< Leviticus 21 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pe, “Bá àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú wọn kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí àwọn ènìyàn wọn tí ó kù.
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: — Sǝn kaⱨinlar bolƣan Ⱨarunning oƣulliriƣa mundaⱪ degin: — bir kaⱨin ɵz hǝlⱪining arisidiki ɵlgǝnlǝr wǝjidin ɵzini napak ⱪilmisun.
2 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe àwọn tí ó súnmọ́ ọn bí ìyá rẹ̀, baba rẹ̀, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, àti arákùnrin rẹ̀.
Pǝⱪǝt ɵzining yeⱪin tuƣⱪanliri üqün — anisi bilǝn atisi, oƣli bilǝn ⱪizi wǝ aka-inisining ɵlüki tüpǝylidin ɵzini napak ⱪilsa bolidu;
3 Tàbí fún arábìnrin rẹ̀ tí kò ì tí ì wọ ilé ọkọ tí ó ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí tí arábìnrin bẹ́ẹ̀, ó lè sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
xuningdǝk ǝgǝr aqa-singlisi ǝrgǝ tǝgmǝy pak ⱪiz ⱨalǝttǝ ɵzi bilǝn billǝ turuwatⱪan bolsa, uning ɵlüki tüpǝylidin ɵzini napak ⱪilsa bolidu;
4 Nítorí tí ó jẹ́ olórí, òun kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ ba ara rẹ̀ jẹ́ láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
qünki [kaⱨin] ɵz hǝlⱪining arisida mɵtiwǝr bolƣaqⱪa, ɵzini napak ⱪilip bulƣimasliⱪi kerǝk.
5 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ fá irun orí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ rẹ́ irùngbọ̀n rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi abẹ ya ara rẹ̀ láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Kaⱨinlar bexini yerim-yata ⱪilip qüxürmǝsliki, saⱪilining uq-yanlirini ⱨǝm qüxürmǝsliki, bǝdinigimu zǝhim yǝtküzüp tilmasliⱪi kerǝk,
6 Wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún Ọlọ́run, kí wọ́n má ba à sọ orúkọ Ọlọ́run wọn di àìmọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń fi iná sun ẹbọ sí Olúwa wọn, ti ó jẹ oúnjẹ Ọlọ́run wọn. Nítorí náà wọn gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́.
bǝlki ular ɵz Hudasiƣa muⱪǝddǝs turup, Hudasining namini bulƣimasliⱪi kerǝk; qünki ular Pǝrwǝrdigarƣa atap otta sunulidiƣan ⱪurbanliⱪlarni, ɵz Hudasining nenini sunidu; xunga ular muⱪǝddǝs boluxi kerǝk.
7 “‘Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ fẹ́ panṣágà tàbí obìnrin tí ó ti fi ọkùnrin ba ara rẹ̀ jẹ́ tàbí obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti kọ̀sílẹ̀ nítorí pé àwọn àlùfáà jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Ular bir ayalni ɵz ǝmrigǝ alƣanda paⱨixǝ ayalnimu, buzuⱪ ayalnimu almasliⱪi kerǝk wǝ eri ⱪoyuwǝtkǝn ayalnimu almisun. Qünki kaⱨin bolsa ɵz Hudasiƣa has muⱪǝddǝs ⱪilinƣan.
8 Àwọn ènìyàn gbọdọ̀ máa kà wọ́n sí mímọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń rú ẹbọ oúnjẹ fún mi. Èmi ni Olúwa, mo jẹ́ mímọ́, mo sì ya àwọn ènìyàn mi sí mímọ́.
U Hudayingning nenini sunƣini üqün u sanga nisbǝtǝn muⱪǝddǝs dǝp sanilixi kerǝk; qünki silǝrni muⱪǝddǝs ⱪilƣuqi Pǝrwǝrdigar Ɵzüm muⱪǝddǝsturmǝn.
9 “‘Bí ọmọbìnrin àlùfáà kan bá fi iṣẹ́ àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ó dójútì baba rẹ̀, iná ni a ó dá sun ún.
Əgǝr bir kaⱨinning ⱪizi paⱨixilik ⱪilip ɵzini bulƣiƣan ⱪilsa, ɵz atisini bulƣiƣan bolidu; u otta kɵydürülsun.
10 “‘Lẹ́yìn tí a ti fi òróró yan olórí àlùfáà láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, tí a sì ti fi àmì òróró yàn án láti máa wọ aṣọ àlùfáà, ó gbọdọ̀ tọ́jú irun orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fa aṣọ rẹ̀ ya láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Bexiƣa mǝsiⱨlǝx zǝytun meyi tɵkülgǝn, kaⱨinliⱪ kiyimlǝrni kiyixkǝ tiklǝngǝn, ɵz ⱪerindaxlirining arisida bax kaⱨin ⱪilinƣan kixi yalangbax bolmisun, kiyimlirinimu yirtmisun;
11 Kí ó ma ṣe wọlé tọ òkú lọ, kí ó má ṣe sọ ará rẹ di àìmọ́ nítorí baba tàbí nítorí ìyá rẹ̀.
U yǝnǝ ⱨeq ɵlükkǝ yeⱪinlaxmasliⱪi kerǝk, ⱨǝtta atisi wǝ yaki anisining ɵlüklirining wǝjidin ɵzini napak ⱪilmasliⱪi kerǝk.
12 Kò gbọdọ̀ kúrò ní ibi mímọ́ Ọlọ́run tàbí kí ó sọ ọ́ di aláìmọ́ torí pé a ti fi ìfòróróyàn Ọlọ́run yà á sí mímọ́. Èmi ni Olúwa.
