọ di àìmọ́ tàbí bí ó bá farakan ẹnikẹ́ni tí ó ní ìtújáde.
Din sămânța lui Aaron, orice bărbat care este lepros, sau are o scurgere, acela să nu mănânce din lucrurile sfinte, până este curat. Și oricine atinge orice lucru necurat prin moarte, sau pe un bărbat căruia îi iese sămânța de împreunare;
5 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan èyíkéyìí nínú ohun tí ń rákò, tí ó sọ ọ́ di aláìmọ́, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó sọ ọ́ di àìmọ́, ohunkóhun yówù kí àìmọ́ náà jẹ́.
Sau oricine atinge orice târâtoare, prin care el este făcut necurat, sau un om de la care poate lua necurăție, orice fel de necurăție ar avea;
6 Ẹni náà tí ó fọwọ́ kan irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú ọrẹ mímọ́ àyàfi bí ó bá wẹ ara rẹ̀.
Sufletul care a atins așa ceva să fie necurat până seara și să nu mănânce din lucrurile sfinte, decât dacă își spală carnea cu apă.
7 Bí oòrùn bá wọ̀, ẹni náà di mímọ́, lẹ́yìn náà ni ó tó le jẹ ọrẹ mímọ́, torí pé wọ́n jẹ́ oúnjẹ rẹ̀.
Și când soarele a apus, să fie curat și după aceea să mănânce din lucrurile sfinte; deoarece aceasta este mâncarea sa.
8 Kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti kú sílẹ̀, tàbí tí ẹranko fàya, kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa.
Ceea ce moare de la sine, sau este sfâșiat de fiare, să nu mănânce pentru a nu se pângări în aceasta: Eu sunt DOMNUL.
9 “‘Kí àwọn àlùfáà pa ìlànà mi mọ́, kí wọn má ba à jẹ̀bi, kí wọn sì kú nítorí pé wọ́n ṣe ọrẹ wọ̀nyí pẹ̀lú fífojútẹ́ńbẹ́lú wọn. Èmi ni Olúwa tí ó sọ wọ́n di mímọ́.
De aceea ei să țină rânduiala mea, ca nu cumva să poarte păcat pentru aceasta și de aceea să moară, dacă o pângărește: Eu DOMNUL îi sfințesc.
10 “‘Kò sí ẹnikẹ́ni lẹ́yìn ìdílé àlùfáà tí ó le jẹ ọrẹ mímọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni, àlejò àlùfáà tàbí alágbàṣe rẹ̀ kò le jẹ ẹ́.
Niciun străin să nu mănânce din lucrul sfânt, un călător oaspete al preotului, sau un servitor angajat, să nu mănânce lucrul sfânt.
11 Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá ra ẹrú, pẹ̀lú owó, tàbí tí a bí ẹrú kan nínú ìdílé rẹ̀, ẹrú náà lè jẹ oúnjẹ rẹ̀.
Dar dacă preotul cumpără vreun suflet cu banii săi, el să mănânce din aceasta și cel ce este născut în casa lui, să mănânce din mâncarea lui.
12 Bí ọmọbìnrin àlùfáà bá fẹ́ ẹni tí kì í ṣe àlùfáà, kò gbọdọ̀ jẹ nínú èyíkéyìí nínú ohun ọrẹ mímọ́.
De asemenea dacă fiica preotului este măritată după un străin, ea nu poate mânca dintr-o ofrandă a lucrurilor sfinte.
13 Ṣùgbọ́n bí ọmọbìnrin àlùfáà bá jẹ́ opó tàbí tí a ti kọ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n tí kò lọ́mọ tí ó sì padà sínú ilé baba rẹ̀ láti máa gbé bẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀, ó le jẹ oúnjẹ baba rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, àlejò tí kò lẹ́tọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ náà.
Dar dacă fiica preotului este văduvă sau divorțată și nu are copil și este întoarsă la casa tatălui ei, ca în tinerețea ei, să mănânce din mâncarea tatălui ei, dar niciun străin să nu mănânce din ea.
14 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì jẹ ọrẹ mímọ́ kan, ó gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe lórí ẹbọ náà fún àlùfáà, kí ó sì fi ìdámárùn-ún ohun tí ọrẹ náà jẹ́ kún un.
Și dacă un bărbat mănâncă din lucrul sfânt în neștiință, atunci, el să adauge la acesta a cincea parte din el și să îl dea preotului cu lucrul sfânt.
15 Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli mú wá síwájú Olúwa di àìmọ́.
Iar ei să nu spurce lucrurile sfinte ale copiilor lui Israel, pe care le aduc DOMNULUI;
16 Nípa fífi ààyè fún wọn láti jẹ ọrẹ mímọ́ náà, kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú ẹ̀bi tí wọn yóò san nǹkan fún wá sórí wọn. Èmi ni Olúwa, tí ó sọ wọ́n di mímọ́.’”
