< Leviticus 18 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé:
Yahweh disse a Moisés,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé: ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
“Fala aos filhos de Israel e diz-lhes: 'Eu sou Yahweh, vosso Deus'.
3 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní Ejibiti níbi tí ẹ ti gbé rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní ilẹ̀ Kenaani níbi tí èmi ń mú yín lọ. Ẹ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ìṣe wọn.
Não fareis como eles fazem na terra do Egito, onde vivestes. Não farás como eles fazem na terra de Canaã, onde eu te trago”. Não seguireis os estatutos deles.
4 Kí ẹ̀yin kí ó sì máa ṣe òfin mi, kí ẹ̀yin sì máa pa ìlànà mi mọ́, láti máa rìn nínú wọn, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Você fará minhas ordenanças. Guardareis os meus estatutos e andareis neles. Eu sou Yahweh, vosso Deus.
5 Ẹ̀yin ó sì máa pa ìlànà mi mọ́ àti òfin mi; Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn. Èmi ni Olúwa.
Portanto, guardareis meus estatutos e minhas ordenanças, as quais, se um homem as cumprir, viverá nelas. Eu sou Yahweh.
6 “‘Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ súnmọ́ ìbátan rẹ̀ láti bá a lòpọ̀. Èmí ni Olúwa.
“'Nenhum de vocês deve se aproximar de parentes próximos, para descobrir a nudez deles: Eu sou Yahweh.
7 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyá rẹ lòpọ̀, ìyá rẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ bá a lòpọ̀.
“'Você não deve descobrir a nudez de seu pai, nem a nudez de sua mãe: ela é sua mãe. Você não deve descobrir a nudez dela.
8 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyàwó baba rẹ lòpọ̀, nítorí ìhòhò baba rẹ ni.
“'Você não deve descobrir a nudez da esposa de seu pai. É a nudez de seu pai.
9 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin rẹ tí ó jẹ́ ọmọ ìyá rẹ lòpọ̀, yálà a bí i nílé yín tàbí lóde.
“'Você não deve descobrir a nudez de sua irmã, da filha de seu pai ou da filha de sua mãe, nascida em casa ou nascida no exterior.
10 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin, ọmọ rẹ ọkùnrin lòpọ̀ tàbí ọmọbìnrin ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀ nítorí pé ìhòhò wọn, ìhòhò ìwọ fúnra rẹ̀ ni.
“'Você não descobrirá a nudez da filha de seu filho, ou da filha de sua filha, mesmo a nudez deles; pois a nudez deles é sua própria nudez.
11 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin aya baba rẹ lòpọ̀; èyí tí a bí fún baba rẹ nítorí pé arábìnrin rẹ ni.
“'Você não deve descobrir a nudez da filha da esposa de seu pai, concebida por seu pai, já que ela é sua irmã.
12 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin baba rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan baba rẹ ni.
“'Você não deve descobrir a nudez da irmã de seu pai. Ela é a parente próxima de seu pai.
13 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin màmá rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan ìyá rẹ ni.
“'Você não deve descobrir a nudez da irmã de sua mãe, pois ela é a parente próxima de sua mãe.
14 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù arákùnrin baba rẹ nípa sísún mọ́ aya rẹ̀ láti bá a lòpọ̀ nítorí pé ìyàwó ẹ̀gbọ́n baba rẹ ni.
“'Você não deve descobrir a nudez do irmão de seu pai. Não te aproximarás da esposa dele. Ela é sua tia.
15 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọ àna obìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé aya ọmọ rẹ ni. Má ṣe bá a lòpọ̀.
“'Você não deve descobrir a nudez de sua nora. Ela é a esposa de seu filho. Você não deve desvendar a nudez dela.
16 “‘Má ṣe bá aya ẹ̀gbọ́n rẹ ọkùnrin lòpọ̀ nítorí pé yóò tàbùkù ẹ̀gbọ́n rẹ.
“'Você não deve descobrir a nudez da esposa de seu irmão. É a nudez de seu irmão.
17 “‘Má ṣe bá ìyá àti ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin ọmọkùnrin rẹ tàbí ọmọbìnrin ọmọbìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan rẹ tímọ́tímọ́ ni: nítorí àbùkù ni.
“'Você não deve descobrir a nudez de uma mulher e de sua filha. Você não deve levar a filha de seu filho, ou a filha de sua filha, para desvendar sua nudez. Elas são parentes próximas. É a perversidade.
