< Leviticus 19 >
2 “Bá gbogbo àpéjọpọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ mímọ́ nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ mímọ́.
Nang ni Isarel miphun, rangpuinaw koe bout na dei pouh hane teh, nangmae BAWIPA, Kai teh kathounge patetlah nangmouh hai thoung van awh.
3 “‘Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ bọ̀wọ̀ fún ìyá àti baba rẹ̀, kí ẹ sì ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Tami pueng ni na manu hoi na pa na bari awh han. Kaie sabbath hnin hai na ya awh han. Kai teh nangmae BAWIPA Cathut doeh.
4 “‘Ẹ má ṣe yípadà tọ ère òrìṣà lẹ́yìn, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ rọ ère òrìṣà idẹ fún ara yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Kutsak na bawk awh mahoeh. Ma hanelah hlun e cathutnaw na sak awh mahoeh. Kai teh nangmae BAWIPA Cathut doeh.
5 “‘Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, kí ẹ̀yin kí ó ṣe é ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà dípò yín.
Roum thuengnae sathei BAWIPA koe thuengnae na sak pawiteh, BAWIPA lung ka youk lah na thueng awh han.
6 Ní ọjọ́ tí ẹ bá rú u náà ni ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ tàbí ní ọjọ́ kejì; èyí tí ó bá ṣẹ́kù di ọjọ́ kẹta ni kí ẹ fi iná sun.
Thuengnae hnin hoi atangtho hnin dawk na ca awh han. Cawi pawiteh, a tawkkahnin teh hmai na sawi awh han.
7 Bí ẹ bá jẹ nínú èyí tí ó ṣẹ́kù di ọjọ́ kẹta, àìmọ́ ni èyí jẹ́, kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà.
Tawkkahnin dawk yitca nakunghai na cat awh pawiteh, panuettho e lah ao. Lungyouk lah awm mahoeh.
8 Nítorí náà ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù, nítorí pé ó ti ba ohun mímọ́ Olúwa jẹ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ka cat e tami teh BAWIPA thoungnae a khinsak dawkvah, a yonnae phu teh ama ni a khang han. Hote tami teh a miphun dawk hoi takhoe lah ao han.
9 “‘Nígbà tí ẹ̀yin bá kórè nǹkan oko yín, kí ẹ̀yin kí ó fi díẹ̀ sílẹ̀ láìkórè ní àwọn igun oko yín, ẹ̀yin kò sì gbọdọ̀ ṣa ẹ̀ṣẹ́ (nǹkan oko tí ẹ ti gbàgbé tàbí tí ó bọ́ sílẹ̀).
Na law dawk e cang na a torei teh, lawrai lae koung na a awh mahoeh. Cabong bout na hrawm a torei hai na pahnim a e bout na hrawm awh mahoeh.
10 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kórè oko yín tan pátápátá, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣa èso tí ó rẹ̀ bọ́ sílẹ̀ nínú ọgbà àjàrà yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn aláìní àti fún àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Misur paw hai koung na khi awh mahoeh. Kacawie a paw bout na khi awh mahoeh. Hote a paw teh, kamathoe e tami, hoi imyinnaw hanelah, na pek awh han. Kai teh nangmae BAWIPA Cathut doeh.
11 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè. “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ parọ́. “‘Ẹ kò gbọdọ̀ tan ara yín jẹ.
Ayâ e hno na parawt awh mahoeh. Ayâ na dum awh mahoeh. Buetbuet touh laithoe na kâdei awh mahoeh.
12 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fi orúkọ mi búra èké, kí o sì tipa bẹ́ẹ̀ ba orúkọ Ọlọ́run rẹ jẹ́. Èmi ni Olúwa.
Kaie min lahoi kahmanhoeh lah thoe na ka bo awh mahoeh. Na Cathut e min mathout sak awh hanh. Kai teh BAWIPA doeh.
13 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ rẹ́ aládùúgbò rẹ jẹ bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ jà á lólè. “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dá owó iṣẹ́ alágbàṣe dúró di ọjọ́ kejì.
Na imri e hno kamsoum hoeh lahoi lawm hanh. Thama lahoi lat pouh hanh. Counnae phu hah karum loum sak hanh.
14 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣépè lé adití, bẹ́ẹ̀ ni o kò gbọdọ̀ fi ohun ìdìgbòlù sí iwájú afọ́jú, ṣùgbọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run rẹ. Èmi ni Olúwa.
Hnâpang thoe na bo mahoeh. Mitdawn hmalah kamthui kawi hno na tat pouh mahoeh. Na Cathut hah barih. Kai teh BAWIPA doeh.