Sau să le permită să poarte nelegiuirea fărădelegii, mâncând lucrurile lor sfinte, pentru că eu DOMNUL îi sfințesc.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, zicând:
18 “Sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ rẹ̀ àti fún gbogbo Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín yálà ọmọ Israẹli ni tàbí àlejò tí ń gbé ní Israẹli bá mú ẹ̀bùn wá fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa, yálà láti san ẹ̀jẹ́ tàbí ọrẹ àtinúwá.
Vorbește lui Aaron și fiilor săi și tuturor copiilor lui Israel și spune-le: Oricine din casa lui Israel sau dintre străinii din Israel, care dorește să își aducă darul pentru toate promisiunile sale și toate ofrandele sale de bunăvoie, pe care să le aducă DOMNULUI ca ofrandă arsă;
19 Ẹ gbọdọ̀ mú akọ láìní àbùkù láti ara màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́, kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Să aduceți de bunăvoie o parte bărbătească, fără cusur, dintre boi, dintre oi sau dintre capre.
20 Ẹ má ṣe mú ohunkóhun tí ó ní àbùkù wá, torí pé kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Dar orice are cusur, să nu îl aduceți, pentru că nu vă va fi bine primit.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá mú ọrẹ àlàáfíà wá láti inú agbo màlúù tàbí ti àgùntàn, fún Olúwa láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí fún ọrẹ àtinúwá. Ó gbọdọ̀ jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà láìní àbùkù.
Și oricine aduce un sacrificiu al ofrandelor de pace DOMNULUI, ca să își împlinească promisiunea, sau ofrandă de bunăvoie dintre boi sau oi, aceasta să fie fără cusur pentru a fi bine primită, niciun cusur să nu fie în el.
22 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí ó fọ́jú, tí ó fi ara pa, tí ó yarọ, tí ó ní kókó, tí ó ní èkúkú, èépá àti egbò kíkẹ̀ rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé èyíkéyìí nínú wọn sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bi ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
Să nu aduceți DOMNULUI nimic dintre acestea: orb sau zdrobit sau ciung sau având o rană care curge sau cruste scărpinate sau râios, nici să nu faceți, din ele pe altar, ofrandă prin foc pentru DOMNUL.
23 Ẹ le mú màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù tàbí tí ó yọ iké wá fún ọrẹ àtinúwá, ṣùgbọ́n kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ ẹ̀jẹ́.
Fie un taur sau un miel care are ceva în plus sau o lipsă în părțile lui, să îl aduci ca ofrandă de bunăvoie, dar ca promisiune nu va fi bine primit.
24 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí kóró ẹpọ̀n rẹ̀ fọ́ tàbí tí a tẹ̀, tàbí tí a yà tàbí tí a là rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí ní ilẹ̀ yín.
Să nu aduceți DOMNULUI ceea ce este lovit sau zdrobit sau frânt sau tăiat; nici să nu faceți din ele ofrandă în țara voastră.
25 Ẹ kò gbọdọ̀ gba irú ẹranko bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àlejò kankan láti fi rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ sí Ọlọ́run yín. A kò nígbà wọ́n fún yín nítorí pé wọ́n ní àbùkù, wọ́n sì díbàjẹ́.’”
Nici să nu aduceți pâinea Dumnezeului vostru în niciuna din acestea din mâna unui străin; deoarece în ele este putreziciunea lor și cusururi sunt în ele, nu vă vor fi bine primite.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
27 “Nígbà tí màlúù bá bímọ, tí àgùntàn bímọ, tí ewúrẹ́ sì bímọ, ọmọ náà gbọdọ̀ wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Láti ọjọ́ kẹjọ ni ó ti di ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ àfinásun sí Olúwa.
Când un taur sau o oaie sau o capră se nasc, să fie șapte zile sub mamă; și din ziua a opta și de aici încolo va fi bine primit ca ofrandă făcută DOMNULUI prin foc.
28 Ẹ má ṣe pa màlúù àti ọmọ rẹ̀ tàbí àgùntàn àti ọmọ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
Și dacă este vacă sau oaie, să nu o înjunghiați pe ea și puiul ei în aceeași zi.
29 “Nígbà tí ẹ bá rú ẹbọ ọpẹ́ sí Olúwa, ẹ rú u ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Și când doriți să aduceți un sacrificiu de mulțumire DOMNULUI, să îl aduceți de bunăvoie.
30 Ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ọjọ́ náà gan an, ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀. Èmi ni Olúwa.
În aceeași zi să fie mâncat; să nu lăsați nimic din el până dimineața: Eu sunt DOMNUL.
31 “Ẹ pa òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.
De aceea să păziți poruncile mele și să le împliniți: Eu sunt DOMNUL.
32 Ẹ má ṣe ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Àwọn ọmọ Israẹli gbọdọ̀ mọ̀ mí ní mímọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Să nu pângăriți numele meu sfânt, ci eu să fiu sfințit printre copiii lui Israel: Eu sunt DOMNUL care vă sfințește,
33 Tí ó sì mú yín jáde láti Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.”
Cel care v-a scos afară din țara Egiptului, pentru a fi Dumnezeul vostru: Eu sunt DOMNUL.

< Leviticus 22 >