< Leviticus 20 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
BAWIPA ni Mosi koe, nang ni Isarel miphunnaw koe bout na dei pouh hane teh,
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
Isarel taminaw thoseh, Isarelnaw koe kho ka sak e alouke miphunnaw thoseh, amae canaw Molek koe, ka poe e tami teh thei roeroe han. Khocanaw ni talung hoi a dei awh han.
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
Kaie hmuen kathoung kakhin sak niteh, Ka min kathoung kamathout sak niteh, amae canaw Molek koe ka poe e tami teh, Kai ni mithmaithung sin vaiteh, a miphun dawk hoi ka takhoe han.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
Amae canaw Molek koe ka poe e tami hah, khocanaw ni nout laipalah thet awh hoeh pawiteh,
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
Hottelah kaawm e tami hoi a imthungkhunaw hah, Kai ni mithmaithung sin vaiteh, ahni hai thoseh, ahni hoi cungtalah Molek koe, ka kâyawtnaw hai thoseh, ahnimae miphun dawk hoi ka takhoe han.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Lam ka phen ni teh kahrai khueyue koe kamlang e taminaw hoi camkathoumnaw koe kâyawt e naw hah, mithmaithung sin vaiteh, a miphun dawk hoi ka takhoe han.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Nangmae BAWIPA KAI Cathut teh kathoung dawkvah nangmouh hai kâthoung sak awh nateh, kathoung lah awm awh.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Kaie ka phunglamnaw hah na tarawi awh han. Kai teh BAWIPA, nangmouh na kathoung sak e BAWIPA doeh.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
Apipatethai a manu, hoi a na pa thoe ka bo e tami pueng teh, thei roeroe lah ao han. A manu hoi a na pa thoe a bo dawkvah, a thi phu teh amae lû dawk a bo han.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
Ayâ yu yonkhai pawiteh, ka uicuk e napui hoi tongpa hah mek thei lah ao han.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Apihai a na pa e yu yonkhai pawiteh, a na pa kaya sak e lah ao dawkvah, hote napui hoi tongpa mek thei lah ao han. Ahnimae thi phu teh amae lû dawk a bo han.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Apihai amae langa ipkhai pawiteh, ahnimouh roi panuettho e hno hah a sak dawkvah, mek thei lah ao han.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
Apihai napui ikhai e patetlah tongpa reira ipkhai pawiteh, ahnimouh roi teh panuettho e hno a sak roi dawkvah, mek thei lah ao han. Ahnimouh roi e thi phu teh amamouh roi dawk a bo han.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
Apihai a manu hoi canu a yu lah mek lat pawiteh, Hot teh, kahawihoehe hno doeh. Nangmouh koevah kahawihoehe hno ao hoeh nahanelah, ahnimanaw teh hmai na sawi awh han.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
Apihai saring ipkhai pawiteh, ahni teh thei lah ao han. Hote saring hai thei lah ao han.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
Napui ni saring koe kâ ipkhai sak pawiteh, hote napui hoi saring teh mek thei lah ao han. Ahnie thi phu teh amae lû dawk a bo han.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
Tongpa ni a tawncanu, a na pa e canu, na hoehpawiteh, a manu e canu a yu lah a paluen teh ipkhai pawiteh, hot hateh, kamsoumhoehe hno doeh. Ahnimouh roi teh a taminaw e hmaitung hoi takhoe lah ao han. Hote tongpa teh amae tawncanu a okhai dawkvah a yonnae phu ama ni a khang han.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
Tongpa ni kampheng lahun e napui ipkhai pawiteh, thi palawng hanlah a lungkuep roi dawkvah, ahnimouh roi teh a miphun dawk hoi takhoe lah ao han.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
Na mani hoi na manta na ipkhai mahoeh. Hottelah, kâhnai e imthung hoi ka ipawm e tami teh amamae yonnae a khang han.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
Tongpa ni a na pa e hmaunawngha yu ipkhai pawiteh, a na pa e hmaunawngha hoi dueng kâkuen e a ikhai dawkvah, ahnimouh teh amae yon phu teh amae lû dawk a bo han. Carôe laihoi a due han.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
Tami ni a hmaunawngha e yu ipkhai pawiteh, kakhin e hno lah ao. A hmaunawngha hoi dueng kâkuen e a ikhai dawkvah, ahnimouh teh carôe lahoi a due han.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
Kai ni nangmouh na hrawi awh teh, kho na sak hane ram ni na palo awh hoeh nahanelah, Kaie phunglawknaw pueng na tarawi awh han.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
Nangmae hmalah ka takhoe e miphunnaw e singyoe hah na tarawi awh mahoeh. Ahnimanaw ni hot patet e hno a sak awh dawkvah ka panuet.
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
Ahnimae ram lah kaawm e sanutui hoi khoitui a lawngnae ram hah, nangmouh ni râw lah na coe awh hanelah, Kai ni khoeroe na poe awh han telah Kai ni kâ na poe awh toe. Kai teh alouke miphunnaw hoi nangmouh na kapek e nangmae BAWIPA Cathut lah ka o.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
Hatdawkvah, kathounge moi, kathounghoehe moi, kathounge tava, kathounghoehe tavanaw hah na kapek han. Kai ni kapek e patetlah Kathounghoehe moi, tava, talai dawk a von hoi kâva e saring buetbuet touh lahoi namahoima kâkhinsak awh hanh.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
Kai Cathut, kathoung dawkvah nangmouh na panki teh Jentelnaw hoi na kapek dawkvah, Kai hanelah na kâthoung awh han.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
Tongpa thoseh, napui thoseh, kahrai khueyue, camkathoum lah kaawm e tami teh thei roeroe lah ao han. Hot patet e tami teh, talung hoi dei lah ao han. Amae thi phu amae lû dawk a bo han.

< Leviticus 20 >