< Leviticus 20 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Szóla ismét az Úr Mózesnek, mondván:
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
Izráel fiainak pedig mondd meg: Valaki Izráel fiai közül és az Izráelben tartózkodó jövevények közül odaadja az ő magzatát a Moloknak, halállal lakoljon, a földnek népe kövezze agyon kővel.
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
Én is kiontom haragomat az ilyen emberre, és kiirtom azt az ő népe közül, mivelhogy adott az ő magzatából a Moloknak, hogy megfertőztesse az én szentségemet, és megszentségtelenítse az én szent nevemet.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
Ha pedig a föld népe behúnyja szemeit az ilyen ember előtt, a mikor az oda adja az ő magzatát a Moloknak, és azt meg nem öli:
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
Akkor én ontom ki haragomat arra az emberre és annak házanépére, és kiirtom azt és mindazokat, a kik ő utána paráználkodnak, hogy a Molokkal paráználkodjanak, az ő népök közül.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
A mely ember pedig az ígézőkhöz és a jövendőmondókhoz fordul, hogy azok után paráználkodjék, arra is kiontom haragomat, és kiirtom azt az ő népe közül.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Szenteljétek meg azért magatokat, és szentek legyetek, mert én, az Úr, vagyok a ti Istenetek.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
És tartsátok meg az én rendeléseimet, és cselekedjétek azokat. Én vagyok az Úr, a ti megszentelőtök.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
Mert valaki szidalmazza az ő atyját vagy anyját, halállal lakoljon; atyját és anyját szidalmazta; vére rajta.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
Ha valaki más ember feleségével paráználkodik, mivelhogy az ő felebarátjának feleségével paráználkodik: halállal lakoljon a parázna férfi és a parázna nő.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Ha valaki az ő atyjának feleségével hál, az ő atyjának szemérmét fedi fel: halállal lakoljanak mindketten; vérök rajtok.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Ha valaki az ő menyével hál, halállal lakoljanak mindketten, fertelmességet követtek el; vérök rajtok.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
És ha valaki férfival hál, úgy a mint asszonynyal hálnak: útálatosságot követtek el mindketten, halállal lakoljanak; vérök rajtok.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
És ha valaki feleségül vesz valamely asszonyt annak anyjával egybe: fajtalankodás ez; tűzzel égessék meg azt és azokat, hogy ne legyen köztetek fajtalankodás.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
Ha pedig valaki barommal közösül, halállal lakoljon, és a barmot is öljétek meg.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
Ha valamely asszony akármely baromhoz járul, hogy az meghágja őt: öld meg mind az asszonyt, mind a barmot, halállal lakoljanak; vérök rajtok.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
És ha valaki feleségül veszi az ő leánytestvérét, atyjának leányát, vagy anyjának leányát, és meglátja annak szemérmét, és az is meglátja az ő szemérmét: gyalázatosság ez; azért irtassanak ki népök fiainak láttára, az ő leánytestvérének szemérmét fedte fel: viselje gonoszságának terhét.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
És ha valaki havi bajos asszonynyal hál, és felfedi annak szemérmét, és forrását feltakarja, és az asszony is felfedi az ő vérének forrását: mindketten irtassanak ki az ő népökből.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
A te anyád leánytestvérének, vagy az atyád leánytestvérének szemérmét se fedd fel; mivelhogy az ő vérrokonát takarja ki: viseljék gonoszságuk terhét.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
És ha valaki az ő nagynénjével hál, az ő nagybátyjának szemérmét fedte fel: viseljék gonoszságuk terhét, magtalanul haljanak meg.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
Ha pedig elveszi valaki az ő fiútestvérének feleségét: vérfertőzés az; az ő fiútestvérének szemérmét fedte fel; magtalanok legyenek.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
Tartsátok meg minden rendelésemet és minden végzésemet, és azokat cselekedjétek, hogy ki ne okádjon titeket az a föld, a melybe én viszlek be titeket, hogy ott lakjatok.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
És ne járjatok annak a népnek rendtartási szerint, a melyet kiűzök én előletek. Mivelhogy mindezeket cselekedték, azért megútáltam őket.
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
Néktek pedig mondom: Ti örökölni fogjátok az ő földüket, mert én néktek adom azt örökségül, azt a tejjel és mézzel folyó földet. Én vagyok az Úr, a ti Istenetek, a ki kiválasztottalak titeket a népek közül.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
Tegyetek különbséget azért a tiszta és tisztátalan barmok között, a tiszta és tisztátalan szárnyas állatok között, és ne fertőztessétek meg magatokat barommal vagy szárnyas állattal, sem semmiféle földön csúszó állattal, a melyeket megkülönböztettem előttetek, mint tisztátalanokat.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
És legyetek nékem szentek, mert én, az Úr, szent vagyok, a ki kiválasztottalak titeket a népek közül, hogy enyéim legyetek.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
És akár férfi, akár asszony, hogyha ígéző vagy jövendőmondó lesz közöttök, halállal lakoljanak; kővel kövezzétek azokat agyon; vérök rajtok.

< Leviticus 20 >