U [wǝzipisidǝ turuwatⱪanda] muⱪǝddǝs jaydin ⱨǝrgiz ayrilmisun wǝ xuningdǝk Hudasining muⱪǝddǝs jayini bulƣimasliⱪi kerǝk; qünki uning Hudasining uni Ɵzigǝ has ⱪilƣan «mǝsiⱨlǝx meyi» uning bexida turidu. Mǝn Pǝrwǝrdigardurmǝn.
13 “‘Ọmọbìnrin tí yóò fẹ́ gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí kò mọ ọkùnrin rí.
U hotun alsa pak ⱪizni elixi kerǝk;
14 Kò gbọdọ̀ fẹ́ opó tàbí ẹni tí a kọ̀sílẹ̀ tàbí obìnrin tí ó ti fi àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n kí ó fẹ́ obìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí, láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
tul wǝ yaki ǝrdin ⱪoyuwetilgǝn ayal wǝ yaki buzuⱪ wǝ yaki paⱨixǝ ayal bolsa bularni almasliⱪi, bǝlki ɵz hǝlⱪidin bolƣan pak ⱪizni hotunluⱪⱪa elixi kerǝk.
15 Kí ó má ba à sọ di aláìmọ́ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. Èmi ni Olúwa tí ó sọ ọ́ di mímọ́.’”
Bolmisa u ɵz hǝlⱪining arisida ɵz uruⱪini napak ⱪilidu; qünki uni muⱪǝddǝs ⱪilƣuqi Pǝrwǝrdigar Mǝndurmǝn.
16 Olúwa sì bá Mose sọ̀rọ̀ pé,
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
17 “Sọ fún Aaroni pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú irú-ọmọ rẹ̀ ní ìran-ìran wọn, tí ó bá ní ààrùn kan, kí ó má ṣe súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ ohun jíjẹ sí Ọlọ́run rẹ̀.
Sǝn Ⱨarunƣa mundaⱪ degin: — «Əwladtin-ǝwladⱪiqǝ sening nǝslingdin bolƣan birsi meyip bolsa, Hudaning nenini sunux üqün yeⱪin kǝlmisun;
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi ẹbọ náà. Kò gbọdọ̀ sí afọ́jú tàbí arọ, alábùkù ara tàbí àwọn tí ara wọn kò pé.
meyip bolƣan ⱨǝrⱪandaⱪ kixi ⱨǝrgiz yeⱪin kǝlmisun — yaki kor bolsun, tokur bolsun, panaⱪ bolsun yaki bir ǝzasi yǝnǝ bir jüpidin uzun bolƣan adǝm bolsun,
19 Kò gbọdọ̀ sí ẹnikẹ́ni yálà ó rọ lápá lẹ́sẹ̀,
puti yaki ⱪoli sunuⱪ bolsun,
20 tàbí tí ó jẹ́ abuké, tàbí tí ó ya aràrá tàbí tí ó ní àìsàn ojú tàbí tí ó ní egbò tàbí tí a ti yọ nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀.
dok bolsun, parpa bolsun, kɵzidǝ aⱪ bolsun, ⱪiqixⱪaⱪ bolƣan bolsun, tǝmrǝtkǝ basⱪan bolsun yaki uruⱪdeni ezilgǝn ⱨǝrkim bolsun,
21 Ẹnikẹ́ni tí ó ní àbùkù nínú irú-ọmọ Aaroni àlùfáà kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ tí fi iná sun sí Olúwa. Nítorí pé ó jẹ́ alábùkù, kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ àkàrà sí Ọlọ́run rẹ̀.
Ⱨarun kaⱨinning nǝslidin bolƣan undaⱪ meyip kixilǝrning ⱨeqbiri Pǝrwǝrdigarƣa atap otta sunulidiƣan nǝrsilǝrni kǝltürüxkǝ yeⱪin barmisun; undaⱪ kixi meyiptur; u ɵz Hudasining nenini sunuxⱪa yeⱪin kǝlmisun.
22 Ó lè jẹ́ oúnjẹ Ọlọ́run rẹ̀ tàbí èyí tí ó mọ́ jùlọ, ṣùgbọ́n torí pé ó ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi aṣọ títa tàbí pẹpẹ.
Ⱨalbuki, u ɵz Hudasining nenini, yǝni «ǝng muⱪǝddǝs» wǝ «muⱪǝddǝs» ⱨesablanƣan nǝrsilǝrning ⱨǝr ikkisidin yesun.
23 Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò ba ibi mímọ́ mi jẹ́ torí pé, Èmi Olúwa ló ti sọ wọ́n di mímọ́.’”
Pǝⱪǝt u pǝrdidin ɵtüp iqkirisigǝ kirmǝsliki yaki ⱪurbangaⱨⱪimu yeⱪin barmasliⱪi kerǝk; qünki u meyiptur; bolmisa, u Mening muⱪǝddǝs jaylirimni bulƣiƣan bolidu; qünki ularni muⱪǝddǝs ⱪilƣuqi Pǝrwǝrdigar Ɵzümdurmǝn».
24 Wọ̀nyí ni àwọn ohun tí Mose sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ Aaroni àti gbogbo ọmọ Israẹli.
Bu sɵzlǝrning ⱨǝmmisini Musa Ⱨarun bilǝn uning oƣulliri wǝ Israillarning ⱨǝmmisigǝ eytip bǝrdi.

< Leviticus 21 >