< Leviticus 21 >

1 Olúwa sọ fún Mose wí pe, “Bá àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú wọn kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí àwọn ènìyàn wọn tí ó kù.
Och HERREN sade till Mose: Säg till prästerna, Arons söner, säg till dem så: En präst får icke ådraga sig orenhet genom någon död bland sina fränder,
2 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe àwọn tí ó súnmọ́ ọn bí ìyá rẹ̀, baba rẹ̀, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, àti arákùnrin rẹ̀.
utom genom sina närmaste blodsförvanter: sin moder, sin fader, sin dotter, sin broder; son, sin dotter, sin broder;
3 Tàbí fún arábìnrin rẹ̀ tí kò ì tí ì wọ ilé ọkọ tí ó ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí tí arábìnrin bẹ́ẹ̀, ó lè sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
så ock genom sin syster, om hon var jungfru och stod honom närmare och icke tillhörde någon man, i sådant fall må han ådraga sig orenhet genom henne.
4 Nítorí tí ó jẹ́ olórí, òun kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ ba ara rẹ̀ jẹ́ láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Eftersom han är en herre bland sina fränder, får han icke ådraga sig orenhet och göra sig ohelig.
5 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ fá irun orí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ rẹ́ irùngbọ̀n rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi abẹ ya ara rẹ̀ láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Prästerna skola icke raka någon del av sitt huvud skallig eller avraka kanten av sitt skägg eller rista något märke på sin kropp.
6 Wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún Ọlọ́run, kí wọ́n má ba à sọ orúkọ Ọlọ́run wọn di àìmọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń fi iná sun ẹbọ sí Olúwa wọn, ti ó jẹ oúnjẹ Ọlọ́run wọn. Nítorí náà wọn gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́.
De skola vara helgade åt sin Guds och må icke ohelga sin Guds namn, ty de bära fram HERRENS eldsoffer sin Guds spis; därför skola de heliga.
7 “‘Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ fẹ́ panṣágà tàbí obìnrin tí ó ti fi ọkùnrin ba ara rẹ̀ jẹ́ tàbí obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti kọ̀sílẹ̀ nítorí pé àwọn àlùfáà jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Ingen av dem skall taga till hustru en sköka eller en vanärad kvinna, ej heller skall någon taga till hustru en kvinna som har blivit förskjuten av sin man, ty prästen är helgad åt sin Gud.
8 Àwọn ènìyàn gbọdọ̀ máa kà wọ́n sí mímọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń rú ẹbọ oúnjẹ fún mi. Èmi ni Olúwa, mo jẹ́ mímọ́, mo sì ya àwọn ènìyàn mi sí mímọ́.
Därför skall du akta honom helig, ty han bär fram din Guds spis; han skall vara dig helig, ty jag, HERREN, som helgar eder, är helig.
9 “‘Bí ọmọbìnrin àlùfáà kan bá fi iṣẹ́ àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ó dójútì baba rẹ̀, iná ni a ó dá sun ún.
Om en prästs dotter ohelgar sig genom skökolevnad, så ohelgar hon sin fader; hon skall brännas upp i eld.
10 “‘Lẹ́yìn tí a ti fi òróró yan olórí àlùfáà láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, tí a sì ti fi àmì òróró yàn án láti máa wọ aṣọ àlùfáà, ó gbọdọ̀ tọ́jú irun orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fa aṣọ rẹ̀ ya láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Den som är överstepräst bland sina bröder, den på vilkens huvud smörjelseoljan har blivit utgjuten, och som har mottagit handfyllning till att ikläda sig prästkläderna, han skall icke hava sitt hår oordnat, ej heller riva sönder sina kläder;
11 Kí ó ma ṣe wọlé tọ òkú lọ, kí ó má ṣe sọ ará rẹ di àìmọ́ nítorí baba tàbí nítorí ìyá rẹ̀.
och han skall icke gå in till någon död; icke ens genom sin fader eller genom sin moder får han ådraga sig orenhet.
