< Leviticus 21 >
1 Olúwa sọ fún Mose wí pe, “Bá àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú wọn kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí àwọn ènìyàn wọn tí ó kù.
Og Herren sagde til Mose: Tal til Præsterne, Arons Sønner, og sig til dem: En Præst skal ikke gøre sig uren ved et Lig iblandt sit Folk,
2 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe àwọn tí ó súnmọ́ ọn bí ìyá rẹ̀, baba rẹ̀, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, àti arákùnrin rẹ̀.
uden ved hans næste Slægt, som ham næst tilhører, ved hans Moder og ved hans Fader og ved hans Søn og ved hans Datter og ved hans Broder
3 Tàbí fún arábìnrin rẹ̀ tí kò ì tí ì wọ ilé ọkọ tí ó ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí tí arábìnrin bẹ́ẹ̀, ó lè sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
og ved hans Søster, som er en Jomfru, hans næste Paarørende, som ikke har været nogen Mands Hustru; ved hende maa han gøre sig uren.
4 Nítorí tí ó jẹ́ olórí, òun kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ ba ara rẹ̀ jẹ́ láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Han skal ikke besmitte sig, da han er en Herre iblandt sit Folk, saa han vanhelliger sig.
5 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ fá irun orí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ rẹ́ irùngbọ̀n rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi abẹ ya ara rẹ̀ láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
De skulle ikke gøre deres Hoved skaldet og ikke afrage det yderste af deres Skæg, og ej skære et Indsnit i deres Kød.
6 Wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún Ọlọ́run, kí wọ́n má ba à sọ orúkọ Ọlọ́run wọn di àìmọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń fi iná sun ẹbọ sí Olúwa wọn, ti ó jẹ oúnjẹ Ọlọ́run wọn. Nítorí náà wọn gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́.
De skulle være hellige for deres Gud og ikke vanhellige deres Guds Navn; thi de ofre Herrens Ildoffer, deres Guds Brød, og derfor skulle de være aldeles hellige.
7 “‘Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ fẹ́ panṣágà tàbí obìnrin tí ó ti fi ọkùnrin ba ara rẹ̀ jẹ́ tàbí obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti kọ̀sílẹ̀ nítorí pé àwọn àlùfáà jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run wọn.
De skulle ikke tage nogen Horekone eller en, som er krænket, til Ægte; og den Kvinde, som er forskudt af sin Mand, skulle de ikke tage; thi han er hellig for Gud.
8 Àwọn ènìyàn gbọdọ̀ máa kà wọ́n sí mímọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń rú ẹbọ oúnjẹ fún mi. Èmi ni Olúwa, mo jẹ́ mímọ́, mo sì ya àwọn ènìyàn mi sí mímọ́.
Derfor skal du holde ham hellig, thi han ofrer din Guds Brød; han skal være dig hellig, thi jeg Herren er hellig, som gør eder hellige.
9 “‘Bí ọmọbìnrin àlùfáà kan bá fi iṣẹ́ àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ó dójútì baba rẹ̀, iná ni a ó dá sun ún.
Og naar nogen Præsts Datter begynder at bedrive Hor, har hun vanhelliget sin Fader, hun skal brændes med Ild.
10 “‘Lẹ́yìn tí a ti fi òróró yan olórí àlùfáà láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, tí a sì ti fi àmì òróró yàn án láti máa wọ aṣọ àlùfáà, ó gbọdọ̀ tọ́jú irun orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fa aṣọ rẹ̀ ya láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
Og den, som er Ypperstepræst iblandt sine Brødre, paa hvis Hoved Salveolien er udøst, og hvis Haand man har fyldt, for at han skal iføre sig Klæderne, han skal ikke blotte sit Hoved og ej sønderrive sine Klæder.
11 Kí ó ma ṣe wọlé tọ òkú lọ, kí ó má ṣe sọ ará rẹ di àìmọ́ nítorí baba tàbí nítorí ìyá rẹ̀.
Og han skal ikke komme til noget Lig, han skal ikke gøre sig uren, hverken ved sin Fader eller ved sin Moder.
