< Leviticus 20 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse et dit:
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
Tu diras aux enfants d'Israël: « Si quelqu'un parmi les enfants d'Israël ou parmi les étrangers qui vivent en Israël donne un de ses descendants à Moloch, il sera puni de mort. Les habitants du pays lapideront cette personne.
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
Moi aussi, je tournerai ma face contre cet homme, et je le retrancherai du milieu de son peuple, parce qu'il a donné de sa progéniture à Moloch, pour souiller mon sanctuaire et profaner mon saint nom.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
Si tous les habitants du pays cachent les yeux de cette personne lorsqu'elle donne de sa progéniture à Moloc, et ne la font pas mourir,
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
je tournerai ma face contre cet homme et contre sa famille, et je la retrancherai du milieu de son peuple, ainsi que tous ceux qui se prostituent après lui pour se prostituer à Moloc.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
"'Celui qui se tourne vers les médiums et les magiciens, pour se prostituer après eux, je tournerai ma face contre lui, et je le retrancherai du milieu de son peuple.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
« Sanctifiez-vous donc et soyez saints, car je suis Yahvé votre Dieu.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Vous observerez mes lois et vous les mettrez en pratique. C'est moi, Yahvé, qui vous sanctifie.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
"'Car quiconque maudit son père ou sa mère sera puni de mort. Il a maudit son père ou sa mère. Son sang retombera sur lui.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
"'L'homme qui commet un adultère avec la femme d'un autre homme, même celui qui commet un adultère avec la femme de son prochain, l'adultère et la femme adultère seront punis de mort.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
"'L'homme qui couche avec la femme de son père a découvert la nudité de son père. Ils seront tous deux mis à mort. Leur sang retombera sur eux.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
"'Si un homme couche avec sa belle-fille, ils seront tous deux mis à mort. Ils ont commis une perversion. Leur sang retombera sur eux.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
"'Si un homme couche avec un mâle, comme avec une femme, tous deux ont commis une abomination. Ils seront mis à mort. Leur sang retombera sur eux.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
"'Si un homme prend une femme et sa mère, c'est une infamie. Ils seront brûlés au feu, lui et elles, afin qu'il n'y ait pas de méchanceté parmi vous.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
"'Si un homme couche avec un animal, il sera mis à mort, et vous tuerez l'animal.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
"'Si une femme s'approche d'un animal et couche avec lui, vous tuerez la femme et l'animal. Ils seront mis à mort. Leur sang retombera sur eux.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
"'Si un homme prend sa sœur, fille de son père ou fille de sa mère, et qu'il voit sa nudité, et qu'elle voit sa nudité, c'est une honte. Ils seront retranchés aux yeux des enfants de leur peuple. Il a découvert la nudité de sa sœur. Il portera son iniquité.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
"'Si un homme couche avec une femme qui a ses règles et découvre sa nudité, il a mis à nu sa source, et elle a découvert la source de son sang. Tous deux seront retranchés du milieu de leur peuple.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
"'Tu ne découvriras pas la nudité de la sœur de ta mère, ni celle de la sœur de ton père, car il a mis à nu son proche parent. Ils porteront la peine de leur iniquité.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
Si un homme couche avec la femme de son oncle, il a découvert la nudité de son oncle. Ils porteront la peine de leur péché. Ils mourront sans enfant.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
"'Si un homme prend la femme de son frère, c'est une impureté. Il a découvert la nudité de son frère. Ils seront sans enfants.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
"'Vous observerez donc toutes mes lois et toutes mes ordonnances, et vous les mettrez en pratique, afin que le pays où je vous fais habiter ne vous vomisse pas.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
Tu ne marcheras pas selon les coutumes de la nation que je rejette devant toi; car ils ont fait toutes ces choses, et c'est pourquoi je les ai en horreur.
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
Mais je vous ai dit: « Vous hériterez de leur pays, et je vous le donnerai en propriété, un pays où coulent le lait et le miel. » Je suis Yahvé, votre Dieu, qui vous a séparés des peuples.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
"'Vous ferez donc la distinction entre l'animal pur et l'impur, et entre le volatile impur et le pur. Vous ne vous rendrez pas abominables par un animal, par un oiseau ou par tout ce dont regorge le sol, que j'ai séparé de vous comme impur pour vous.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
Vous serez saints pour moi, car moi, Yahvé, je suis saint, et je vous ai séparés des peuples, pour que vous soyez à moi.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
"'Un homme ou une femme qui est un médium ou un magicien sera mis à mort. Ils seront lapidés. Leur sang retombera sur eux. »

< Leviticus 20 >