18 “‘Má ṣe fẹ́ àbúrò ìyàwó rẹ obìnrin ní aya gẹ́gẹ́ bí orogún tàbí bá a lòpọ̀, nígbà tí ìyàwó rẹ sì wà láààyè.
“'Você não deve levar uma esposa além de sua irmã, para ser uma rival, para descobrir sua nudez, enquanto sua irmã ainda estiver viva.
19 “‘Má ṣe súnmọ́ obìnrin láti bá a lòpọ̀ nígbà tí ó bá ń ṣe nǹkan oṣù, nítorí àkókò àìmọ́ ni.
“'Você não deve se aproximar de uma mulher para descobrir sua nudez, desde que ela seja impura por sua impureza.
20 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá aya aládùúgbò rẹ lòpọ̀, kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́ pẹ̀lú rẹ̀.
“'Você não deve mentir carnalmente com a esposa de seu vizinho e se contaminar com ela.
21 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ rú ẹbọ lórí pẹpẹ sí òrìṣà Moleki, kí o sì tipa bẹ́ẹ̀ ba orúkọ Ọlọ́run rẹ jẹ́. Èmi ni Olúwa.
“'Você não deve dar nenhum de seus filhos como sacrifício a Molech. Você não profanará o nome de seu Deus. Eu sou Yahweh.
22 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọkùnrin lòpọ̀ bí ìgbà tí ènìyàn ń bá obìnrin lòpọ̀: ìríra ni èyí jẹ́.
“'Você não deve deitar-se com um homem como com uma mulher. Isso é detestável.
23 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ẹranko lòpọ̀ kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́. Obìnrin kò sì gbọdọ̀ jọ̀wọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ fún ẹranko láti bá a lòpọ̀, ohun tó lòdì ni.
“'Você não deve deitar-se com nenhum animal para se contaminar com ele. Nenhuma mulher pode se entregar a um animal, deitar-se com ele: é uma perversão.
24 “‘Má ṣe fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ba ara rẹ jẹ́, torí pé nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé kúrò níwájú yín ti ba ara wọn jẹ́.
“'Não se contaminem em nenhuma destas coisas; pois em todas estas nações que estou expulsando antes de vocês foram contaminadas.
25 Nítorí pé ilẹ̀ náà di àìmọ́ nítorí náà mo fi ìyà jẹ ẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Ilẹ̀ náà sì pọ àwọn olùgbé ibẹ̀ jáde.
A terra foi profanada. Portanto, castiguei sua iniqüidade e a terra vomitou seus habitantes.
26 Ṣùgbọ́n kí ẹ máa pa àṣẹ àti òfin mi mọ́. Onílé tàbí àjèjì tó ń gbé láàrín yín kò gbọdọ̀ ṣe ọ̀kan nínú àwọn ohun ìríra wọ̀nyí.
Portanto, guardareis meus estatutos e minhas ordenanças, e não fareis nenhuma destas abominações; nem o nativo nascido, nem o estrangeiro que vive como estrangeiro entre vós
27 Nítorí pé gbogbo ohun ìríra wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ti gbé ilẹ̀ náà ṣáájú yín ti ṣe tí ó sì mú kí ilẹ̀ náà di aláìmọ́.
(para os homens da terra que foram antes de vós que fizeram todas estas abominações, e a terra foi contaminada),
28 Bí ẹ bá sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́ yóò pọ̀ yín jáde bí ó ti pọ àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ti wá ṣáájú yín jáde.
que a terra não vos vomite também, quando a contaminardes, como vomitou a nação que foi antes de vós.
29 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ohun ìríra wọ̀nyí, kí ẹ gé irú ẹni náà kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
“'Para quem quer que faça qualquer uma destas abominações, até mesmo as almas que as fizerem serão cortadas do meio de seu povo.
30 Nítorí náà ẹ gbọdọ̀ ṣe ohun tí mo fẹ́, kí ẹ má sì lọ́wọ́ nínú àṣà ìríra wọ̀nyí, tí wọn ń ṣe kí ẹ tó dé. Ẹ má ṣe fi wọ́n ba ara yín jẹ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Portanto, guardareis minhas exigências, que não pratiqueis nenhum desses abomináveis costumes que foram praticados antes de vós, e que não vos contamineis com eles. Eu sou Yahweh, vosso Deus”.

< Leviticus 18 >