< Leviticus 22 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
INkosi yasikhuluma kuMozisi isithi:
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí wọ́n fi ọ̀wọ̀ fún ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli yà sọ́tọ̀ fún mi, kí wọ́n má ba à ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Èmi ni Olúwa.
Tshono kuAroni lakumadodana akhe ukuthi bazehlukanise lezinto ezingcwele zabantwana bakoIsrayeli, bangangcolisi ibizo lami elingcwele; ngoba zingcwele kimi: NgiyiNkosi.
3 “Sọ fún wọn pé, ‘Fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ yín tí kò mọ́ bá wá sí ibi ọrẹ mímọ́ tí àwọn ara Israẹli ti yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, kí ẹ yọ ẹni náà kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà ní iwájú mi. Èmi ni Olúwa.
Tshono kibo uthi: Loba nguwuphi umuntu ezizukulwaneni zenu owenzalo yenu yonke osondela ezintweni ezingcwele, abantwana bakoIsrayeli abazingcwelisela iNkosi, nxa ukungcola kwakhe kuphezu kwakhe, lowomuntu uzaqunywa asuke phambi kwami. NgiyiNkosi.
4 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Aaroni bá ní ààrùn ara tí ń ran ni, tàbí ìtújáde nínú ara. Ó lè má jẹ ọrẹ mímọ́ náà títí di ìgbà tí a ó fi wẹ̀ ẹ́ mọ́. Òun tún lè di aláìmọ́ bí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí òkú nǹkan bá sọ di àìmọ́ tàbí bí ó bá farakan ẹnikẹ́ni tí ó ní ìtújáde.
Ngulowo lalowo owenzalo kaAroni, ongumlephero, loba olokugobhoza, kangadli ezintweni ezingcwele aze ahlambuluke. Lothinta lakuphi okungcoliswe yisidumbu, kumbe indoda okuphuma kuyo ubudoda bokuhlangana,
5 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan èyíkéyìí nínú ohun tí ń rákò, tí ó sọ ọ́ di aláìmọ́, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó sọ ọ́ di àìmọ́, ohunkóhun yówù kí àìmọ́ náà jẹ́.
kumbe loba ngubani othinta loba yiyiphi into ehuquzelayo, angcoliswa yiyo, kumbe umuntu angcoliswa nguye, ngakho konke ukungcola kwakhe,
6 Ẹni náà tí ó fọwọ́ kan irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú ọrẹ mímọ́ àyàfi bí ó bá wẹ ara rẹ̀.
umuntu othinta lokhu uzakuba ngongcolileyo kuze kuhlwe, angadli okwezinto ezingcwele ngaphandle kokuthi ageze umzimba wakhe ngamanzi.
7 Bí oòrùn bá wọ̀, ẹni náà di mímọ́, lẹ́yìn náà ni ó tó le jẹ ọrẹ mímọ́, torí pé wọ́n jẹ́ oúnjẹ rẹ̀.
Nxa selitshonile ilanga uzahlambuluka; lemva kwalokho angadla okwezinto ezingcwele, ngoba kuyikudla kwakhe.
8 Kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti kú sílẹ̀, tàbí tí ẹranko fàya, kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa.
Ingcuba lokudatshuliweyo kangakudli ukuzingcolisa ngakho. NgiyiNkosi.
9 “‘Kí àwọn àlùfáà pa ìlànà mi mọ́, kí wọn má ba à jẹ̀bi, kí wọn sì kú nítorí pé wọ́n ṣe ọrẹ wọ̀nyí pẹ̀lú fífojútẹ́ńbẹ́lú wọn. Èmi ni Olúwa tí ó sọ wọ́n di mímọ́.
Ngakho bazagcina umlayo wami, ukuze bangathwali isono ngawo, bafele kuso, sebewungcolisile. NgiyiNkosi ebangcwelisayo.
10 “‘Kò sí ẹnikẹ́ni lẹ́yìn ìdílé àlùfáà tí ó le jẹ ọrẹ mímọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni, àlejò àlùfáà tàbí alágbàṣe rẹ̀ kò le jẹ ẹ́.