12 Kò gbọdọ̀ kúrò ní ibi mímọ́ Ọlọ́run tàbí kí ó sọ ọ́ di aláìmọ́ torí pé a ti fi ìfòróróyàn Ọlọ́run yà á sí mímọ́. Èmi ni Olúwa.
Og han skal ikke gaa ud af Helligdommen, og han skal ikke vanhellige sin Guds Helligdom; thi hans Guds Salveolies Hovedsmykke er paa ham. Jeg er Herren.
13 “‘Ọmọbìnrin tí yóò fẹ́ gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí kò mọ ọkùnrin rí.
Og han skal tage sig en Hustru i hendes Jomfrustand.
14 Kò gbọdọ̀ fẹ́ opó tàbí ẹni tí a kọ̀sílẹ̀ tàbí obìnrin tí ó ti fi àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n kí ó fẹ́ obìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí, láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
En Enke eller en forskudt eller en krænket, en Hore, dem skal han ikke tage, men en Jomfru af sit Folk skal han tage til Hustru.
15 Kí ó má ba à sọ di aláìmọ́ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. Èmi ni Olúwa tí ó sọ ọ́ di mímọ́.’”
Og han skal ikke vanhellige sin Sæd iblandt sit Folk; thi jeg er Herren, som gør ham hellig.
16 Olúwa sì bá Mose sọ̀rọ̀ pé,
Og Herren talede til Mose og sagde:
17 “Sọ fún Aaroni pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú irú-ọmọ rẹ̀ ní ìran-ìran wọn, tí ó bá ní ààrùn kan, kí ó má ṣe súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ ohun jíjẹ sí Ọlọ́run rẹ̀.
Tal til Aron og sig: Naar der er en Mand af din Sæd i deres Slægter, paa hvem der er en Lyde, han skal ikke komme nær til, at ofre sin Guds Brød;
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi ẹbọ náà. Kò gbọdọ̀ sí afọ́jú tàbí arọ, alábùkù ara tàbí àwọn tí ara wọn kò pé.
thi ingen Mand, paa hvem der er Lyde, skal komme nær, hvad enten det er en Mand, som er blind eller lam, eller som har noget Lem for kort eller for langt,
19 Kò gbọdọ̀ sí ẹnikẹ́ni yálà ó rọ lápá lẹ́sẹ̀,
eller en Mand, som har Bræk paa Fod eller Bræk paa Haand,
20 tàbí tí ó jẹ́ abuké, tàbí tí ó ya aràrá tàbí tí ó ní àìsàn ojú tàbí tí ó ní egbò tàbí tí a ti yọ nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀.
eller som er krogrygget eller er en Dværg eller har Men paa sit Øje, eller som har Skurv eller Fnat, eller som har Brok.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó ní àbùkù nínú irú-ọmọ Aaroni àlùfáà kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ tí fi iná sun sí Olúwa. Nítorí pé ó jẹ́ alábùkù, kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ àkàrà sí Ọlọ́run rẹ̀.
Og ingen Mand af Præsten Arons Sæd, paa hvem der er Lyde, skal gaa frem at ofre Herrens Ildofre; der er Lyde paa ham, han skal ikke gaa frem til at ofre sin Guds Brød.
22 Ó lè jẹ́ oúnjẹ Ọlọ́run rẹ̀ tàbí èyí tí ó mọ́ jùlọ, ṣùgbọ́n torí pé ó ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi aṣọ títa tàbí pẹpẹ.
Dog maa han æde sin Guds Brød, baade af de højhellige Ting og af de andre hellige Ting.
23 Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò ba ibi mímọ́ mi jẹ́ torí pé, Èmi Olúwa ló ti sọ wọ́n di mímọ́.’”
Kun skal han ikke komme til Forhænget og ej gaa frem til Alteret; thi der er Lyde paa ham, og han skal ikke vanhellige mine Helligdomme; thi jeg er Herren, som gør dem hellige.
24 Wọ̀nyí ni àwọn ohun tí Mose sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ Aaroni àti gbogbo ọmọ Israẹli.
Og Mose sagde dette til Aron og til hans Sønner og til alle Israels Børn.