< Leviticus 21 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pe, “Bá àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú wọn kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí àwọn ènìyàn wọn tí ó kù.
Perwerdigar Musagha söz qilip mundaq dédi: — Sen kahinlar bolghan Harunning oghullirigha mundaq dégin: — bir kahin öz xelqining arisidiki ölgenler wejidin özini napak qilmisun.
2 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe àwọn tí ó súnmọ́ ọn bí ìyá rẹ̀, baba rẹ̀, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, àti arákùnrin rẹ̀.
Peqet özining yéqin tughqanliri üchün — anisi bilen atisi, oghli bilen qizi we aka-inisining ölüki tüpeylidin özini napak qilsa bolidu;
3 Tàbí fún arábìnrin rẹ̀ tí kò ì tí ì wọ ilé ọkọ tí ó ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí tí arábìnrin bẹ́ẹ̀, ó lè sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
shuningdek eger acha-singlisi erge tegmey pak qiz halette özi bilen bille turuwatqan bolsa, uning ölüki tüpeylidin özini napak qilsa bolidu;
4 Nítorí tí ó jẹ́ olórí, òun kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ ba ara rẹ̀ jẹ́ láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
chünki [kahin] öz xelqining arisida mötiwer bolghachqa, özini napak qilip bulghimasliqi kérek.
5 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ fá irun orí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ rẹ́ irùngbọ̀n rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi abẹ ya ara rẹ̀ láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Kahinlar béshini yérim-yata qilip chüshürmesliki, saqilining uch-yanlirini hem chüshürmesliki, bedinigimu zexim yetküzüp tilmasliqi kérek,
6 Wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún Ọlọ́run, kí wọ́n má ba à sọ orúkọ Ọlọ́run wọn di àìmọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń fi iná sun ẹbọ sí Olúwa wọn, ti ó jẹ oúnjẹ Ọlọ́run wọn. Nítorí náà wọn gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́.
belki ular öz Xudasigha muqeddes turup, Xudasining namini bulghimasliqi kérek; chünki ular Perwerdigargha atap otta sunulidighan qurbanliqlarni, öz Xudasining nénini sunidu; shunga ular muqeddes bolushi kérek.
7 “‘Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ fẹ́ panṣágà tàbí obìnrin tí ó ti fi ọkùnrin ba ara rẹ̀ jẹ́ tàbí obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti kọ̀sílẹ̀ nítorí pé àwọn àlùfáà jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Ular bir ayalni öz emrige alghanda pahishe ayalnimu, buzuq ayalnimu almasliqi kérek we éri qoyuwetken ayalnimu almisun. Chünki kahin bolsa öz Xudasigha xas muqeddes qilin’ghan.
8 Àwọn ènìyàn gbọdọ̀ máa kà wọ́n sí mímọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń rú ẹbọ oúnjẹ fún mi. Èmi ni Olúwa, mo jẹ́ mímọ́, mo sì ya àwọn ènìyàn mi sí mímọ́.
U Xudayingning nénini sun’ghini üchün u sanga nisbeten muqeddes dep sanilishi kérek; chünki silerni muqeddes qilghuchi Perwerdigar Özüm muqeddesturmen.
9 “‘Bí ọmọbìnrin àlùfáà kan bá fi iṣẹ́ àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ó dójútì baba rẹ̀, iná ni a ó dá sun ún.
Eger bir kahinning qizi pahishilik qilip özini bulghighan qilsa, öz atisini bulghighan bolidu; u otta köydürülsun.
10 “‘Lẹ́yìn tí a ti fi òróró yan olórí àlùfáà láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, tí a sì ti fi àmì òróró yàn án láti máa wọ aṣọ àlùfáà, ó gbọdọ̀ tọ́jú irun orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fa aṣọ rẹ̀ ya láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Béshigha mesihlesh zeytun méyi tökülgen, kahinliq kiyimlerni kiyishke tiklen’gen, öz qérindashlirining arisida bash kahin qilin’ghan kishi yalangbash bolmisun, kiyimlirinimu yirtmisun;
11 Kí ó ma ṣe wọlé tọ òkú lọ, kí ó má ṣe sọ ará rẹ di àìmọ́ nítorí baba tàbí nítorí ìyá rẹ̀.
U yene héch ölükke yéqinlashmasliqi kérek, hetta atisi we yaki anisining ölüklirining wejidin özini napak qilmasliqi kérek.
12 Kò gbọdọ̀ kúrò ní ibi mímọ́ Ọlọ́run tàbí kí ó sọ ọ́ di aláìmọ́ torí pé a ti fi ìfòróróyàn Ọlọ́run yà á sí mímọ́. Èmi ni Olúwa.