12 Kò gbọdọ̀ kúrò ní ibi mímọ́ Ọlọ́run tàbí kí ó sọ ọ́ di aláìmọ́ torí pé a ti fi ìfòróróyàn Ọlọ́run yà á sí mímọ́. Èmi ni Olúwa.
Och ur helgedomen skall han icke gå ut, på det att han icke må ohelga sin Guds helgedom, ty hans Guds smörjelseolja, varmed han har blivit invigd, är på honom. Jag är HERREN.
13 “‘Ọmọbìnrin tí yóò fẹ́ gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí kò mọ ọkùnrin rí.
Till hustru skall han taga en kvinna som är jungfru.
14 Kò gbọdọ̀ fẹ́ opó tàbí ẹni tí a kọ̀sílẹ̀ tàbí obìnrin tí ó ti fi àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n kí ó fẹ́ obìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí, láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
En änka eller en förskjuten hustru eller en vanärad kvinna, en sköka -- en sådan får han icke taga, utan en jungfru bland sina fränder skall han taga till hustru,
15 Kí ó má ba à sọ di aláìmọ́ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. Èmi ni Olúwa tí ó sọ ọ́ di mímọ́.’”
för att han icke må ohelga sin livsfrukt bland sina fränder; ty jag är HERREN, som helgar honom.
16 Olúwa sì bá Mose sọ̀rọ̀ pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
17 “Sọ fún Aaroni pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú irú-ọmọ rẹ̀ ní ìran-ìran wọn, tí ó bá ní ààrùn kan, kí ó má ṣe súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ ohun jíjẹ sí Ọlọ́run rẹ̀.
Tala till Aron och säg: Av dina avkomlingar i kommande släkten skall ingen som har något lyte träda fram för att frambära sin Guds spis.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi ẹbọ náà. Kò gbọdọ̀ sí afọ́jú tàbí arọ, alábùkù ara tàbí àwọn tí ara wọn kò pé.
Ingen skall träda fram, som har något lyte, varken en blind eller en halt, eller en som har lyte i ansiktet, eller som har någon lem för stor,
19 Kò gbọdọ̀ sí ẹnikẹ́ni yálà ó rọ lápá lẹ́sẹ̀,
ingen som har brutit arm eller ben,
20 tàbí tí ó jẹ́ abuké, tàbí tí ó ya aràrá tàbí tí ó ní àìsàn ojú tàbí tí ó ní egbò tàbí tí a ti yọ nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀.
ingen som är puckelryggig eller förkrympt, eller som har fel på ögat, eller som har skabb eller annat utslag, eller som är snöpt.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó ní àbùkù nínú irú-ọmọ Aaroni àlùfáà kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ tí fi iná sun sí Olúwa. Nítorí pé ó jẹ́ alábùkù, kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ àkàrà sí Ọlọ́run rẹ̀.
Av prästen Arons avkomlingar skall ingen som har något lyte gå fram för att frambära HERRENS eldsoffer; han har ett lyte, han skall icke gå fram för att frambära sin Guds spis.
22 Ó lè jẹ́ oúnjẹ Ọlọ́run rẹ̀ tàbí èyí tí ó mọ́ jùlọ, ṣùgbọ́n torí pé ó ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi aṣọ títa tàbí pẹpẹ.
Sin Guds spis må han äta, både det som är högheligt och det som är heligt,
23 Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò ba ibi mímọ́ mi jẹ́ torí pé, Èmi Olúwa ló ti sọ wọ́n di mímọ́.’”
men eftersom han har ett lyte, skall han icke gå in till förlåten, ej heller skall han gå fram till altaret, på det att han icke må ohelga mina heliga ting; ty jag är HERREN, som helgar dem.
24 Wọ̀nyí ni àwọn ohun tí Mose sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ Aaroni àti gbogbo ọmọ Israẹli.
Och Mose talade detta till Aron och hans söner och alla Israels barn.

< Leviticus 21 >