< Leviticus 21 >
1 Olúwa sọ fún Mose wí pe, “Bá àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú wọn kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí àwọn ènìyàn wọn tí ó kù.
Rzekł też Pan do Mojżesza: Mów do kapłanów, synów Aaronowych, a powiedz im: Niech się nad umarłym nie plugawi żaden kapłan w ludu swym;
2 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe àwọn tí ó súnmọ́ ọn bí ìyá rẹ̀, baba rẹ̀, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, àti arákùnrin rẹ̀.
Tylko przy pokrewnym swoim, powinowatym swoim, przy matce swej, i przy ojcu swym, i przy synu swym, i przy córce swej, i przy bracie swym;
3 Tàbí fún arábìnrin rẹ̀ tí kò ì tí ì wọ ilé ọkọ tí ó ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí tí arábìnrin bẹ́ẹ̀, ó lè sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
Także przy siostrze swej, pannie sobie najbliższej, która nie miała męża; przy tych splugawić się może.
4 Nítorí tí ó jẹ́ olórí, òun kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ ba ara rẹ̀ jẹ́ láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Nie splugawi się przy przełożonym ludu swego, tak żeby się zmazał.
5 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ fá irun orí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ rẹ́ irùngbọ̀n rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi abẹ ya ara rẹ̀ láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Nie będą sobie czynić łysiny na głowie swej, i brody swej nie mają golić, ani na ciele swem czynić będą rzezania.
6 Wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún Ọlọ́run, kí wọ́n má ba à sọ orúkọ Ọlọ́run wọn di àìmọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń fi iná sun ẹbọ sí Olúwa wọn, ti ó jẹ oúnjẹ Ọlọ́run wọn. Nítorí náà wọn gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́.
Świętymi będą Bogu swemu, i nie splugawią imienia Boga swego; albowiem ofiary ogniste Pańskie, chleb Boga swego, ofiarują; przetoż będą świętymi.
7 “‘Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ fẹ́ panṣágà tàbí obìnrin tí ó ti fi ọkùnrin ba ara rẹ̀ jẹ́ tàbí obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti kọ̀sílẹ̀ nítorí pé àwọn àlùfáà jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Niewiasty wszetecznej, i w panieństwie naruszonej, pojmować nie będą; także niewiasty odrzuconej od męża jej, pojmować nie będą; bo święty jest każdy z nich Bogu swemu.
8 Àwọn ènìyàn gbọdọ̀ máa kà wọ́n sí mímọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń rú ẹbọ oúnjẹ fún mi. Èmi ni Olúwa, mo jẹ́ mímọ́, mo sì ya àwọn ènìyàn mi sí mímọ́.
A tak będziesz go miał za świętego, bo chleb Boga twego ofiaruje; przetoż świętym będzie tobie, bom Ja święty Pan, który poświęcam was.
9 “‘Bí ọmọbìnrin àlùfáà kan bá fi iṣẹ́ àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ó dójútì baba rẹ̀, iná ni a ó dá sun ún.
Jeźliby się córka kapłańska nierządu dopuściła, ojca swego zelżyła, ogniem spalona będzie.
10 “‘Lẹ́yìn tí a ti fi òróró yan olórí àlùfáà láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, tí a sì ti fi àmì òróró yàn án láti máa wọ aṣọ àlùfáà, ó gbọdọ̀ tọ́jú irun orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fa aṣọ rẹ̀ ya láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Najwyższy też kapłan między bracią swą, na którego głowę wylany jest olejek pomazania, i który poświęcił ręce swe, aby obłoczył szaty święte, głowy swej nie obnaży i szat swoich nie rozedrze;
11 Kí ó ma ṣe wọlé tọ òkú lọ, kí ó má ṣe sọ ará rẹ di àìmọ́ nítorí baba tàbí nítorí ìyá rẹ̀.
I do żadnego z umarłych nie przystąpi, a nawet i przy ojcu swym, i przy matce swej plugawić się nie będzie.
