< Leviticus 20 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, zicând:
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
Mai spune o dată copiilor lui Israel: Oricine dintre copiii lui Israel, sau dintre străinii care locuiesc temporar în Israel, dă pe cineva din sămânța sa lui Moloh, acela negreșit să fie dat morții, poporul să îl ucidă cu pietre.
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
Și îmi voi întoarce fața împotriva acelui om și îl voi stârpi din mijlocul poporului său, pentru că el a dat din sămânța sa lui Moloh, ca să spurce sanctuarul meu și să pângărească numele meu sfânt.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
Și dacă oamenii pământului fac cumva și își ascund ochii de la acel om, când el dă din sămânța sa lui Moloh și nu îl ucid;
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
Atunci îmi voi întoarce fața împotriva acelui om și împotriva familiei sale și îl voi stârpi din mijlocul poporului lor, pe el și pe toți cei ce merg curvind după el, ca să curvească cu Moloh.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Și sufletul care se întoarce după cei ce au demoni și după vrăjitori, ca să curvească după ei, eu îmi voi întoarce fața împotriva acelui suflet și îl voi stârpi din mijlocul poporului său.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Sfințiți-vă de aceea și fiți sfinți, pentru că eu sunt DOMNUL Dumnezeul vostru.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Și să țineți statutele mele și să le împliniți: Eu sunt DOMNUL care vă sfințește.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
Pentru că fiecare om ce blestemă pe tatăl său sau pe mama sa, negreșit să fie dat morții; cel ce a blestemat pe tatăl său sau pe mama sa, sângele său să fie asupra sa.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
Și bărbatul care comite adulter cu soția unui alt bărbat, chiar cel ce comite adulter cu soția aproapelui său, bărbatul și femeia adulteră să fie negreșit uciși.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Și bărbatul care se culcă cu soția tatălui său, a descoperit goliciunea tatălui său, amândoi negreșit să fie uciși; sângele lor să fie asupra lor.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Și dacă un bărbat se culcă cu nora sa, amândoi să fie uciși negreșit, au lucrat încurcătură; sângele lor să fie asupra lor.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
De asemenea dacă un bărbat se culcă cu un bărbat, precum se culcă cu o femeie, amândoi au făcut o urâciune, negreșit să fie uciși; sângele lor să fie asupra lor.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
Și dacă un bărbat ia o soție și pe mama ei, aceasta este stricăciune, să fie arși cu foc, deopotrivă el și ele; ca să nu fie stricăciune între voi.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
Și dacă un bărbat se culcă cu o fiară, negreșit să fie ucis; și să ucideți fiara.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
Și dacă o femeie se apropie de vreo fiară și se culcă cu ea, să ucizi și femeia și fiara, negreșit să fie ucise; sângele lor să fie asupra lor.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
Și dacă un bărbat ia pe sora sa, pe fiica tatălui său, sau pe fiica mamei sale și vede goliciunea ei și ea vede goliciunea lui, acesta este un lucru stricat; și să fie stârpiți înaintea ochilor poporului lor; cel ce a descoperit goliciunea surorii sale va purta propria nelegiuire.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
Și dacă un bărbat se culcă cu o femeie, având necurăția ei, și va descoperi goliciunea ei, el i-a dezgolit fântâna; iar ea și-a descoperit fântâna sângerării; și amândoi să fie stârpiți din mijlocul poporului lor.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
Și să nu descoperi goliciunea surorii mamei tale, sau a surorii tatălui tău, pentru că el dezgolește pe ruda sa apropiată, ei să poarte nelegiuirea lor.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
Și dacă un bărbat se va culca cu soția unchiului său, el a descoperit goliciunea unchiului său, să poarte păcatul lor, să moară fără copii.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
Și dacă un bărbat ia pe soția fratelui său, acesta este un lucru necurat, cel ce a descoperit goliciunea fratelui său, să fie fără copii.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
De aceea să țineți toate statutele mele și toate judecățile mele și să le împliniți, ca țara, în care eu vă aduc să locuiți în ea, să nu vă vomite afară.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
Și să nu umblați în obiceiurile națiunii, pe care o arunc afară dinaintea voastră, pentru că ei au făcut toate aceste lucruri și de aceea sunt dezgustat de ei.
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
Dar eu v-am spus: Veți moșteni țara lor și am să v-o dau vouă ca să o stăpâniți, o țară care curge cu lapte și miere: Eu sunt DOMNUL Dumnezeul vostru, care v-am separat de alte popoare.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
De aceea să deosebiți între vitele curate și necurate și între păsări necurate și curate; și să nu vă faceți sufletele scârboase prin vite, sau păsări, sau orice fel de târâtoare care se târăște pe pământ, pe care le-am separat de voi, ca fiind necurate.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
Și să îmi fiți sfinți, pentru că eu DOMNUL sunt sfânt și v-am separat de alte popoare, ca să fiți ai mei.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
De asemenea un bărbat sau o femeie care are demon, sau care este vrăjitor, negreșit să fie dat morții, să îi ucidă cu pietre, sângele lor să fie asupra lor.

< Leviticus 20 >