Njalo kakho owemzini ozakudla into engcwele. Ohlala lompristi loyisisebenzi esiqhatshiweyo kangadli into engcwele.
11 Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá ra ẹrú, pẹ̀lú owó, tàbí tí a bí ẹrú kan nínú ìdílé rẹ̀, ẹrú náà lè jẹ oúnjẹ rẹ̀.
Kodwa uba umpristi ethenga umuntu eyintengo yemali yakhe, yena angadla okwayo, lozelwe emzini wakhe, bona bangadla okokudla kwakhe.
12 Bí ọmọbìnrin àlùfáà bá fẹ́ ẹni tí kì í ṣe àlùfáà, kò gbọdọ̀ jẹ nínú èyíkéyìí nínú ohun ọrẹ mímọ́.
Lendodakazi yompristi, uba isiba ngeyendoda yemzini, yona kayingadli okomnikelo wezinto ezingcwele.
13 Ṣùgbọ́n bí ọmọbìnrin àlùfáà bá jẹ́ opó tàbí tí a ti kọ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n tí kò lọ́mọ tí ó sì padà sínú ilé baba rẹ̀ láti máa gbé bẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀, ó le jẹ oúnjẹ baba rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, àlejò tí kò lẹ́tọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ náà.
Kodwa indodakazi yompristi, nxa ingumfelokazi loba ingelahliweyo ingelanzalo, isibuyele emzini kayise njengebutsheni bayo, izakudla okokudla kukayise; kanti kakho owemzini ongadla kukho.
14 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì jẹ ọrẹ mímọ́ kan, ó gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe lórí ẹbọ náà fún àlùfáà, kí ó sì fi ìdámárùn-ún ohun tí ọrẹ náà jẹ́ kún un.
Njalo nxa umuntu esidla into engcwele ngokungazi, uzakwengezelela kuyo ingxenye yesihlanu yayo, anike umpristi into engcwele.
15 Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli mú wá síwájú Olúwa di àìmọ́.
Njalo kabayikungcolisa izinto ezingcwele zabantwana bakoIsrayeli abaziphakamisela iNkosi,
16 Nípa fífi ààyè fún wọn láti jẹ ọrẹ mímọ́ náà, kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú ẹ̀bi tí wọn yóò san nǹkan fún wá sórí wọn. Èmi ni Olúwa, tí ó sọ wọ́n di mímọ́.’”
babenze bathwale ububi becala, lapho besidla izinto zabo ezingcwele; ngoba ngiyiNkosi ebangcwelisayo.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
INkosi yasikhuluma kuMozisi isithi:
18 “Sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ rẹ̀ àti fún gbogbo Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín yálà ọmọ Israẹli ni tàbí àlejò tí ń gbé ní Israẹli bá mú ẹ̀bùn wá fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa, yálà láti san ẹ̀jẹ́ tàbí ọrẹ àtinúwá.
Tshono kuAroni, lakumadodana akhe, lakubo bonke abantwana bakoIsrayeli, uthi kubo: Ngulowo lalowo owendlu kaIsrayeli, lowabezizweni koIsrayeli, ozanikela umnikelo wakhe ngezithembiso zabo zonke, langokweminikelo yabo yonke yesihle, abazayinikela eNkosini kube ngumnikelo wokutshiswa,
19 Ẹ gbọdọ̀ mú akọ láìní àbùkù láti ara màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́, kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
ukuze lemukeleke, iduna elingelasici, elezinkomo, elezimvu, loba elembuzi.
20 Ẹ má ṣe mú ohunkóhun tí ó ní àbùkù wá, torí pé kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Linganikeli loba ngakuphi okulesici kukho, ngoba kakuyikwemukeleka kini.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá mú ọrẹ àlàáfíà wá láti inú agbo màlúù tàbí ti àgùntàn, fún Olúwa láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí fún ọrẹ àtinúwá. Ó gbọdọ̀ jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà láìní àbùkù.
