< Leviticus 20 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
Powiedz synom Izraelskim: Ktobykolwiek z synów Izraelskich, albo z przychodniów mieszkających w Izraelu ofiarował potomstwo swoje Molochowi, śmiercią niech umrze; lud ziemi niechaj go ukamionuje;
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
Bo Ja postawię twarz moję rozgniewaną przeciwko temu mężowi, i wytracę go z pośrodku ludu jego, przeto, iż potomstwo swoje ofiarował Molochowi, i splugawił świątnicę moję, a zmazał imię świątobliwości mojej.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
A jeźliby lud ziemi nie dbając przeglądał mężowi takiemu, który by ofiarował Molochowi potomstwo swe, i nie zabiłby go:
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
Tedy Ja postawię twarz moję zagniewaną przeciw temu mężowi i przeciw domowi jego, i wytracę go i wszystkie, którzy cudzołożąc, szliby za nim, aby cudzołożyli, naśladując Molocha, z pośrodku ludu jego.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Człowiek, który by się udał do czarowników, i do wieszczków, aby cudzołożył idąc za nimi, postawię twarz swoję rozgniewaną przeciwko niemu, i wytracę go z pośrodku ludu jego.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Przetoż poświęcajcie się, a bądźcie świętymi; bom Ja Pan, Bóg wasz.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
A strzeżcie ustaw moich, i czyńcie je; Jam Pan poświęcający was.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
Ktobykolwiek złorzeczył ojcu swemu, albo matce swej, śmiercią umrze; ojcu swemu, i matce swej złorzeczył, krew jego będzie na nim.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
Kto by się kolwiek cudzołóstwa dopuścił z czyją żoną, ponieważ cudzołożył z żoną bliźniego swego, śmiercią umrze cudzołożnik on i cudzołożnica.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Ktobykolwiek też spał z żoną ojca swego, sromotę ojca swego odkrył, śmiercią umrą oboje; krew ich będzie na nich.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Jeźliby też kto spał z synową swoją, śmiercią umrą oboje; obrzydliwości się dopuścili, krew ich będzie na nich.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Mąż także, który by z mężczyzną obcował sposobem niewieścim, obrzydliwość uczynili oba; śmiercią umrą, krew ich będzie na nich.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
Kto by też pojął córkę z matką jej, sprośna rzecz jest; ogniem spalą onego i onę, aby nie była ta sprośność między wami.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
Także kto by się złączył z bydlęciem, śmiercią umrze, bydlę też zabijecie.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
Niewiasta, która by przystąpiła do jakiego bydlęcia, aby z niem obcowała, zabijesz niewiastę i bydlę; śmiercią umrą, krew ich będzie na nich.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
Kto by też pojął siostrę swoję, córkę ojca swego, albo córkę matki swej, i widziałby sromotę jej, i ona by widziała sromotę jego, rzecz haniebna jest; przetoż wytraceni będą przed oczyma synów ludu swego; sromotę siostry swej odkrył, nieprawość swoję poniesie.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
Kto by spał z niewiastą czasu przyrodzonej choroby jej, i odkryłby sromotę jej, i obnażyłby płynienie jej, i ona by też odkrywała płynienie krwi swojej, wytraceni będą oboje z pośrodku ludu swego.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
Sromoty siostry matki twej i siostry ojca twego nie odkryjesz; bo kto by pokrewną swoję obnażył, nieprawość swoję poniesie.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
Kto by też spał z żoną stryja swego, sromotę stryja swego odkrył, grzech swój poniosą, bez dzieci pomrą.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
Także kto by pojął żonę brata swego, sprośność jest; sromotę brata swego odkrył, bez dzieci będą.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
Strzeżcież tedy wszystkich ustaw moich, i wszystkich sądów moich, a czyńcie je, aby was nie wyrzuciła ziemia, do której Ja was wprowadzę, abyście w niej mieszkali.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
A nie chodźcie w ustawach tego narodu, który Ja wypędzam od oblicza waszego; bo to wszystko czynili, i obrzydziłem je sobie.
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
Wam zaś powiedziałem: Wy posiądziecie ziemię ich, a Ja wam ją dam w dziedzictwo, ziemię opływającą mlekiem i miodem. Jam Pan, Bóg wasz, którym was wyłączył od innych narodów.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
A tak wy rozeznawajcie między bydlęciem czystem i nieczystem, i między ptakiem nieczystym i czystym, a nie plugawcie dusz waszych bydłem i ptastwem i wszystkiem, co się czołga po ziemi, którem wam odłączył za nieczyste.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
I będziecie mi świętymi, bom Ja święty Pan, i odłączyłem was od innych narodów, abyście byli moimi.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
Mąż albo niewiasta, w których by był duch czarnoksięski albo wieszczy, śmiercią umrą: kamieniem ukamionują ich, krew ich będzie na nich.

< Leviticus 20 >