15 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, má ṣe ojúsàájú sí ẹjọ́ tálákà, bẹ́ẹ̀ ni o kò gbọdọ̀ gbé ti ọlọ́lá lẹ́yìn, ṣùgbọ́n fi òdodo ṣe ìdájọ́, àwọn aládùúgbò rẹ.
Lawkcengnae koe kamsoum hoeh lah lawk na ceng mahoeh. Kamathoe e noutna laipalah awm hanh. Athakaawme tami minhmai khen hanh. Na imri hah kamsoum lah lawk na ceng han.
16 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ máa ṣèyíṣọ̀hún bí olóòfófó láàrín àwọn ènìyàn rẹ. “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ohunkóhun tí yóò fi ẹ̀mí aládùúgbò rẹ wéwu. Èmi ni Olúwa.
Ayânaw minhmai mathoenae kamthang hah dei hanelah na taminaw koe na kâhlai mahoeh. Na imri runae kâhmo sak hanlah na kâcai mahoeh. Kai teh BAWIPA doeh.
17 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra arákùnrin rẹ lọ́kàn rẹ, bá aládùúgbò rẹ wí, kí o má ba à jẹ́ alábápín nínú ẹ̀bi rẹ̀.
Na lung thung hoi na hmaunawngha hmuhmanae na tawn mahoeh. Na imri a payonnae hah pak khen laipalah na yue katang han.
18 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ gbẹ̀san: má sì ṣe bínú sí èyíkéyìí nínú àwọn ènìyàn rẹ. Ṣùgbọ́n, kí ìwọ kí ó fẹ́ ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ. Èmi ni Olúwa.
Na taminaw ni nang koe payon awh pawiteh, bout pathung hanh. A yonnae hah pâkuem pouh hanh. Na imri hah nama patetlah lungpataw. Kai teh BAWIPA doeh.
19 “‘Máa pa àṣẹ mi mọ́. “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ohun ọ̀sìn rẹ máa gùn pẹ̀lú ẹ̀yà mìíràn. “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ gbin dàrúdàpọ̀ oríṣìí irúgbìn méjì sínú oko kan. “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ wọ aṣọ èyí tí a fi oríṣìí ohun èlò ìhunṣọ méjì ṣe.
Kaie phunglawk na tarawi awh han. Aphun alouklouk e saring a napui, a na tongpa âvâ na yawng sak mahoeh. Cati alouklouk e mak kâkalawt lah law dawk na patue awh mahoeh. Pahla hoi tumuen carouk teh kawng e khohna na khohnat awh mahoeh.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin tí ó jẹ́ ẹrú lòpọ̀, ẹni tí a ti mọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin mìíràn tí a kò sì tí ì rà á padà tàbí sọ ọ́ di òmìnira. Ẹ gbọdọ̀ ṣe ìwádìí kí ẹ sì jẹ wọ́n ní ìyà tó tọ́ ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ pa wọ́n, torí pé kò ì tí ì di òmìnira.
Paluen hanelah sut ham teh ratang hoeh rae a sannu ka ipkhai e tami teh hemnae a khang han. Hote napui teh amae san lah ao dawkvah thei lah awm mahoeh.
21 Kí ọkùnrin náà mú àgbò kan wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé bí i ẹbọ ẹ̀bi sí Olúwa.
Tongpa ni hai kâtapoe thueng nahanelah, tutan buet touh kamkhuengnae lukkareiim takhang koe BAWIPA koevah a thokhai han.
22 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù fún un, pẹ̀lú àgbò ẹbọ ẹ̀bi náà níwájú Olúwa fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀. A ó sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ náà jì í.
Hote tongpa ni a sakpayon e yontha nahanelah, kâtapoe thuengnae tutan hah, vaihma ni BAWIPA hmalah a thueng han. Hote tongpa teh yon ngaithoum lah ao han.
23 “‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí ẹ sì gbin igi eléso, kí ẹ ká èso wọn sí ohun èèwọ̀. Fún ọdún mẹ́ta ni kí ẹ kà á sí èèwọ̀, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́.
Nangmouh koe Kai ni na poe e ram dawk na pha awh toteh, cakawi thingthai aphunphun na ung awh hnukkhu, kum thum touh thung kapaw e a pawnaw hah, vuensoma hoeh e a paw telah na pouk awh vaiteh, na cat awh mahoeh.
24 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹrin, gbogbo èso wọ̀nyí yóò jẹ́ mímọ́, ọrẹ fún ìyìn Olúwa.
A kum palinae kapaw e a paw pueng teh a thoung dawkvah BAWIPA pholen nahanelah pasoum lah ao.
25 Ní ọdún karùn-ún ni ẹ̀yin tó lè jẹ nínú èso igi náà, kí èso wọn ba à le máa pọ̀ sí i. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
A kum panganae a pawnaw hah na ca awh han. Hottelah na sak pawiteh thingthainaw hoe a paw han. Kai teh nangmae BAWIPA Cathut lah ka o.
