< Leviticus 20 >
Et l'Éternel parla à Moïse en ces termes:
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
Et tu diras aux enfants d'Israël: Quiconque parmi les enfants d'Israël et les étrangers domiciliés en Israël donnera de ses enfants à Moloch, sera mis à mort; le peuple du pays le lapidera.
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
Et moi, je tournerai ma face contre cet homme-là, et je l'éliminerai du sein de son peuple pour avoir donné de ses enfants à Moloch, et ainsi souillé mon Sanctuaire et profané mon saint nom.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
Et si le peuple du pays veut fermer les yeux sur le fait de cet homme qui a donné de ses enfants à Moloch, afin de ne point le faire mourir,
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
je tournerai ma face contre cet homme-là et contre sa race et je l'éliminerai du sein de leur peuple lui et tous ceux qui le suivent dans sa prostitution pour aller se prostituer à Moloch.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Et quant à la personne qui s'adressera aux évocateurs et aux devins pour se prostituer à leur suite, je tournerai ma face contre cette personne-là et l'éliminerai du sein de son peuple.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Conservez-vous donc saints, et soyez saints, car je suis l'Éternel, votre Dieu.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Et gardez mes statuts et vous y conformez. Je suis l'Éternel qui veux vous sanctifier.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
Quiconque maudira son père ou sa mère sera mis à mort; il a maudit son père et sa mère; son sang retombe sur lui.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
Et si un homme commet adultère avec la femme d'un autre, s'il commet adultère avec la femme de son prochain, l'homme et la femme adultères seront mis à mort.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Et si quelqu'un a commerce avec la femme de son père, il a découvert la nudité de son père: ils seront l'un et l'autre mis à mort; leur sang retombe sur eux.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Et si quelqu'un a commerce avec sa bru, ils seront l'un et l'autre mis à mort, ils ont commis un hideux attentat, leur sang retombe sur eux.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Et si quelqu'un a commerce avec un homme comme on a commerce avec une femme, ils ont l'un et l'autre fait une chose abominable: ils seront mis à mort; leur sang retombe sur eux.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
Et si quelqu'un prend pour femmes la fille et la mère, c'est un crime: ils seront brûlés lui et elles, afin que ce crime n'existe pas parmi vous.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
Et si quelqu'un a ce commerce avec un animal, il sera mis à mort, et vous tuerez aussi l'animal.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
Et si une femme se livre à un animal quelconque pour s'accoupler avec lui, tu feras périr la femme et l'animal; ils seront mis à mort; leur sang retombe sur eux.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
Et si quelqu'un prend pour femme sa sœur, fille de son père, ou fille de sa mère, et qu'il voie sa nudité, et qu'elle voie sa nudité, c'est une infamie, et ils seront éliminés sous les yeux des enfants de leur peuple; il a découvert la nudité de sa sœur, il est sous le poids de sa faute.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
Et si un homme a commerce avec une femme pendant son indisposition et découvre sa nudité et met à nu la source de son sang, et qu'elle-même montre la source de son sang, ils seront l'un et l'autre éliminés du sein de leur peuple.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
Et tu ne découvriras point la nudité de la sœur de ta mère ou de la sœur de ton père; car c'est découvrir celle qui est de son sang; ils sont sous le poids de leur faute.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
Et si quelqu'un a commerce avec la femme de son oncle, il a découvert la nudité de son oncle; ils sont sous le poids de leur péché; ils mourront sans enfants.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
Et si quelqu'un prend la femme de son frère, c'est une immondicité, il a découvert la nudité de son frère ils seront sans enfants.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
Gardez donc tous mes statuts et toutes mes lois, et pratiquez-les, et vous ne serez pas vomis par le pays où je vais vous introduire pour vous y établir.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
Et ne suivez pas les usages des peuples que j'expulserai devant vous; car ils ont fait toutes ces choses et je les ai pris en dégoût, et je vous ai dit:
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
C'est vous qui posséderez leur pays, et je vous le donne en propriété, pays découlant de lait et de miel. Je suis l'Éternel, votre Dieu, qui vous ai séparés des peuples.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
Et distinguez entre l'animal pur et l'animal impur, et entre l'oiseau impur et l'oiseau pur, afin que vous ne rendiez pas vos personnes abominables par les animaux et les oiseaux et tout ce qui rampe sur la terre, et que je vous ai fait distinguer comme impur.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
Soyez saints pour moi, car je suis Saint, moi l'Éternel, et je vous ai séparés des peuples pour que vous soyez à moi.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
Et s'il se trouve parmi vous un homme ou une femme qui pratique les évocations ou la divination, ils seront mis à mort, on les lapidera, leur sang retombe sur eux.