12 Kò gbọdọ̀ kúrò ní ibi mímọ́ Ọlọ́run tàbí kí ó sọ ọ́ di aláìmọ́ torí pé a ti fi ìfòróróyàn Ọlọ́run yà á sí mímọ́. Èmi ni Olúwa.
Z świątnicy też nie wynijdzie, aby nie splugawił świątnicy Boga swego, gdyż korona olejku pomazania Boga jego jest na nim: Jam Pan.
13 “‘Ọmọbìnrin tí yóò fẹ́ gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí kò mọ ọkùnrin rí.
Tenże pannę w panieństwie jej pojmie.
14 Kò gbọdọ̀ fẹ́ opó tàbí ẹni tí a kọ̀sílẹ̀ tàbí obìnrin tí ó ti fi àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n kí ó fẹ́ obìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí, láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Wdowy, i odrzuconej i splugawionej nierządnicy, żadnej z tych nie pojmie; ale pannę z ludu swego za żonę.
15 Kí ó má ba à sọ di aláìmọ́ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. Èmi ni Olúwa tí ó sọ ọ́ di mímọ́.’”
A nie będzie plugawił nasienia swego w ludu swym; bom Ja Pan, który go poświęcam.
16 Olúwa sì bá Mose sọ̀rọ̀ pé,
Przytem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
17 “Sọ fún Aaroni pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú irú-ọmọ rẹ̀ ní ìran-ìran wọn, tí ó bá ní ààrùn kan, kí ó má ṣe súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ ohun jíjẹ sí Ọlọ́run rẹ̀.
Powiedz Aaronowi, i rzecz: Ktobykolwiek z potomstwa swego w narodziech swych, miał na sobie wadę, niechaj nie przystępuje, aby ofiarował chleb Boga swego;
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi ẹbọ náà. Kò gbọdọ̀ sí afọ́jú tàbí arọ, alábùkù ara tàbí àwọn tí ara wọn kò pé.
Bo żaden mąż, który by miał na sobie wadę, przystępować nie ma; mąż ślepy, albo chromy, albo niezupełnych albo zbytnich członków;
19 Kò gbọdọ̀ sí ẹnikẹ́ni yálà ó rọ lápá lẹ́sẹ̀,
Także mąż, który by miał złamaną nogę, albo złamaną rękę;
20 tàbí tí ó jẹ́ abuké, tàbí tí ó ya aràrá tàbí tí ó ní àìsàn ojú tàbí tí ó ní egbò tàbí tí a ti yọ nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀.
Także garbaty, i płynących oczu, albo który ma bielmo na oku swem, albo krostawy, albo parszywy, albo wypukły:
21 Ẹnikẹ́ni tí ó ní àbùkù nínú irú-ọmọ Aaroni àlùfáà kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ tí fi iná sun sí Olúwa. Nítorí pé ó jẹ́ alábùkù, kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ àkàrà sí Ọlọ́run rẹ̀.
Wszelki mąż, który by miał jaką wadę, z potomstwa Aarona kapłana nie przystąpi, aby ofiarował ofiary ogniste Panu; wada na nim jest, nie przystąpi, aby ofiarował chleb Boga swego.
22 Ó lè jẹ́ oúnjẹ Ọlọ́run rẹ̀ tàbí èyí tí ó mọ́ jùlọ, ṣùgbọ́n torí pé ó ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi aṣọ títa tàbí pẹpẹ.
Chleba jednak Boga swego z rzeczy najświętszych i poświęconych pożywać będzie.
23 Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò ba ibi mímọ́ mi jẹ́ torí pé, Èmi Olúwa ló ti sọ wọ́n di mímọ́.’”
Wszakże za zasłonę nie wnijdzie, i do ołtarza nie przystąpi, bo wada na nim jest, aby nie splugawił świątnicy mojej; bom Ja Pan, który ją poświęcam.
24 Wọ̀nyí ni àwọn ohun tí Mose sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ Aaroni àti gbogbo ọmọ Israẹli.
To mówił Mojżesz do Aarona, i do synów jego, i do wszystkich synów Izraelskich.