26 “‘Ẹ má ṣe jẹ ẹrankẹ́ran pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. “‘Ẹ kò gbọdọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ yẹ̀míwò tàbí oṣó.
A thi hoi bangpatet e a moi hai mek na cat awh mahoeh. Tami na ân mahoeh. Kut na khet hoi khueyue lawk na dei mahoeh.
27 “‘Ẹ má ṣe dá òṣù sí àárín orí yín (fífá irun ẹ̀gbẹ́ orí, tí a ó sì dá irun àárín orí sí) tàbí kí ẹ ré orí irùngbọ̀n yín bí àwọn aláìkọlà ti ń ṣe.
Na lû kâkalup lah na sam na ngaw mahoeh. Pâkhamuen na ngaw mahoeh.
28 “‘Ẹ má ṣe tìtorí òkú, gé ibi kankan nínú ẹ̀yà ara yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ sín gbẹ́rẹ́ kankan. Èmi ni Olúwa.
Kadout e tami hanelah na tak na a mahoeh. Mangkâkhuinae na sak mahoeh. Kai teh BAWIPA doeh.
29 “‘Ẹ má ṣe ba ọmọbìnrin yín jẹ́ láti sọ ọ́ di panṣágà, kí ilẹ̀ yín má ba à di ti àgbèrè, kí ó sì kún fún ìwà búburú.
Na canu kâyawt sak hanh. Hoehpawiteh ram ni kâyawt e koe kâbang vaiteh, kahawihoehe hno hoi akawi han.
30 “‘Ẹ gbọdọ̀ máa pa ìsinmi mi mọ́ kí ẹ sì fi ọ̀wọ̀ fún ibi mímọ́ mi. Èmi ni Olúwa.
Sabbath hnin hah na ya han. Kaie hnin kathoung hah na bari han. Kai teh BAWIPA doeh.
31 “‘Ẹ má ṣe tọ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí àwọn àjẹ́ lọ, ẹ kò gbọdọ̀ tọ̀ wọ́n lẹ́yìn láti jẹ́ kí wọ́n sọ yín di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Nama hoi nama kâkhinsak hanelah kahrai khueyue koe, kamlang hanh. Hmaui hai tawng awh hanh. Kai teh nangmae BAWIPA Cathut doeh.
32 “‘Fi ọ̀wọ̀ fún ọjọ́ orí arúgbó, ẹ sì bu ọlá fún àwọn àgbàlagbà kí ẹ sì bẹ̀rù Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.
Sam ka po e hmalah kangdout nateh, matawng e minhmai na bari han. Na Cathut hah na taki han. Kai teh BAWIPA doeh.
33 “‘Nígbà tí àjèjì kan bá ń gbé pẹ̀lú yín ní ilẹ̀ yín, ẹ má ṣe ṣe é ní ibi
Nangmouh koe kârayen e imyin hah na rektap mahoeh.
34 kí àjèjì tí ń gbé pẹ̀lú yín dàbí onílé láàrín yín kí ẹ sì fẹ́ràn rẹ̀ bí i ara yín, torí pé ẹ̀yin ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti rí. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Nangmouh koe kârayen e imyin hah na tami patetlah na pouk han. Nama patetlah na lungpataw han. Nangmouh teh Izip ram vah imyin lah ouk na o awh toe. Kai teh nangmae BAWIPA Cathut doeh.
35 “‘Ẹ má ṣe lo òsùwọ̀n èké, nígbà tí ẹ bá ń díwọ̀n yálà nípa òsùwọ̀n ọ̀pá, òsùwọ̀n ìwúwo tàbí òsùwọ̀n onínú.
Bangnuenae, Khingnae, tonae dawkvah kamsoum hoeh lah na sak mahoeh.
36 Ẹ jẹ́ olódodo pẹ̀lú àwọn òsùwọ̀n yín òsùwọ̀n ìtẹ̀wọ̀n, òsùwọ̀n wíwúwo, òsùwọ̀n ìyẹ̀fun àti òsùwọ̀n nǹkan olómi yín ní láti jẹ́ èyí tí kò ní èrú nínú. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti.
Kahman e yawcu, khinglung, Kahman e ephah, kahman e hinnaw hah na hno han. Kai teh Izip ram hoi nangmouh ka tâcawtkhai e nangmae BAWIPA Cathut lah ka o.
37 “‘Ẹ ó sì máa pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, ẹ ó sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.’”
Kaie phunglamnaw puenghoi lawk tâtueng e naw pueng hah na tarawi awh han. Kai teh BAWIPA doeh telah ati.