Umuntu, nxa enikela-ke umhlatshelo weminikelo yokuthula eNkosini wesithembiso esikhethekileyo loba womnikelo wesihle, enkomeni loba ezimvini, kumele uphelele ukuze wemukeleke, kungabi lasici kuwo.
22 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí ó fọ́jú, tí ó fi ara pa, tí ó yarọ, tí ó ní kókó, tí ó ní èkúkú, èépá àti egbò kíkẹ̀ rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé èyíkéyìí nínú wọn sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bi ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
Eziyiziphofu, kumbe ezephukileyo, kumbe eziyizilima, kumbe ezilensumpa, kumbe eziloqweqwe, kumbe ezilamathumba, linganikeli lezi eNkosini, futhi linganikeli kulezi umnikelo owenziwe ngomlilo eNkosini phezu kwelathi.
23 Ẹ le mú màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù tàbí tí ó yọ iké wá fún ọrẹ àtinúwá, ṣùgbọ́n kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ ẹ̀jẹ́.
Kodwa inkunzi loba imvu elesitho eselulekileyo kumbe esidundubeleyo lingayinikela ibe ngumnikelo wesihle; kodwa kayiyikwemukeleka ukuba ngeyesithembiso.
24 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí kóró ẹpọ̀n rẹ̀ fọ́ tàbí tí a tẹ̀, tàbí tí a yà tàbí tí a là rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí ní ilẹ̀ yín.
Njalo linganikeli eNkosini okuhluzukileyo kumbe okugxotshiweyo loba okudatshuliweyo loba okuqunyiweyo; lingakwenzi elizweni lakini.
25 Ẹ kò gbọdọ̀ gba irú ẹranko bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àlejò kankan láti fi rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ sí Ọlọ́run yín. A kò nígbà wọ́n fún yín nítorí pé wọ́n ní àbùkù, wọ́n sì díbàjẹ́.’”
Ngokuvela esandleni sowemzini linganikeli isinkwa sikaNkulunkulu wenu okuvela kuzo zonke lezi; ngoba ukonakala kwazo kukuzo, isici sikuzo, kaziyikwemukeleka kini.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
INkosi yasikhuluma kuMozisi isithi:
27 “Nígbà tí màlúù bá bímọ, tí àgùntàn bímọ, tí ewúrẹ́ sì bímọ, ọmọ náà gbọdọ̀ wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Láti ọjọ́ kẹjọ ni ó ti di ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ àfinásun sí Olúwa.
Nxa kuzalwa inkunzi loba imvu loba imbuzi, izakuba ngaphansi kukanina insuku eziyisikhombisa. Njalo kusukela kusuku lwesificaminwembili njalo kusiya phambili izakwemukeleka ibe ngumnikelo, umnikelo owenzelwe iNkosi ngomlilo.
28 Ẹ má ṣe pa màlúù àti ọmọ rẹ̀ tàbí àgùntàn àti ọmọ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
Kodwa inkomokazi loba imvukazi lingayihlabi lomntwana wayo ngasuku lunye.
29 “Nígbà tí ẹ bá rú ẹbọ ọpẹ́ sí Olúwa, ẹ rú u ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Njalo nxa lihlabela iNkosi umhlatshelo wokubonga, lizawuhlaba ukuze lemukeleke.
30 Ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ọjọ́ náà gan an, ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀. Èmi ni Olúwa.
Uzadliwa ngalolosuku, lingatshiyi okwawo kuze kube sekuseni. NgiyiNkosi.
31 “Ẹ pa òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.
Ngakho gcinani imilayo yami, liyenze. NgiyiNkosi.
32 Ẹ má ṣe ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Àwọn ọmọ Israẹli gbọdọ̀ mọ̀ mí ní mímọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Njalo lingeyisi ibizo lami elingcwele, kodwa ngizangcweliswa phakathi kwabantwana bakoIsrayeli. NgiyiNkosi elingcwelisayo,
33 Tí ó sì mú yín jáde láti Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.”
eyalikhupha elizweni leGibhithe ukuze ngibe nguNkulunkulu wenu. NgiyiNkosi.

< Leviticus 22 >