U [wezipiside turuwatqanda] muqeddes jaydin hergiz ayrilmisun we shuningdek Xudasining muqeddes jayini bulghimasliqi kérek; chünki uning Xudasining uni Özige xas qilghan «mesihlesh méyi» uning béshida turidu. Men Perwerdigardurmen.
13 “‘Ọmọbìnrin tí yóò fẹ́ gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí kò mọ ọkùnrin rí.
U xotun alsa pak qizni élishi kérek;
14 Kò gbọdọ̀ fẹ́ opó tàbí ẹni tí a kọ̀sílẹ̀ tàbí obìnrin tí ó ti fi àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n kí ó fẹ́ obìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí, láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
tul we yaki erdin qoyuwétilgen ayal we yaki buzuq we yaki pahishe ayal bolsa bularni almasliqi, belki öz xelqidin bolghan pak qizni xotunluqqa élishi kérek.
15 Kí ó má ba à sọ di aláìmọ́ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. Èmi ni Olúwa tí ó sọ ọ́ di mímọ́.’”
Bolmisa u öz xelqining arisida öz uruqini napak qilidu; chünki uni muqeddes qilghuchi Perwerdigar Mendurmen.
16 Olúwa sì bá Mose sọ̀rọ̀ pé,
Perwerdigar Musagha söz qilip mundaq dédi: —
17 “Sọ fún Aaroni pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú irú-ọmọ rẹ̀ ní ìran-ìran wọn, tí ó bá ní ààrùn kan, kí ó má ṣe súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ ohun jíjẹ sí Ọlọ́run rẹ̀.
Sen Harun’gha mundaq dégin: — «Ewladtin-ewladqiche séning neslingdin bolghan birsi méyip bolsa, Xudaning nénini sunush üchün yéqin kelmisun;
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi ẹbọ náà. Kò gbọdọ̀ sí afọ́jú tàbí arọ, alábùkù ara tàbí àwọn tí ara wọn kò pé.
méyip bolghan herqandaq kishi hergiz yéqin kelmisun — yaki kor bolsun, tokur bolsun, panaq bolsun yaki bir ezasi yene bir jüpidin uzun bolghan adem bolsun,
19 Kò gbọdọ̀ sí ẹnikẹ́ni yálà ó rọ lápá lẹ́sẹ̀,
puti yaki qoli sunuq bolsun,
20 tàbí tí ó jẹ́ abuké, tàbí tí ó ya aràrá tàbí tí ó ní àìsàn ojú tàbí tí ó ní egbò tàbí tí a ti yọ nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀.
dok bolsun, parpa bolsun, közide aq bolsun, qichishqaq bolghan bolsun, temretke basqan bolsun yaki uruqdéni ézilgen herkim bolsun,
21 Ẹnikẹ́ni tí ó ní àbùkù nínú irú-ọmọ Aaroni àlùfáà kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ tí fi iná sun sí Olúwa. Nítorí pé ó jẹ́ alábùkù, kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ àkàrà sí Ọlọ́run rẹ̀.
Harun kahinning neslidin bolghan undaq méyip kishilerning héchbiri Perwerdigargha atap otta sunulidighan nersilerni keltürüshke yéqin barmisun; undaq kishi méyiptur; u öz Xudasining nénini sunushqa yéqin kelmisun.
22 Ó lè jẹ́ oúnjẹ Ọlọ́run rẹ̀ tàbí èyí tí ó mọ́ jùlọ, ṣùgbọ́n torí pé ó ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi aṣọ títa tàbí pẹpẹ.
Halbuki, u öz Xudasining nénini, yeni «eng muqeddes» we «muqeddes» hésablan’ghan nersilerning her ikkisidin yésun.
23 Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò ba ibi mímọ́ mi jẹ́ torí pé, Èmi Olúwa ló ti sọ wọ́n di mímọ́.’”
Peqet u perdidin ötüp ichkirisige kirmesliki yaki qurban’gahqimu yéqin barmasliqi kérek; chünki u méyiptur; bolmisa, u Méning muqeddes jaylirimni bulghighan bolidu; chünki ularni muqeddes qilghuchi Perwerdigar Özümdurmen».
24 Wọ̀nyí ni àwọn ohun tí Mose sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ Aaroni àti gbogbo ọmọ Israẹli.
Bu sözlerning hemmisini Musa Harun bilen uning oghulliri we Israillarning hemmisige éytip berdi.

< Leviticus 21 >